< Neemia 7 >

1 Și s-a întâmplat, după ce zidul a fost construit și eu am așezat ușile și portarii și cântăreții și leviții au fost rânduiți,
Lẹ́yìn ìgbà tí a tún odi mọ tán tí mo sì ri àwọn ìlẹ̀kùn sí ààyè wọn, a sì yan àwọn aṣọ́bodè, àwọn akọrin àti àwọn Lefi.
2 Că am dat fratelui meu Hanani și lui Hanania, conducătorul palatului, sarcina asupra Ierusalimului: pentru că era om credincios și se temea de Dumnezeu mai mult decât alții.
Mo fún Hanani arákùnrin mi pẹ̀lú Hananiah olórí ilé ìṣọ́ ní àṣẹ lórí Jerusalẹmu, nítorí tí ó jẹ́ ènìyàn olóòtítọ́, ó sì bẹ̀rù Ọlọ́run jù bí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ti ṣe lọ.
3 Și le-am spus: Să nu fie porțile Ierusalimului deschise până soarele nu va fi arzător; și în timp ce ei stau acolo, să închidă ușile și să le zăvorască; și să rânduiască gărzi dintre locuitorii Ierusalimului, fiecare la garda lui și fiecare să fie în dreptul casei lui.
Mo sọ fún wọn pé, “A kò gbọdọ̀ ṣí ìlẹ̀kùn Jerusalẹmu títí oòrùn yóò fi mú. Nígbà tí àwọn aṣọ́bodè bá sì wà lẹ́nu iṣẹ́, jẹ́ kí wọn ti ìlẹ̀kùn kí wọn sì há wọn. Bákan náà, yàn nínú àwọn tí ń gbé Jerusalẹmu gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́. Àwọn mìíràn níbi tí a pín wọn sí àti àwọn mìíràn ní tòsí ilé e wọn.”
4 Și cetatea era întinsă și mare, dar poporul era puțin în ea și casele nu erau construite.
Ìlú náà tóbi ó sì ní ààyè, ṣùgbọ́n ènìyàn inú rẹ̀ kéré, a kò sì tí ì tún àwọn ilé inú rẹ̀ kọ́.
5 Și Dumnezeul meu a pus în inima mea să adun pe nobili și pe conducători și pe popor, ca să fie socotiți prin genealogie. Și am găsit un registru al genealogiei celor care se urcaseră întâi și am găsit scris în el,
Nígbà náà ni Ọlọ́run mi fi sí mi ní ọkàn láti kó àwọn ọlọ́lá, àwọn ìjòyè, àti àwọn ènìyàn jọ fún ìforúkọsílẹ̀ ní ìdílé ìdílé. Mo rí ìwé àkọsílẹ̀ ìtàn ìran àwọn tí ó kọ́ gòkè padà wá láti ìgbèkùn. Èyí ni ohun tí mo rí tí a kọ sínú ìwé náà.
6 Aceștia sunt copiii provinciei, care s-au urcat din captivitate, dintre cei care fuseseră duși în captivitate, pe care Nebucadnețar, împăratul Babilonului, i-a dus, și care s-au întors la Ierusalim și în Iuda, fiecare la cetatea lui;
Èyí ni àwọn ènìyàn agbègbè náà tí wọ́n sọ̀kalẹ̀ wá láti ìgbèkùn, àwọn tí Nebukadnessari ọba Babeli ti kó ní ìgbèkùn (wọ́n padà sí Jerusalẹmu àti Juda, olúkúlùkù sí ìlú u rẹ̀.
7 Care au venit cu Zorobabel, Ieșua, Neemia, Azaria, Raamia, Nahamani, Mardoheu, Bilșan, Misperet, Bigvai, Nehum, Baana. Numărul, spun eu, al bărbaților poporului lui Israel era acesta:
Wọ́n jọ rìn wá pẹ̀lú u Serubbabeli, Jeṣua, Nehemiah, Asariah, Raamiah, Nahamani, Mordekai, Bilṣani, Misperi, Bigfai, Nehumu, àti Baanah). Àkọsílẹ̀ orúkọ àwọn ọkùnrin Israẹli,
