< Judecătorii 8 >

1 Și bărbații lui Efraim i-au spus: De ce ne-ai servit astfel, încât nu ne-ai chemat, când ai mers să te lupți cu madianiții? Și s-au certat foarte tare cu el.
Àwọn àgbàgbà ẹ̀yà Efraimu sì bínú gidigidi sí Gideoni wọ́n bi í léèrè pé, kí ló dé tí o fi ṣe irú èyí sí wa? Èéṣe tí ìwọ kò fi pè wá nígbà tí ìwọ kọ́kọ́ jáde lọ láti bá àwọn ará Midiani jagun? Ohùn ìbínú ni wọ́n fi bá a sọ̀rọ̀.
2 Și el le-a spus: Ce am făcut eu acum pe lângă voi? Nu este mai bună strângerea strugurilor rămași din Efraim decât culesul viei din Abiezer?
Ṣùgbọ́n Gideoni dá wọn lóhùn pé, “Àṣeyọrí wo ni mo ti ṣe tí ó tó fiwé tiyín? Àṣàkù àjàrà Efraimu kò ha dára ju gbogbo ìkórè àjàrà Abieseri lọ bí?
3 Dumnezeu a dat în mâinile voastre pe prinții lui Madian, Oreb și Zeeb; și ce am fost eu în stare să fac pe lângă voi? Atunci mânia lor s-a potolit față de el, după ce a spus aceasta.
Ọlọ́run ti fi Orebu àti Seebu àwọn olórí àwọn ará Midiani lé yín lọ́wọ́. Kí ni ohun tí Mose ṣe tí ó tó fiwé e yín tàbí tí ó tó àṣeyọrí i yín?” Nígbà tí ó wí èyí ríru ìbínú wọn rọlẹ̀.
4 Și Ghedeon a venit la Iordan și a trecut, el și cei trei sute de bărbați care erau cu el, obosiți, totuși urmărindu-i.
Gideoni àti àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ tẹ̀síwájú láti lépa àwọn ọ̀tá bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ti rẹ̀ wọ́n, wọ́n dé Jordani wọ́n sì kọjá sí òdìkejì.
5 Și a spus bărbaților din Sucot: Dați, vă rog, pâini poporului care mă urmează, pentru că sunt obosiți și eu urmăresc pe Zebah și pe Țalmuna, împărații lui Madian.
Ó wí fún àwọn ọkùnrin Sukkoti pé, “Ẹ fún àwọn ọmọ-ogun mi ní oúnjẹ díẹ̀, nítorí ó ti rẹ̀ wọ́n, èmi sì ń lépa Seba àti Salmunna àwọn ọba Midiani.”
6 Și prinții din Sucot au spus: Sunt acum mâinile lui Zebah și ale lui Țalmuna în mâna ta, încât să dăm pâine armatei tale?
Ṣùgbọ́n àwọn ìjòyè Sukkoti fèsì pé ṣé ọwọ́ rẹ ti tẹ Seba àti Salmunna náà ni? Èéṣe tí àwa yóò ṣe fún àwọn ológun rẹ ní oúnjẹ?
7 Și Ghedeon a spus: De aceea, când DOMNUL va fi dat pe Zebah și pe Țalmuna în mâna mea, atunci vă voi smulge carnea cu spinii pustiului și cu mărăcini.
Gideoni dá wọn lóhùn pé, “Ó dára, nígbà tí Olúwa bá fi Seba àti Salmunna lé mi lọ́wọ́ tán èmi yóò fi ẹ̀gún ijù àti ẹ̀gún òṣùṣú ya ẹran-ara yín.”
8 Și de acolo s-a urcat la Penuel și le-a vorbit la fel, iar bărbații din Penuel i-au răspuns cum au răspuns bărbații din Sucot.
Láti ibẹ̀, ó lọ sí Penieli ó sì bẹ̀ wọ́n bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́, ṣùgbọ́n àwọn náà dá a lóhùn bí àwọn ará Sukkoti ti dá a lóhùn.
9 Și a vorbit și bărbaților din Penuel, spunând: Când voi veni din nou în pace, voi dărâma acest turn.
