< Sofonia 3 >

1 Vai celei murdare şi întinate, cetăţii asupritoare!
Ègbé ni fún ìlú aninilára, ọlọ̀tẹ̀ àti aláìmọ́.
2 Ea nu a ascultat de acea voce; nu a primit disciplinarea; nu s-a încrezut în DOMNUL; nu s-a apropiat de Dumnezeul ei.
Òun kò gbọ́rọ̀ sí ẹnikẹ́ni, òun kò gba ìtọ́ni, òun kò gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni òun kò súnmọ́ ọ̀dọ̀ Ọlọ́run rẹ̀.
3 Prinţii dinlăuntrul ei sunt lei răcnind; judecătorii ei sunt lupi de seară; ei nu rod oasele până ziua următoare.
Àwọn olórí rẹ̀ jẹ́ kìnnìún tí ń ké ramúramù, àwọn onídàájọ́ rẹ̀, ìkookò àṣálẹ́ ni wọn, wọn kò sì fi nǹkan kan kalẹ̀ fún òwúrọ̀.
4 Profeţii ei sunt persoane uşoare şi perfide; preoţii ei au întinat sanctuarul, ei au încălcat legea.
Àwọn wòlíì rẹ̀ gbéraga, wọ́n sì jẹ́ alárékérekè ènìyàn. Àwọn àlùfáà rẹ̀ ti ba ibi mímọ́ jẹ́, wọ́n sì rú òfin.
5 DOMNUL cel drept este în mijlocul ei; el nu va face nelegiuire, în fiecare dimineaţă el îşi aduce judecata la lumină, el nu eşuează; dar cel nedrept nu cunoaşte ruşine.
Olúwa ni àárín rẹ̀ jẹ́ olódodo; kì yóò ṣe ohun tí kò tọ̀nà. Àràárọ̀ ni ó máa ń mú ìdájọ́ rẹ̀ wá sí ìmọ́lẹ̀, kì í sì kùnà ní gbogbo ọjọ́ tuntun, síbẹ̀ àwọn aláìṣòótọ́ kò mọ ìtìjú.
6 Eu am stârpit naţiunile, turnurile lor sunt pustiite; eu le-am risipit străzile, încât nimeni nu trece pe acolo; cetăţile lor sunt distruse, încât nu este niciun om, nu este niciun locuitor.
“Èmi ti ké àwọn orílẹ̀-èdè kúrò, ilé gíga wọn sì ti bàjẹ́. Mo ti fi ìgboro wọn sílẹ̀ ní òfo tó bẹ́ẹ̀ tí ẹnìkankan kò kọjá níbẹ̀. Ìlú wọn parun tó bẹ́ẹ̀ tí kò sí ẹnìkan tí yóò ṣẹ́kù, kò sì ní sí ẹnìkan rárá.
7 Am spus: Sigur te vei teme de mine, vei primi instruirea; astfel încât locuinţa lor să nu fie stârpită, oricum i-am pedepsit, dar ei s-au sculat devreme şi şi-au corupt toate facerile lor.
Èmi wí fún ìlú náà wí pé, ‘Nítòótọ́, ìwọ yóò bẹ̀rù mi, ìwọ yóò sì gba ìtọ́ni!’ Bẹ́ẹ̀ ni, a kì yóò ké ibùgbé rẹ̀ kúrò bí ó ti wù kí ń jẹ wọ́n ní yà tó. Ṣùgbọ́n síbẹ̀ wọ́n sì tún ní ìtara láti ṣe ìbàjẹ́.
8 De aceea, aşteptaţi-mă, spune DOMNUL, până în ziua în care mă voi ridica pentru pradă: căci hotărârea mea este să adun naţiunile, să strâng împărăţiile, să îmi vărs indignarea asupra lor, toată mânia mea înverşunată, pentru că tot pământul va fi mistuit de focul geloziei mele.
Nítorí náà ẹ dúró dè mí,” ni Olúwa wí, “títí di ọjọ́ náà tí èmi yóò fi jẹ́rìí sí yin. Nítorí ìpinnu mi ni láti kó orílẹ̀-èdè jọ kí èmi kí ó lè kó ilẹ̀ ọba jọ àti láti da ìbínú mi jáde sórí wọn, àní gbogbo ìbínú gbígbóná mi. Nítorí gbogbo ayé ni a ó fi iná owú mi jẹ run.
9 Pentru că atunci voi da din nou popoarelor o limbă pură, ca toţi să cheme numele DOMNULUI, să îi servească într-un singur gând.
“Nígbà náà ni èmi yóò yí èdè àwọn ènìyàn padà sí èdè mímọ́, nítorí kí gbogbo wọn bá a lè máa pe orúkọ Olúwa, láti fi ọkàn kan sìn ín.
10 De dincolo de râurile Etiopiei, închinătorii mei, chiar fiica risipiţilor mei, îmi vor aduce ofranda.
Láti òkè odò Etiopia, àwọn olùjọsìn mi, àwọn ènìyàn mi tí ó ti fọ́nká, yóò mú ọrẹ wá fún mi.
