< Psalmii 27 >

1 Un psalm al lui David. DOMNUL este lumina mea și salvarea mea; de cine să mă tem? DOMNUL este puterea vieții mele; de cine să mă înspăimânt?
Ti Dafidi. Olúwa ni ìmọ́lẹ̀ mi àti ìgbàlà mi; ta ni èmi yóò bẹ̀rù? Olúwa ni ibi ìsádi ẹ̀mí mi, ẹ̀rù ta ni yóò bà mí?
2 Când cei stricați, dușmanii mei și potrivnicii mei, au venit peste mine ca să îmi mănânce carnea, s-au împiedicat și au căzut.
Nígbà tí àwọn ènìyàn búburú kọjú ìjà sí mi láti jẹ ẹran-ara mi, àní àwọn ọ̀tá mi àti àwọn abínúkú mi, wọn yóò kọsẹ̀, wọn yóò sì ṣubú.
3 Chiar dacă o armată ar tăbărî împotriva mea, inima mea nu se va teme; chiar dacă s-ar ridica război împotriva mea, în aceasta voi fi eu încrezător.
Bí ọmọ-ogun tilẹ̀ yí mi ká tí wọ́n sì dìde sí mi, ọkàn mi kì yóò bẹ̀rù; bí ogun tilẹ̀ dìde sí mi, nínú èyí ni ọkàn mi yóò le.
4 Un lucru am dorit de la DOMNUL, pe acesta îl voi căuta: să locuiesc în casa DOMNULUI toate zilele vieții mele, să privesc frumusețea DOMNULUI și să aduc cerere în templul său.
Ohun kan ni mo béèrè lọ́dọ̀ Olúwa, òhun ni èmi yóò máa wá kiri: kí èmi kí ó le wà ní ilé Olúwa ní ọjọ́ ayé mi gbogbo, kí èmi: kí ó le kíyèsi ẹwà Olúwa, kí èmi kí ó sì máa wà ní tẹmpili rẹ̀.
5 Fiindcă în timp de tulburare el mă va ascunde în cortul lui, în tăinicia tabernacolului său mă va ascunde el; mă va așeza pe o stâncă.
Nítorí pé ní ìgbà ìpọ́njú òun yóò pa mí mọ́ nínú àgọ́ rẹ̀; níbi ìkọ̀kọ̀ àgọ́ rẹ̀ ni òun yóò pa mí mọ́; yóò sì gbé mi sókè lórí àpáta.
6 Și acum capul meu va fi înălțat deasupra dușmanilor mei dimprejurul meu; de aceea voi oferi în tabernacolul său sacrificii de bucurie; voi cânta, da, voi cânta laude DOMNULUI.
Ní ìsinsin yìí, a ti gbé orí mi sókè ga ju ti àwọn ọ̀tá mi lọ tí ó yí mí ká; èmi yóò rú ẹbọ nínú àgọ́ rẹ, ẹbọ ariwo àti ti ayọ̀; èmi yóò kọrin àní orin dídùn sí Olúwa.
7 Ascultă, DOAMNE, când strig cu vocea mea; ai milă de mine și răspunde-mi.
Gbọ́ ohùn mi nígbà tí ẹ̀mí bá à ń pè, Olúwa, ṣe àánú fún mi kí o sì dá mi lóhùn,
8 Când ai spus: Căutați fața mea; inima mea ți-a spus: Fața ta, DOAMNE, o voi căuta.
Ọkàn mi wí pé, “Wá ojú u rẹ̀!” Ojú rẹ, Olúwa, ni ti èmí ń wá.
9 Nu îți ascunde fața de mine; nu înlătura pe servitorul tău în mânia ta; ai fost ajutorul meu; nu pleca de la mine, nici nu mă părăsi, Dumnezeul salvării mele.
Má ṣe fi ojú rẹ pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ mi, má ṣe fi ìbínú sá ìránṣẹ́ rẹ tì; ìwọ tí o ti jẹ́ olùrànlọ́wọ́ mi, Má ṣe fi mí sílẹ̀, má sì ṣe kọ̀ mí, háà! Ọlọ́run ìgbàlà mi.
10 Când tatăl meu și mama mea mă părăsesc, atunci DOMNUL mă va lua.
Bí ìyá àti baba bá kọ̀ mí sílẹ̀, Olúwa yóò tẹ́wọ́ gbà mí.
11 Învață-mă calea ta, DOAMNE, și condu-mă pe o cărare netedă, din cauza dușmanilor mei.
Kọ́ mi ní ọ̀nà rẹ, Olúwa, kí o sì sìn mi lọ sí ọ̀nà tí ó tẹ́jú nítorí àwọn ọ̀tá mi.
12 Nu mă da la voia dușmanilor mei, fiindcă martori falși se ridică împotriva mea și cei care suflă cruzime.
Má ṣe fi mí lé ìfẹ́ àwọn ọ̀tá mi lọ́wọ́, nítorí àwọn ẹlẹ́rìí èké ti dìde sí mi, wọ́n sì mí ìmí ìkà.
13 Aș fi leșinat, dacă nu aș fi crezut că voi vedea bunătatea DOMNULUI în țara celor vii.
Èmi ní ìgbàgbọ́ pé, èmi yóò rí ìre Olúwa ní ilẹ̀ alààyè.
14 Așteaptă pe DOMNUL; încurajează-te și el îți va întări inima; așteaptă, spun eu, pe DOMNUL.
Dúró de Olúwa; kí ó jẹ alágbára, kí o sì mú ọkàn le àní dúró de Olúwa.

< Psalmii 27 >