< Numerele 22 >
1 Și copiii lui Israel au plecat și au așezat corturile în câmpiile lui Moab de partea aceasta a Iordanului lângă Ierihon.
Nígbà náà àwọn ọmọ Israẹli rin ìrìnàjò lọ sí pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu wọ́n sì pa ibùdó lẹ́gbẹ̀ẹ́ Jordani tí ó kọjá lọ sí Jeriko.
2 Și Balac, fiul lui Țipor, a văzut tot ceea ce Israel făcuse amoriților.
Nísinsin yìí, Balaki ọmọ Sippori rí gbogbo ohun tí àwọn Israẹli ti ṣe sí àwọn ará Amori,
3 Și Moab a fost foarte înfricoșat de popor, pentru că erau mulți, și Moab s-a tulburat din cauza copiilor lui Israel.
ẹ̀rù sì ba Moabu nítorí pé ọ̀pọ̀ ènìyàn wà níbẹ̀ nítòótọ́, Moabu kún fún ẹ̀rù nítorí àwọn ọmọ Israẹli.
4 Și Moab le-a spus bătrânilor lui Madian: Acum, această mulțime va linge pe toți cei ce sunt de jur împrejurul nostru, precum boul linge iarba câmpului. Și Balac, fiul lui Țipor, era împăratul moabiților în acel timp.
Moabu sọ fún àwọn àgbàgbà Midiani pé, “Nísinsin yìí ni àwọn wọ̀nyí yóò lá gbogbo ohun tí ó yí wa ká, bí màlúù ṣe ń jẹ koríko tí ó wà nínú oko.” Bẹ́ẹ̀ ni Balaki ọmọ Sippori, tí ó jẹ́ ọba Moabu nígbà náà,
5 De aceea a trimis mesageri la Balaam, fiul lui Beor, la Petor, care este lângă râul din țara copiilor poporului său, pentru a-l chema, spunând: Iată, a ieșit un popor din Egipt; iată, ei acoperă fața pământului și s-au așezat înaintea mea;
rán oníṣẹ́ pé Balaamu ọmọ Beori, tí ó wà ní Petori, ní ẹ̀bá odò Eufurate, ti ilẹ̀ àwọn ènìyàn rẹ. Balaki sọ pé, “Àwọn ènìyàn kan jáde wá láti Ejibiti; wọ́n bo gbogbo ilẹ̀ ayé wọ́n sì pa ibùdó súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi.
6 Vino, te rog, blestemă-mi pe acest popor, (căci ei sunt prea puternici pentru mine, poate că voi învinge; ) ca să îi batem și ca să îi alungăm din țară; căci știu că pe cine binecuvântezi tu, este binecuvântat, și pe cine blestemi tu, este blestemat.
Nísinsin yìí, wá fi àwọn ènìyàn wọ̀nyí bú, nítorí wọ́n ní agbára jù fún mi. Nípa ṣíṣe èyí èmi ó ṣẹ́gun wọn, kí n sì lé wọn kúrò ní ilẹ̀ yìí. Nítorí tí mo mọ̀ pé ìbùkún ni fún àwọn tí ìwọ bá bùkún, ìfibú sì ni ẹni tí ìwọ bá fi bú.”
7 Și bătrânii lui Moab și bătrânii lui Madian au plecat cu răsplățile pentru ghicire în mâna lor; și au venit la Balaam și i-au spus cuvintele lui Balac.
Àti àwọn àgbàgbà Moabu àti Midiani sì lọ pẹ̀lú owó àyẹ̀wò lọ́nà wọn, nígbà tí wọ́n dé ọ̀dọ̀ Balaamu, wọ́n sọ nǹkan tí Balaki sọ fún wọn.
8 Și el le-a spus: Rămâneți aici în această noapte și vă voi aduce vorbă din nou, precum DOMNUL îmi va vorbi și prinții lui Moab au rămas cu Balaam.
“Ẹ sùn níbí lálẹ́ yìí,” Balaamu sọ fún un pé, “èmi ó padà wá fún un yín ní èsì nǹkan tí Olúwa bá wí fún mi.” Nítorí tí àwọn ìjòyè Moabu dúró sọ́dọ̀ rẹ̀.
9 Și Dumnezeu a venit la Balaam și a spus: Cine sunt acești oameni găzduiți la tine?
Ọlọ́run tọ Balaamu wá ó sì wí pé, “Ta ni àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ yìí?”
