< Psalmii 106 >

1 Lăudați pe DOMNUL. Aduceți mulțumiri DOMNULUI, pentru că este bun, că a lui milă dăinuiește pentru totdeauna.
Yin Olúwa! Ẹ fi ìyìn fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun. Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí tí ó ṣeun, nítorí tí ìfẹ́ rẹ̀ dúró láéláé.
2 Cine poate rosti faptele puternice ale DOMNULUI? Cine poate arăta toată lauda sa?
Ta ni ó lè ròyìn iṣẹ́ agbára Olúwa, ta ní lè sọ nípa ìyìn rẹ̀?
3 Binecuvântați sunt cei ce țin judecata și cel ce face dreptate tot timpul.
Ìbùkún ni fún àwọn tí ń pa ìdájọ́ mọ́? Ẹni tí n ṣe ohun tí ó tọ́.
4 Amintește-ți de mine, DOAMNE, cu favoarea pe care o porți poporului tău, cercetează-mă cu salvarea ta,
Rántí mi, Olúwa, nígbà tí o bá fi ojúrere rẹ hàn, wá sí ìhà mi nígbà tí ìwọ bá gbà wọ́n,
5 Ca să văd binele aleșilor tăi, să mă bucur în veselia națiunii tale, să mă laud cu moștenirea ta.
kí èmi kí ó lè jẹ ìgbádùn àlàáfíà àwọn tí ìwọ ti yàn, kí èmi kí ó sì darapọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn, ìní rẹ láti jọ yìn ọ́ lógo.
6 Noi am păcătuit împreună cu părinții noștri, am făcut nelegiuire, am lucrat cu stricăciune.
Àwa ti dẹ́ṣẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wa ti ṣe, àwa ti ṣe ohun tí kò dá a, a sì ti hùwà búburú.
7 Părinții noștri nu au înțeles minunile tale în Egipt; nu și-au amintit mulțimea îndurărilor tale, ci te-au provocat la mare, la Marea Roșie.
Nígbà tí àwọn baba wa wà ní Ejibiti, iṣẹ́ ìyanu rẹ kò yé wọn, wọn kò rántí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àánú rẹ, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí ọ níbi Òkun, àní níbi Òkun Pupa.
8 Cu toate acestea el i-a salvat pentru numele său, ca să facă puterea lui mare să fie cunoscută.
Ṣùgbọ́n o gbà wọ́n là nítorí orúkọ rẹ láti jẹ́ kí agbára ńlá rẹ di mí mọ̀.
9 A mustrat Marea Roșie de asemenea și a secat, astfel i-a condus prin adâncuri, ca prin pustie.
O bá Òkun Pupa wí, ó sì gbẹ; o sì mú wọn la ìbú já bí aginjù.
10 Și i-a salvat din mâna celui ce îi ura și i-a răscumpărat din mâna dușmanului.
O gbà wọ́n là kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn, láti ọwọ́ ọ̀tá ni o ti gbà wọ́n.
11 Și apele au acoperit pe dușmanii lor, niciunul dintre ei nu a rămas.
Omi ya lu àwọn ọ̀tá wọn; bẹ́ẹ̀ ni kò sí èyí tí ó yè nínú wọn.
12 Atunci au crezut cuvintele sale; au cântat lauda lui.
Nígbà náà wọn gba ìpinnu rẹ gbọ́ wọ́n sì kọrin ìyìn rẹ.
13 Dar i-au uitat curând lucrările; nu i-au așteptat sfatul,
Ṣùgbọ́n wọn kò pẹ́ gbàgbé ohun tí o ṣe wọn kò sí dúró gba ìmọ̀ràn rẹ.
14 Ci au poftit peste măsură în pustie și au ispitit pe Dumnezeu în pustie.
Nínú aginjù ni wọ́n tí ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́, nínú aṣálẹ̀, wọ́n dán Ọlọ́run wò.
15 Iar el le-a dat ce au cerut, dar a trimis slăbiciune în sufletul lor.
Nígbà náà, ó fún wọn ní ohun tí wọ́n béèrè fún ṣùgbọ́n ó rán àìsàn búburú sí wọn.
16 De asemenea l-au invidiat pe Moise în tabără și pe Aaron, sfântul DOMNULUI.
Nínú ibùdó ni wọ́n ṣe ìlara Mose pẹ̀lú Aaroni, ẹni tí ó jẹ́ mímọ́ sí Olúwa.
