< Judecătorii 9 >

1 Și Abimelec, fiul lui Ierubaal, a mers la Sihem, la frații mamei sale, și a vorbit îndeaproape cu ei și cu toată familia casei tatălui mamei sale, spunând:
Ní ọjọ́ kan Abimeleki ọmọ Jerubbaali lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin ìyá rẹ̀ ní Ṣekemu ó sì bá wọn sọ̀rọ̀ àti gbogbo àwọn ìbátan ìyá rẹ̀ wí pé,
2 Vorbiți, vă rog, în auzul tuturor bărbaților din Sihem: Ce este mai bine pentru voi: să stăpânească peste voi toți fiii lui Ierubaal care sunt șaptezeci de persoane, sau să stăpânească peste voi unul singur? Amintiți-vă de asemenea că eu sunt osul vostru și carnea voastră.
“Ẹ bi gbogbo àwọn ará Ṣekemu léèrè, ‘Èwo ló sàn fún un yín, ṣé kí gbogbo àwọn àádọ́rin ọmọ Jerubbaali jẹ ọba lórí yín ni tàbí kí ẹnìkan ṣoṣo ṣe àkóso yín?’ Ṣùgbọ́n ẹ rántí pé ẹran-ara yín àti ẹ̀jẹ̀ yín ni èmi ń ṣe.”
3 Și frații mamei sale au vorbit toate aceste cuvinte despre el, în urechile tuturor bărbaților din Sihem; și inima lor s-a plecat spre a-l urma pe Abimelec, pentru că au spus: El este fratele nostru.
Nígbà tí àwọn arákùnrin rẹ̀ sọ èyí ní etí àwọn ará Ṣekemu, ọkàn wọn fà sí àti tẹ̀lé Abimeleki torí, wọ́n sọ wí pé, “Arákùnrin wa ní í ṣe.”
4 Și i-au dat șaptezeci de arginți din casa lui Baal-Berit, cu care Abimelec a angajat persoane fără căpătâi și ușuratice, care l-au urmat.
Wọ́n fún un ní àádọ́rin ṣékélì fàdákà láti ilé òrìṣà Baali-Beriti, Abimeleki fi owó náà gba àwọn jàǹdùkú àti aláìníláárí ènìyàn tí wọ́n sì di olùtẹ̀lé rẹ̀.
5 Și a mers la casa tatălui său, la Ofra, și a ucis, pe o singură piatră, pe frații săi, pe fiii lui Ierubaal, șaptezeci de oameni; și a rămas numai Iotam, cel mai tânăr fiu al lui Ierubaal, pentru că s-a ascuns.
Ó kó wọn lọ sí ilé baba rẹ̀ ní Ofira, níbẹ̀ ní orí òkúta kan ṣoṣo ni ó ti pa àádọ́rin nínú àwọn arákùnrin rẹ̀, àwọn Jerubbaali, ṣùgbọ́n Jotamu, àbíkẹ́yìn nínú àwọn ọmọ Jerubbaali, bọ́ yọ nítorí pé ó sá pamọ́.
6 Și toți bărbații din Sihem și toată casa lui Milo s-au adunat și au mers și l-au făcut împărat pe Abimelec la câmpia stâlpului care era în Sihem.
Gbogbo àwọn ará Ṣekemu àti àwọn ará Beti-Milo pàdé pọ̀ ní ẹ̀bá igi óákù ní ibi òpó ní Ṣekemu láti fi Abimeleki jẹ ọba.
7 Și când i-au spus lui Iotam, el a mers și a stat pe vârful muntelui Garizim și și-a înălțat vocea și a strigat și le-a spus: Dați-mi ascultare, voi bărbați din Sihem, ca și Dumnezeu să vă dea ascultare.
Nígbà tí wọ́n sọ ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀ yìí fún Jotamu, ó gun orí ṣóńṣó òkè Gerisimu lọ, ó sì ké lóhùn rara pé, “Ẹ tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin àgbàgbà Ṣekemu, kí Ọlọ́run le tẹ́tí sí yín.
8 Copacii au mers odată să ungă un împărat peste ei; și au spus măslinului: Domnește peste noi.
Ní ọjọ́ kan àwọn igi jáde lọ láti fi òróró yan ọba fún ara wọn. Wọ́n pe igi Olifi pé, ‘Wá ṣe ọba wa.’
9 Dar măslinul le-a spus: Să îmi las eu grăsimea mea, cu care, prin mine, ei onorează pe Dumnezeu și pe om și să mă duc să fiu înălțat peste copaci?