10 Și Balaam i-a spus lui Dumnezeu: Balac, fiul lui Țipor, împăratul lui Moab, a trimis la mine, spunând:
Balaamu sọ fún Ọlọ́run pé, “Balaki ọmọ Sippori, ọba Moabu, rán iṣẹ́ yìí sí mi pé,
11 Iată, a ieșit din Egipt un popor care acoperă fața pământului, vino acum, blestemă-i pentru mine; poate că voi fi în stare să îi înving și să îi alung.
‘Àwọn ènìyàn kan ti ilẹ̀ Ejibiti jáde wá tí wọ́n bo ojú ilẹ̀. Nísinsin yìí, wá, kí o wá fi wọ́n bú fún mi. Bóyá èmi yóò lè bá wọn jà, èmi ó sì lé wọn jáde.’”
12 Și Dumnezeu i-a spus lui Balaam: Să nu mergi cu ei; să nu blestemi poporul, pentru că ei sunt binecuvântați.
Ṣùgbọ́n Ọlọ́run sọ fún Balaamu pé, “Má ṣe bá wọn lọ. Ìwọ kò gbọdọ̀ gé ègún lé àwọn ènìyàn náà lórí, nítorí a ti bùkún wọn.”
13 Și Balaam s-a sculat dimineața și a spus prinților lui Balac: Întoarceți-vă în țara voastră, pentru că DOMNUL refuză să îmi dea voie să merg cu voi.
Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì Balaamu dìde ó sì sọ fún àwọn ìjòyè Balaki pé, “Ẹ padà sí orílẹ̀-èdè yín, nítorí tí Olúwa ti kọ̀ láti jẹ́ kí n tẹ̀lé yín.”
14 Și prinții lui Moab s-au ridicat și au mers la Balac și au spus: Balaam refuză să vină cu noi.
Nígbà náà àwọn ìjòyè Moabu sì padà tọ Balaki lọ wọ́n sì wí pé, “Balaamu kọ̀ láti tẹ̀lé wa.”
15 Și Balac a trimis din nou prinți, mai mulți și demni de mai multă cinste decât ceilalți.
Nígbà náà Balaki rán àwọn ìjòyè mìíràn tí wọ́n pọ̀ àwọn tí wọ́n sì níyì ju alákọ́kọ́ lọ.
16 Și ei au venit la Balaam și i-au spus: Astfel spune Balac, fiul lui Țipor: Te rog, nu lăsa nimic să te împiedice de a veni la mine;
Wọ́n lọ sí ọ̀dọ̀ Balaamu wọ́n sì sọ pé, “Èyí ni ohun tí Balaki ọmọ Sippori sọ, má ṣe jẹ́ kí ohunkóhun kí ó dè ọ́ lọ́nà láti wá sí ọ̀dọ̀ mi,
17 Pentru că foarte mult te voi onora și voi face orice îmi spui, vino de aceea, te rog, blestemă-mi acest popor.
nítorí pé èmi yóò fún ọ ní ẹ̀bùn dáradára, èmi yóò sì ṣe ohunkóhun tí ìwọ bá sọ. Wá, kí o sì wá fi àwọn ènìyàn wọ̀nyí bú fún mi.”
18 Și Balaam a răspuns și a spus servitorilor lui Balac: Dacă Balac mi-ar da casa lui plină de argint și aur, eu nu pot trece peste cuvântul DOMNULUI Dumnezeul meu, pentru a face mai puțin sau mai mult.
Ṣùgbọ́n Balaamu dá wọn lóhùn pé, “Kódà tí Balaki bá fún mi ní ààfin rẹ̀ tí ó kún fún fàdákà àti wúrà, èmi kò ní ṣe ohunkóhun tí ó tóbi tàbí kéré tí ó kọjá òfin Olúwa Ọlọ́run mi.
19 De aceea acum, vă rog, rămâneți și voi aici în această noapte, ca să știu ce îmi va spune mai mult DOMNUL.
Nísinsin yìí ẹ dúró níbí di ọjọ́ kejì gẹ́gẹ́ bí àwọn tókù ti ṣe nígbà náà èmi yóò mọ ohun tí Olúwa yóò tún sọ fún mi.”
20 Și Dumnezeu a venit la Balaam în timpul nopții și i-a spus: Dacă bărbații vin să te cheme, scoală-te și du-te cu ei; dar totuși cuvântul pe care ți-l voi spune: Acela să îl faci.
Ní alẹ́ ọjọ́ náà Ọlọ́run sì tọ Balaamu wá ó sì sọ wí pé, “Nígbà tí ọkùnrin yìí ti wá pè ọ́, lọ pẹ̀lú wọn, ṣùgbọ́n ẹnu nǹkan tí mo sọ fún ọ ni kí o ṣe.”
21 Și Balaam s-a sculat dimineața și și-a înșeuat măgărița și a mers cu prinții lui Moab.
