< Apocolipsa 1 >
1 Revelația lui Isus Cristos, pe care Dumnezeu i-a dat-o, pentru a arăta robilor săi lucrurile care trebuie să se întâmple în curând; și el a înștiințat și a trimis aceasta prin îngerul său robului său Ioan,
Ìfihàn ti Jesu Kristi, tí Ọlọ́run fi fún un, láti fihàn fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, ohun tí kò le ṣàìṣẹ ní lọ́ọ́lọ́ọ́; ó sì ránṣẹ́, ó sì fi í hàn láti ọwọ́ angẹli rẹ̀ wá fún Johanu, ìránṣẹ́ rẹ̀,
2 Care a adus mărturie despre cuvântul lui Dumnezeu și despre mărturia lui Isus Cristos și despre toate lucrurile pe care le-a văzut.
ẹni tí ó jẹ́rìí ohun gbogbo tí ó rí, èyí ì ni ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, àti ẹ̀rí ti Jesu Kristi.
3 Binecuvântat este cel ce citește și cei ce aud cuvintele acestei profeții și țin cele scrise în ea, căci timpul este aproape.
Ẹni ìbùkún ni ẹni tí ń kà, àti àwọn tí ó ń gbọ́ ọ̀rọ̀ ìsọtẹ́lẹ̀ yìí, tí ó sì ń pa nǹkan wọ̀n-ọn-nì tí a kọ sínú rẹ̀ mọ́, nítorí ìgbà kù sí dẹ̀dẹ̀.
4 Ioan, celor șapte biserici care sunt în Asia: Har vouă și pace de la cel care este și care era și care vine, și de la cele șapte Duhuri care sunt înaintea tronului său,
Johanu, Sí àwọn ìjọ méje tí ń bẹ ní Asia: Oore-ọ̀fẹ́ fún yín, àti àlàáfíà, láti ọ̀dọ̀ ẹni tí ó ń bẹ, tí ó sì ti wà, tí ó sì ń bọ̀ wá; àti láti ọ̀dọ̀ àwọn ẹ̀mí méje tí ń bẹ níwájú ìtẹ́ rẹ̀;
5 Și de la Isus Cristos, martorul credincios și întâiul născut dintre morți și prințul împăraților pământului. A lui, care ne-a iubit și ne-a spălat de păcatele noastre în propriul lui sânge,
àti láti ọ̀dọ̀ Jesu Kristi, ẹlẹ́rìí olóòtítọ́, àkọ́bí nínú àwọn òkú, àti aláṣẹ àwọn ọba ayé. Ẹni tí ó fẹ́ wa, ẹni tí ó gbà wá kúrò lọ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ wa nípa ẹ̀jẹ̀ rẹ̀,
6 Și ne-a făcut împărați și preoți pentru Dumnezeu și Tatăl său, a lui fie gloria și domnia pentru totdeauna și întotdeauna. Amin. (aiōn )
tí ó sì ti fi wá jẹ ọba àti àlùfáà láti sin Ọlọ́run àti Baba rẹ; tirẹ̀ ni ògo àti ìjọba láé àti láéláé. Àmín. (aiōn )
7 Iată, el vine cu norii; și fiecare ochi îl va vedea și cei care l-au străpuns; și toate semințiile pământului vor boci din cauza lui. Da, Amin.
“Kíyèsi i, o ń bọ̀ nínú àwọsánmọ̀, gbogbo ojú ni yóò sì rí i, àti àwọn tí ó gún un ní ọ̀kọ̀ pẹ̀lú”; àti gbogbo orílẹ̀-èdè ayé ni “yóò sì máa pohùnréré ẹkún nítorí rẹ̀.”
8 Eu sunt Alfa și Omega, începutul și sfârșitul, spune Domnul, care este și care era și care vine, Cel Atotputernic.
“Èmi ni Alfa àti Omega,” ni Olúwa Ọlọ́run wí, “ẹni tí ó ń bẹ, tí ó ti wà, tí ó sì ń bọ̀ wá, alágbára.”
9 Eu, Ioan, care de altfel sunt fratele vostru și părtaș în necazul și în împărăția și în răbdarea lui Isus Cristos, eram pe insula numită Patmos, din cauza cuvântului lui Dumnezeu și din cauza mărturiei lui Isus Cristos.
Èmi, Johanu, arákùnrin yín àti alábápín pẹ̀lú yín nínú wàhálà àti ìjọba àti sùúrù tí ń bẹ nínú Jesu, wà ní erékúṣù tí a ń pè ní Patmo, nítorí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, àti nítorí ẹ̀rí Jesu Kristi.