“Ṣùgbọ́n igi Olifi dá wọn lóhùn pé, ‘Èmi yóò ha fi òróró mi sílẹ̀ èyí tí a ń lò láti fi ọ̀wọ̀ fún àwọn ọlọ́run àti ènìyàn kí èmi sì wá ṣe olórí àwọn igi?’
10 Și copacii au spus smochinului: Vino tu și domnește peste noi.
“Àwọn igi sọ fún igi ọ̀pọ̀tọ́ pé, ‘Wá jẹ ọba ní orí wa.’
11 Dar smochinul le-a spus: Să îmi las eu dulceața mea și rodul meu bun și să mă duc să fiu înălțat peste copaci?
“Ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀tọ́ dá wọn lóhùn pé, ‘Kí èmi fi èso mi tí ó dára tí ó sì dùn sílẹ̀ láti wá ṣe olórí àwọn igi?’
12 Atunci copacii au spus viței: Vino tu și domnește peste noi.
“Àwọn igi sì tún sọ fún àjàrà pé, ‘Wá, kí o ṣe ọba wa.’
13 Și vița le-a spus: Să îmi las eu vinul meu, care înveselește pe Dumnezeu și pe om și să mă duc să fiu înălțată peste copaci?
“Ṣùgbọ́n àjàrà dáhùn pé, ‘Ṣé kí èmi dẹ́kun àti máa so èso wáìnì mi èyí tí ó ń mú inú Ọlọ́run àti àwọn ènìyàn dùn láti máa ṣe olórí àwọn igi?’
14 Atunci toți copacii au spus tufei de spini: Vino tu și domnește peste noi.
“Ní ìparí gbogbo àwọn igi lọ bá igi ẹ̀gún wọ́n sì sọ fún un pé, ‘Wá kí ó ṣe ọba wa.’
15 Iar tufa de spini a spus copacilor: Dacă într-adevăr mă ungeți împărat peste voi, veniți, puneți-vă încrederea în umbra mea, și dacă nu, să iasă foc din tufa de spini și să mistuie cedrii Libanului.
“Igi ẹ̀gún dá àwọn igi lóhùn pé, ‘Bí olóòtítọ́ ni ẹ bá fẹ́ yàn mí ní ọba yín. Ẹ sá àsálà sí abẹ́ ibòòji mi; ṣùgbọ́n tí kì í bá ṣe bẹ́ẹ̀ jẹ́ kí iná jáde láti inú igi ẹ̀gún kí ó sì jó àwọn igi kedari àti ti Lebanoni run!’
16 Și acum, dacă ați făcut aceasta cu adevăr și în sinceritate, în aceea că ați făcut împărat pe Abimelec și dacă v-ați purtat bine cu Ierubaal și cu casa lui și i-ați făcut conform meritului mâinilor lui;
“Báyìí tí ó bá jẹ́ pé ẹ̀yin ṣe ohun tí ó ní ọlá àti pẹ̀lú ẹ̀mí òtítọ́ ní fífi Abimeleki jẹ ọba, tí ó bá ṣe pé ohun tí ó tọ́ ni ẹ ṣe sí Jerubbaali àti ìdílé rẹ̀, bí ẹ bá san ẹ̀san tó yẹ fún un.
17 (Pentru că tatăl meu a luptat pentru voi și și-a primejduit mult viața și v-a eliberat din mâna lui Madian;
Nítorí pé baba mi jà nítorí yín, ó fi ẹ̀mí rẹ̀ wéwu láti gbà yín sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ará Midiani;
18 Iar voi v-ați ridicat astăzi împotriva casei tatălui meu și ați ucis pe fiii săi, șaptezeci de oameni, pe o singură piatră, și ați făcut pe Abimelec, fiul servitoarei sale, împărat peste bărbații din Sihem, pentru că el este fratele vostru);
ṣùgbọ́n lónìí ẹ̀yin ṣọ̀tẹ̀ sí ilé baba mi, ní orí òkúta kan ṣoṣo ni ẹ ti pa àwọn àádọ́rin ọmọ rẹ̀, ẹ̀yin sì ti fi Abimeleki ọmọ ẹrúbìnrin rẹ̀ jẹ ọba lórí àwọn ènìyàn Ṣekemu nítorí tí ó jẹ́ arákùnrin yín.
