< Psalmii 34 >
1 Un psalm al lui David, când și-a schimbat purtarea față de Abimelec, care l-a alungat, iar el a plecat. Voi binecuvânta pe DOMNUL întotdeauna, lauda lui va fi continuu în gura mea.
Tí Dafidi. Nígbà tí ó díbọ́n bí ẹni tí ń ṣe wèrè níwájú Abimeleki, ẹni tí ó lé e lọ, ó sì jáde lọ. Èmi yóò máa fi ìbùkún fún Olúwa nígbà gbogbo; ìyìn rẹ̀ yóò máa wà ní ẹnu mi títí láé.
2 Sufletul meu se va făli în DOMNUL, cei umili vor asculta și se vor veseli.
Ọkàn mí yóò máa ṣògo nínú Olúwa; jẹ́ kí àwọn onírẹ̀lẹ̀ gbọ́ kí inú wọn kí ó sì máa dùn.
3 Preamăriți pe DOMNUL împreună cu mine, și împreună să înălțăm numele lui.
Gbé Olúwa ga pẹ̀lú mi; kí ẹ sì jẹ́ kí a jọ gbé orúkọ rẹ̀ lékè.
4 Am căutat pe DOMNUL și el m-a ascultat și m-a eliberat de toate temerile mele.
Èmi wá Olúwa, ó sì dá mi lóhùn; Ó sì gbà mí kúrò nínú ìbẹ̀rù mi gbogbo.
5 Ei au privit către el și au fost luminați, și fețele lor nu au fost făcute de rușine.
Wọ́n wò ó, ìmọ́lẹ̀ sì mọ́ wọn; ojú kò sì tì wọ́n.
6 Săracul a strigat și DOMNUL l-a ascultat și l-a salvat din toate tulburările lui.
Ọkùnrin olùpọ́njú yí kígbe, Olúwa sì gbóhùn rẹ̀; ó sì gbà á là kúrò nínú gbogbo ìpọ́njú rẹ̀.
7 Îngerul DOMNULUI își așază tabăra de jur împrejurul celor ce se tem de el și îi eliberează.
Angẹli Olúwa yí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀ ká ó sì gbà wọ́n.
8 Gustați și vedeți că DOMNUL este bun; binecuvântat este omul care se încrede în el.
Tọ́ ọ wò kí o sì rí i wí pé Olúwa dára; ẹni ayọ̀ ni ọkùnrin náà tí ó gbẹ́kẹ̀lé ààbò nínú rẹ̀.
9 Temeți-vă de DOMNUL, voi sfinții lui, pentru că nimic nu le lipsește celor ce se tem de el.
Ẹ bẹ̀rù Olúwa, ẹ̀yin ènìyàn rẹ̀ mímọ́, nítorí pé kò sí àìní fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀.
10 Leii tineri duc lipsă și le este foame, dar cei ce caută pe DOMNUL nu vor duce lipsă de niciun bine.
Àwọn ọmọ kìnnìún a máa ṣe aláìní ebi a sì máa pa wọ́n; ṣùgbọ́n àwọn tí ó wá Olúwa kì yóò ṣe aláìní ohun tí ó dára.
11 Veniți, voi copii, dați-mi ascultare, vă voi învăța teama de DOMNUL.
Wá, ẹ̀yin ọmọ mi, fi etí sí mi; èmi yóò kọ́ ọ yín ní ẹ̀rù Olúwa.
12 Cine este omul care dorește viața și iubește zile multe, ca să vadă binele?
Ta ni nínú yín tí ń fẹ́ ìyè, tí ó sì ń fẹ́ ọjọ́ púpọ̀; kí ó lè gbádùn ọjọ́ rere?
13 Păzește-ți limba de la rău, și buzele tale de la a vorbi viclenie.
Pa ahọ́n rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ibi àti ètè rẹ̀ kúrò ní ẹ̀tàn sísọ.
14 Pleacă de la rău și fă binele; caută pacea și urmărește-o.
Yà kúrò nínú ibi kí o sì ṣe rere; wá àlàáfíà, kí o sì lépa rẹ̀.
15 Ochii DOMNULUI sunt peste cei drepți și urechile lui sunt deschise la strigătul lor.
Ojú Olúwa ń bẹ lára àwọn olódodo; etí i rẹ̀ sì ṣí sí ẹkún wọn.
16 Fața DOMNULUI este împotriva celor ce fac răul, pentru a stârpi amintirea lor de pe pământ.
Ojú Olúwa korò sí àwọn tí ń ṣe búburú; láti ké ìrántí wọn kúrò lórí ilẹ̀.
17 Cei drepți strigă și DOMNUL ascultă și îi eliberează din toate tulburările lor.
Nígbà tí olódodo bá ké fún ìrànlọ́wọ́, Olúwa a máa gbọ́, a sì yọ wọ́n jáde láti inú gbogbo wàhálà wọn.
18 DOMNUL este aproape de cei cu o inimă frântă și salvează pe cei cu un duh căit.
Olúwa súnmọ́ etí ọ̀dọ̀ àwọn oníròbìnújẹ́ ọkàn; ó sì gba irú àwọn tí í ṣe oníròra ọkàn là.
19 Multe sunt nenorocirile celui drept, dar DOMNUL îl eliberează din toate.
Ìpọ́njú àwọn olódodo pọ̀, ṣùgbọ́n Olúwa gbà wọ́n kúrò nínú gbogbo rẹ̀.
20 El păzește toate oasele lui, niciunul din ele nu este frânt.
Ó pa gbogbo egungun wọn mọ́; kò sí ọ̀kan tí ó dá nínú wọn.
21 Răul îl va ucide pe cel stricat și cei ce urăsc pe cel drept vor fi pustiiți.
Ibi ni ó mú ikú ìkà wá, àti àwọn tí ó kórìíra olódodo ni yóò jẹ̀bi.
22 DOMNUL răscumpără sufletul servitorilor săi și niciunul dintre cei ce se încred în el nu va fi pustiit.
Olúwa ra ọkàn àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ padà; kò sí ọ̀kan nínú àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé tí yóò jẹ̀bi.