< Psalmii 42 >
1 Mai marelui muzician, „Maschil”, pentru fiii lui Core. Cum tânjește căpriorul după apa pâraielor, așa tânjește sufletul meu după tine, Dumnezeule.
Fún adarí orin. Maskili ti àwọn ọmọ Kora. Bí àgbọ̀nrín ti ń mí hẹlẹ sí ipa odò omi, bẹ́ẹ̀ ni ọkàn mi ń mí hẹlẹ sí ọ Ọlọ́run.
2 Sufletul meu însetează după Dumnezeu, după Dumnezeul cel viu, când voi veni și mă voi arăta înaintea lui Dumnezeu?
Òùngbẹ Ọlọ́run ń gbẹ ọkàn mi, fún Ọlọ́run alààyè. Nígbà wo ni èmi ó lọ bá Ọlọ́run?
3 Lacrimile mele au fost mâncarea mea zi și noapte, în timp ce ei îmi spun continuu: Unde este Dumnezeul tău?
Oúnjẹ mi ni omijé mi ní ọ̀sán àti ní òru, nígbà tí àwọn ènìyàn ń wí fún mi ní gbogbo ọjọ́ pé, “Ọlọ́run rẹ dà?”
4 Când îmi amintesc acestea, îmi vărs sufletul în mine, fiindcă m-am dus cu mulțimea, am mers cu ei la casa lui Dumnezeu, cu vocea bucuriei și a laudei, cu o mulțime ce ținea sărbătoare.
Nígbà tí mo bá rántí nǹkan yìí, èmi tú ọkàn mi jáde nínú mi: èmi ti bá ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn lọ, èmi bá wọn lọ sí ilé Ọlọ́run pẹ̀lú ohùn ayọ̀ àti ìyìn, pẹ̀lú ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ń pa ọjọ́ mímọ́ mọ́.
5 De ce ești doborât, sufletul meu? Și de ce ești neliniștit în mine? Speră în Dumnezeu, căci încă îl voi lăuda pentru ajutorul înfățișării sale.
Èéṣe tí o fi ń rẹ̀wẹ̀sì, ìwọ ọkàn mi? Èéṣe tí ara rẹ kò fi lélẹ̀ nínú mi? Ìwọ ṣe ìrètí ní ti Ọlọ́run, nítorí èmi yóò sá à máa yìn ín, Olùgbàlà mi àti Ọlọ́run mi.
6 Dumnezeul meu, sufletul îmi este doborât în mine, de aceea îmi voi aminti de tine din țara Iordanului și din piscurile Hermoniților, din dealul Mițar.
Ọlọ́run mi, ọkàn mi ń rẹ̀wẹ̀sì nínú mi: nítorí náà, èmi ó rántí rẹ láti ilẹ̀ Jordani wá, láti Hermoni láti òkè Mibsari.
7 Adânc strigă către adânc la sunetul vârtejurilor tale de apă, toate valurile tale și talazurile tale au trecut peste mine.
Ibú omi ń pe ibú omi nípa híhó omi ṣíṣàn rẹ̀ gbogbo rírú omi àti bíbì omi rẹ̀ bò mí mọ́lẹ̀.
8 Totuși DOMNUL va porunci bunătatea sa iubitoare în timpul zilei și noaptea cântarea lui va fi cu mine și rugăciunea mea spre Dumnezeul vieții mele.
Ní ọ̀sán ní Olúwa ran ìfẹ́ rẹ̀, àti ni àṣálẹ́ ni orin rẹ̀ wà pẹ̀lú mi àdúrà sí Ọlọ́run ayé mi.
9 Voi spune lui Dumnezeu stânca mea: De ce m-ai uitat? De ce umblu jelind sub oprimarea dușmanului?
Èmi wí fún Ọlọ́run àpáta mi, “Èéṣe tí ìwọ fi gbàgbé mi? Èéṣe tí èmi o fi máa rìn nínú ìbànújẹ́, nítorí ìnilára ọ̀tá?”
10 Precum cu o sabie în oasele mele dușmanii mei mă ocărăsc, în timp ce îmi spun zilnic: Unde este Dumnezeul tău?
Bí ẹni pé idà egungun mi ni ẹ̀gàn tí àwọn ọ̀tá mi ń gàn mí, bí wọn ti ń béèrè ní gbogbo ọjọ́. “Níbo ni Ọlọ́run rẹ wà?”
11 De ce ești doborât, sufletul meu? Și de ce ești neliniștit în mine? Speră în Dumnezeu, căci încă îl voi lăuda, pe el, care este sănătatea înfățișării mele și Dumnezeul meu.
Èéṣe tí ìwọ fi ń rẹ̀wẹ̀sì, ìwọ ọkàn mi? Èéṣe tí ara rẹ kò fi lélẹ̀ nínú mi? Fi ìrètí rẹ sínú Ọlọ́run, nítorí èmi yóò sì máa yìn ín, Òun ni Olùgbàlà mi àti Ọlọ́run mi.