Nígbà náà ni ó sọ fún àwọn ọkùnrin Penieli pé, “Nígbà tí mo bá ṣẹ́gun tí mo sì padà dé ní àlàáfíà, èmi yóò wó ilé ìṣọ́ yìí.”
10 Acum, Zebah și Țalmuna erau în Carcor și oștirile lor erau cu ei, cam cincisprezece mii, toți câți au rămas din toate oștirile copiilor estului, căci căzuseră o sută douăzeci de mii de oameni care scoteau sabia.
Ní àsìkò náà Seba àti Salmunna wà ní Karkori pẹ̀lú ọmọ-ogun wọn tí ó tó ẹgbẹ̀rún mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ọkùnrin, àwọn wọ̀nyí ni ó ṣẹ́kù nínú gbogbo ogun àwọn ènìyàn apá ìlà-oòrùn, nítorí ọ̀kẹ́ mẹ́fà ọkùnrin tí ó fi idà jà ti kú ní ojú ogun.
11 Și Ghedeon s-a urcat pe calea celor care locuiau în corturi, la est de Nobah și Iogbeha, și a lovit oștirea, pentru că oștirea era în siguranță.
Gideoni gba ọ̀nà tí àwọn darandaran máa ń rìn ní apá ìhà ìlà-oòrùn Noba àti Jogbeha ó sì kọjú ogun sí àwọn ọmọ-ogun náà nítorí wọ́n ti túra sílẹ̀.
12 Și după ce Zebah și Țalmuna au fugit, el i-a urmărit și a prins pe cei doi împărați ai lui Madian, pe Zebah și pe Țalmuna; și a învins toată oștirea.
Seba àti Salmunna, àwọn ọba Midiani méjèèjì sá, ṣùgbọ́n Gideoni lépa wọn ó sì mú wọn, ó run gbogbo ogun wọn.
13 Și Ghedeon, fiul lui Ioas, s-a întors de la bătălie înainte ca soarele să răsară.
Gideoni ọmọ Joaṣi gba ọ̀nà ìgòkè Heresi padà sẹ́yìn láti ojú ogun.
14 Și a prins pe un tânăr al bărbaților din Sucot și l-a întrebat; și el i-a descris pe prinții din Sucot și pe bătrânii săi, șaptezeci și șapte de bărbați.
Ó mú ọ̀dọ́mọkùnrin kan ará Sukkoti, ó sì béèrè àwọn ìbéèrè ní ọwọ́ rẹ̀, ọ̀dọ́mọkùnrin náà sì kọ orúkọ àwọn ìjòyè Sukkoti mẹ́tàdínlọ́gọ́rin fún un tí wọ́n jẹ́ àgbàgbà ìlú náà.
15 Iar el a venit la bărbații din Sucot și a spus: Iată, pe Zebah și pe Țalmuna, cu care m-ați ocărât, zicând: Sunt acum mâinile lui Zebah și ale lui Țalmuna în mâna ta, ca să dăm pâine bărbaților tăi obosiți?
Nígbà náà ni Gideoni wá ó sọ fún àwọn ọkùnrin Sukkoti pé, “Seba àti Salmunna nìwọ̀nyí nípa àwọn tí ẹ̀yin fi mí ṣẹ̀fẹ̀ nígbà tí ẹ wí pé, ‘Ṣé ó ti ṣẹ́gun Seba àti Salmunna? Èéṣe tí àwa ó fi fún àwọn ọmọ-ogun rẹ tí ó ti rẹ̀ ní oúnjẹ?’”
16 Și a luat pe bătrânii cetății și spini din pustie și mărăcini și cu ei i-a învățat pe oamenii din Sucot.
Ó mú àwọn àgbàgbà ìlú náà, ó sì fi kọ́ àwọn Sukkoti lọ́gbọ́n nípa jíjẹ wọ́n ní yà pẹ̀lú àwọn ẹ̀gún ijù àti ẹ̀gún ọ̀gàn.
17 Și a dărâmat turnul din Penuel și a ucis pe bărbații cetății.