19 Dacă așadar ați lucrat cu adevăr și în sinceritate cu Ierubaal și cu casa lui în această zi, atunci bucurați-vă în Abimelec și să se bucure și el în voi;
Bí ohun tí ẹ ṣe sí Jerubbaali àti ìdílé rẹ̀ bá jẹ́ ohun tí ó yẹ, tí ẹ sì ṣe òtítọ́ inú sí i, kí ẹ ní ayọ̀ nínú Abimeleki kí òun náà sì ní ayọ̀ nínú yín.
20 Dar dacă nu, să iasă foc din Abimelec și să mistuie pe bărbații din Sihem și casa lui Bet-Milo; și să iasă foc din bărbații din Sihem și din casa lui Bet-Milo și să mistuie pe Abimelec.
Ṣùgbọ́n tí kò bá ṣe bẹ́ẹ̀ jẹ́ kí iná jó jáde wá láti ọ̀dọ̀ Abimeleki kí ó sì jó yín run. Ẹ̀yin ará Ṣekemu àti ará Beti-Milo, kí iná pẹ̀lú jáde láti ọ̀dọ̀ yín wá ẹ̀yin ará Ṣekemu àti ará Beti-Milo kí ó sì jó Abimeleki run.”
21 Și Iotam a alergat și a fugit și a mers la Beer și a locuit acolo de frica lui Abimelec, fratele său.
Lẹ́yìn tí Jotamu ti sọ èyí tan, ó sá àsálà lọ sí Beeri, ó sì gbé níbẹ̀ nítorí ó bẹ̀rù arákùnrin rẹ̀ Abimeleki.
22 După ce Abimelec a domnit peste Israel trei ani,
Lẹ́yìn tí Abimeleki ti ṣe àkóso Israẹli fún ọdún mẹ́ta,
23 Dumnezeu a trimis un duh rău între Abimelec și bărbații din Sihem; și bărbații din Sihem s-au purtat cu perfidie cu Abimelec;
Ọlọ́run rán ẹ̀mí búburú sáàárín Abimeleki àti àwọn ará Ṣekemu, àwọn ẹni tí ó hu ìwà ọ̀tẹ̀.
24 Pentru ca violența, făcută celor șaptezeci de fii ai lui Ierubaal și sângele lor, să vină asupra lui Abimelec, fratele lor, care i-a ucis, și asupra bărbaților din Sihem, care l-au ajutat în uciderea fraților săi.
Ọlọ́run ṣe èyí láti gbẹ̀san àwọn ìwà búburú, àti ìtàjẹ̀ sílẹ̀ àwọn àádọ́rin ọmọ Jerubbaali lára Abimeleki arákùnrin wọn àti lára àwọn ènìyàn Ṣekemu, ẹni tí ó ràn án lọ́wọ́ láti pa àwọn arákùnrin rẹ̀.
25 Și bărbații din Sihem au pus pânditori pentru el pe vârfurile munților și au jefuit pe toți cei care treceau pe acea cale pe lângă ei; și i s-a spus lui Abimelec.
Nítorí ìkórìíra tí wọ́n ni sí àwọn olórí, ni Ṣekemu dẹ àwọn ènìyàn sí àwọn orí òkè láti máa dá àwọn ènìyàn tó ń kọjá lọ́nà, kí wọn sì máa jà wọ́n lólè, àwọn kan ló sọ èyí fún Abimeleki.
26 Și Gaal, fiul lui Ebed, a venit cu frații săi și au trecut la Sihem, și bărbații din Sihem și-au pus încrederea în el.
Gaali ọmọ Ebedi àti àwọn arákùnrin rẹ̀ wá sí Ṣekemu, àwọn ará Ṣekemu sì gbẹ́kẹ̀lé wọn, wọ́n sì fi inú tán wọn.
27 Și au ieșit în câmpuri și le-au cules viile și au călcat strugurii și s-au veselit și au intrat în casa dumnezeului lor și au mâncat și au băut și au blestemat pe Abimelec.
Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jáde lọ sí oko, wọ́n sì ṣa èso àjàrà wọn jọ, wọ́n fún èso àjàrà náà, wọ́n sì ṣe àjọ̀dún nínú ilé òrìṣà wọn. Nígbà tí wọ́n ń jẹ tí wọ́n ń mu wọ́n fi Abimeleki ré.
28 Și Gaal, fiul lui Ebed, a spus: Cine este Abimelec și cine este Sihem, ca să îi servim? Nu este el fiul lui Ierubaal? Și Zebul, căpetenia sa? Serviți bărbaților lui Hamor, tatăl lui Sihem; pentru ce să îi servim lui?
