< Luca 21 >
1 Și a ridicat privirea și a văzut pe bogați aruncându-și darurile în vistierie.
Nígbà tí ó sì gbé ojú sókè, ó rí àwọn ọlọ́rọ̀ ń fi ẹ̀bùn wọn sínú àpótí ìṣúra.
2 Și a văzut și pe o anumită văduvă săracă aruncând acolo doi bănuți.
Ó sì rí tálákà opó kan pẹ̀lú, ó ń sọ owó idẹ wẹ́wẹ́ méjì síbẹ̀.
3 Și a spus: Adevărat vă spun, această văduvă săracă a aruncat în vistierie mai mult decât toți;
Ó sì wí pé, “Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, tálákà opó yìí fi sí i ju gbogbo wọn lọ,
4 Fiindcă toți aceștia au aruncat din abundența lor pentru ofrandele lui Dumnezeu; dar ea, din sărăcia ei, a aruncat în vistierie tot ce avea ca să trăiască.
nítorí gbogbo àwọn wọ̀nyí fi sínú ẹ̀bùn Ọlọ́run láti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìní wọn; ṣùgbọ́n òun nínú àìní rẹ̀ ó sọ gbogbo ohun ìní rẹ̀ tí ó ní sínú rẹ̀.”
5 Și, pe când unii vorbeau despre templu, cum era ornamentat cu pietre frumoase și daruri, a spus:
Bí àwọn kan sì ti ń sọ̀rọ̀ nípa tẹmpili, bí a ti fi òkúta dáradára àti ẹ̀bùn ṣe é ní ọ̀ṣọ́, fun Ọlọ́run, Jesu wí pé
6 Cât despre acestea pe care le vedeți, vor veni zilele în care nu va fi lăsată piatră pe piatră care nu va fi dărâmată.
“Ohun tí ẹ̀yin ń wò wọ̀nyí, ọjọ́ ń bọ̀, nígbà tí a kì yóò fi òkúta kan sílẹ̀ lórí èkejì tí a kì yóò wó lulẹ̀.”
7 Iar ei l-au întrebat, spunând: Învățătorule, dar când vor fi acestea? Și ce semn va fi când acestea se vor întâmpla?
Wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, pé, “Olùkọ́, nígbà wo ni nǹkan wọ̀nyí yóò rí bẹ́ẹ̀? Àti àmì kín ni yóò wà, nígbà tí nǹkan wọ̀nyí yóò fi ṣẹ?”
8 Iar el a spus: Luați seama să nu fiți amăgiți; fiindcă mulți vor veni în numele meu, spunând: Eu sunt Cristos; și timpul se apropie; nu vă duceți așadar după ei.
Ó sì wí pé, “Ẹ máa kíyèsára, kí a má bá à mú yín ṣìnà: nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ yóò wá ní orúkọ mi, tí yóò máa wí pé, ‘Èmi ní Kristi náà àkókò náà sì kù sí dẹ̀dẹ̀.’ Ẹ má ṣe tọ̀ wọ́n lẹ́yìn.
9 Dar când veți auzi de războaie și răscoale, nu vă îngroziți; fiindcă acestea trebuie întâi să se întâmple; dar nu [este] îndată sfârșitul.
Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹ̀yin bá gbúròó ogun àti ìdágìrì, ẹ má ṣe fòyà; nítorí nǹkan wọ̀nyí ní láti kọ́kọ́ ṣẹlẹ̀, ṣùgbọ́n òpin náà kì í ṣe lójúkan náà.”
10 Apoi le-a spus: Se va ridica națiune contra națiune și împărăție contra împărăție.
Nígbà náà ni ó wí fún wọn pé, “Orílẹ̀-èdè yóò dìde sí orílẹ̀-èdè, àti ìjọba sí ìjọba.
11 Și vor fi mari cutremure de pământ în diferite locuri și foamete și molime; și din cer vor fi arătări înspăimântătoare și semne mari.
Ilẹ̀-rírì ńlá yóò sì wà káàkiri, àti ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn; ohun ẹ̀rù, àti àmì ńlá yóò sì ti ọ̀run wá.
12 Dar înaintea tuturor acestora, vor pune mâinile pe voi și vă vor persecuta, predându-vă la sinagogi și închisori, fiind aduși înaintea împăraților și a guvernatorilor, din cauza numelui meu.