8 Copiii lui Pareoș, două mii o sută șaptezeci și doi.
àwọn ọmọ Paroṣi jẹ́ ẹgbàá ó lé méjìléláàádọ́sàn-án
9 Copiii lui Șefatia, trei sute șaptezeci și doi.
Ṣefatia jẹ́ òjìdínnírinwó ó lé méjìlá
10 Copiii lui Arah, șase sute cincizeci și doi.
Arah jẹ́ ẹgbẹ̀tàléláàádọ́ta ó lé méjì
11 Copiii lui Pahat-Moab, dintre copiii lui Ieșua și ai lui Ioab, două mii opt sute optsprezece.
Pahati-Moabu (láti ipasẹ̀ ọmọ Jeṣua àti Joabu) jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìnlá ó lé méjìdínlógún
12 Copiii lui Elam, o mie două sute cincizeci și patru.
Elamu jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀fà ó lé mẹ́rin
13 Copiii lui Zatu, opt sute patruzeci și cinci.
Sattu jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀rin ó lé márùn-ún
14 Copiii lui Zacai, șapte sute șaizeci.
Sakkai jẹ́ òjìdínlẹ́gbẹ̀rin
15 Copiii lui Binui, șase sute patruzeci și opt.
Binnui jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé mẹ́jọ
16 Copiii lui Bebai, șase sute douăzeci și opt.
Bebai jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé méjìdínlọ́gbọ̀n
17 Copiii lui Azgad, două mii trei sute douăzeci și doi.
Asgadi jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó dín méjìdínlọ́gọ́rin
18 Copiii lui Adonicam, șase sute șaizeci și șapte.
Adonikami jẹ́ ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méje
19 Copiii lui Bigvai, două mii șaizeci și șapte.
Bigfai jẹ́ ẹgbàá ó lé mẹ́tàdínláàádọ́rin
20 Copiii lui Adin, șase sute cincizeci și cinci.
Adini jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀ta ó lé márùn-ún
21 Copiii lui Ater din Ezechia, nouăzeci și opt.
Ateri (láti ipasẹ̀ Hesekiah) jẹ́ méjìdínlọ́gọ́rùn-ún
22 Copiii lui Hașum, trei sute douăzeci și opt.
Haṣumu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó ó lé mẹ́jọ
23 Copiii lui Bețai, trei sute douăzeci și patru.
Besai jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó ó lé mẹ́rin
24 Copiii lui Harif, o sută doisprezece.
Harifu jẹ́ méjìléláàádọ́fà
25 Copiii lui Gabaon, nouăzeci și cinci.
Gibeoni jẹ́ márùndínlọ́gọ́rùn.
26 Bărbații din Betleem și Netofa, o sută optzeci și opt.
Àwọn ọmọ Bẹtilẹhẹmu àti Netofa jẹ́ igba ó dín méjìlélógún
27 Bărbații din Anatot, o sută douăzeci și opt.
Anatoti jẹ́ méjìdínláàádóje
28 Bărbații din Bet-Azmavet, patruzeci și doi.
Beti-Asmafeti jẹ́ méjìlélógójì
29 Bărbații din Chiriat-Iearim, Chefira și Beerot, șapte sute patruzeci și trei.
Kiriati-Jearimu, Kefira, àti Beeroti jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó lé mẹ́ta
30 Bărbații din Rama și din Gheba, șase sute douăzeci și unu.
Rama àti Geba jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mọ́kànlélógún
31 Bărbații din Micmas, o sută douăzeci și doi.
Mikmasi jẹ́ méjìlélọ́gọ́fà
32 Bărbații din Betel și din Ai, o sută douăzeci și trei.
Beteli àti Ai jẹ́ mẹ́tàlélọ́gọ́fà
33 Bărbații celuilalt Nebo, cincizeci și doi.
Nebo mìíràn jẹ́ méjìléláàádọ́ta
34 Copiii celuilalt Elam, o mie două sute cincizeci și patru.
Elamu mìíràn jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́rìnléláàádọ́ta
35 Copiii lui Harim, trei sute douăzeci.
Harimu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó
36 Copiii Ierihonului, trei sute patruzeci și cinci.
Jeriko jẹ́ ọ̀tàdínnírinwó ó lé márùn-ún.
37 Copiii lui Lod, ai lui Hadid și ai lui Ono, șapte sute douăzeci și unu.
Lodi, Hadidi, àti Ono jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rin ó lé ọ̀kan
38 Copiii lui Sena, trei mii nouă sute treizeci.
Senaa jẹ́ ẹgbàajì ó dín àádọ́rin.
39 Preoții: copiii lui Iedaia, din casa lui Ieșua, nouă sute șaptezeci și trei.
Àwọn àlùfáà: àwọn ọmọ Jedaiah (láti ipasẹ̀ ìdílé Jeṣua) jẹ́ ogún dín lẹ́gbẹ̀rin ó dín méje
40 Copiii lui Imer, o mie cincizeci și doi.
Immeri jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀rún ó lé méjì
41 Copiii lui Pașhur, o mie două sute patruzeci și șapte.
Paṣuri jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́tàdínláàádọ́ta
42 Copiii lui Harim, o mie șaptesprezece.
Harimu jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó lé mẹ́tàdínlógún.
