< Luca 16 >

1 Și le-a spus și discipolilor săi: Era un anumit om bogat, care avea un administrator; și acesta a fost acuzat înaintea lui că i-a risipit averile.
Ó sì wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pẹ̀lú pé, “Ọkùnrin ọlọ́rọ̀ kan wà, tí ó ní ìríjú kan; òun náà ni wọ́n fi sùn ún pé, ó ti ń fi ohun ìní rẹ̀ ṣòfò.
2 Și l-a chemat și i-a spus: Cum de aud aceasta despre tine? Dă socoteală de administrarea ta, fiindcă nu mai poți fi administrator.
Nígbà tí ó sì pè é, ó wí fún un pé, ‘Èéṣe tí èmi fi ń gbọ́ èyí sí ọ? Ṣírò iṣẹ́ ìríjú rẹ; nítorí ìwọ kò lè ṣe ìríjú mi mọ́.’
3 Atunci administratorul a spus în el însuși: Ce să fac? Pentru că domnul meu ia administrația de la mine; nu sunt în stare să sap; să cerșesc îmi este rușine.
“Ìríjú náà sì wí nínú ara rẹ̀ pé, ‘Èwo ni èmi ó ṣe? Nítorí tí olúwa mi gba iṣẹ́ ìríjú lọ́wọ́ mi: èmi kò le ṣiṣẹ́ oko, bẹ́ẹ̀ ni ojú ń tì mí láti ṣagbe.
4 Am hotărât ce să fac, pentru ca, atunci când voi fi scos din administrație, să mă primească în casele lor.
Mo mọ èyí tí èmi yóò ṣe, nígbà tí a bá mú mi kúrò níbi iṣẹ́ ìríjú, kí àwọn ènìyàn le gbà mí sínú ilé wọn.’
5 Și a chemat pe fiecare dintre datornicii domnului său și a spus primului: Cât datorezi domnului meu?
“Ó sì pe àwọn ajigbèsè olúwa rẹ̀ sọ́dọ̀ rẹ̀, ó sì wí fún èkínní pé, ‘Èló ni ìwọ jẹ olúwa mi?’
6 Iar el a spus: O sută de bați de untdelemn. Iar el i-a spus: Ia înscrisul tău și șezi degrabă și scrie cincizeci.
“Ó sì wí pé, ‘Ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rún òsùwọ̀n òróró.’ “Ó sì wí fún un pé, ‘Mú ìwé rẹ, sì jókòó nísinsin yìí, kí o sì kọ àádọ́ta lé ní irinwó.’
7 Apoi a spus altuia: Dar tu, cât datorezi? Iar el a spus: O sută de cori de grâu. Iar el i-a spus: Ia înscrisul tău și scrie optzeci.
“Nígbà náà ni ó sì bi ẹnìkejì pé, ‘Èló ni ìwọ jẹ?’ “Òun sì wí pé, ‘Ẹgbẹ̀rún òsùwọ̀n alikama.’ “Ó sì wí fún un pé, ‘Mú ìwé rẹ, kí o sì kọ ẹgbẹ̀rin.’
8 Și domnul a lăudat pe administratorul nedrept, pentru că lucrase cu înțelepciune, pentru că în generația lor copiii acestei lumi sunt mai înțelepți decât fiii luminii. (aiōn g165)
“Olúwa rẹ̀ sì yin aláìṣòótọ́ ìríjú náà, nítorí tí ó fi ọgbọ́n ṣe é, àwọn ọmọ ayé yìí sá à gbọ́n ní ìran wọn ju àwọn ọmọ ìmọ́lẹ̀ lọ. (aiōn g165)
9 Și eu vă spun: Faceți-vă prieteni din mamona nedreptății; pentru ca, atunci când eșuați, ei să vă primească în locuințe veșnice. (aiōnios g166)
Èmi sì wí fún yín, ẹ fi ọrọ̀ ayé yìí yan ọ̀rẹ́ fún ara yín pé, nígbà tí o ba lọ, kí wọn kí ó le gbà yín sí ibùjókòó wọn títí ayé. (aiōnios g166)
10 Cel ce este credincios în puțin, este credincios și în mult; și cel ce este nedrept în puțin, este nedrept și în mult.
“Ẹni tí ó bá ṣe olóòtítọ́ nínú ohun kínkínní, ó ṣe olóòtítọ́ ní púpọ̀ pẹ̀lú: ẹni tí ó bá sì ṣe aláìṣòótọ́ ní ohun kínkínní, ó ṣe aláìṣòótọ́ ní ohun púpọ̀ pẹ̀lú.
