< Psalmii 79 >

1 Un psalm al lui Asaf. Dumnezeule, păgânii au intrat în moștenirea ta; templul tău cel sfânt l-au pângărit; au făcut Ierusalimul ruine.
Saamu ti Asafu. Ọlọ́run, àwọn orílẹ̀-èdè ti wá ilẹ̀ ìní rẹ; wọ́n ti ba tẹmpili mímọ́ rẹ jẹ́, wọn di Jerusalẹmu kù sí òkìtì àlàpà.
2 Trupurile moarte ale servitorilor tăi le-au dat să fie hrană pentru păsările cerului, carnea sfinților tăi pentru fiarele pământului.
Wọn ti fi ara òkú àwọn ìránṣẹ́ rẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run ní oúnjẹ, ẹran-ara àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ fún ẹranko ilẹ̀.
3 Le-au vărsat sângele ca apa în jurul Ierusalimului; și nu a fost nimeni să îi îngroape.
Wọ́n tu ẹ̀jẹ̀ jáde gẹ́gẹ́ bí omi yí Jerusalẹmu ká, kò sì ṣí àwọn tí yóò sìn wọ́n.
4 Noi am devenit de ocară pentru vecinii noștri, o batjocură și un lucru de râs pentru cei ce sunt împrejurul nostru.
Àwa di ohun ẹ̀gàn sí àwọn tí ó yí wa ká, àbùkù àti ìfiṣe ẹlẹ́yà sí àwọn tí ó yí wa ká.
5 Până când, DOAMNE? Vei fi mânios pentru totdeauna? Va arde gelozia ta ca un foc?
Nígbà wo, Olúwa? Ní ìwọ ó máa bínú títí láé? Yóò ti pẹ́ tó ti owú rẹ yóò ha jò bí iná?
6 Revarsă-ți mânia peste păgânii ce nu te-au cunoscut și peste împărățiile ce nu au chemat numele tău.
Tú ìbínú rẹ jáde sí orílẹ̀-èdè tí kò ní ìmọ̀ rẹ, lórí àwọn ìjọba tí kò pe orúkọ rẹ;
7 Fiindcă au mâncat pe Iacob și i-au pustiit locuința.
nítorí wọ́n ti run Jakọbu wọ́n sì sọ ibùgbé rẹ di ahoro.
8 Nu îți aminti împotriva noastră de nelegiuirile dinainte; să ne întâmpine degrabă îndurările tale blânde, căci suntem foarte înjosiți.
Má ṣe ka ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba wa sí wa lọ́rùn jẹ́ kí àánú rẹ wá kánkán láti bá wa, nítorí tí a rẹ̀ wá sílẹ̀ gidigidi.
9 Ajută-ne, Dumnezeul salvării noastre, pentru gloria numelui tău, și scapă-ne și îndepărtează păcatele noastre, pentru numele tău.
Ràn wá lọ́wọ́, Ọlọ́run Olùgbàlà wa, fún ògo orúkọ rẹ; gbà wá kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ wa jì nítorí orúkọ rẹ.
10 De ce să spună păgânii: Unde este Dumnezeul lor? Să fie el cunoscut printre păgâni, înaintea ochilor noștri, prin răzbunarea sângelui vărsat al servitorilor tăi.
Àwọn orílẹ̀-èdè yóò máa wí pé, “Níbo ni Ọlọ́run wọn wà?” Ní ojú wa, kí a mọ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè kí ó sì gbẹ̀san àwọn ẹ̀jẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ tí a tú jáde.
11 Să ajungă geamătul prizonierului înaintea ta; conform măreției puterii tale păstrează pe cei ce sunt rânduiți să moară.
Jẹ́ kí ìmí ẹ̀dùn oǹdè náà wá síwájú rẹ, gẹ́gẹ́ bí títóbi agbára rẹ ìwọ ṣe ìtọ́jú àwọn ti a dá lẹ́bi ikú.
12 Și întoarce vecinilor noștri de șapte ori în sânul lor, ocara lor, cu care te-au ocărât, Doamne.
San án padà sí àyà àwọn aládùúgbò wa nígbà méje nípa ẹ̀gàn tí wọn ti gàn ọ́ Olúwa.
13 Așa că noi, poporul tău și oile pășunii tale, îți vom aduce mulțumiri pentru totdeauna, vom vesti lauda ta din generație în generație.
Nígbà náà àwa ènìyàn rẹ, àti àgùntàn pápá rẹ, yóò fi ọpẹ́ fún ọ títí láé; láti ìran dé ìran ni àwa ó fi ìyìn rẹ hàn.

< Psalmii 79 >