11 În acea zi nu vei fi ruşinat de toate facerile tale, în care ai încălcat legea împotriva mea, pentru că atunci voi scoate afară din mijlocul tău pe cei care se bucură în mândria ta, şi nu te vei mai îngâmfa datorită muntelui meu sfânt.
Ní ọjọ́ náà ni a kì yóò sì dójútì nítorí gbogbo iṣẹ́ ibi ni tí ó ti ṣẹ̀ sí mi, nígbà náà ni èmi yóò mu kúrò nínú ìlú yìí, àwọn tí ń yọ̀ nínú ìgbéraga wọn. Ìwọ kì yóò sì gbéraga mọ́ ní òkè mímọ́ mi.
12 De asemenea, voi lăsa în mijlocul tău un popor chinuit şi sărac, şi ei se vor încrede în numele DOMNULUI.
Ṣùgbọ́n Èmi yóò fi àwọn ọlọ́kàn tútù àti onírẹ̀lẹ̀ sílẹ̀ pẹ̀lú ni àárín rẹ̀, wọn yóò sì gbẹ́kẹ̀lé orúkọ Olúwa.
13 Rămăşiţa lui Israel nu va face nelegiuire, nici nu va vorbi minciuni; nici nu se va găsi în gura lor o limbă înşelătoare, pentru că ei se vor hrăni şi se vor culca şi nimeni nu îi va înspăimânta.
Àwọn ìyókù Israẹli kì yóò hùwà ibi, wọn kì yóò sọ̀rọ̀ èké. Bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò rí ahọ́n àrékérekè ní ẹnu wọn. Àwọn yóò jẹun, wọn yóò sì dùbúlẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ẹnikẹ́ni kì yóò dẹ́rùbà wọ́n.”
14 Cântă, fiică a Sionului; strigă, Israele; veseleşte-te şi bucură-te cu toată inima, fiică a Ierusalimului.
Kọrin, ìwọ ọmọbìnrin Sioni, kígbe sókè, ìwọ Israẹli! Fi gbogbo ọkàn yọ̀, kí inú rẹ kí ó sì dùn, ìwọ ọmọbìnrin Jerusalẹmu.
15 DOMNUL a luat judecăţile tale, el a alungat pe duşmanul tău; împăratul lui Israel, DOMNUL este în mijlocul tău, nu vei mai vedea răul.
Olúwa ti mú ìdájọ́ rẹ wọ̀n-ọn-nì kúrò, ó sì ti ti àwọn ọ̀tá rẹ padà sẹ́yìn. Olúwa, ọba Israẹli wà pẹ̀lú rẹ; ìwọ kì yóò sì bẹ̀rù ibi kan mọ́.
16 În acea zi se va spune Ierusalimului: Nu te teme; şi Sionului: Să nu îţi slăbească mâinile.
Ní ọjọ́ náà, wọn yóò sọ fún Jerusalẹmu pé, “Má ṣe bẹ̀rù Sioni; má sì ṣe jẹ́ kí ọwọ́ rẹ kí ó dẹ̀.
17 DOMNUL Dumnezeul tău în mijlocul tău este puternic; el va salva, el se va bucura de tine cu bucurie; el se va odihni în dragostea lui, se va bucura de tine cu cântare.
Olúwa Ọlọ́run rẹ wà pẹ̀lú rẹ, Ó ní agbára láti gbà ọ là. Yóò yọ̀ ni orí rẹ fún ayọ̀; Yóò tún ọ ṣe nínú ìfẹ́ rẹ̀, Yóò sì fi orin yọ̀ ní orí rẹ.”
18 Îi voi aduna pe cei întristaţi pentru adunarea solemnă, care sunt ai tăi, pentru care ocara ei era o povară.
“Èmi ó kó àwọn tí ó ń banújẹ́ fún àjọ̀dún tí a yàn jọ, àwọn tí ó jẹ́ tirẹ̀; àwọn tí ẹ̀gàn rẹ̀ jásí ẹ̀rù.
19 Iată, atunci îi voi aduce la nimic pe toţi cei care te chinuiesc; şi voi salva pe cea şchioapă şi o voi aduna pe cea alungată; şi le voi aduce laudă şi faimă în fiecare ţară unde au fost făcuţi de ruşine.
Ní àkókò náà ni èmi yóò dojúkọ àwọn tí ń ni yín lára, èmi yóò gba àtiro là, èmi yóò sì ṣa àwọn tí ó ti fọ́nká jọ, èmi yóò fi ìyìn àti ọlá fún wọn ní gbogbo ilẹ̀ tí a bá ti dójútì wọ́n.
20 În acel timp vă voi aduce din nou, la timpul în care vă adun, fiindcă vă voi face un nume şi o laudă printre toate popoarele pământului, când vă voi aduce înapoi din captivitate înaintea ochilor voştri, spune DOMNUL.
Ní àkókò náà ni èmi yóò ṣà yín jọ; nígbà náà ni èmi yóò mú un yín padà wá sílé. Èmi yóò fi ọlá àti ìyìn fún un yín láàrín gbogbo ènìyàn àgbáyé, nígbà tí èmi yóò yí ìgbèkùn yín padà bọ sípò ní ojú ara yín,” ni Olúwa wí.

< Sofonia 3 >