Gaali ọmọ Ebedi dáhùn pé, “Ta ni Abimeleki tàbí ta ni Ṣekemu tí àwa ó fi sìn ín? Ọmọ Jerubbaali kọ́ ní ṣe tàbí Sebulu kọ́ ní igbákejì rẹ̀? Ẹ má sin àwọn ará Hamori baba àwọn ará Ṣekemu, èéṣe tí a ó fi sin Abimeleki?
29 De ar fi acest popor în mâna mea! Atunci aș îndepărta pe Abimelec. Și el i-a spus lui Abimelec: Înmulțește-ți armata și ieși afară.
Ìbá se pé àwọn ènìyàn yìí wà ní abẹ́ ìṣàkóso mi ni! Èmi ìbá bọ́ àjàgà rẹ̀ kúrò ní ọrùn yín. Èmi yóò wí fún Abimeleki pé, ‘Kó gbogbo àwọn ogun rẹ jáde láti jà.’”
30 Și după ce Zebul, conducătorul cetății, a auzit cuvintele lui Gaal, fiul lui Ebed, mânia lui s-a aprins.
Nígbà tí Sebulu, alákòóso ìlú náà gbọ́ ohun tí Gaali ọmọ Ebedi sọ, inú bí i gidigidi.
31 Și a trimis mesageri la Abimelec pe ascuns, spunând: Iată, Gaal, fiul lui Ebed, și frații săi au venit la Sihem; și, iată, ei întăresc cetatea împotriva ta.
Ó ránṣẹ́ sí Abimeleki pé, “Gaali ọmọ Ebedi àti àwọn arákùnrin rẹ̀ wá láti máa gbé ní Ṣekemu ṣùgbọ́n, wọ́n ń rú àwọn ènìyàn sókè láti ṣọ̀tẹ̀ sí ọ.
32 Acum de aceea ridică-te noaptea, tu și poporul care este cu tine și stai la pândă în câmp;
Wá ní òru kí ìwọ àti àwọn ogun rẹ sá pamọ́ dè wọ́n nínú igbó.
33 Și va fi astfel: dimineața, imediat ce soarele a răsărit, să te scoli devreme și să te așezi asupra cetății; și, iată, el și poporul care este cu el, vor ieși împotriva ta, atunci le vei face după cum vei găsi de cuviință.
Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù bí oòrùn ti ń yọ ìwọ yóò wọ inú ìlú náà lọ láti bá a jà. Yóò sì ṣe nígbà tí Gaali àti àwọn ogun rẹ̀ tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ bá jáde sí ọ láti bá ọ jà, ìwọ yóò ṣe ohunkóhun tí o bá fẹ́ sí wọn.”
34 Și Abimelec s-a ridicat noaptea, el și tot poporul care era cu el, și s-au așezat la pândă împotriva Sihemului în patru cete.
Abimeleki àti gbogbo àwọn ogun rẹ̀ sì jáde ní òru, wọ́n sì sá pamọ́ sí ọ̀nà mẹ́rin yí Ṣekemu ká.
35 Și Gaal, fiul lui Ebed, a ieșit și a stat la intrarea porții cetății; iar Abimelec s-a ridicat, el și poporul care era cu el, de la pândă.
Gaali ọmọ Ebedi jáde síta, ó sì dúró ní ẹnu-ọ̀nà ibodè ìlú náà ní àkókò tí Abimeleki àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ jáde kúrò níbi tí wọn sá pamọ́ sí.
36 Și când Gaal a văzut poporul, i-a spus lui Zebul: Iată, coboară oameni din vârfurile munților. Și Zebul i-a spus: Tu vezi umbra munților de parcă ar fi oameni.
Nígbà tí Gaali rí àwọn ènìyàn náà, ó sọ fún Sebulu pé, “Wò ó, àwọn ènìyàn ń ti orí òkè sọ̀kalẹ̀ wá!” Sebulu sì wí fún un pé, “Òjìji òkè wọ̀n-ọn-nì ni ìwọ rí bi ẹni pé ènìyàn.”
37 Și Gaal a vorbit din nou și a spus: Vezi acolo, coboară oameni prin mijlocul țării și o altă ceată vine pe la câmpia lui Monenim.
Gaali ké ó ní, “Wòkè, àwọn ènìyàn ń tọ̀ wá bọ̀ láti agbede-méjì ilẹ̀ wá àti ẹ̀gbẹ́ kan sì ń ti ọ̀nà igi óákù Meonenimu wá.”
