< Psalmii 147 >
1 Lăudați pe DOMNUL, pentru că este bine a cânta laude Dumnezeului nostru, pentru că este plăcut; și lauda este cuvenită.
Ẹ fi ìyìn fún Olúwa. Nítorí ohun rere ni láti máa kọrin ìyìn sí Ọlọ́run wa, ó yẹ láti kọrin ìyìn sí i!
2 DOMNUL zidește Ierusalimul, adună pe proscrișii lui Israel.
Olúwa kọ́ Jerusalẹmu; Ó kó àwọn Israẹli tí a lé sọnù jọ.
3 El vindecă pe cei cu inima frântă și le leagă rănile.
Ó wo àwọn tí ọkàn wọ́n bàjẹ́ sàn ó sì di ọgbẹ́ wọ́n.
4 El socotește numărul stelelor, el le cheamă pe toate pe numele lor.
Ó ka iye àwọn ìràwọ̀ ó sì pe ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn ní orúkọ.
5 Mare este Domnul nostru și mare în putere, înțelegerea lui este infinită.
Títóbi ni Olúwa wa ó sì pọ̀ ní agbára òye rẹ̀ kò sì ní òpin.
6 DOMNUL înalță pe cei umili, el aruncă pe cei stricați la pământ.
Olúwa wa pẹ̀lú àwọn onírẹ̀lẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni ó rẹ̀ àwọn ènìyàn búburú sílẹ̀.
7 Cântați DOMNULUI cu mulțumire; cântați laudă pe harpă, Dumnezeului nostru,
Fi ọpẹ́ kọrin sí Olúwa fi ohun èlò orin olókùn yin Ọlọ́run.
8 Care acoperă cerul cu nori, care pregătește ploaie pentru pământ, care face să crească iarbă pe munți.
Ó fi ìkùùkuu bo àwọ̀ sánmọ̀ ó rọ òjò sí orílẹ̀ ayé ó mú kí koríko hù lórí àwọn òkè
9 Dă vitei mâncarea ei și corbilor tineri care strigă.
Ó pèsè oúnjẹ fún àwọn ẹranko àti fún àwọn ọmọ ẹyẹ ìwò ní ìgbà tí wọ́n bá ń ké.
10 El nu găsește plăcere în tăria calului, el nu are plăcere în picioarele unui om.
Òun kò ní inú dídùn nínú agbára ẹṣin, bẹ́ẹ̀ ni Òun kò ní ayọ̀ sí ẹ̀ṣẹ̀ ọkùnrin
11 DOMNUL își găsește plăcerea în cei ce se tem de el, în cei ce speră în mila lui.
Olúwa ni ayọ̀ nínú àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, sí àwọn tí ó ní ìrètí nínú àánú rẹ̀.
12 Laudă pe DOMNUL, Ierusalime; laudă pe Dumnezeul tău, Sioane.
Yin Olúwa, ìwọ Jerusalẹmu; yin Ọlọ́run rẹ, ìwọ Sioni.
13 Căci el a întărit zăvoarele porților tale; el a binecuvântat pe copiii tăi în mijlocul tău.
Nítorí tí ó ti mú ọ̀pá ìdábùú ibodè rẹ̀ lágbára, Òun sì ti bùkún fún àwọn ọmọ rẹ̀ nínú rẹ
14 El dă pace între granițele tale și te satură cu grăsimea grâului.
Òun jẹ́ kí àlàáfíà wà ní àwọn ẹnu ibodè rẹ̀, òun sì fi jéró dáradára tẹ́ ọ lọ́rùn.
15 El trimite porunca lui pe pământ, cuvântul lui aleargă foarte repede.
Òun sì rán àṣẹ rẹ̀ sí ayé ọ̀rọ̀ rẹ̀ sáré tete.
16 El dă zăpadă ca lâna, el împrăștie bruma ca cenușa.
Ó fi yìnyín fún ni bi irun àgùntàn ó sì fọ́n ìrì dídì ká bí eérú
17 El își aruncă gheața ca îmbucături, cine poate sta înaintea frigului său?
Ó rọ òjò yìnyín rẹ̀ bí òkúta wẹ́wẹ́ ta ni ó lè dúró níwájú òtútù rẹ̀
18 El trimite cuvântul său și le topește, el face ca vânturile sale să sufle și apele curg.
Ó rán ọ̀rọ̀ rẹ̀ jáde ó sì mú wọn yọ̀ ó mú kí afẹ́fẹ́ rẹ̀ fẹ́ ó sì mú odò rẹ̀ sàn.
19 El arată cuvântul său lui Iacob, statutele sale și judecățile sale lui Israel.
Ó sọ ọ̀rọ̀ rẹ̀ di mí mọ̀ fún Jakọbu àwọn òfin àti ìlànà rẹ̀ fún Israẹli.
20 El nu s-a purtat astfel cu nicio națiune; iar judecățile sale, ei nu le-au cunoscut. Lăudați pe DOMNUL.
Òun kó tí ṣe irú èyí sí orílẹ̀-èdè kan rí, bí ó ṣe ti ìdájọ́ rẹ̀ wọn ko mọ òfin rẹ̀. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.