< Psalmii 146 >

1 Lăudați pe DOMNUL. Laudă pe DOMNUL, suflete al meu.
Ẹ fi ìyìn fún Olúwa. Fi ìyìn fún Olúwa, ìwọ ọkàn mi.
2 Cât timp trăiesc voi lăuda pe DOMNUL, voi cânta laude Dumnezeului meu cât voi fi.
Èmi yóò yin Olúwa ní gbogbo ayé mi, èmi yóò kọrin ìyìn sí Ọlọ́run, níwọ̀n ìgbà tí mo bá wà láààyè.
3 Nu vă puneți încrederea în prinți, nici în fiul omului, în care nu este ajutor.
Ẹ má ṣe ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú àwọn ọmọ-aládé, àní, ọmọ ènìyàn, lọ́wọ́ ẹni tí kò sí ìrànlọ́wọ́.
4 Suflarea lui iese, el se întoarce în pământul lui; chiar în ziua aceea gândurile lui pier.
Ẹ̀mí rẹ jáde lọ, ó padà sí erùpẹ̀, ní ọjọ́ náà gan, èrò wọn yóò di òfo.
5 Ferice de cel ce are pe Dumnezeul lui Iacob ca ajutor al său, a cărui speranță este în DOMNUL Dumnezeul său;
Ìbùkún ni fún ẹni tí Ọlọ́run Jakọbu ń ṣe ìrànlọ́wọ́ rẹ̀ tí ìrètí rẹ̀ wà nínú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀.
6 Care a făcut cerul și pământul, marea și tot ce este în ea, care ține adevărul pentru totdeauna.
Ẹni tí ó dá ọ̀run àti ayé, òkun àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú wọn, ẹni tí ó pa òtítọ́ mọ́ títí ayé.
7 Care face judecată pentru cei oprimați, care dă mâncare celor flămânzi. DOMNUL dezleagă prizonierii;
Ẹni tí ń ṣe ìdájọ́ àwọn tí a ni lára, tí ó fi oúnjẹ fún àwọn tí ebi ń pa, Olúwa, tú àwọn oǹdè sílẹ̀,
8 DOMNUL deschide ochii orbilor, DOMNUL ridică pe cei încovoiați; DOMNUL iubește pe cei drepți;
Olúwa mú àwọn afọ́jú ríran, Olúwa, gbé àwọn tí a rẹ̀ sílẹ̀ ga, Olúwa fẹ́ràn àwọn olódodo.
9 DOMNUL păzește pe străini; el ușurează pe cel fără tată și pe văduvă, dar calea celor stricați o răstoarnă.
Olúwa ń dá ààbò bo àwọn àlejò ó sì ń dá àwọn aláìní baba àti opó sí ṣùgbọ́n ó ba ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú jẹ́.
10 DOMNUL va domni pentru totdeauna, chiar Dumnezeul tău, Sioane, din generație în generație. Lăudați pe DOMNUL.
Olúwa jẹ ọba títí láé; Ọlọ́run rẹ, ìwọ Sioni, àti fún gbogbo ìran. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.

< Psalmii 146 >