Balaamu dìde ní òwúrọ̀, ó sì di ẹrù lé kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ òun pẹ̀lú àwọn ìjòyè Moabu.
22 Și mânia lui Dumnezeu s-a aprins pentru că el s-a dus și îngerul DOMNULUI a stat în picioare pe cale ca potrivnic împotriva lui. Acum el călărea pe măgărița sa și cei doi servitori ai lui erau cu el.
Ṣùgbọ́n Ọlọ́run bínú gidigidi, angẹli Olúwa sì dúró lójú ọ̀nà láti dojú ìjà kọ ọ́. Balaamu ń gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ lọ, àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ méjì sì wà pẹ̀lú rẹ̀.
23 Și măgărița a văzut îngerul DOMNULUI stând în picioare pe cale și sabia lui trasă în mâna sa și măgărița s-a abătut afară de pe cale și a intrat în câmp; și Balaam a lovit măgărița să o întoarcă pe cale.
Nígbà tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà sì rí angẹli Olúwa tí ó dúró ní ojú ọ̀nà pẹ̀lú idà tí a fàyọ ní ọwọ́ rẹ̀, ó kọjú kúrò ní ọ̀nà lọ sínú oko. Balaamu sì lù ú pé kí ó gbé òhun padà lọ sí ojú ọ̀nà.
24 Dar îngerul DOMNULUI a stat pe o cărare a viilor, un zid fiind de această parte și un zid de cealaltă parte.
Nígbà náà angẹli Olúwa dúró ní ojú ọ̀nà tóóró láàrín ọgbà àjàrà, pẹ̀lú ògiri ní ọ̀nà méjèèjì.
25 Și când măgărița a văzut îngerul DOMNULUI, s-a trântit de zid și a turtit piciorul lui Balaam de zid și el a lovit-o din nou.
Nígbà tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rí angẹli Olúwa, ó lẹ̀ mọ́ ẹ̀gbẹ́ ògiri, ó sì rún ẹsẹ̀ Balaamu mọ́ ògiri. Nígbà náà, ó tún nà án, lẹ́ẹ̀kan sí i.
26 Și îngerul DOMNULUI a mers mai departe și a stat în picioare într-un loc strâmt, unde nu era drum să întorci nici la dreapta nici la stânga.
Nígbà náà angẹli Olúwa súnmọ́ wájú ó sì dúró níbi ọ̀nà tóóró níbi tí kò ti sí ọ̀nà láti yípadà, bóyá ní ọ̀tún tàbí òsì.
27 Și când măgărița a văzut pe îngerul DOMNULUI, a căzut sub Balaam și mânia lui Balaam s-a aprins și el a lovit măgărița cu un toiag.
Nígbà tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rí angẹli Olúwa, ó sì jókòó ní abẹ́ Balaamu, inú sì bí i tó sì nà án pẹ̀lú ọ̀pá rẹ̀.
28 Și DOMNUL a deschis gura măgăriței și ea a spus lui Balaam: Ce ți-am făcut, că m-ai lovit de aceste trei ori?
Nígbà náà Olúwa ṣí ẹnu kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó sì sọ fún Balaamu pé, “Kí ni mo ṣe fún ọ tí o fi nà mí lẹ́ẹ̀mẹ́ta?”
29 Și Balaam a spus măgăriței: Pentru că m-ai batjocorit, de ar fi fost o sabie în mâna mea te-aș fi ucis chiar acum.
Balaamu sọ fún kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ pé, “Nítorí ìwọ fi mí ṣẹ̀sín! Bí mo bá ní idà ní ọwọ́ ni èmi ìbá pa ọ́ nísinsin yìí.”
30 Iar măgărița i-a spus lui Balaam: Nu sunt eu măgărița ta, pe care ai călărit de când am fost a ta până în această zi? Obișnuiam vreodată să îți fac astfel? Iar el a spus: Nu.
Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sọ fún Balaamu pé, “Ṣé mi kì í ṣe kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ ni, tí o máa ń gùn ní gbogbo ìgbà, láti ìgbà pípẹ́ wá? Ǹjẹ́ mo hu irú ìwà báyìí sí ọ rí?” “Rárá,” Ó dáhùn.
31 Atunci DOMNUL a deschis ochii lui Balaam și el a văzut pe îngerul DOMNULUI stând în picioare pe cale și sabia lui trasă în mâna lui și și-a plecat capul și s-a aruncat cu fața sa la pământ.
Nígbà náà Olúwa ṣí ojú Balaamu, ó sì rí angẹli Olúwa tí ó dúró ní ojú ọ̀nà pẹ̀lú idà rẹ̀ tí ó fàyọ. Ó sì tẹ orí rẹ̀ ba.
