< Numerele 1 >

1 Și DOMNUL i-a vorbit lui Moise în pustiul Sinai, în tabernacolul întâlnirii, în prima zi a lunii a doua, în al doilea an după ce au ieșit din țara Egiptului, spunând:
Olúwa bá Mose sọ̀rọ̀ ní aginjù Sinai nínú àgọ́ àjọ ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kejì ní ọdún kejì tí àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, ó wí pé,
2 Faceți numărătoarea întregii adunări a copiilor lui Israel, după familiile lor, după casa părinților lor, după numărul numelor lor, fiecare parte bărbătească după capii lor;
“Ka gbogbo àgbájọ ènìyàn Israẹli nípa ẹbí wọn, àti nípa ìdílé baba wọn, to orúkọ wọn olúkúlùkù ọkùnrin ní ọ̀kọ̀ọ̀kan.
3 De la douăzeci de ani în sus, toți cei care sunt în stare să iasă la război în Israel; tu și Aaron să îi numeri după oștirile lor.
Ìwọ àti Aaroni ni kí ẹ kà gbogbo ọmọkùnrin Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn láti ọmọ ogún ọdún sókè, àwọn tí ó tó lọ sójú ogun.
4 Și cu tine să fie un bărbat din fiecare trib; fiecare cap al casei părinților lui.
Kí ẹ mú ọkùnrin kọ̀ọ̀kan láti inú olúkúlùkù ẹ̀yà kí ó sì wá pẹ̀lú yín, kí olúkúlùkù jẹ́ olórí ilé àwọn baba rẹ̀.
5 Și acestea sunt numele bărbaților care vor sta în picioare cu tine, din tribul lui Ruben, Elițur, fiul lui Ședeur.
“Orúkọ àwọn ọkùnrin tí yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ nìyí: “Láti ọ̀dọ̀ Reubeni, Elisuri ọmọ Ṣedeuri.
6 Din Simeon: Șelumiel, fiul lui Țurișadai.
Láti ọ̀dọ̀ Simeoni, Ṣelumieli ọmọ Suriṣaddai.
7 Din Iuda: Nahșon, fiul lui Aminadab.
Láti ọ̀dọ̀ Juda, Nahiṣoni ọmọ Amminadabu.
8 Din Isahar: Nataneel, fiul lui Țuar.
Láti ọ̀dọ̀ Isakari, Netaneli ọmọ Suari.
9 Din Zabulon: Eliab, fiul lui Helon.
Láti ọ̀dọ̀ Sebuluni, Eliabu ọmọ Heloni.
10 Din copiii lui Iosif, din Efraim: Elișama, fiul lui Amihud; din Manase: Gamaliel, fiul lui Pedahțur.
Láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Josẹfu: láti ọ̀dọ̀ Efraimu, Eliṣama ọmọ Ammihudu. Láti ọ̀dọ̀ Manase, Gamalieli ọmọ Pedasuri.
11 Din Beniamin: Abidan, fiul lui Ghideoni.
Láti ọ̀dọ̀ Benjamini, Abidani ọmọ Gideoni.
12 Din Dan: Ahiezer, fiul lui Amișadai.
Láti ọ̀dọ̀ Dani, Ahieseri ọmọ Ammiṣaddai.
13 Din Așer: Paguiel, fiul lui Ocran.
Láti ọ̀dọ̀ Aṣeri, Pagieli ọmọ Okanri.
14 Din Gad: Eliasaf, fiul lui Deuel.
Láti ọ̀dọ̀ Gadi, Eliasafu ọmọ Deueli.
15 Din Neftali: Ahira, fiul lui Enan.
Láti ọ̀dọ̀ Naftali, Ahira ọmọ Enani.”
16 Aceștia erau cei renumiți ai adunării, prinți ai triburilor părinților lor, căpeteniile miilor în Israel.
Àwọn wọ̀nyí ni wọ́n yàn nínú àwùjọ ènìyàn, olórí àwọn ẹ̀yà baba wọn. Àwọn ni olórí àwọn ẹbí Israẹli.
17 Și Moise și Aaron au luat pe acești bărbați numiți după numele lor;
Mose àti Aaroni mú àwọn ènìyàn tí a dárúkọ wọ̀nyí
18 Și au adunat toată adunarea în prima zi a lunii a doua și au declarat nașterile lor după familiile lor, după casa părinților lor, conform numărului numelor, de la vârsta de douăzeci de ani în sus, după capii lor.
wọ́n sì pe gbogbo àwùjọ ènìyàn Israẹli jọ ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kejì. Àwọn ènìyàn sì dárúkọ baba ńlá wọn nípa ẹbí àti ìdílé wọn. Wọ́n sì ṣe àkọsílẹ̀ orúkọ àwọn ọmọkùnrin ní ọ̀kọ̀ọ̀kan láti ọmọ ogún ọdún sókè,
19 Precum DOMNUL i-a poruncit lui Moise, astfel i-a numărat în pustiul Sinai.
gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose. Bẹ́ẹ̀ náà ló ṣe kà wọ́n nínú aginjù Sinai.
