< Psalmii 69 >
1 Mai marelui muzician, pe trâmbiță, un psalm al lui David. Salvează-mă, Dumnezeule, căci apele mi-au intrat până la suflet.
Fún adarí orin. Tí ohùn “Àwọn Lílì.” Ti Dafidi. Gbà mí, Ọlọ́run, nítorí omi ti kún dé ọrùn mi.
2 Mă scufund în adânc noroi, unde nu este sprijin, am ajuns în ape adânci, unde potopurile mă acoperă.
Mo ń rì nínú irà jíjìn, níbi tí kò sí ibi ìfẹsẹ̀lé. Mo ti wá sínú omi jíjìn; ìkún omi bò mí mọ́lẹ̀.
3 Am obosit de a mai striga, mi s-a uscat gâtul, ochii mei se sfârșesc în timp ce aștept pe Dumnezeul meu.
Agara dá mi, mo ń pè fún ìrànlọ́wọ́; ọ̀fun mí gbẹ, ojú mi ṣú, nígbà tí èmi dúró de Ọlọ́run mi.
4 Cei ce mă urăsc fără motiv sunt mai mulți decât perii capului meu, cei ce m-ar nimici, fiind dușmanii mei pe nedrept, sunt puternici: atunci am dat înapoi ce nu am luat.
Àwọn tí ó kórìíra mi láìnídìí wọ́n ju irun orí mi lọ, púpọ̀ ni àwọn ọ̀tá mi láìnídìí, àwọn tí ń wá láti pa mí run. A fi ipá mú mi láti san ohun tí èmi kò jí.
5 Dumnezeule, tu cunoști nechibzuința mea; și păcatele mele nu sunt ascunse de tine.
Ìwọ mọ òmùgọ̀ mi, Ọlọ́run; ẹ̀bi mi kò pamọ́ lójú rẹ.
6 Să nu fie rușinați cei ce te așteaptă, Doamne DUMNEZEUL oștirilor, să nu fie încurcați din cauza mea cei ce te caută, Dumnezeul lui Israel.
Má ṣe dójútì àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ nítorí mi, Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun; má ṣe jẹ́ kí àwọn tó ń wá ọ dààmú nítorí mi, Ọlọ́run Israẹli.
7 Deoarece pentru tine am purtat ocară; rușine mi-a acoperit fața.
Nítorí rẹ ni mo ń ru ẹ̀gàn, ìtìjú sì bo ojú mi.
8 Am devenit un străin fraților mei și un înstrăinat copiilor mamei mele.
Mo jẹ́ àjèjì si àwọn arákùnrin mi; àlejò sí àwọn arákùnrin ìyá mi;
9 Pentru că zelul casei tale m-a mâncat; și ocările celor ce te-au ocărât au căzut peste mine.
nítorí ìtara ilé rẹ jẹ mí run, àti ẹ̀gàn àwọn tí ń gàn ọ́ ṣubú lù mí.
10 Când am plâns și mi-am disciplinat sufletul cu postire, aceasta a fost pentru ocara mea.
Nígbà tí mo sọkún tí mo sì ń fi àwẹ̀ jẹ ara mi ní ìyà èyí náà sì dín ẹ̀gàn mi kù;
11 Pânza de sac am făcut-o de asemenea îmbrăcămintea mea; și am devenit un proverb pentru ei.
nígbà tí mo wọ aṣọ àkísà, àwọn ènìyàn ń pa òwe mọ́ mi.
12 Cei ce stau în poartă vorbesc împotriva mea; și eu am fost cântarea bețivilor.
Àwọn tí ó jókòó ní ẹnu ibodè ń bú mi, mo sì di orin àwọn ọ̀mùtí.
13 Dar cât despre mine, rugăciunea mea este către tine, DOAMNE, la timpul potrivit ascultă-mă în adevărul salvării tale, Dumnezeule, în mulțimea milei tale.
Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi ni ìwọ ni èmi ń gbàdúrà mi sí Olúwa, ní ìgbà ìtẹ́wọ́gbà Ọlọ́run, nínú ìfẹ́ títóbi rẹ, dá mi lóhùn pẹ̀lú ìgbàlà rẹ tí ó dájú.
14 Scapă-mă din noroi și nu mă lăsa să mă scufund, să fiu scăpat de cei ce mă urăsc și din apele adânci!
Gbà mí kúrò nínú ẹrẹ̀, má ṣe jẹ́ kí n rì; gbà mí lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra mi, kúrò nínú ibú omi.
15 Nu lăsa potopul de ape să mă acopere, nici nu lăsa adâncul să mă înghită și nu lăsa groapa să își închidă gura peste mine.
Má ṣe jẹ́ kí ìkún omi bò mí mọ́lẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni má ṣe jẹ́ kí ọ̀gbìn gbé mi mì kí o má sì ṣe jẹ́ kí ihò pa ẹnu rẹ̀ dé mọ́ mi.
16 Ascultă-mă, DOAMNE, căci bunătatea ta iubitoare este bună, conform cu mulțimea îndurărilor tale blânde întoarce-te spre mine,
Dá mí lóhùn, Olúwa, nínú ìṣeun ìfẹ́ rẹ; nínú ọ̀pọ̀ àánú rẹ yípadà sí mi.
17 Și nu îți ascunde fața de servitorul tău, căci sunt în necaz, ascultă-mă repede.
Má ṣe pa ojú rẹ mọ́ fún ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ: yára dá mi lóhùn, nítorí mo wà nínú ìpọ́njú.
