< Psalmii 37 >
1 Un psalm al lui David. Nu te îngrijora din cauza făcătorilor de rău, nici nu fi invidios împotriva lucrătorilor nelegiuirii.
Ti Dafidi. Má ṣe ìkanra nítorí àwọn olùṣe búburú, kí ìwọ má sì ṣe ṣe ìlara nítorí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀;
2 Căci degrabă vor fi cosiți ca iarba și se vor ofili ca iarba verde.
nítorí pé wọn yóò gbẹ bí i koríko, wọn yóò sì rẹ̀ dànù bí ewéko tútù.
3 Încrede-te în DOMNUL și fă binele; astfel vei locui în țară și într-adevăr vei fi hrănit.
Gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, kí o sì máa ṣe rere; torí pé ìwọ yóò gbé ilẹ̀ náà, kí o sì gbádùn ààbò rẹ̀.
4 Desfată-te de asemenea în DOMNUL și el îți va da dorințele inimii tale.
Ṣe inú dídùn sí Olúwa; òun yóò sì fún ọ ní ìfẹ́ inú rẹ̀.
5 Încredințează DOMNULUI calea ta și încrede-te de asemenea în el, iar el o va înfăptui.
Fi ọ̀nà rẹ lé Olúwa lọ́wọ́; gbẹ́kẹ̀lé pẹ̀lú, òun yóò sì ṣe é.
6 Și va aduce dreptatea ta ca lumina și judecata ta ca și amiaza.
Yóò sì mú kí òdodo rẹ̀ jáde bí ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀, àti ìdájọ́ rẹ̀ bí ọ̀sán gangan.
7 Odihnește-te în DOMNUL și așteaptă-l cu răbdare; nu te îngrijora din cauza celui ce prosperă pe calea sa, din cauza omului care înfăptuiește planuri stricate.
Ìwọ dákẹ́ jẹ́ẹ́ níwájú Olúwa, kí o sì fi sùúrù dúró dè é; má ṣe ṣe ìkanra nítorí àwọn tí ń rí rere ní ọ̀nà wọn, nítorí ọkùnrin náà ti mú èrò búburú ṣẹ.
8 Oprește-te de la mânie și părăsește furia, nu te îngrijora în vreun fel pentru a face rău.
Fàsẹ́yìn nínú inúbíbí, kí o sì kọ ìkáàánú sílẹ̀, má ṣe ṣe ìkanra, kí ó má ba à ṣé búburú pẹ̀lú.
9 Pentru că făcătorii de rău vor fi stârpiți, dar cei ce așteaptă pe DOMNUL, ei vor moșteni pământul.
Nítorí tí á ó gé àwọn olùṣe búburú kúrò, ṣùgbọ́n àwọn tí ó bá dúró de Olúwa àwọn ni yóò jogún ilẹ̀ náà.
10 Căci încă puțin timp și cel rău nu va mai fi, da, cu atenție vei lua aminte la locul lui și nu va mai fi.
Síbẹ̀ nígbà díẹ̀ sí i, àwọn ènìyàn búburú kì yóò sí mọ̀; nítòótọ́ ìwọ yóò fi ara balẹ̀ wo ipò rẹ̀, wọn kì yóò sí níbẹ̀.
11 Dar cei blânzi vor moșteni pământul și se vor desfăta în abundența păcii.
Ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́kàn tútù ni yóò jogún ilẹ̀ náà, wọn yóò sì máa ṣe inú dídùn nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ àlàáfíà.
12 Cel stricat uneltește împotriva celui drept și își scrâșnește din dinți asupra lui.
Ènìyàn búburú di rìkíṣí sí olóòtítọ́, wọ́n sì pa eyín wọn keke sí wọn;
13 Domnul va râde de el, fiindcă vede că ziua lui vine.
ṣùgbọ́n Olúwa rẹ́rìn-ín sí àwọn ènìyàn búburú, nítorí tí ó rí wí pé ọjọ́ wọn ń bọ̀.