20 Și copiii lui Ruben, fiul cel mai mare al lui Israel, după generațiile lor, după familiile lor, după casa părinților lor, conform numărului numelor, după capii lor, fiecare parte bărbătească de la vârsta de douăzeci de ani în sus, toți care erau în stare să iasă la război;
Láti ìran Reubeni tí í ṣe àkọ́bí Israẹli, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn, lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
21 Cei numărați dintre ei, din tribul lui Ruben, au fost patruzeci și șase de mii cinci sute.
Àwọn tí a kà ní ẹ̀yà Reubeni jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàlélógún ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
22 Dintre copiii lui Simeon, după generațiile lor, după familiile lor, după casa părinților lor, cei numărați dintre ei, conform numărului numelor, după capii lor, fiecare parte bărbătească de la vârsta de douăzeci de ani în sus, toți care erau în stare să iasă la război;
Láti ìran Simeoni, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè, tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n kà, wọ́n sì to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
23 Cei numărați dintre ei, din tribul lui Simeon, au fost cincizeci și nouă de mii trei sute.
Iye àwọn tí á kà nínú ẹ̀yà Simeoni jẹ́ ẹgbàá mọ́kàndínlọ́gbọ̀n ó lé ọ̀ọ́dúnrún.
24 Dintre copiii lui Gad, după generațiile lor, după familiile lor, după casa părinților lor, conform numărului numelor, de la vârsta de douăzeci de ani în sus, toți care erau în stare să iasă la război;
Láti ìran Gadi, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan, gẹ́gẹ́ bí ẹbí àti ìdílé wọn.
25 Cei numărați dintre ei, din tribul lui Gad, au fost patruzeci și cinci de mii șase sute cincizeci.
Iye àwọn tí a kà nínú ẹ̀yà Gadi jẹ́ ẹgbàá méjìlélógún ó lé àádọ́talélẹ́gbẹ̀jọ.
26 Dintre copiii lui Iuda, după generațiile lor, după familiile lor, după casa părinților lor, conform numărului numelor, de la vârsta de douăzeci de ani în sus, toți care erau în stare să iasă la război;
Láti ìran Juda, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè, tí wọ́n le lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
27 Cei numărați dintre ei, din tribul lui Iuda, au fost șaptezeci și patru de mii șase sute.
Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Juda jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàdínlógójì ó lé ẹgbẹ̀ta.
28 Dintre copiii lui Isahar, după generațiile lor, după familiile lor, după casa părinților lor, conform numărului numelor, de la vârsta de douăzeci de ani în sus, toți care erau în stare să iasă la război;
Láti ìran Isakari, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè tí wọ́n le lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
29 Cei numărați dintre ei, din tribul lui Isahar, au fost cincizeci și patru de mii patru sute.
Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Isakari jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàdínlọ́gbọ̀n ó lé irinwó.
30 Dintre copiii lui Zabulon, după generațiile lor, după familiile lor, după casa părinților lor, conform numărului numelor, de la vârsta de douăzeci de ani în sus, toți care erau în stare să iasă la război;
Láti ìran Sebuluni, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
31 Cei numărați dintre ei, din tribul lui Zabulon, au fost cincizeci și șapte de mii patru sute.
Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Sebuluni jẹ́ ẹgbàá méjìdínlọ́gbọ̀n ó lé egbèje.
32 Dintre copiii lui Iosif, adică, din copiii lui Efraim, după generațiile lor, după familiile lor, după casa părinților lor, conform numărului numelor, de la vârsta de douăzeci de ani în sus, toți care erau în stare să iasă la război;
Láti inú àwọn ọmọ Josẹfu. Láti ìran Efraimu, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọ́n jẹ́ ogún ọdún sókè tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
33 Cei numărați dintre ei, din tribul lui Efraim, au fost patruzeci de mii cinci sute.
Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Efraimu jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
34 Dintre copiii lui Manase, după generațiile lor, după familiile lor, după casa părinților lor, conform numărului numelor, de la vârsta de douăzeci de ani în sus, toți care erau în stare să iasă la război;
Láti ìran Manase, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè, tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
35 Cei numărați dintre ei, din tribul lui Manase, au fost treizeci și două de mii două sute.
Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Manase jẹ́ ẹgbàá ẹẹ́rìndínlógún ó lé igba.
36 Dintre copiii lui Beniamin, după generațiile lor, după familiile lor, după casa părinților lor, conform numărului numelor, de la vârsta de douăzeci de ani în sus, toți care erau în stare să iasă la război;
Láti ìran Benjamini, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
37 Cei numărați dintre ei, din tribul lui Beniamin, au fost treizeci și cinci de mii patru sute.
Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Benjamini jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàdínlógún ó lé egbèje.
38 Dintre copiii lui Dan, după generațiile lor, după familiile lor, după casa părinților lor, conform numărului numelor, de la vârsta de douăzeci de ani în sus, toți care erau în stare să iasă la război;
Láti ìran Dani, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ọmọ ogún ọdún sókè, tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
39 Cei numărați dintre ei, din tribul lui Dan, au fost șaizeci și două de mii șapte sute.
Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Dani jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélọ́gbọ̀n ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin.