17 Pământul s-a deschis și a înghițit pe Datan și a acoperit ceata lui Abiram.
Ilẹ̀ la ẹnu ó sì gbé Datani mì ó bo ẹgbẹ́ Abiramu mọ́lẹ̀.
18 Și un foc s-a aprins în ceata lor; flacăra a ars pe cei stricați.
Ọwọ́ iná yọ ní ẹgbẹ́ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀; iná jo àwọn ènìyàn búburú.
19 Ei au făcut un vițel în Horeb și s-au închinat chipului turnat.
Ní Horebu wọ́n ṣe ẹgbọrọ màlúù wọ́n sì sin òrìṣà tí a ṣe láti ara irin.
20 Astfel au schimbat gloria lor cu chipul unui bou care mănâncă iarbă.
Wọ́n pa ògo wọn dà sí àwòrán màlúù, tí ń jẹ koríko.
21 L-au uitat pe Dumnezeu, salvatorul lor, care a făcut lucruri mari în Egipt,
Wọ́n gbàgbé Ọlọ́run, ẹni tí ó gbà wọ́n ẹni tí ó ti ṣe ohun ńlá ní Ejibiti,
22 Lucrări minunate în țara lui Ham și lucruri înfricoșătoare lângă Marea Roșie.
iṣẹ́ ìyanu ní ilẹ̀ Hamu àti ohun ẹ̀rù ni ẹ̀bá Òkun Pupa.
23 De aceea a spus că i-ar nimici, de nu ar fi stat în picioare Moise, alesul său, înaintea lui în spărtură, ca să abată furia lui, ca nu cumva să îi nimicească.
Bẹ́ẹ̀ ni, ó sọ wí pé, òun yóò pa wọ́n run bí kò bá ṣe ti Mose, tí ó yàn, tí ó dúró níwájú ẹ̀yà náà tí ó pa ìbínú rẹ̀ mọ́ láti má pa wọ́n run mọ́.
24 Da, au disprețuit țara plăcută, nu au crezut cuvântul său,
Nígbà náà, wọ́n kẹ́gàn ilẹ̀ dídára náà wọn kò gba ìlérí rẹ̀ gbọ́.
25 Ci au cârtit în corturile lor și nu au dat ascultare vocii DOMNULUI.
Wọ́n ń kùn nínú àgọ́ wọn wọn kò sì gbọ́rọ̀ sí Olúwa.
26 De aceea și-a înălțat mâna împotriva lor, ca să îi doboare în pustie,
Bẹ́ẹ̀ ni ó búra fún wọn nípa gbígbé ọwọ́ rẹ̀ sókè kí òun lè jẹ́ kí wọn ṣubú nínú aginjù,
27 Pentru a doborî de asemenea sămânța lor printre națiuni și pentru a-i împrăștia prin țări.
láti jẹ́ kí àwọn ọmọ rẹ̀ ṣubú lára orílẹ̀-èdè láti fọ́n wọn káàkiri lórí ilẹ̀.
28 Ei înșiși s-au alipit de Baal-Peor și au mâncat sacrificiile morților.
Wọ́n da ara wọn pọ̀ mọ́ Baali-Peori, wọ́n sì ń jẹ ẹbọ tí a rú sí àwọn òkú òrìṣà,
29 Astfel l-au provocat la mânie cu faptele lor și plaga a izbucnit peste ei.
wọ́n mú Ọlọ́run bínú pẹ̀lú ohun búburú tí wọn ń ṣe àjàkálẹ̀-ààrùn jáde láàrín wọn.
30 Atunci Fineas s-a ridicat în picioare și a făcut judecată și plaga s-a oprit.
Ṣùgbọ́n Finehasi dìde láti dá sí i, àjàkálẹ̀-ààrùn náà sì dáwọ́ dúró lọ́gán.
31 Și aceasta i s-a socotit dreptate din generație în generație, până în veșnicie.
A sì ka èyí sí òdodo fún un àti fún àwọn ìrandíran tí ń bọ̀
32 L-au mâniat de asemenea la apele certei, așa că i-a mers rău lui Moise datorită lor,
Níbi omi Meriba, wọ́n bí Ọlọ́run nínú, ohun búburú wá sí orí Mose nítorí wọn.