10 Eram în Duhul în ziua Domnului și am auzit în spatele meu o voce tare, ca a unei trâmbițe,
Mo wà nínú Ẹ̀mí ní ọjọ́ Olúwa, mo sì gbọ́ ohùn ńlá kan lẹ́yìn mi, bí ìró ìpè,
11 Spunând: Eu sunt Alfa și Omega, cel dintâi și cel de pe urmă; și: Ceea ce vezi, scrie într-o carte și trimite-o celor șapte biserici care sunt în Asia: la Efes și la Smirna și la Pergam și la Tiatira și la Sardes și la Filadelfia și la Laodiceea.
Ó ń wí pé, “Kọ́ ìwé rẹ̀, ohun tí ìwọ rí, kí ó sí fi ránṣẹ́ sí àwọn ìjọ méje; sí Efesu, àti sí Smirna, àti sí Pargamu, àti sí Tiatira, àti sí Sardi, àti sí Filadelfia, àti sí Laodikea.”
12 Și m-am întors ca să văd vocea care vorbea cu mine. Și, fiind întors, am văzut șapte sfeșnice de aur;
Mo sì yí padà láti wo ohùn tí ń bá mi sọ̀rọ̀. Nígbà tí mo yípadà, mo rí ọ̀pá fìtílà wúrà méje,
13 Și în mijlocul celor șapte sfeșnice era cineva asemănător Fiului Omului, îmbrăcat cu o haină lungă până la picioare și încins la piept cu un brâu de aur.
àti láàrín àwọn ọ̀pá fìtílà náà, ẹnìkan tí ó dàbí “ọmọ ènìyàn,” tí a wọ̀ ní aṣọ tí ó kanlẹ̀ dé ẹsẹ̀, tí a sì fi àmùrè wúrà dì ní ẹ̀gbẹ́.
14 Capul și părul lui erau albe ca lâna, ca zăpada [erau] de albe; și ochii lui erau ca flacăra focului;
Orí rẹ̀ àti irun rẹ̀ funfun bí ẹ̀gbọ̀n òwú, ó funfun bí yìnyín; ojú rẹ̀ sì dàbí, ọwọ́ iná.
15 Și picioarele lui asemănătoare aramei fine, ca arzând într-un cuptor; și vocea lui ca vuietul multor ape.
Ẹsẹ̀ rẹ̀ sì dàbí idẹ dáradára, bí ẹni pé a dà á nínú ìléru; ohùn rẹ̀ sì dàbí ìró omi púpọ̀.
16 Și avea în mâna lui dreaptă șapte stele; și din gura lui ieșea o sabie ascuțită cu două tăișuri; și înfățișarea lui era ca soarele când strălucește în puterea lui.
Ó sì ní ìràwọ̀ méje ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀; àti láti ẹnu rẹ̀ wá ni idà olójú méjì mímú ti jáde. Ojú rẹ̀ sì dàbí oòrùn tí ó ń fi agbára rẹ̀ hàn.
17 Și când l-am văzut, am căzut la picioarele lui, ca mort. Iar el și-a pus mâna dreaptă peste mine, spunându-mi: Nu te teme, eu sunt cel dintâi și cel de pe urmă,
Nígbà tí mo rí i, mo wólẹ̀ ní ẹsẹ̀ rẹ̀ bí ẹni tí ó kú. Ó sì fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ lé mi, ó ń wí fún mi pé, “Má ṣe bẹ̀rù. Èmi ni ẹni ìṣáájú àti ẹni ìkẹyìn.
18 Și sunt cel ce trăiește deși a fost mort; și, iată, eu sunt viu pentru totdeauna și întotdeauna, Amin; și am cheile iadului și ale morții. (aiōn , Hadēs )
Èmi ni ẹni tí ó ń bẹ láààyè, tí ó sì ti kú; sì kíyèsi i, èmi sì ń bẹ láààyè sí i títí láé! Mo sì ní kọ́kọ́rọ́ ikú àti ti ipò òkú lọ́wọ́. (aiōn , Hadēs )
19 Scrie lucrurile pe care le-ai văzut și cele care sunt și cele care vor fi după acestea,
“Kọ̀wé nítorí náà ohun tí ìwọ ti rí, àti ti ohun tí ń bẹ, àti ti ohun tí yóò hù lẹ́yìn èyí;
20 Misterul celor șapte stele pe care le-ai văzut în mâna mea dreaptă și a celor șapte sfeșnice de aur. Cele șapte stele sunt îngerii celor șapte biserici și cele șapte sfeșnice pe care le-ai văzut sunt cele șapte biserici.
ohun ìjìnlẹ̀ tí ìràwọ̀ méje náà tí ìwọ rí ní ọwọ́ ọ̀tún mi, àti ọ̀pá wúrà fìtílà méje náà. Ìràwọ̀ méje ni àwọn angẹli ìjọ méje náà: àti ọ̀pá fìtílà méje náà ní àwọn ìjọ méje.