< Proverbe 22 >

1 Un nume bun este mai de ales decât mari bogății și favoare binevoitoare mai bine decât aur și argint.
Yíyan orúkọ rere sàn ju púpọ̀ ọrọ̀ lọ, àti ojúrere dára ju fàdákà àti wúrà lọ.
2 Cel bogat și cel sărac se întâlnesc; DOMNUL este făcătorul lor al tuturor.
Ọlọ́rọ̀ àti tálákà péjọpọ̀: Olúwa ni ẹlẹ́dàá gbogbo wọn.
3 Un om chibzuit prevede răul și se ascunde, dar simplii merg înainte și sunt pedepsiți.
Ọlọ́gbọ́n ènìyàn ti rí ibi tẹ́lẹ̀, ó ṣé ara rẹ̀ mọ́: ṣùgbọ́n àwọn òpè tẹ̀síwájú, a sì jẹ wọ́n ní yà.
4 Prin umilință și teama de DOMNUL sunt bogății și onoare și viață.
Èrè ìrẹ̀lẹ̀ àti ìbẹ̀rù Olúwa ni ọrọ̀ ọlá, àti ìyè.
5 Spini și capcane sunt în calea celui pervers; cel ce își păstrează sufletul va fi departe de ele.
Ègún àti ìdẹ̀kùn ń bẹ ní ọ̀nà aláyídáyidà: ẹni tí ó bá pa ọkàn rẹ̀ mọ́ yóò jìnnà sí wọn.
6 Educă un copil pe calea pe care ar trebui să meargă, și când ajunge bătrân nu se va depărta de ea.
Tọ́ ọmọdé ní ọ̀nà tí yóò tọ̀: nígbà tí ó bá dàgbà, kì yóò kúrò nínú rẹ̀.
7 Bogatul stăpânește peste sărac și cel ce ia cu împrumut este servitor al celui ce dă cu împrumut.
Ọlọ́rọ̀ ṣe olórí olùpọ́njú, ajigbèsè sì ṣe ìránṣẹ́ fún ẹni tí a jẹ ní gbèsè.
8 Cel ce seamănă nelegiuire va secera deșertăciune, și nuiaua mâniei sale se va sfârși.
Ẹni tí ó bá fúnrúgbìn ẹ̀ṣẹ̀, yóò ká asán: ọ̀pá ìbínú rẹ̀ yóò kùnà.
9 Cel ce are un ochi mărinimos va fi binecuvântat, fiindcă dă săracului din pâinea lui.
Ẹni tí ó ní ojú àánú ni a ó bùkún fún; nítorí tí ó fi nínú oúnjẹ rẹ̀ fún olùpọ́njú.
10 Alungă batjocoritorul și cearta se va duce; da, discordia și ocara vor înceta.
Lé ẹlẹ́gàn sí ìta, ìjà yóò sì jáde; nítòótọ́ ìjà àti ẹ̀gàn yóò dẹ́kun.
11 Cel ce iubește puritatea inimii, pentru harul buzelor sale împăratul îi va fi prieten.
Ẹni tí ó fẹ́ ìwà funfun ti àyà, tí ó sì ń sọ̀rọ̀ iyì jáde, ọba yóò ṣe ọ̀rẹ́ rẹ̀.
12 Ochii DOMNULUI păstrează cunoașterea și el răstoarnă cuvintele călcătorului de lege.
Ojú Olúwa pa ìmọ̀ mọ́, ó sì yí ọ̀rọ̀ olùrékọjá pò.
13 Leneșul spune: Este un leu afară, voi fi ucis pe străzi.
Ọ̀lẹ wí pé, “Kìnnìún ń bẹ lóde! Yóò pa mí ní ìgboro!”
14 Gura femeilor străine este o groapă adâncă; cel ce este detestat de DOMNUL va cădea în ea.
Ẹnu àwọn àjèjì obìnrin, ihò jíjìn ni; ẹni tí a ń bínú sí láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá ni yóò ṣubú sínú rẹ̀.
15 Nechibzuința este legată în inima unui copil, dar nuiaua disciplinării o va alunga departe de la el.
Àyà ọmọdé ni ìwà wèrè dì sí; ṣùgbọ́n pàṣán ìtọ́ni ni yóò lé e jìnnà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.