18 Aproprie-te de sufletul meu și răscumpără-l, eliberează-mă, din cauza dușmanilor mei.
Súnmọ́ tòsí kí o sì gbà mí là; rà mí padà nítorí àwọn ọ̀tá mi.
19 Tu ai cunoscut ocara mea și rușinea mea și dezonoarea mea, potrivnicii mei sunt toți înaintea ta.
Ìwọ ti mọ ẹ̀gàn mi, ìtìjú mi àti àìlọ́lá; gbogbo àwọn ọ̀tá mi wà níwájú rẹ.
20 Ocara mi-a frânt inima; și sunt plin de disperare și am căutat pe cineva să aibă milă, dar nu s-a găsit nimeni, și mângâietori, dar nu am găsit pe nimeni.
Ẹ̀gàn ba ọkàn mi jẹ́, wọ́n fi mí sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́; mo ń wá aláàánú, ṣùgbọ́n kò sí, mo ń wá olùtùnú, ṣùgbọ́n n kò rí ẹnìkankan.
21 Mi-au dat de asemenea fiere ca mâncare și în setea mea mi-au dat oțet să beau.
Wọ́n fi òróró fún mi pẹ̀lú ohun jíjẹ mi, àti ní òùngbẹ mi, wọ́n fi ọtí kíkan fún mi.
22 Să devină masa o cursă înaintea lor și ceea ce ar fi fost pentru bunăstarea lor, să le fie o capcană.
Jẹ́ kí tábìlì wọn kí ó di ìkẹ́kùn ní iwájú wọn, kí ó sì di okùn dídẹ fún àwọn tó wà ní àlàáfíà.
23 Să li se întunece ochii, pentru ca să nu vadă; și fă rărunchii lor să tremure continuu.
Kí ojú wọn kì í ó ṣókùnkùn, kí wọn má ṣe ríran, kí ẹ̀yin wọn di títẹ̀ títí láé.
24 Revarsă-ți indignarea peste ei și furioasa ta mânie să îi apuce.
Tú ìbínú rẹ jáde sí wọn; kí ìbínú gbígbóná rẹ bò wọ́n mọ́lẹ̀.
25 Să le fie pustii locuințele; și nimeni să nu locuiască în corturile lor.
Kí ibùjókòó wọn di ahoro; kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé nínú wọn.
26 Fiindcă ei persecută pe cel pe care tu l-ai lovit; și vorbesc spre mâhnirea celor pe care i-ai rănit.
Nítorí wọ́n ń ṣe inúnibíni sí ẹni tí ìwọ ti lù, àti ìrora àwọn tí ó ti ṣèṣe.
27 Adaugă nelegiuire nelegiuirii lor și nu îi lăsa să intre în dreptatea ta.
Fi ẹ̀sùn kún ẹ̀sùn wọn; Má ṣe jẹ́ kí wọn pín nínú ìgbàlà rẹ.
28 Să fie numele lor șterse din cartea celor vii și să nu fie scriși cu drepții.
Jẹ́ kí a yọ wọ́n kúrò nínú ìwé ìyè kí á má kà wọ́n pẹ̀lú àwọn olódodo.
29 Dar eu sunt sărac și întristat, salvarea ta, Dumnezeule, să mă așeze în înalt!
Ṣùgbọ́n tálákà àti ẹni-ìkáàánú ni èmí, Ọlọ́run, jẹ́ kí ìgbàlà rẹ gbé mi lékè.
30 Voi lăuda numele lui Dumnezeu cu o cântare și îl voi preamări cu mulțumire.
Èmi yóò fi orin gbé orúkọ Ọlọ́run ga èmi yóò fi ọpẹ́ gbé orúkọ rẹ̀ ga.
31 Aceasta de asemenea îi va plăcea DOMNULUI mai mult decât un bou sau un taur care are coarne și copite.
Eléyìí tẹ́ Olúwa lọ́rùn ju ọ̀dá màlúù lọ ju akọ màlúù pẹ̀lú ìwo rẹ̀ àti bàtà rẹ̀.
32 Cel umil va vedea aceasta și se va veseli; și inima voastră va trăi, cei ce căutați pe Dumnezeu.
Àwọn òtòṣì yóò rí, wọn yóò sì yọ̀: ẹ̀yin yóò wá Ọlọ́run, ọkàn yín yóò sì wà láààyè!
33 Pentru că DOMNUL ascultă pe cel sărac și nu disprețuiește pe prizonierii săi.
Olúwa, gbọ́ ti aláìní, kì ó sì kọ àwọn ìgbèkùn sílẹ̀.
34 Cerul și pământul să îl laude, mările și fiecare lucru care se mișcă în ele!
Kí ọ̀run àti ayé yìn ín, òkun àti àwọn tí ń gbé inú rẹ̀,
35 Căci Dumnezeu va salva Sionul și va zidi cetățile lui Iuda, ca ei să locuiască acolo și să îl stăpânească.
nítorí tí Ọlọ́run yóò gba Sioni là yóò sì tún àwọn ìlú Juda wọ̀nyí kọ́. Kí wọn ó lè máa gbé ibẹ̀, kí wọn ó lè máa ní ní ilẹ̀ ìní;
36 De asemenea sămânța servitorilor săi îl va moșteni și cei ce iubesc numele lui vor locui în el.
àwọn ọmọ ọmọ ọ̀dọ̀ ni yóò máa jogún rẹ̀, àwọn tí ó fẹ́ orúkọ rẹ ni yóò máa gbé inú rẹ̀.