< Psalmii 16 >

1 Un poem al lui David. Păstrează-mă, Dumnezeule, fiindcă în tine îmi pun încrederea.
Miktamu ti Dafidi. Pa mí mọ́, Ọlọ́run, nítorí nínú rẹ ni ààbò mi wà.
2 O, sufletul meu, tu ai spus DOMNULUI: Tu ești Domnul meu, bunătatea mea nu ajunge până la tine,
Mo sọ fún Olúwa, “Ìwọ ni Olúwa mi, lẹ́yìn rẹ èmi kò ní ìre kan.”
3 Ci până la sfinții care sunt pe pământ și până la cei nobili, în care este toată desfătarea mea.
Sí àwọn ènìyàn tí ó wà ní ayé, àwọn ni ológo nínú èyí tí ayọ̀ mí wà.
4 Întristările le vor fi înmulțite celor ce se grăbesc după un alt dumnezeu, ofrandele lor de băutură de sânge nu le voi oferi, nici nu voi lua numele lor pe buzele mele.
Ìṣòro àwọn wọ̀n-ọn-nì yóò pọ̀ sí i, àní àwọn tí ń tọ ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn. Ẹbọ ohun mímu ẹ̀jẹ̀ wọn ni èmi kì yóò ta sílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò dá orúkọ wọn lẹ́nu mi.
5 DOMNUL este partea moștenirii mele și a paharului meu; tu susții sorțul meu.
Olúwa, ni ìpín ìní mi tí mo yàn àti ago mi, ó ti pa ohun tí í ṣe tèmi mọ́.
6 Frânghiile de măsurat mi-au căzut în locuri plăcute; da, am o moștenire bună.
Okùn ààlà ilẹ̀ ti bọ́ sí ọ̀dọ̀ mi ní ibi dídára; nítòótọ́ mo ti ní ogún rere.
7 Voi binecuvânta pe DOMNUL, care m-a sfătuit; rărunchii mei de asemenea mă învață în timpurile nopții.
Èmi yóò yin Olúwa, ẹni tí ó gbà mí ní ìyànjú; ní òru, ọkàn mí ń bá mi sọ̀rọ̀.
8 Am pus pe DOMNUL totdeauna înaintea mea, pentru că el este la dreapta mea, nu mă voi clătina.
Mo ti gbé Olúwa síwájú mi ní ìgbà gbogbo. Nítorí tí ó wà ní ọwọ́ ọ̀tún mi, a kì yóò mì mí.
9 De aceea inima mea se veselește și gloria mea se bucură; carnea mea de asemenea se va odihni în speranță.
Nítorí èyí, ọkàn mi yọ̀, ahọ́n mi pẹ̀lú ń fò fáyọ̀; ara mi pẹ̀lú yóò sinmi ní ààbò,
10 Fiindcă nu vei lăsa sufletul meu în iad, nici nu vei da pe Sfântul tău să vadă putrezirea. (Sheol h7585)
nítorí ìwọ kò ní fi ọ̀kan sílẹ̀ nínú isà òkú, tàbí kí ìwọ jẹ́ kí ẹni mímọ́ rẹ kí ó rí ìdíbàjẹ́. (Sheol h7585)
11 Îmi vei arăta cărarea vieții; în prezența ta este plinătatea bucuriei; la dreapta ta se află plăceri pentru totdeauna.
Ìwọ ti fi ipa ọ̀nà ìyè hàn mí; Ìwọ yóò kún mi pẹ̀lú ayọ̀ ní iwájú rẹ, pẹ̀lú ìdùnnú ayérayé ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ.

< Psalmii 16 >