< Mica 1 >

1 Cuvântul DOMNULUI care a venit la Mica, morașitul, în zilele lui Iotam, Ahaz și Ezechia, împărați ai lui Iuda, pe care el l-a văzut referitor la Samaria și Ierusalim.
Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Mika ará Moreṣeti wá ní àkókò ìjọba Jotamu, Ahasi, àti Hesekiah, àwọn ọba Juda nìwọ̀nyí, ìran tí ó rí nípa Samaria àti Jerusalẹmu.
2 Ascultați, toți oamenii; dă ascultare pământule și tot ce este pe tine, și Domnul DUMNEZEU să fie martor împotriva voastră, Domnul din templul lui sfânt.
Ẹ gbọ́, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn, fetísílẹ̀, ìwọ ayé àti gbogbo ohun tó wà níbẹ̀, kí Olúwa Olódùmarè lè ṣe ẹlẹ́rìí sí yín, Olúwa láti inú tẹmpili mímọ́ rẹ̀ wá.
3 Fiindcă, iată, DOMNUL iese din locul lui și va coborî și va călca în picioare înălțimile pământului.
Wò ó! Olúwa ń bọ̀ wá láti ibùgbé rẹ̀; yóò sọ̀kalẹ̀, yóò sì tẹ ibi gíga ayé mọ́lẹ̀.
4 Și munții se vor topi sub el și văile, ca ceara înaintea focului, se vor despica și ca apele turnate dintr-o râpă.
Àwọn òkè ńlá yóò sí yọ́ lábẹ́ rẹ̀, àwọn àfonífojì yóò sì pínyà, bí idà níwájú iná, bí omi tí ó ń sàn lọ ni ibi gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́.
5 Toate acestea sunt pentru păcatul lui Iacob și pentru păcatele casei lui Israel. Care este păcatul lui Iacob? Nu este Samaria? Și care sunt locurile înalte ale lui Iuda? Nu sunt ele Ierusalimul?
Nítorí ìré-òfin-kọjá Jakọbu ni gbogbo èyí, àti nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ilé Israẹli. Kí ni ìré-òfin-kọjá Jakọbu? Ǹjẹ́ Samaria ha kọ? Kí ni àwọn ibi gíga Juda? Ǹjẹ́ Jerusalẹmu ha kọ?
6 De aceea voi face Samaria ca o movilă de pe câmp și ca plantații de vii; și voi rostogoli pietrele ei în vale și îi voi dezveli temeliile.
“Nítorí náà, èmi yóò ṣe Samaria bí òkìtì lórí pápá, bí ibi ti à ń lò fún gbígbin ọgbà àjàrà. Èmi yóò gbá àwọn òkúta rẹ̀ dànù sínú àfonífojì. Èmi yóò sí tú ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ palẹ̀.
7 Și toate chipurile ei cioplite vor fi zdrobite în bucăți și toate darurile ei vor fi arse cu foc și toți idolii ei îi voi lăsa pustii, căci ea a adunat din plata curvei și se vor întoarce la plata curvei.
Gbogbo àwọn ère fínfín rẹ̀ ni a ó fọ́ sí wẹ́wẹ́ gbogbo àwọn ẹ̀bùn tẹmpili rẹ̀ ni a ó fi iná sun, Èmi yóò sì pa gbogbo àwọn òrìṣà rẹ̀ run. Nítorí tí ó ti kó àwọn ẹ̀bùn rẹ̀ jọ láti inú owó èrè panṣágà, gẹ́gẹ́ bí owó èrè panṣágà, wọn yóò sì tún padà sí owó iṣẹ́ panṣágà.”
8 De aceea eu voi boci și voi urla, voi umbla dezbrăcat și gol; voi face bocet ca dragonii și voi jeli ca bufnițele.
Nítorí èyí, èmi yóò sì sọkún, èmi yóò sì pohùnréré ẹkún: èmi yóò máa lọ ní ẹsẹ̀ lásán àti ní ìhòhò. Èmi yóò ké bí akátá, èmi yóò sì máa dárò bí àwọn ọmọ ògòǹgò.
9 Fiindcă rana ei este incurabilă; fiindcă a venit la Iuda; a venit la poarta poporului meu, la Ierusalim.
Nítorí tí ọgbẹ́ rẹ̀ jẹ́ aláìlèwòtán; ó sì ti wá sí Juda. Ó sì ti dé ẹnu-bodè àwọn ènìyàn mi, àní sí Jerusalẹmu.
10 Nu spuneți aceasta la Gat, nu plângeți deloc; în casa lui Afra rostogolește-te în țărână.
Ẹ má ṣe sọ ní Gati ẹ má ṣe sọkún rárá. Ní ilẹ̀ Beti-Ofra mo yí ara mi nínú eruku.
11 Treceți! Tu locuitor al Safirului, având rușinea ta dezgolită; locuitorul lui Țaanan nu a venit la jelirea lui Bet-Ețel; el va primi adăpost de la tine.
Ẹ kọjá lọ ni ìhòhò àti ni ìtìjú, ìwọ tí ó ń gbé ni Ṣafiri. Àwọn tí ó ń gbé ni Saanani kì yóò sì jáde wá. Beti-Eseli wà nínú ọ̀fọ̀; a ó sì gba ààbò rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ yin.
12 Fiindcă locuitorul Marotului a așteptat cu grijă binele; dar răul a coborât de la DOMNUL la poarta Ierusalimului.
Nítorí àwọn tí ó ń gbé ni Marati ń retí ìre, ṣùgbọ́n ibi sọ̀kalẹ̀ ti ọ̀dọ̀ Olúwa wá sí ẹnu-bodè Jerusalẹmu.
13 O, tu locuitor din Lachiș, înhamă animalul iute la car, ea este începutul păcatului fiicei Sionului, fiindcă păcatele Israelului s-au găsit în tine.
Ìwọ olùgbé Lakiṣi, dì kẹ̀kẹ́ mọ́ ẹranko tí ó yára. Òun sì ni ìbẹ̀rẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀ sí àwọn ọmọbìnrin Sioni, nítorí a rí àìṣedéédéé Israẹli nínú rẹ̀.
14 De aceea tu vei da daruri Moreșet-Gatului: casele lui Aczib vor fi o minciună împăraților lui Israel.
Nítorí náà ni ìwọ ó ṣe fi ìwé ìkọ̀sílẹ̀ fún Moreṣeti Gati. Àwọn ilé Aksibu yóò jẹ́ ẹlẹ́tàn sí àwọn ọba Israẹli.
15 Totuși eu îți voi aduce un moștenitor, locuitor al Mareșahului, gloria lui Israel va ajunge până la Adulam.
Èmi yóò sì mú àrólé kan wá sórí rẹ ìwọ olùgbé Meraṣa. Ẹni tí ó jẹ́ ògo Israẹli yóò sì wá sí Adullamu.
16 Chelește-te și tunde-te pentru copiii desfătărilor tale; mărește-ți chelia ca acvila; fiindcă ei sunt plecați de la tine în captivitate.
Fá irun orí rẹ nínú ọ̀fọ̀ nítorí àwọn ọmọ rẹ aláìlágbára, sọ ra rẹ̀ di apárí bí ẹyẹ igún, nítorí wọn yóò kúrò lọ́dọ̀ rẹ lọ sí ìgbèkùn.

< Mica 1 >