11 De aceea dacă nu ați fost credincioși în nedreapta mamonă, cine va încredința adevăratele bogății încrederii voastre?
Ǹjẹ́ bí ẹ̀yin kò bá ti jẹ́ olóòtítọ́ nínú ọrọ̀ ayé yìí, ta ni yóò fi ọ̀rọ̀ tòótọ́ fún yín?
12 Și dacă nu ați fost credincioși în ceea ce este al altuia, cine vă va da ceea ce este al vostru?
Bí ẹ̀yin kò bá sì ti jẹ́ olóòtítọ́ nínú ohun tí í ṣe ti ẹlòmíràn, ta ni yóò fún yín ní ohun tí í ṣe ti ẹ̀yin tìkára yín?
13 Niciun servitor nu poate servi la doi stăpâni; fiindcă, ori pe unul îl va urî și pe celălalt îl va iubi; ori la unul va ține și pe celălalt îl va disprețui. Nu puteți servi lui Dumnezeu și lui mamona.
“Kò sì í ẹnìkan tí ó lè sin ọ̀gá méjì. Òun yóò yà kórìíra ọ̀kan tí yóò fẹ́ràn èkejì, tàbí kí ó fi ara mọ́ ọ̀kan kí ó sì yan èkejì ní ìpọ̀sí. Ẹ̀yin kò lè sin Ọlọ́run àti owó papọ̀.”
14 Și fariseii de asemenea, fiind lacomi, au auzit toate acestea și l-au luat în derâdere.
Àwọn Farisi, tí wọ́n ní ojúkòkòrò sì gbọ́ gbogbo nǹkan wọ̀nyí, wọ́n sì yọ ṣùtì sí i.
15 Dar el le-a spus: Voi sunteți cei care vă declarați drepți pe voi înșivă înaintea oamenilor; dar Dumnezeu vă cunoaște inimile, pentru că ce este înălțat între oameni este urâciune înaintea lui Dumnezeu.
Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ni àwọn tí ń dá àre fún ara yín níwájú ènìyàn; ṣùgbọ́n Ọlọ́run mọ ọkàn yín, nítorí ohun ti a gbéga lójú ènìyàn, ìríra ni níwájú Ọlọ́run.
16 Legea și profeții au ținut până la Ioan; de atunci, împărăția lui Dumnezeu se predică și fiecare se înghesuie să intre în ea.
“Òfin àti àwọn wòlíì ń bẹ títí di ìgbà Johanu, Láti ìgbà náà wá ni a ti ń wàásù ìròyìn ayọ̀ ìjọba Ọlọ́run, olúkúlùkù sì ń fi ipá wọ inú rẹ̀.
17 Dar este mai ușor pentru cer și pământ să treacă, decât să cadă o frântură de literă a legii.
Ṣùgbọ́n ó rọrùn fún ọ̀run òun ayé láti kọjá lọ, ju kí èyí tí ó kéré jù nínú òfin kí ó yẹ.
18 Oricine divorțează de soția lui și se căsătorește cu alta, comite adulter; și oricine se căsătorește cu cea care este divorțată de soț, comite adulter.
“Ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ aya rẹ̀ sílẹ̀, tí ó sì gbé ẹlòmíràn ní ìyàwó, ó ṣe panṣágà: ẹnikẹ́ni tí ó bá sì gbé, ẹni tí ọkọ rẹ̀ kọ̀sílẹ̀ ní ìyàwó náà, ó ṣe panṣágà.
19 Și era un anumit om bogat, care era îmbrăcat în purpură și in subțire și se veselea somptuos în fiecare zi;
“Ǹjẹ́ ọkùnrin ọlọ́rọ̀ kan wà, tí ó ń wọ aṣọ elése àlùkò àti aṣọ àlà dáradára, a sì máa jẹ dídùndídùn lójoojúmọ́.
20 Și era un anumit cerșetor, numit Lazăr, care era pus la poarta lui, plin de răni,
Alágbe kan sì wà tí à ń pè ní Lasaru, tí wọ́n máa ń gbé wá kalẹ̀ lẹ́bàá ọ̀nà ilé rẹ̀, ó kún fún ooju,
21 Și dorind să se sature cu firimiturile care cădeau de la masa bogatului; mai mult și câinii veneau și îi lingeau rănile.