32 Și îngerul DOMNULUI i-a spus: Pentru ce ți-ai lovit măgărița de aceste trei ori? Iată, am ieșit să stau împotriva ta, deoarece calea ta este perversă înaintea mea,
Nígbà náà angẹli Olúwa béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Kí ni ó dé tí o fi na kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ nígbà mẹ́ta yìí? Mo wá síbí láti kọ ojú ìjà sí ọ nítorí ọ̀nà rẹ kò tọ́ níwájú mi.
33 Și măgărița m-a văzut și s-a abătut de la mine de aceste trei ori, dacă nu s-ar fi abătut de la mine, cu siguranță te-aș fi ucis și pe ea aș fi lăsat-o vie.
Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rí mi ó sì yà kúrò fún mi lẹ́ẹ̀mẹ́ta yìí. Tí ó bá jẹ́ wí pé kò yà kúrò. Èmi kì ìbá ti pa ọ́ pátápátá nísinsin yìí, ṣùgbọ́n Èmi yóò sì dá òun sí.”
34 Și Balaam a spus îngerului DOMNULUI: Am păcătuit, pentru că nu am știut că stai în cale împotriva mea; acum de aceea dacă aceasta te nemulțumește, mă voi întoarce înapoi.
Balaamu sọ fún angẹli Olúwa pé, “Mo ti dẹ́ṣẹ̀, èmi kò mọ̀ pé o dúró níwájú ọ̀nà láti dojúkọ mí, nísinsin yìí tí inú rẹ kò bá dùn, èmi ó padà.”
35 Și îngerul DOMNULUI i-a spus lui Balaam: Du-te cu acești bărbați, dar numai cuvântul pe care ți-l voi spune, acela să îl vorbești. Astfel Balaam a mers cu prinții lui Balac.
Angẹli Olúwa sọ fún Balaamu pé, “Lọ pẹ̀lú àwọn arákùnrin náà, ṣùgbọ́n nǹkan tí mo sọ fún ọ nìkan ni kí o sọ.” Nígbà náà Balaamu lọ pẹ̀lú àwọn ìjòyè Balaki.
36 Și când Balac a auzit că a venit Balaam, a ieșit să îl întâlnească la o cetate a lui Moab, care este pe granița Arnonului, care este în ținutul cel mai îndepărtat.
Nígbà tí Balaki gbọ́ pé Balaamu ń bọ̀ wá, ó jáde lọ láti lọ pàdé rẹ̀ ní ìlú Moabu tí ó wà ní agbègbè Arnoni, ní ẹ̀gbẹ́ ilẹ̀ rẹ̀.
37 Și Balac i-a spus lui Balaam: Nu am trimis la tine cu stăruință ca să te cheme? Pentru ce nu ai venit la mine? Nu sunt eu în stare să te onorez?
Balaki sì sọ fún Balaamu pé, “Ǹjẹ́ èmi kò a ránṣẹ́ kánjúkánjú sí ọ? Kí ló dé tí ìwọ kò fi wá sí ọ̀dọ̀ mi? Ṣé èmi kò tó láti sọ ọ́ di ẹni ńlá?”
38 Și Balaam i-a spus lui Balac: Iată, am venit la tine, am eu vreo putere în vreun fel să spun ceva? cuvântul pe care Dumnezeu îl pune în gura mea, aceea voi vorbi.
Balaamu sì wí fún Balaki pé, “Kíyèsi, èmi tọ̀ ọ́ wá, èmi kò ha ní agbára kan nísinsin yìí rárá láti wí ohun kan? Mo gbọdọ̀ sọ nǹkan tí Ọlọ́run fi sí mi lẹ́nu.”
39 Și Balaam a mers cu Balac și au venit la Chiriat-Huțot.
Nígbà náà Balaamu lọ pẹ̀lú Balaki sí Kiriati-Hosotia.
40 Și Balac a oferit boi și oi și a trimis la Balaam și la prinții care erau cu el.
Balaki rú ẹbọ akọ màlúù pẹ̀lú àgùntàn, ó sì fún Balaamu ní díẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìjòyè tí ó wà ní ọ̀dọ̀ rẹ̀.
41 Și s-a întâmplat, a doua zi, că Balac a luat pe Balaam și l-a urcat la înălțimile lui Baal, ca de acolo să vadă până și cea mai îndepărtată margine a poporului.
Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì Balaki gbé Balaamu lọ sí Bamoti Baali, láti ibẹ̀ ló ti rí apá kan àwọn ènìyàn.