38 Atunci Zebul i-a spus: Unde este acum gura ta, cu care ai zis: Cine este Abimelec, de ar trebui să îi servim? Nu este acesta poporul pe care l-ai disprețuit? Ieși acum, te rog, și luptă cu ei.
Nígbà náà ni Sebulu dá a lóhùn pé, “Níbo ni ẹnu tí ó ń ṣe ni wà báyìí. Ṣe bí o wí pé, ‘Ta ni Abimeleki tí àwa ó fi máa sìn ín?’ Àwọn ẹni tí ó gàn án kọ́ nìyí? Jáde lọ kí o sì bá wọn jà!”
39 Și Gaal a ieșit înaintea bărbaților din Sihem și a luptat cu Abimelec.
Gaali sì síwájú àwọn ogun ará Ṣekemu lọ kọjú Abimeleki láti bá wọn jagun.
40 Și Abimelec l-a urmărit și el a fugit dinaintea lui și mulți au fost doborâți și răniți, până la intrarea porții.
Abimeleki sì lé e, ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọmọ-ogun ṣubú wọ́n sì gbọgbẹ́ bí wọ́n ṣe ń sálọ, títí dé ẹnu-ọ̀nà ibùdó ìlú náà.
41 Și Abimelec a locuit în Aruma; și Zebul a alungat pe Gaal și pe frații săi, ca să nu locuiască în Sihem.
Abimeleki dúró sí Aruma, nígbà tí Sebulu lé Gaali àti àwọn arákùnrin rẹ̀ kúrò ni Ṣekemu, kò sì jẹ́ kí wọ́n gbé Ṣekemu mọ́.
42 Și a doua zi s-a întâmplat, că poporul a ieșit la câmp; și i-au spus lui Abimelec.
Ní ọjọ́ kejì àwọn ará Ṣekemu sì jà lọ́ sí oko, ẹnìkan ló ṣe òfófó rẹ̀ fún Abimeleki.
43 Și el a luat poporul și i-a împărțit în trei cete și s-a așezat la pândă în câmp și s-a uitat și, iată, poporul era ieșit din cetate; și s-a ridicat împotriva lor și i-a lovit.
Ó kó àwọn ènìyàn rẹ̀, ó pín wọn sí ẹgbẹ́ mẹ́ta ó sì sá pamọ́ sí inú oko. Nígbà tí ó sì rí tí àwọn ènìyàn náà ń jáde kúrò nínú ìlú, ó dìde ó gbóguntì wọ́n.
44 Și Abimelec și ceata care era cu el s-au năpustit înainte și au stat la intrarea porții cetății, și celelalte două cete au alergat asupra tuturor celor care erau în câmpuri și i-au ucis.
Abimeleki àti àwọn ọmọ-ogun tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ sáré síwájú, wọ́n gba ẹnu ibodè ìlú náà, wọ́n sì dúró níbẹ̀. Àwọn ẹgbẹ́ méjì tókù sì sáré sí àwọn tó wà ní oko wọ́n sì gbóguntì wọ́n.
45 Și Abimelec a luptat împotriva cetății toată ziua aceea; și a luat cetatea și a ucis poporul care era în ea și a dărâmat cetatea și a presărat-o cu sare.
Ní gbogbo ọjọ́ náà ni Abimeleki fi bá àwọn ará ìlú náà jà, ó sì ṣẹ́gun wọn, ó sì pa àwọn ènìyàn ìlú náà ó wó ìlú náà palẹ̀ pátápátá ó sì fọ́n iyọ̀ sí i.
46 Și după ce toți bărbații din turnul Sihemului au auzit, au intrat în turnul casei dumnezeului Berit.
Àwọn ènìyàn ilé ìṣọ́ Ṣekemu gbọ́ ohun tí ó ṣẹlẹ̀, wọ́n sálọ fún ààbò sí inú ilé ìṣọ́ òrìṣà El-Beriti.
47 Și i s-a spus lui Abimelec că s-au adunat toți bărbații turnului Sihemului.
Nígbà tí wọ́n sọ fún Abimeleki pé gbogbo àwọn ènìyàn ilé ìṣọ́ Ṣekemu kó ara wọn jọ pọ̀.
48 Și Abimelec s-a urcat pe muntele Țalmon, el și tot poporul care era cu el, și Abimelec a luat un topor în mâna sa și a tăiat o ramură dintr-un copac și a luat-o și a pus-o pe umărul său și a spus poporului care era cu el: Ce m-ați văzut că fac, grăbiți-vă, să faceți ca mine.