Òun a sì máa fẹ́ kí a fi èérún tí ó ti orí tábìlì ọlọ́rọ̀ bọ́ sílẹ̀ bọ́ òun, àwọn ajá sì wá, wọ́n sì fá a ní ooju lá.
22 Și s-a întâmplat că cerșetorul a murit și a fost dus de îngeri în sânul lui Avraam; și bogatul a murit de asemenea și a fost îngropat;
“Ó sì ṣe, alágbe kú, a sì ti ọwọ́ àwọn angẹli gbé e lọ sí oókan àyà Abrahamu: ọlọ́rọ̀ náà sì kú pẹ̀lú, a sì sin ín;
23 Și în iad își ridică ochii, fiind în chinuri; și vede pe Avraam de departe și pe Lazăr în sânul lui. (Hadēs g86)
Ní ipò òkú ni ó gbé ojú rẹ̀ sókè, ó ń bẹ nínú ìjìyà oró, ó sì rí Abrahamu ní òkèrè, àti Lasaru ní oókan àyà rẹ̀. (Hadēs g86)
24 Și a strigat și a spus: Tată Avraame, ai milă de mine și trimite pe Lazăr ca să își înmoaie vârful degetului în apă și să îmi răcorească limba, pentru că sunt chinuit în această flacără.
Ó sì ké, ó wí pé, ‘Baba Abrahamu, ṣàánú fún mi, kí o sì rán Lasaru, kí ó tẹ orí ìka rẹ̀ bọ omi, kí ó sì fi tù mí ní ahọ́n; nítorí èmi ń joró nínú ọ̀wọ́n iná yìí.’
25 Dar Avraam i-a spus: Fiule, amintește-ți că tu în timpul vieții tale, ai primit lucrurile tale bune și tot așa, Lazăr pe cele rele; dar acum este mângâiat, iar tu ești chinuit.
“Ṣùgbọ́n Abrahamu wí pé, ‘Ọmọ, rántí pé, nígbà ayé rẹ, ìwọ ti gba ohun rere tìrẹ, àti Lasaru ohun búburú, ṣùgbọ́n nísinsin yìí ara rọ̀ ọ́, ìwọ sì ń joró.
26 Și pe lângă toate acestea, între noi și voi este stabilită o prăpastie mare; așa că cei ce voiesc să treacă de aici la voi, nu pot; nici cei de acolo să treacă la noi.
Àti pẹ̀lú gbogbo èyí, a gbé ọ̀gbun ńlá kan sí agbede-méjì àwa àti ẹ̀yin, kí àwọn tí ń fẹ́ má ba á le rékọjá láti ìhín lọ sọ́dọ̀ yín, kí ẹnikẹ́ni má sì le ti ọ̀hún rékọjá tọ̀ wá wá.’
27 Atunci a spus: De aceea te rog tată, să îl trimiți la casa tatălui meu;
“Ó sì wí pé, ‘Ǹjẹ́ mo bẹ̀ ọ́, baba, kí ìwọ kí ó rán Lasaru lọ sí ilé baba mi,
28 Fiindcă am cinci frați; ca el să le adeverească, pentru ca nu cumva să vină și ei în acest loc de chin.
nítorí mo ní arákùnrin márùn-ún; kí ó lè rò fún wọn kí àwọn kí ó má ba á wá sí ibi oró yìí pẹ̀lú.’
29 Avraam i-a spus: Au pe Moise și pe profeți; să îi asculte pe ei.
“Abrahamu sì wí fún un pé, ‘Wọ́n ní Mose àti àwọn wòlíì; kí wọn kí ó gbọ́ tiwọn.’
30 Dar el a spus: Nu, tată Avraame; ci, dacă cineva dintre morți se va duce la ei, se vor pocăi.
“Ó sì wí pé, ‘Bẹ́ẹ̀ kọ́, Abrahamu baba; ṣùgbọ́n bí ẹnìkan bá ti inú òkú tọ̀ wọ́n lọ, wọn ó ronúpìwàdà.’
31 Iar el i-a spus: Dacă nu ascultă pe Moise și pe profeți, nu vor fi convinși nici chiar dacă ar învia cineva dintre morți.
“Ó sì wí fún un pé, ‘Bí wọn kò bá gbọ́ ti Mose àti ti àwọn wòlíì, a kì yóò yí wọn ní ọkàn padà bí ẹnìkan tilẹ̀ ti inú òkú dìde.’”

< Luca 16 >