14 Cei stricați au scos sabia și și-au încordat arcurile, pentru a doborî pe cel sărac și nevoiaș și pentru a ucide pe cei ce au o purtare integră.
Ènìyàn búburú fa idà yọ, wọ́n sì tẹ àwọn ọrun wọn, láti sọ tálákà àti aláìní kalẹ̀, láti pa àwọn tí ó dúró ṣinṣin.
15 Sabia lor va intra în propria lor inimă și arcurile lor vor fi frânte.
Idà wọn yóò wọ àyà wọn lọ, àti wí pé ọrun wọn yóò sì ṣẹ́.
16 Puținul pe care un om drept îl are este mai bun decât bogățiile multor stricați.
Ohun díẹ̀ tí olódodo ní, sàn ju ọ̀pọ̀ ọrọ̀ ènìyàn búburú;
17 Pentru că brațele celor stricați vor fi frânte, dar DOMNUL susține pe cei drepți.
nítorí pé a óò ṣẹ́ ọwọ́ àwọn ènìyàn búburú, ṣùgbọ́n Olúwa gbé olódodo sókè.
18 DOMNUL cunoaște zilele celor integri și moștenirea lor va fi pentru totdeauna.
Olúwa mọ àwọn ọjọ́ àwọn tó dúró ṣinṣin, àti wí pé ilẹ̀ ìní wọn yóò wà títí ayérayé.
19 Ei nu vor fi făcuți de rușine în timpul cel rău și în zilele foametei vor fi săturați.
Ojú kì yóò tì wọ́n ní àkókò ibi, àti ní ọjọ́ ìyàn, a ó tẹ́ wọn lọ́rùn.
20 Dar cei stricați vor pieri și dușmanii DOMNULUI vor fi ca grăsimea mieilor, se vor mistui; în fum se vor mistui.
Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn búburú yóò ṣègbé. Àwọn ọ̀tá Olúwa yóò dàbí ẹwà oko tútù; wọn fò lọ; bi èéfín ni wọn yóò fò lọ kúrò.
21 Cel stricat împrumută și nu plătește înapoi, dar cel drept arată milă și dă.
Àwọn ènìyàn búburú yá, wọn kò sì san án padà, ṣùgbọ́n àwọn olódodo a máa ṣàánú, a sì máa fi fún ni;
22 Fiindcă toți cei binecuvântați de el vor moșteni pământul; și cei ce sunt blestemați de el vor fi stârpiți.
nítorí àwọn tí Olúwa bá bùkún ni yóò jogún ilẹ̀ náà, àwọn tí ó fi bú ni a ó gé kúrò.
23 Pașii omului bun sunt rânduiți de DOMNUL și își găsește plăcere în calea lui.
Ìlànà ìgbésẹ̀ ènìyàn rere wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá, o sì ṣe inú dídùn sí ọ̀nà rẹ̀;
24 Deși cade, el nu va fi doborât de tot, pentru că DOMNUL îl susține cu mâna lui.
bí ó tilẹ̀ ṣubú a kì yóò ta á nù pátápátá, nítorí tí Olúwa di ọwọ́ rẹ̀ mú.
25 Am fost tânăr și acum am îmbătrânit; totuși nu am văzut pe cel drept părăsit, nici sămânța lui cerșind pâine.
Èmi ti wà ni èwe, báyìí èmi sì dàgbà; síbẹ̀ èmi kò ì tí ì ri kí a kọ olódodo sílẹ̀, tàbí kí irú-ọmọ rẹ̀ máa ṣagbe oúnjẹ.
26 El este totdeauna milos și împrumută; și sămânța lui este binecuvântată.
Aláàánú ni òun nígbà gbogbo a máa yá ni; a sì máa bùsi i fún ni.
27 Pleacă de la rău și fă binele; și rămâi pentru totdeauna.
Lọ kúrò nínú ibi, kí o sì máa ṣe rere; nígbà náà ni ìwọ yóò gbé ní ilẹ̀ náà títí láéláé.