33 Deoarece i-au provocat duhul, astfel că a vorbit nechibzuit cu buzele sale.
Nítorí tí wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí Ẹ̀mí Ọlọ́run. Ọ̀rọ̀ àìdára sì ti ẹnu Mose wá.
34 Nu au nimicit națiunile, referitor la care DOMNUL le-a poruncit,
Wọn kò pa àwọn ènìyàn run gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún wọn,
35 Ci s-au amestecat printre păgâni și le-au învățat lucrările.
Ṣùgbọ́n wọ́n dàpọ̀ mọ́ àwọn orílẹ̀-èdè, wọ́n sì gbà láti ṣe bí àṣà wọn.
36 Și au servit idolilor lor, care au fost o capcană pentru ei.
Wọ́n sì sin àwọn òrìṣà wọn tí ó di ìkẹ́kùn fún wọn.
37 Da, au sacrificat dracilor pe fiii lor și pe fiicele lor,
Wọ́n fi àwọn ọmọkùnrin wọn rú ẹbọ àti àwọn ọmọbìnrin fún òrìṣà.
38 Și au vărsat sânge nevinovat, sângele fiilor lor și al fiicelor lor, pe care i-au sacrificat idolilor Canaanului; și țara a fost profanată cu sânge.
Wọ́n ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀, ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọ. Wọ́n fi wọ́n rú ẹbọ sí ère Kenaani, ilẹ̀ náà sì di àìmọ́ fún ẹ̀jẹ̀.
39 Astfel s-au pângărit cu propriile fapte și au curvit cu propriile lor născociri.
Wọ́n sì fi ìṣe wọn sọ ara wọn di aláìmọ́, wọ́n sì ṣe àgbèrè lọ pẹ̀lú iṣẹ́ wọn.
40 De aceea s-a aprins furia DOMNULUI împotriva poporului său, într-atât că a detestat propria lui moștenire.
Nígbà náà ni Olúwa bínú sí àwọn ènìyàn rẹ̀ ó sì kórìíra àwọn ènìyàn ìní rẹ̀
41 Și i-a dat în mâna păgânilor; și cei ce i-au urât au condus asupra lor.
Ó sì fà wọ́n lé àwọn orílẹ̀-èdè lọ́wọ́, àwọn ọ̀tá wọn sì jẹ ọba lórí wọn.
42 Dușmanii lor de asemenea i-au oprimat și au fost supuși sub mâinile lor.
Àwọn ọ̀tá wọn sì ń pọ́n wọn lójú wọn sì mú wọn sìn lábẹ́ àṣẹ wọn.
43 De multe ori el i-a eliberat, dar ei l-au provocat cu sfatul lor și au fost înjosiți pentru nelegiuirea lor.
Ní ọ̀pọ̀ ìgbà òun gbà wọ́n, síbẹ̀ wọ́n sì ń ṣọ̀tẹ̀ sí i wọ́n sì ṣòfò dànù nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
44 Cu toate acestea el a dat atenție nenorocirii lor, când le-a ascultat strigătul,
Ṣùgbọ́n ó kíyèsi wọn nítorí ìṣòro nígbà tí ó gbọ́ ẹkún wọn,
45 Și pentru ei și-a amintit de legământul său și s-a pocăit conform mulțimii îndurărilor sale.
ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ nítorí wọn Nítorí agbára ìfẹ́ rẹ̀, ó ṣàánú wọn.
46 El i-a făcut să găsească milă la toți cei ce i-au dus captivi.
Lójú gbogbo àwọn tí ó kó wọn ní ìgbèkùn ó mú wọn rí àánú.
47 Salvează-ne, DOAMNE Dumnezeul nostru, și adună-ne dintre păgâni, ca să dăm mulțumiri numelui tău sfânt și să triumfăm în lauda ta.
Gbà wá, Olúwa Ọlọ́run wa, kí o sì ṣà wá jọ kúrò láàrín àwọn kèfèrí, láti máa fi ọpẹ́ fún orúkọ mímọ́ rẹ láti máa ṣògo nínú ìyìn rẹ.
48 Binecuvântat fie DOMNUL Dumnezeul lui Israel din veșnicie în veșnicie, și tot poporul să spună: Amin. Lăudați pe DOMNUL.
Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, láti ìrandíran. Jẹ́ kí gbogbo ènìyàn kí ó wí pé, “Àmín!” Ẹ fi ìyìn fún Olúwa!

< Psalmii 106 >