< Psalmii 85 >

1 Mai marelui muzician, un psalm pentru fiii lui Core. DOAMNE, tu ai fost binevoitor cu țara ta, ai adus înapoi pe captivii lui Iacob.
Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu. Ìwọ fi ojúrere hàn fún ilé rẹ, Olúwa; ìwọ mú ohun ìní Jakọbu bọ̀ sí ipò.
2 Ai iertat nelegiuirea poporului tău, ai acoperit tot păcatul lor. (Selah)
Ìwọ dárí àìṣedéédéé àwọn ènìyàn rẹ jì ìwọ sì bó ẹ̀ṣẹ̀ wọn mọ́lẹ̀. (Sela)
3 Ți-ai abătut toată furia, te-ai întors de la înverșunarea mâniei tale.
Ìwọ fi àwọn ìbínú rẹ sápá kan ìwọ sì yípadà kúrò nínú ìbínú gbígbóná rẹ.
4 Întoarce-ne, Dumnezeul salvării noastre, și fă să înceteze mânia ta față de noi.
Yí wa padà, Ọlọ́run ìgbàlà wa, kí o sì yí ìbínú rẹ̀ padà kúrò lọ́dọ̀ wa.
5 Te vei mânia pe noi pentru totdeauna? Îți vei prelungi mânia din generație în generație?
Ìwọ yóò ha máa bínú sí wa títí láé? Ìwọ yóò ha mú ìbínú rẹ pẹ́ yí gbogbo ìran ká?
6 Nu ne vei înviora din nou, ca poporul tău să se bucure în tine?
Ìwọ kì yóò ha sọ wá jí padà mọ́, pé kí àwọn ènìyàn rẹ lè yọ nínú rẹ?
7 Arată-ne mila ta, DOAMNE, și dă-ne salvarea ta.
Fi ìfẹ́ rẹ tí kò le è kùnà hàn wá, Olúwa, kí o sì fún wa ní ìgbàlà rẹ.
8 Voi asculta ce va vorbi Dumnezeu DOMNUL, căci va vorbi pace poporului său și sfinților săi, dar nu îi lăsa să se întoarcă din nou la nebunie.
Èmi ó gbọ́ ohun tí Olúwa Ọlọ́run yóò wí; ó ṣèlérí àlàáfíà fún àwọn ènìyàn rẹ̀, àní ẹni mímọ́ rẹ̀, ṣùgbọ́n má ṣe jẹ́ kí wọn padà sí àìmoye.
9 Cu siguranță salvarea lui este aproape de cei ce se tem de el, ca gloria să locuiască în țara noastră.
Nítòótọ́ ìgbàlà rẹ̀ súnmọ́ àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, pé kí ògo rẹ̀ kí ó lè gbé ní ilẹ̀ wa.
10 Mila și adevărul s-au întâlnit; dreptatea și pacea s-au sărutat.
Ìfẹ́ àti òtítọ́ parapọ̀; òdodo àti àlàáfíà fẹnu ko ara wọn.
11 Adevărul va țâșni din pământ și dreptatea va privi din cer.
Òtítọ́ ń sun jáde láti ilẹ̀ wá òdodo sì bojú wolẹ̀ láti ọ̀run.
12 Da, DOMNUL va da ce este bun; și țara noastră își va da venitul.
Olúwa yóò fi ohun dídára fún ni nítòótọ́, ilẹ̀ wa yóò sì mú ìkórè rẹ̀ jáde.
13 Dreptatea va merge înaintea lui; și ne va așeza pe calea pașilor săi.
Òdodo síwájú rẹ lọ o sì pèsè ọ̀nà fún ìgbésẹ̀ rẹ̀.

< Psalmii 85 >