16 Cel ce oprimă pe sărac ca să își mărească bogățiile și cel ce dă celui bogat, vor ajunge cu siguranță la lipsă.
Ẹni tó ń ni tálákà lára láti ní ọrọ̀, tí ó sì ń ta ọlọ́rọ̀ lọ́rẹ, yóò di aláìní bí ó ti wù kó rí. Gbọ́ ọ̀rọ̀ ọlọ́gbọ́n ènìyàn.
17 Apleacă-ți urechea și ascultă cuvintele celui înțelept și dedică-ți inima cunoașterii mele.
Dẹtí rẹ sílẹ̀, kí o gbọ́ ọ̀rọ̀ àwọn ọlọ́gbọ́n, kí o sì fi àyà rẹ sí ẹ̀kọ́ mi.
18 Fiindcă este un lucru plăcut dacă le ții înăuntrul tău; ele vor fi întru totul potrivite pe buzele tale.
Nítorí ohun dídùn ni bí ìwọ bá pa wọ́n mọ́ ní inú rẹ; nígbà tí a sì pèsè wọn tán ní ètè rẹ.
19 Eu ți-am făcut cunoscută astăzi, tocmai ție, pentru ca încrederea ta să fie în DOMNUL.
Kí ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ lè wà ní ti Olúwa, èmi fihàn ọ́ lónìí, àní fún ọ.
20 Nu ți-am scris lucruri alese în sfaturi și cunoaștere,
Èmi kò ha ti kọ̀wé ohun dáradára sí ọ ní ti ìmọ̀ràn àti ní ti ẹ̀kọ́,
21 Ca să îți fac cunoscută certitudinea cuvintelor adevărului, ca să răspunzi cu cuvintele adevărului acelora ce trimit la tine?
kí ó lè mú ọ mọ ìdájú ọ̀rọ̀ òtítọ́; kí ìwọ le máa fi ìdáhùn òtítọ́ fún àwọn tí ó rán ọ?
22 Nu jefui pe sărac, pentru că el este sărac; nici nu asupri pe cel nenorocit la poartă,
Má ṣe ja tálákà ní olè, nítorí tí ó jẹ́ tálákà: bẹ́ẹ̀ ni kí o má sì ṣe ni olùpọ́njú lára ní ibodè,
23 Fiindcă DOMNUL va pleda în cauza lor și va prăda sufletul acelora ce i-au prădat.
nítorí Olúwa yóò gbèjà wọn, yóò sì gba ọkàn àwọn tí ń gba tiwọn náà.
24 Nu te împrieteni cu un om mânios și nu merge împreună cu un om furios,
Má ṣe bá oníbìínú ènìyàn ṣe ọ̀rẹ́; má sì ṣe bá ọkùnrin onínú-fùfù rìn.
25 Ca nu cumva să înveți căile lui și să obții o capcană pentru sufletul tău.
Kí ìwọ má ba à kọ́ ìwà rẹ̀, ìwọ a sì gba ìkẹ́kùn fún ara rẹ.
26 Nu fi unul dintre cei ce bat palma, sau din cei care sunt garanți pentru datorii.
Má ṣe wà nínú àwọn tí ń ṣe ìgbọ̀nwọ́, tàbí nínú àwọn tí ó dúró fún gbèsè.
27 Dacă nu ai nimic de plătit, de ce să ia patul tău de sub tine?
Bí ìwọ kò bá ní nǹkan tí ìwọ ó fi san, nítorí kín ni yóò ṣe gba ẹni rẹ kúrò lábẹ́ rẹ?
28 Nu scoate vechea piatră de hotar, pe care părinții tăi au pus-o.
Má ṣe yẹ ààlà ilẹ̀ ìgbàanì, tí àwọn baba rẹ ti pa.
29 Vezi tu un om harnic în ocupația lui? El va sta în picioare înaintea împăraților; nu va sta în picioare înaintea celor neînsemnați.
Ìwọ ha rí ènìyàn tí ó ń fi àìṣe ìmẹ́lẹ́ ṣe iṣẹ́ rẹ̀? Òun yóò dúró níwájú àwọn ọba; òun kì yóò dúró níwájú àwọn ènìyàn lásán.

< Proverbe 22 >