Ó wó ilé ìṣọ́ Penieli, ó sì pa àwọn ọkùnrin ìlú náà.
18 Atunci le-a spus lui Zebah și lui Țalmuna: Ce fel de bărbați erau cei pe care i-ați ucis la Tabor? Iar ei au răspuns: Ca tine, astfel erau; fiecare semăna cu copiii unui împărat.
Gideoni bi Seba àti Salmunna pé, “Irú ọkùnrin tí ẹ pa ní Tabori, báwo ni wọ́n ṣe rí?” “Àwọn ọkùnrin náà dàbí rẹ ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn dàbí ọmọ ọba,” ní ìdáhùn wọn.
19 Și el a spus: Ei erau frații mei, fiii mamei mele; precum DOMNUL trăiește, dacă i-ați fi lăsat în viață, nu v-aș fi ucis.
Gideoni dáhùn pé, “Arákùnrin mi ni wọ́n, àwọn ọmọ ìyá mi. Mo fi Olúwa búra, bí ó bá ṣe pé ẹ dá ẹ̀mí wọn sí, èmi náà ò nípa yín.”
20 Și a spus către Ieter, întâiul născut al său: Ridică-te, ucide-i. Dar tânărul nu și-a scos sabia, pentru că se temea, fiindcă era încă tânăr.
Ó yí padà sí Jeteri, ọmọ rẹ̀ tí ó dàgbà jùlọ, ó wí fún un pé, “Pa wọ́n!” Ṣùgbọ́n Jeteri kò fa idà rẹ̀ yọ láti pa wọ́n nítorí ó jẹ́ ọ̀dọ́mọdé ẹ̀rù sì bà á láti pa wọ́n.
21 Atunci Zebah și Țalmuna au spus: Ridică-te tu și aruncă-te asupra noastră, căci precum este bărbatul, astfel este puterea lui. Și Ghedeon s-a ridicat și a ucis pe Zebah și pe Țalmuna și a luat ornamentele care erau la gâturile cămilelor lor.
Seba àti Salmunna dá Gideoni lóhùn pé, “Wá pa wá fún raàrẹ, ‘Nítorí bí ènìyàn bá ti rí bẹ́ẹ̀ ni agbára rẹ̀ yóò rí.’” Gideoni bọ́ síwájú ó sì pa wọ́n, ó sì mú ohun ọ̀ṣọ́ tí ó wà ní ọrùn àwọn ìbákasẹ wọn.
22 Atunci bărbații lui Israel i-au spus lui Ghedeon: Stăpânește peste noi, deopotrivă tu și fiul tău și fiul fiului tău de asemenea, pentru că ne-ai eliberat din mâna lui Madian.
Àwọn ará Israẹli wí fún Gideoni pé, “Jọba lórí wa—ìwọ, àwọn ọmọ rẹ àti àwọn ọmọ ọmọ rẹ pẹ̀lú, nítorí tí ìwọ ti gbà wá lọ́wọ́ àwọn ará Midiani.”
23 Și Ghedeon le-a spus: Nu eu voi stăpâni peste voi, nici fiul meu nu va stăpâni peste voi, DOMNUL va stăpâni peste voi.
Ṣùgbọ́n Gideoni dá wọn lóhùn pé, “Èmi kì yóò jẹ ọba lórí yín, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ mi kì yóò jẹ ọba lórí yín. Olúwa ni yóò jẹ ọba lórí yín.”
24 Și Ghedeon le-a spus: Aș dori să vă cer ceva, să îmi dați fiecare bărbat cerceii prăzii sale. (Pentru că aveau cercei de aur, fiindcă erau ismaeliți).
Gideoni sì wí pé, “Mo ní ẹ̀bẹ̀ kan tí mo fẹ́ bẹ̀ yín kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín fún mi ní yẹtí kọ̀ọ̀kan láti inú ohun ti ó kàn yín láti inú ìkógun.” (Àṣà àwọn ará Iṣmaeli ni láti máa fi yẹtí wúrà sétí.)
