< Psalmii 36 >

1 Mai marelui muzician, un psalm al lui David, servitorul DOMNULUI. Fărădelegea celui stricat spune înăuntrul inimii mele, că nu este teamă de Dumnezeu înaintea ochilor lui.
Fún adarí orin. Ti Dafidi ìránṣẹ́ Olúwa. Ìré-òfin-kọjá ènìyàn búburú jẹ́ kí n mọ̀ nínú ọkàn mi pé, ìbẹ̀rù Ọlọ́run kò sí níwájú wọn.
2 Pentru că el se flatează în propriii lui ochi, până când nelegiuirea lui se arată demnă de ură.
Nítorí pé wọ́n pọ́n ara wọn ní ojú ara wọn títí tí a kò fi le rí ẹ̀ṣẹ̀ wọn láti kórìíra.
3 Cuvintele gurii lui sunt nelegiuire și înșelătorie, el a încetat a fi înțelept și a face bine.
Ọ̀rọ̀ ẹnu wọn ni ẹ̀ṣẹ̀ òhun ẹ̀tàn; wọ́n ti fi ọgbọ́n àti ṣíṣe rere sílẹ̀.
4 El plănuiește ticăloșie pe patul său; se așază pe o cale care nu este bună; el nu detestă răul.
Wọ́n gbìmọ̀ ìwà ìkà nígbà tí wọ́n wà lórí ibùsùn wọn: wọ́n gba ọ̀nà tí kò dára wọn kò sì kọ ọ̀nà ibi sílẹ̀.
5 Mila ta, DOAMNE, este în ceruri; și credincioșia ta ajunge până la nori.
Ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ, ìwọ Olúwa, ó ga dé ọ̀run, òtítọ́ ọ̀ rẹ ga dé àwọsánmọ̀.
6 Dreptatea ta este ca munții cei mari; judecățile tale sunt un mare adânc; DOAMNE, tu păstrezi pe om și pe animal.
Òdodo rẹ dàbí àwọn òkè Ọlọ́run, àwọn ìdájọ́ rẹ dàbí ibú ńlá; ìwọ gba ẹranko àti ènìyàn là, Olúwa.
7 Cât de măreață este bunătatea ta iubitoare, Dumnezeule! De aceea copiii oamenilor se încred sub umbra aripilor tale.
Báwo ni ìṣeun ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ ti tó! Ọlọ́run! Kí gbogbo ọmọ ènìyàn le sá sí abẹ́ òjìji ìyẹ́ rẹ.
8 Ei se vor sătura din plin din grăsimea casei tale; și le dai să bea din râul desfătărilor tale.
Àsè ilé rẹ yóò tẹ́ wọn lọ́rùn gidigidi; ìwọ yóò sì mú wọn mu nínú odò inú dídùn rẹ.
9 Căci la tine este fântâna vieții, în lumina ta vom vedea lumină.
Nítorí pé pẹ̀lú rẹ ni orísun ìyè wà: nínú ìmọ́lẹ̀ rẹ ni àwa yóò rí ìmọ́lẹ̀.
10 O, prelungește bunătatea ta iubitoare celor ce te cunosc și dreptatea ta celor integri în inimă.
Mú ìṣeun ìfẹ́ ẹ̀ rẹ sí àwọn tí ó mọ̀ ọ́n àti ìgbàlà rẹ sí àwọn tí ó ní ìdúró ṣinṣin ọkàn!
11 Nu lăsa piciorul mândriei să vină împotriva mea și nu lăsa mâna celor stricați să mă alunge.
Má ṣe jẹ́ kí ẹsẹ̀ agbéraga kí ó wá sí orí mi, kí o má sì jẹ́ kí ọwọ́ àwọn ènìyàn búburú sí mi ní ipò.
12 Acolo sunt căzuți lucrătorii nelegiuirii, sunt aruncați jos și nu vor fi în stare să se ridice.
Níbẹ̀ ni àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ gbé ṣubú sí: a rẹ̀ wọ́n sílẹ̀, wọn kì yóò le è dìde!

< Psalmii 36 >