< Zaharia 13 >

1 În acea zi se va deschide o fântână casei lui David şi locuitorilor Ierusalimului, pentru păcat şi pentru necurăţie.
“Ní ọjọ́ náà ìsun kan yóò ṣí sílẹ̀ fún ilé Dafidi àti fún àwọn ará Jerusalẹmu, láti wẹ̀ wọ́n mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ àti àìmọ́ wọn.
2 Şi se va întâmpla în acea zi, spune DOMNUL oştirilor, că voi stârpi din ţară numele idolilor şi ei nu vor mai fi amintiţi; şi de asemenea voi face pe profeţi şi duhul necurat să iasă din ţară.
“Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ni èmi ó gé orúkọ àwọn òrìṣà kúrò ni ilẹ̀ náà, a kì yóò sì rántí wọn mọ́, àti pẹ̀lú èmi ó mú àwọn wòlíì èké àti àwọn ẹ̀mí àìmọ́ kúrò ni ilẹ̀ náà.
3 Şi se va întâmpla când cineva va mai profeţi că, tatăl său şi mama sa, care l-au născut, îi vor spune: Nu vei trăi, pentru că vorbeşti minciuni în numele DOMNULUI; şi tatăl său şi mama sa, care l-au născut, îl vor străpunge când el profeţeşte.
Yóò sì ṣe, nígbà tí ẹnìkan yóò sọtẹ́lẹ̀ síbẹ̀, ni baba rẹ̀ àti ìyá rẹ̀ tí ó bí í yóò wí fún un pé, ‘Ìwọ ki yóò yè, nítorí ìwọ ń sọ ọ̀rọ̀ èké ni orúkọ Olúwa.’ Àti baba rẹ̀ àti ìyá rẹ̀ tí o bí í yóò gun un ni àgúnpa nígbà tí ó bá sọtẹ́lẹ̀.
4 Şi se va întâmpla în acea zi că, profeţii vor fi ruşinaţi, fiecare de viziunea lui, după ce va fi profeţit; nici nu vor mai purta ei o îmbrăcăminte aspră pentru a înşela;
“Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà, ojú yóò tí àwọn wòlíì èké olúkúlùkù nítorí ìran rẹ̀, nígbà tí òun ba tí sọtẹ́lẹ̀; bẹ́ẹ̀ ni wọn kì yóò sì wọ aṣọ wòlíì onírun rẹ̀ tí o fi ń tan ní jẹ.
5 Ci el va spune: Nu sunt profet, sunt agricultor, pentru că un om m-a învăţat să păzesc vite din tinereţea mea.
Ṣùgbọ́n òun o wí pé, ‘Èmi kí í ṣe wòlíì, àgbẹ̀ ni èmi; nítorí tí a ti fi mí ṣe ìránṣẹ́ láti ìgbà èwe mi wá.’
6 Şi cineva îi va spune: Ce sunt aceste răni în mâinile tale? Atunci el va răspunde: Acelea cu care am fost rănit în casa prietenilor mei.
Ẹnìkan ó sì wí fún un pé, ‘Ọgbẹ́ kín ní wọ̀nyí ni ẹ̀yìn rẹ?’ Òun o sì dáhùn pé, ‘Wọ̀nyí ni ibi tí a ti sá mi ní ilé àwọn ọ̀rẹ́ mi.’
7 Trezeşte-te, sabie, împotriva păstorului meu şi împotriva omului care este tovarăşul meu, spune DOMNUL oştirilor; loveşte păstorul, şi oile vor fi împrăştiate; şi eu îmi voi întoarce mâna asupra micuţilor.
“Dìde, ìwọ idà, sí Olùṣọ́-àgùntàn mi, àti sí ẹni tí í ṣe ẹnìkejì mi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Kọlu Olùṣọ́-àgùntàn, àwọn àgùntàn a sì túká: èmi o sì yí ọwọ́ mi sí àwọn kéékèèké.
8 Şi se va întâmpla în toată ţara, spune DOMNUL, că două părţi din ea vor fi stârpiţi şi vor muri, dar a treia parte va rămâne în ea.
Yóò sì ṣe, ni gbogbo ilẹ̀,” ni Olúwa wí, “a ó gé apá méjì nínú rẹ̀ kúrò yóò sì kú; ṣùgbọ́n apá kẹta yóò kù nínú rẹ̀.
9 Şi eu voi duce a treia parte prin foc şi îi voi curăţa precum argintul este curăţat şi îi voi încerca precum aurul este încercat; ei vor chema numele meu şi eu îi voi asculta; voi spune: Acesta este poporul meu; iar ei vor spune: DOMNUL este Dumnezeul meu.
Èmi ó sì mú apá kẹta náà la àárín iná, èmi yóò sì yọ́ wọn bí a ti yọ́ fàdákà, èmi yóò sì dán wọn wò, bi a tí ń dán wúrà wò: wọn yóò sì pé orúkọ mi, èmi yóò sì dá wọn lóhùn: èmi yóò wí pé, ‘Àwọn ènìyàn mi ni,’ àwọn yóò sì wí pé, ‘Olúwa ni Ọlọ́run wa.’”

< Zaharia 13 >