< Psalmii 9 >

1 Mai marelui muzician, conform melodiei mutlaben, un psalm al lui David. Te voi lăuda, DOAMNE, cu întreaga mea inimă; voi istorisi toate lucrările tale minunate.
Fún adarí orin. Ní ti ohun orin. “Ní ti ikú ọmọ.” Saamu ti Dafidi. Èmi ó yìn ọ́, Olúwa, pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi; èmi ó sọ ti ìyanu rẹ gbogbo.
2 Mă voi veseli și mă voi bucura în tine; voi cânta laudă numelui tău, O, tu, cel Preaînalt.
Inú mi yóò dùn, èmi yóò sì yọ̀ nínú rẹ; èmi ó kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ, Ìwọ Ọ̀gá-Ògo jùlọ.
3 După ce dușmanii mei vor da înapoi, vor cădea și vor pieri la prezența ta,
Àwọn ọ̀tá mi pẹ̀yìndà; wọ́n kọsẹ̀ wọn sì ṣègbé níwájú rẹ.
4 Pentru că ai susținut dreptul meu și cauza mea; ai șezut pe tron, judecând drept.
Nítorí ìwọ ti di òtítọ́ àti ọ̀ràn mi mú; ìwọ ti jókòó lórí ìtẹ́ rẹ, láti ṣe ìdájọ́ òdodo.
5 Ai mustrat păgânii, ai nimicit pe cei stricați, le-ai șters numele pentru totdeauna și întotdeauna.
Ìwọ ti bá orílẹ̀-èdè wí, Ìwọ sì ti pa ẹni búburú run; Ìwọ ti yọ orúkọ wọn kúrò láé àti láéláé.
6 O, dușmanule! Distrugerile s-au sfârșit pentru totdeauna; ai distrus cetăți și amintirea lor a pierit cu ele.
Ìparun àìlópin ti borí àwọn ọ̀tá, ìwọ ti fa àwọn ìlú wọn tu; àní ìrántí wọn sì ti ṣègbé.
7 Dar DOMNUL va dăinui pentru totdeauna; și-a pregătit tronul său pentru judecată.
Olúwa jẹ ọba títí láé; ó ti gbé ìtẹ́ rẹ̀ kalẹ̀ fún ìdájọ́.
8 Și va judeca lumea în dreptate, în integritate va administra judecată popoarelor.
Òun yóò sì ṣe ìdájọ́ ayé ní òdodo; yóò ṣe àkóso ènìyàn pẹ̀lú òdodo.
9 DOMNUL va fi de asemenea un loc de scăpare pentru cel oprimat, un loc de scăpare în timpuri de necaz.
Olúwa ni ààbò fún àwọn tí a ni lára, ibi ìsádi ní àkókò ìpọ́njú.
10 Și cei ce cunosc numele tău își vor pune încrederea în tine, pentru că tu, DOAMNE, nu ai părăsit pe cei ce te caută.
Àwọn tí ó mọ orúkọ rẹ yóò gbẹ́kẹ̀lé ọ, nítorí, Olúwa, kò kọ àwọn tó ń wá a sílẹ̀.
11 Cântați laude DOMNULUI care locuiește în Sion; vestiți între popoare facerile lui.
Kọ orin ìyìn sí Olúwa, tí o ń jẹ ọba ní Sioni; kéde láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ohun tí ó ṣe.
12 Când cercetează vărsarea de sânge, își amintește de ei, el nu uită strigătul celui umil.
Nítorí ẹni tí ó ń gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ rántí; òun kò kọ ẹkún àwọn tí a pọ́n lójú.
13 Ai milă de mine, DOAMNE, privește tulburarea mea din partea celor ce mă urăsc, tu, care mă ridici de la porțile morții,
Olúwa, wo bí àwọn ọ̀tá ṣe ń ṣe inúnibíni sí mi! Ṣàánú, kí o sì gbé mí sókè kúrò ní ẹnu-ọ̀nà ikú,
14 Ca să istorisesc toată lauda ta în porțile fiicei Sionului; mă voi bucura în salvarea ta.
kí èmi kí ó lè sọ ti ìyìn rẹ ni ẹnu-ọ̀nà àwọn ọmọbìnrin Sioni àti láti máa yọ̀ nínú ìgbàlà rẹ.
15 Păgânii sunt scufundați în groapa pe care au făcut-o; piciorul le este prins în plasa pe care au ascuns-o.
Àwọn orílẹ̀-èdè ti jì sí kòtò tí wọn ti gbẹ́; ẹsẹ̀ wọn ni àwọ̀n tí wọ́n dẹ sílẹ̀ kọ́.
16 DOMNUL este cunoscut prin judecata pe care o face; cel stricat este prins în lucrarea propriilor mâini. (Higaion, Selah)
A mọ Olúwa nípa òdodo rẹ̀; àwọn ènìyàn búburú ni a dẹ́kun mú nípa iṣẹ́ ọwọ́ wọn.
17 Cei stricați vor fi întorși în iad împreună cu toate națiunile care uită pe Dumnezeu. (Sheol h7585)
Àwọn ènìyàn búburú ni a ó dà sí isà òkú, àti gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó gbàgbé Ọlọ́run. (Sheol h7585)
18 Căci cei nevoiași nu vor fi uitați întotdeauna; speranța celor săraci nu va pieri pentru totdeauna.
Ṣùgbọ́n àwọn aláìní ni a kò ní gbàgbé láéláé, ìrètí àwọn ti ó tálákà ni a kì yóò gbàgbé láéláé.
19 Ridică-te, DOAMNE, să nu învingă omul; să fie judecați păgânii înaintea ta.
Dìde, Olúwa, má ṣe jẹ́ kí ènìyàn borí; jẹ́ kí a ṣe ìdájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè ni iwájú rẹ.
20 Umple-i de groază, DOAMNE, ca națiunile să știe că ele însele sunt doar oameni. (Selah)
Lù wọ́n pẹ̀lú ìpayà, Olúwa; jẹ́ kí àwọn orílẹ̀-èdè mọ̀ pé ènìyàn lásán ni wọ́n. (Sela)

< Psalmii 9 >