“Ṣùgbọ́n ṣáájú gbogbo nǹkan wọ̀nyí, wọn ó nawọ́ mú yín, wọn ó sì ṣe inúnibíni sí yín, wọn ó mú yín lọ sí Sinagọgu, àti sínú túbú, wọn ó mú yín lọ sọ́dọ̀ àwọn ọba àti àwọn ìjòyè nítorí orúkọ mi.
13 Și aceasta vi se va întoarce pentru mărturie.
Ẹ o si jẹ́rìí nípa mi.
14 De aceea puneți-vă în inimi să nu meditați înainte ce veți răspunde,
Nítorí náà ẹ pinnu rẹ̀ ní ọkàn yín pé ẹ ko ronú ṣáájú, bí ẹ ó ti dáhùn.
15 Fiindcă eu vă voi da o gură și înțelepciune, pe care toți potrivnicii voștri nu vor putea să o combată, nici să i se împotrivească.
Nítorí tí èmi ó fún yín ní ẹnu àti ọgbọ́n, tí gbogbo àwọn ọ̀tá yín kì yóò lè sọ̀rọ̀-òdì sí, tí wọn kì yóò sì lè kò lójú.
16 Și veți fi trădați deopotrivă de părinți și frați și rude și prieteni; și [îi] vor ucide pe unii dintre voi.
A ó sì fi yín hàn láti ọwọ́ àwọn òbí yín wá, àti àwọn arákùnrin, àti àwọn ìbátan, àti àwọn ọ̀rẹ́; òun ó sì mú kì a pa nínú yín.
17 Și veți fi urâți de toți din cauza numelui meu.
A ó sì kórìíra yín lọ́dọ̀ gbogbo ènìyàn nítorí orúkọ mi.
18 Și niciun păr din capul vostru nu va pieri nicidecum.
Ṣùgbọ́n irun orí yín kan kì yóò ṣègbé.
19 În răbdarea voastră păstrați-vă sufletele.
Nínú ìdúró ṣinṣin yín ni ẹ̀yin ó jèrè ọkàn yín.
20 Iar când veți vedea Ierusalimul încercuit de armate, atunci să știți că pustiirea lui este aproape.
“Nígbà tí ẹ̀yin bá sì rí ti a fi ogun yí Jerusalẹmu ká, ẹ mọ̀ nígbà náà pé, ìsọdahoro rẹ̀ kù sí dẹ̀dẹ̀.
21 Atunci, cei din Iudeea să fugă în munți; și cei din mijlocul lui să plece afară; și cei de pe câmpuri să nu intre în el.
Nígbà náà ni kí àwọn tí ń bẹ ní Judea sálọ sórí òkè; àti àwọn tí ń bẹ láàrín rẹ̀ kí wọn jáde kúrò; kí àwọn tí ó sì ń bọ̀ ní ìgbèríko má ṣe wọ inú rẹ̀ wá.
22 Căci acelea vor fi zilele răzbunării, pentru a fi împlinite toate cele scrise.
Nítorí ọjọ́ ẹ̀san ni ọjọ́ wọ̀nyí, kì a lè mú ohun gbogbo tí a ti kọ̀wé rẹ̀ ṣẹ.
23 Dar vai celor însărcinate și celor ce alăptează în acele zile! Fiindcă va fi o mare strâmtorare în țară și furie peste acest popor.
Ṣùgbọ́n ègbé ni fún àwọn tí ó lóyún, àti àwọn tí ó fi ọyàn fún ọmọ mu ní ọjọ́ wọ̀nyí! Nítorí tí ìpọ́njú púpọ̀ yóò wà lórí ilẹ̀ àti ìbínú sí àwọn ènìyàn wọ̀nyí.
24 Și vor cădea sub tăișul sabiei și vor fi duși captivi printre toate națiunile; și Ierusalimul va fi călcat în picioare de neamuri, până se vor împlini timpurile neamurilor.
Wọn ó sì ti ojú idà ṣubú, a ó sì dìwọ́n ní ìgbèkùn lọ sí orílẹ̀-èdè gbogbo; Jerusalẹmu yóò sì di ìtẹ̀mọ́lẹ̀ lẹ́sẹ̀ àwọn aláìkọlà, títí àkókò àwọn aláìkọlà yóò fi kún.
25 Și vor fi semne în soare și în lună și în stele; și pe pământ chinul națiunilor, cu nedumerire; marea și valurile urlând;
“Àmì yóò sì wà ní oorun, àti ní òṣùpá, àti ní ìràwọ̀; àti lórí ilẹ̀ ayé ìdààmú fún àwọn orílẹ̀-èdè nínú ìpayà híhó Òkun àti ìgbì omi.