43 Leviții: copiii lui Ieșua, ai lui Cadmiel și dintre copiii lui Hodva, șaptezeci și patru.
Àwọn ọmọ Lefi: àwọn ọmọ Jeṣua (láti ipasẹ̀ Kadmieli, láti ipasẹ̀ Hodafiah) jẹ́ mẹ́rìnléláàádọ́rin.
44 Cântăreții: copiii lui Asaf, o sută patruzeci și opt.
Àwọn akọrin: àwọn ọmọ Asafu jẹ́ méjìdínláàádọ́jọ.
45 Portarii: copiii lui Șalum, copiii lui Ater, copiii lui Talmon, copiii lui Acub, copiii lui Hatita, copiii lui Șobai, o sută treizeci și opt.
Àwọn aṣọ́nà: àwọn ọmọ Ṣallumu, Ateri, Talmoni, Akkubu, Hatita, àti Ṣobai jẹ́ méjìdínlógóje.
46 Netinimii: copiii lui Țiha, copiii lui Hasufa, copiii lui Tabaot.
Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili. Àwọn ọmọ Siha, Hasufa, Tabboati,
47 Copiii lui Cheros, copiii lui Sia, copiii lui Padon,
Kerosi, Sia, Padoni,
48 Copiii lui Lebana, copiii lui Hagaba, copiii lui Șalmai,
Lebana, Hagaba, Ṣalmai,
49 Copiii lui Hanan, copiii lui Ghidel, copiii lui Gahar,
Hanani, Giddeli, Gahari,
50 Copiii lui Reaia, copiii lui Rețin, copiii lui Necoda,
Reaiah, Resini, Nekoda,
51 Copiii lui Gazam, copiii lui Uza, copiii lui Paseah,
Gassamu, Ussa, Pasea,
52 Copiii lui Besai, copiii lui Meunim, copiii lui Nefișesim,
Besai, Mehuni, Nefisimu,
53 Copiii lui Bacbuc, copiii lui Hacufa, copiii lui Harhur,
Bakbu, Hakufa, Harhuri,
54 Copiii lui Bațlit, copiii lui Mehida, copiii lui Harșa,
Basluti, Mehida, Harṣa,
55 Copiii lui Barcos, copiii lui Sisera, copiii lui Tamah,
Barkosi, Sisera, Tema,
56 Copiii lui Nețiah, copiii lui Hatifa.
Nesia, àti Hatifa.
57 Copiii servitorilor lui Solomon: copiii lui Sotai, copiii lui Soferet, copiii lui Perida,
Àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni: àwọn ọmọ Sotai, Sofereti; Perida,
58 Copiii lui Iaala, copiii lui Darcon, copiii lui Ghidel,
Jaala, Darkoni, Giddeli,
59 Copiii lui Șefatia, copiii lui Hatil, copiii lui Pocheret-Hațebaim, copiii lui Amon.
Ṣefatia, Hattili, Pokereti-Haṣṣebaimu, àti Amoni.
60 Toți netinimii și copiii servitorilor lui Solomon, erau trei sute nouăzeci și doi.
Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ọmọ ìránṣẹ́ Solomoni jẹ́ irinwó ó dín mẹ́jọ.
61 Și aceștia au fost cei care au urcat de asemenea de la Tel-Melah, Tel-Harșa, Cherub, Adon și Imer; dar ei nu au putut arăta casa tatălui lor, nici sămânța lor, dacă erau din Israel.
Àwọn wọ̀nyí gòkè wá láti àwọn ìlú ti Teli-Mela, Teli-Harṣa, Kerubu, Addoni àti Immeri, ṣùgbọ́n wọn kò lè sọ pẹ̀lú ìdánilójú pé ìdílé àwọn wá láti ara ìran ẹ̀yà Israẹli.
62 Copiii lui Delaia, copiii lui Tobia, copiii lui Necoda, șase sute patruzeci și doi.
Àwọn ọmọ Delaiah, Tobiah àti Nekoda jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì.
63 Și dintre preoți: Copiii lui Hobaia, copiii lui Hacoț, copiii lui Barzilai, care a luat pe una dintre fiicele lui Barzilai galaaditul, de soție, și a fost numit după numele lor.