40 Dintre copiii lui Așer, după generațiile lor, după familiile lor, după casa părinților lor, conform numărului numelor, de la vârsta de douăzeci de ani în sus, toți care erau în stare să iasă la război;
Láti ìran Aṣeri, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè, tí wọ́n le lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
41 Cei numărați dintre ei, din tribul lui Așer, au fost patruzeci și una de mii cinci sute.
Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Aṣeri jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ.
42 Dintre copiii lui Neftali, după generațiile lor, după familiile lor, după casa părinților lor, conform numărului numelor, de la vârsta de douăzeci de ani în sus, toți care erau în stare să iasă la război;
Láti ìran Naftali, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún ó lé, tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
43 Cei numărați dintre ei, din tribul lui Neftali, au fost cincizeci și trei de mii patru sute.
Iye àwọn tí a kà nínú ẹ̀yà Naftali jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìndínlọ́gbọ̀n ó lé egbèje.
44 Aceștia sunt cei numărați, pe care Moise și Aaron i-au numărat și prinții lui Israel, fiind doisprezece bărbați; fiecare era pentru casa părinților lui.
Wọ̀nyí ni àwọn ènìyàn tí Mose àti Aaroni kà, pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ àwọn olórí méjìlá fún Israẹli, tí ẹnìkọ̀ọ̀kan ṣojú fún ìdílé rẹ̀.
45 Astfel au fost toți cei numărați dintre copiii lui Israel, după casa părinților lor, de la vârsta de douăzeci de ani în sus, toți cei care erau în stare să iasă la război în Israel;
Gbogbo ọmọkùnrin Israẹli tó jẹ́ ọmọ ogún ọdún sókè, tó sì lè lọ sójú ogun ni wọ́n kà gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn.
46 Da, toți cei numărați au fost șase sute trei mii cinci sute cincizeci.
Àpapọ̀ iye wọn jẹ́ ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ ó lé egbèjìdínlógún dín làádọ́ta.
47 Dar leviții după tribul părinților lor nu au fost numărați printre ei.
A kò ka àwọn ìdílé ẹ̀yà Lefi mọ́ àwọn ìyókù.
48 Fiindcă DOMNUL vorbise lui Moise, spunând:
Nítorí Olúwa ti sọ fún Mose pé,
49 Numai tribul lui Levi să nu îl numeri, nici să nu faci numărătoarea lor printre copiii lui Israel,
“Ìwọ kò gbọdọ̀ ka ẹ̀yà Lefi, tàbí kí o kà wọ́n mọ́ àwọn ọmọ Israẹli.
50 Ci să numești pe leviți peste tabernacolul mărturiei și peste toate vasele lui și peste toate lucrurile care aparțin de el; ei vor purta tabernacolul și toate vasele lui; și vor servi în el și își vor așeza tabăra de jur împrejurul tabernacolului.
Dípò èyí yan àwọn ọmọ Lefi láti jẹ́ alábojútó àgọ́ ẹ̀rí, lórí gbogbo ohun èlò àti ohun gbogbo tó jẹ́ ti àgọ́ ẹ̀rí. Àwọn ni yóò máa gbé àgọ́ àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, wọn ó máa mójútó o, kí wọn ó sì máa pàgọ́ yí i ká.
51 Și când tabernacolul pleacă, leviții să îl desfacă; și când tabernacolul trebuie așezat, leviții să îl așeze; și străinul care se apropie să fie dat morții.
Ìgbàkígbà tí àgọ́ yóò bá tẹ̀síwájú, àwọn ọmọ Lefi ni yóò tú palẹ̀, nígbàkígbà tí a bá sì tún pa àgọ́, àwọn ọmọ Lefi náà ni yóò ṣe é. Àlejò tó bá súnmọ́ tòsí ibẹ̀, pípa ni kí ẹ pa á
52 Și copiii lui Israel să își așeze corturile, fiecare om după tabăra lui și fiecare om după steagul lui, prin toate oștirile lor.
kí àwọn ọmọ Israẹli pa àgọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn olúkúlùkù ní ibùdó tirẹ̀ lábẹ́ ọ̀págun tirẹ̀.
53 Dar leviții să își așeze corturile de jur împrejurul tabernacolului mărturiei, ca să nu fie furie peste adunarea copiilor lui Israel; și leviții vor păstra însărcinarea tabernacolului mărturiei.
Àwọn ọmọ Lefi yóò jẹ́ alábojútó àti olùtọ́jú àgọ́ ẹ̀rí náà, kí ìbínú má ba à sí lára ìjọ àwọn ọmọ Israẹli; kí àwọn ọmọ Lefi sì máa ṣe ìtọ́jú àgọ́ ẹ̀rí náà.”
54 Și copiii lui Israel au făcut conform cu tot ceea ce DOMNUL i-a poruncit lui Moise, astfel au făcut ei.
Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe ohun gbogbo gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.

< Numerele 1 >