26 Inima oamenilor lăsându-i de frică și de anticiparea acelor lucruri ce vin pe pământ; fiindcă puterile cerurilor vor fi clătinate.
Àyà àwọn ènìyàn yóò máa já fún ìbẹ̀rù, àti ìrètí nǹkan wọ̀nyí tí ń bọ̀ sórí ayé: nítorí àwọn agbára ọ̀run ni a ó mì tìtì.
27 Și atunci vor vedea pe Fiul omului venind într-un nor cu putere și glorie mare.
Nígbà náà ni wọn ó sì rí Ọmọ Ènìyàn tí yóò máa bọ̀ wá nínú àwọsánmọ̀ pẹ̀lú agbára àti ògo ńlá.
28 Iar când acestea vor începe să se întâmple, atunci uitați-vă în sus și ridicați-vă capetele, pentru că răscumpărarea voastră se apropie.
Ṣùgbọ́n nígbà tí nǹkan wọ̀nyí bá bẹ̀rẹ̀ sí í ṣẹ, ǹjẹ́ kí ẹ wo òkè, kí ẹ sì gbé orí yín sókè; nítorí ìdáǹdè yín kù sí dẹ̀dẹ̀.”
29 Și le-a spus o parabolă: Priviți smochinul și toți copacii.
Ó sì pa òwe kan fún wọn pé, “Ẹ kíyèsi igi ọ̀pọ̀tọ́, àti sí gbogbo igi.
30 Când deja înfrunzesc, vedeți și știți de la voi înșivă că de acum vara este aproape.
Nígbà tí wọ́n bá rúwé, ẹ̀yin rí i, ẹ sì mọ̀ fúnra ara yín pé, ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn kù fẹ́ẹ́rẹ́.
31 Tot așa și voi, când vedeți acestea întâmplându-se, să știți că împărăția lui Dumnezeu este aproape.
Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ náà ni ẹ̀yin, nígbà tí ẹ̀yin bá rí nǹkan wọ̀nyí tí o ṣẹ, kí ẹ̀yin mọ̀ pé, ìjọba Ọlọ́run kù sí dẹ̀dẹ̀.
32 Adevărat vă spun: Această generație nu va trece până se vor împlini toate.
“Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ìran yìí kì yóò rékọjá, títí gbogbo nǹkan wọ̀nyí yóò fi ṣẹ.
33 Cerul și pământul vor trece; dar cuvintele mele nicidecum nu vor trece.
Ọ̀run àti ayé yóò rékọjá, ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ mi kì yóò rékọjá.
34 Și luați seama la voi înșivă, ca nu cumva să vi se îngreuneze inimile cu depravare și beție și cu îngrijorările acestei vieți și acea zi să vină peste voi pe neașteptate.
“Ṣùgbọ́n ẹ máa kíyèsára yín, kí ọkàn yín má ṣe kún fún wọ̀bìà, àti fún ọtí àmupara, àti fún àníyàn ayé yìí, tí ọjọ́ náà yóò sì fi dé bá yín lójijì bí ìkẹ́kùn.
35 Căci va veni ca o cursă peste toți cei ce locuiesc pe fața întregului pământ.
Nítorí bẹ́ẹ̀ ni yóò dé bá gbogbo àwọn tí ń gbé orí gbogbo ilẹ̀ ayé.
36 De aceea vegheați și rugați-vă tot timpul, ca să fiți socotiți demni să scăpați de toate acestea ce se vor întâmpla și să stați în picioare înaintea Fiului omului.
Ǹjẹ́ kì ẹ máa ṣọ́nà, kí ẹ sì máa gbàdúrà nígbà gbogbo, kí ẹ ba à lè la gbogbo nǹkan wọ̀nyí tí yóò ṣẹlẹ̀, kí ẹ sì lè dúró níwájú Ọmọ Ènìyàn.”
37 Iar în timpul zilei era în templu, învățându-i; iar noaptea ieșea și o petrecea pe muntele care se cheamă al Măslinilor.
Lọ́sàn án, Jesu a sì máa kọ́ni ní tẹmpili, lóru, a sì máa jáde lọ í wọ̀ ní òkè tí à ń pè ní Òkè Olifi.
38 Și tot poporul venea devreme dimineața la el, în templu, ca să îl audă.
Gbogbo ènìyàn sì ń tọ̀ ọ́ wá ní tẹmpili ní kùtùkùtù òwúrọ̀, láti gbọ́rọ̀ rẹ̀.