Lára àwọn àlùfáà ni: àwọn ọmọ Hobaiah, Hakosi àti Barsillai (ọkùnrin tí ó fẹ́ ọmọbìnrin Barsillai ará Gileadi, ẹni tí a ń fi orúkọ yìí pè).
64 Aceștia și-au căutat înregistrarea printre cei care au fost socotiți prin genealogie, dar ea nu s-a găsit; de aceea au fost îndepărtați din preoție, ca întinați.
Àwọn wọ̀nyí wá àkọsílẹ̀ orúkọ ìran wọn, ṣùgbọ́n wọn kò rí í níbẹ̀, fún ìdí èyí, a yọ wọ́n kúrò nínú àwọn tí ń ṣiṣẹ́ àlùfáà gẹ́gẹ́ bí aláìmọ́.
65 Și Tirșata le-a spus să nu mănânce din lucrurile preasfinte, până nu va sta în picioare un preot cu Urim și Tumim.
Baálẹ̀ sọ fún wọn nítorí náà pé wọn kò gbọdọ̀ kópa nínú jíjẹ oúnjẹ mímọ́ títí tí àlùfáà tí yóò wá tí ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú Urimu àti Tumimu yóò fi dé.
66 Toată adunarea împreună era de patruzeci și două de mii trei sute șaizeci,
Gbogbo ìjọ ènìyàn náà jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé òjìdínnírinwó,
67 În afară de servitorii lor și de servitoarele lor, dintre care erau șapte mii trei sute treizeci și șapte; și aveau două sute patruzeci și cinci de cântăreți și cântărețe.
yàtọ̀ sí àwọn ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin tí wọ́n jẹ́ ẹgbẹ̀ta dín lẹ́gbàárin ó dín ẹ̀tàlélọ́gọ́ta; wọ́n sì tún ní àwọn akọrin ọkùnrin àti obìnrin tí wọ́n jẹ́ òjìlúgba ó lé márùn-ún.
68 Caii lor, șapte sute treizeci și șase; catârii lor, două sute patruzeci și cinci;
Ẹṣin wọn jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́rin, ìbákasẹ wọn jẹ́ òjìlúgba ó dín márùn-ún;
69 Cămilele lor, patru sute treizeci și cinci; șase mii șapte sute douăzeci de măgari.
ìbákasẹ wọn jẹ́ òjìlénírinwó ó dín márùn-ún; kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọ́n jẹ́ ẹgbẹ̀rìnlélọ́gbọ̀n ó dín ọgọ́rin.
70 Și unii dintre mai marii părinților au dat pentru lucrare. Tirșata a dat pentru tezaur o mie de drahme de aur, cincizeci de oale, cinci sute treizeci de haine preoțești.
Díẹ̀ lára àwọn olórí ìdílé náà kópa nínú ṣíṣe iṣẹ́ náà. Baálẹ̀ fún ilé ìṣúra ní ẹgbẹ̀rún dariki wúrà, àádọ́ta àwo koto àti ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀ta lé mẹ́wàá ẹ̀wù fún àwọn àlùfáà.
71 Și unii dintre mai marii părinților au dat pentru tezaurul lucrării douăzeci de mii de drahme de aur și două mii două sute de mine de argint.
Díẹ̀ lára àwọn olórí ìdílé fún ilé ìṣúra ní ogún ẹgbẹ̀rún dariki wúrà àti ẹgbọ̀kànlá mina fàdákà.
72 Și ceea ce restul poporului a dat a fost douăzeci de mii de drahme de aur și două mii două sute de mine de argint și șaizeci și șapte de haine preoțești.
Àròpọ̀ gbogbo ohun tí àwọn ènìyàn tókù fi sílẹ̀ jẹ́ ogún ẹgbẹ̀rún dariki wúrà, ẹgbẹ̀rún méjì mina fàdákà àti ẹẹ́tàdínláàdọ́rin ẹ̀wù fún àwọn àlùfáà.
73 Astfel preoții și leviții și portarii și cântăreții și unii din popor și netinimii și tot Israelul au locuit în cetățile lor; și când a venit luna a șaptea, copiii lui Israel erau în cetățile lor.
Àwọn àlùfáà, àwọn Lefi, àwọn aṣọ́bodè, àwọn akọrin, àwọn ènìyàn díẹ̀, àwọn ìránṣẹ́ ilé Ọlọ́run, àti gbogbo ènìyàn Israẹli wà ní ìlú wọn. Nígbà tí ó di oṣù keje, tí àwọn ọmọ Israẹli sì ti wà nínú ìlú u wọn,

< Neemia 7 >