28 Căci DOMNUL iubește judecata și nu părăsește pe sfinții săi; ei sunt păstrați pentru totdeauna, dar sămânța celor stricați va fi stârpită.
Nítorí pé Olúwa fẹ́ràn ìdájọ́ òtítọ́, kò sì kọ àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ sílẹ̀. Àwọn olódodo ni a ó pamọ́ títí ayérayé, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ ènìyàn búburú ni a ó ké kúrò.
29 Cei drepți vor moșteni țara și vor locui în ea pentru totdeauna.
Olódodo ni yóò jogún ilẹ̀ náà, yóò sì máa gbé ibẹ̀ títí ayérayé.
30 Gura celui drept spune înțelepciune și limba lui vorbește judecată.
Ẹnu olódodo sọ̀rọ̀ ọgbọ́n, ahọ́n rẹ̀ a sì máa sọ̀rọ̀ ìdájọ́.
31 Legea Dumnezeului său este în inima lui; niciunul din pașii lui nu va aluneca.
Òfin Ọlọ́run rẹ̀ ń bẹ ní àyà wọn; àwọn ìgbésẹ̀ rẹ̀ kì yóò yẹ̀.
32 Cel stricat pândește pe cel drept și caută să îl ucidă.
Ènìyàn búburú ń ṣọ́ olódodo, Ó sì ń wá ọ̀nà láti pa á.
33 DOMNUL nu îl va lăsa în mâna lui, nici nu îl va condamna când este judecat.
Olúwa kì yóò fi lé e lọ́wọ́ kì yóò sì dá a lẹ́bi, nígbà tí a bá ń ṣe ìdájọ́ rẹ̀.
34 Așteaptă pe DOMNUL și ține calea lui, iar el te va înălța pentru a moșteni țara, când cei stricați sunt stârpiți, vei privi aceasta.
Dúró de Olúwa, kí o sì máa pa ọ̀nà rẹ̀ mọ́. Yóò sì gbé ọ lékè láti jogún ilẹ̀ náà; nígbà tí a bá gé àwọn ènìyàn búburú kúrò ìwọ yóò ri.
35 Am văzut pe cel stricat în mare putere și întinzându-se ca un dafin verde.
Èmi ti rí ènìyàn búburú tí ń hu ìwà ìkà, ó sì fi ara rẹ̀ gbilẹ̀ bí igi tútù ńlá,
36 Totuși a trecut și, iată, el nu mai este, da, l-am căutat, dar nu a putut fi găsit.
ṣùgbọ́n ní ìṣẹ́jú kan sí i ó kọjá lọ, sì kíyèsi, kò sì sí mọ́; bi ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé mo wá a kiri, ṣùgbọ́n a kò le è ri.
37 Însemnează pe cel desăvârșit și privește pe cel integru, fiindcă sfârșitul acelui om este pace.
Máa kíyèsi ẹni pípé, kí o sì wo ẹni tó dúró ṣinṣin; nítorí àlàáfíà ni òpin ọkùnrin náà.
38 Dar călcătorii de lege vor fi nimiciți împreună, sfârșitul celor stricați va fi stârpit.
Ṣùgbọ́n àwọn olùrékọjá ni a ó parun papọ̀; ìran àwọn ènìyàn búburú ni a ó gé kúrò.
39 Dar salvarea celor drepți este a DOMNULUI, el este puterea lor în timpul tulburării.
Ìgbàlà àwọn onídùúró ṣinṣin wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa; òun ni ààbò wọn ní ìgbà ìpọ́njú
40 Și DOMNUL îi va ajuta și îi va elibera; îi va elibera de cei stricați și îi va salva pentru că se încred în el.
Olúwa yóò ràn wọ́n lọ́wọ́ yóò sì gbà wọ́n; yóò gbà wọ́n lọ́wọ́ ènìyàn búburú, yóò sì gbà wọ́n là, nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé e.