Abimeleki àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ gun òkè Salmoni lọ. Ó gé àwọn ẹ̀ka díẹ̀ pẹ̀lú àáké, ó gbé àwọn ẹ̀ka wọ̀nyí sí èjìká rẹ̀. Ó sọ fún àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ pé, “Ẹ ṣe ohun tí ẹ rí tí mo ń ṣe yìí ní kíákíá.”
49 Și tot poporul la fel și-a tăiat fiecare ramura lui și l-au urmat pe Abimelec și le-au pus la turn și au pus foc turnului peste ei, astfel încât au murit de asemenea toți oamenii turnului Sihemului, cam o mie de bărbați și de femei.
Báyìí gbogbo àwọn ọkùnrin tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ gé àwọn ẹ̀ka igi wọn tẹ̀lé Abimeleki. Wọ́n kó wọn ti ilé ìṣọ́ agbára níbi tí àwọn ènìyàn sá pamọ́ sí wọ́n sì fi iná sí i, tóbẹ́ẹ̀ tí gbogbo àwọn ọkùnrin ilé ìṣọ́ Ṣekemu fi kú pẹ̀lú. Gbogbo àwọn ènìyàn náà tí ó tó ẹgbẹ̀rún ènìyàn lọ́kùnrin àti lóbìnrin sì kú.
50 Atunci Abimelec a mers la Tebeț și a tăbărât împotriva Tebețului și l-a luat.
Abimeleki tún lọ sí Tebesi, ó yí ìlú náà ká pẹ̀lú àwọn ọmọ-ogun, ó sì ṣẹ́gun rẹ̀.
51 Dar acolo era un turn tare în interiorul cetății și acolo au fugit toți bărbații și femeile și toți cei din cetate și au încuiat ușile după ei și s-au urcat pe acoperișul turnului.
Ilé ìṣọ́ kan tí ó ní agbára sì wà nínú ìlú náà. Gbogbo àwọn ènìyàn ìlú náà ọkùnrin àti obìnrin sá sínú ilé ìṣọ́ náà. Wọ́n ti ara wọn mọ́ ibẹ̀ wọ́n sì sálọ sí inú àjà ilé ìṣọ́ náà.
52 Și Abimelec a venit până la turn și a luptat împotriva lui și a atacat ușa turnului ca să o ardă cu foc.
Abimeleki lọ sí ìsàlẹ̀ ilé ìṣọ́ náà, ó sì ń bá a jà. Ṣùgbọ́n bí ó ti súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà ilé ìṣọ́ náà láti dáná sun ún,
53 Și o femeie a aruncat o bucată de piatră de moară pe capul lui Abimelec și aproape i-a zdrobit capul.
obìnrin kan sọ ọmọ ọlọ lu Abimeleki lórí, ó sì fọ́ ọ ní agbárí.
54 Atunci el a chemat în grabă pe tânărul care era purtătorul său de arme și i-a spus: Scoate-ți sabia și omoară-mă, ca să nu spună oamenii despre mine: O femeie l-a ucis. Și tânărul său l-a străpuns și el a murit.
Ní ojú kan náà ni ó pe ẹni tí ó ru àpáta rẹ̀ pé, “Yára yọ idà rẹ kí o sì pa mí, kí wọn má ba à sọ pé, ‘Obìnrin ni ó pa á.’” Ọ̀dọ́mọkùnrin náà sì fi ọ̀kọ̀ gún un, ó sì kú.
55 Și când bărbații lui Israel au văzut că Abimelec a murit, s-au depărtat, fiecare la locul său.
Nígbà tí àwọn ará Israẹli rí i pé Abimeleki kú, olúkúlùkù wọn padà sí ilé rẹ̀.
56 Astfel Dumnezeu i-a întors răutatea lui Abimelec, pe care o făcuse tatălui său, ucigând pe cei șaptezeci de frați ai săi;
Báyìí ni Ọlọ́run san ẹ̀san ìwà búburú ti Abimeleki hù sí baba rẹ̀ ní ti pípa tí ó pa, àwọn àádọ́rin arákùnrin rẹ̀.
57 Și toată răutatea bărbaților din Sihem, Dumnezeu a întors-o asupra capetelor lor; și blestemul lui Iotam, fiul lui Ierubaal, a venit asupra lor.
Ọlọ́run jẹ́ kí ìwà búburú àwọn ará Ṣekemu pẹ̀lú padà sí orí wọn. Ègún Jotamu ọmọ Jerubbaali pàápàá wá sí orí wọn.

< Judecătorii 9 >