25 Iar ei au răspuns: Ți-i vom da de bunăvoie. Și au întins o haină și au aruncat pe ea fiecare cerceii prăzii sale.
Wọ́n dáhùn pé, “Tayọ̀tayọ̀ ni àwa yóò fi wọ́n sílẹ̀.” Wọ́n tẹ́ aṣọ kan sílẹ̀ ọkùnrin kọ̀ọ̀kan sì ń sọ yẹtí kọ̀ọ̀kan tí ó kàn wọ́n láti ibi ìkógun síbẹ̀.
26 Și greutatea cerceilor de aur, pe care îi ceruse el, era de o mie șapte sute de șekeli de aur, în afară de ornamentele și colanele și îmbrăcămintea de purpură care erau pe împărații lui Madian și în afară de lanțurile care erau în jurul gâturilor cămilelor lor.
Ìwọ̀n òrùka wúrà tí ó béèrè fún tó ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀sán ìwọ̀n ṣékélì, láìka àwọn ohun ọ̀ṣọ́ àti ohun sísorọ̀ tí ó wà lára ìlẹ̀kẹ̀ ọrùn àti aṣọ elése àlùkò tí àwọn ọba Midiani ń wọ̀ tàbí àwọn ẹ̀wọ̀n tí ó wà ní ọrùn àwọn ìbákasẹ wọn.
27 Și Ghedeon a făcut din ele un efod și l-a pus în cetatea sa, în Ofra, și tot Israelul a curvit după acesta acolo, lucru care a devenit o cursă pentru Ghedeon și pentru casa lui.
Gideoni fi àwọn wúrà náà ṣe efodu èyí tí ó gbé kalẹ̀ ní Ofira ìlú rẹ̀. Àwọn ọmọ Israẹli sì sọ ara wọn di àgbèrè nípa sínsin-ín ní ibẹ̀. Ó sì di ìdẹ̀kùn fún Gideoni àti ìdílé rẹ̀.
28 Astfel a fost Madian supus înaintea copiilor lui Israel, încât nu și-a mai ridicat capul. Și țara a avut liniște patruzeci de ani în zilele lui Ghedeon.
Báyìí ni a ṣe tẹrí àwọn ará Midiani ba níwájú àwọn ọmọ Israẹli bẹ́ẹ̀ ni wọn kò tún gbé orí mọ́. Ní ọjọ́ Gideoni, Israẹli wà ní àlàáfíà fún ogójì ọdún.
29 Și Ierubaal, fiul lui Ioas, a mers și a locuit în casa lui.
Jerubbaali ọmọ Joaṣi padà lọ láti máa gbé ní ìlú rẹ̀.
30 Și Ghedeon a avut șaptezeci de fii născuți din coapsele sale, pentru că avea multe soții.
Àádọ́rin ọmọ ni Gideoni bí, nítorí ó ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ìyàwó.
31 Și concubina lui care era în Sihem, ea de asemenea i-a născut un fiu și el i-a pus numele Abimelec.
Àlè rẹ̀, tó ń gbé ní Ṣekemu, pàápàá bí ọmọkùnrin kan fún un tí ó pe orúkọ rẹ̀ ní Abimeleki.
32 Și Ghedeon, fiul lui Ioas, a murit după o bătrânețe frumoasă și a fost îngropat în mormântul lui Ioas, tatăl său, în Ofra abiezeriților.
Gideoni ọmọ Joaṣi kú ní ògbólógbòó ọjọ́ rẹ̀, ó sì pọ̀ ní ọjọ́ orí, wọ́n sì sin ín sí ibojì baba rẹ̀ ní Ofira ti àwọn ará Abieseri.
33 Și s-a întâmplat că, imediat ce a murit Ghedeon, copiii lui Israel s-au întors din nou și au curvit după Baali și l-au făcut pe Baal-Berit, dumnezeul lor.
Láìpẹ́ jọjọ lẹ́yìn ikú Gideoni ni àwọn ará Israẹli ṣe àgbèrè tọ Baali lẹ́yìn, wọ́n fi Baali-Beriti ṣe òrìṣà wọn.
34 Și copiii lui Israel nu și-au amintit de DOMNUL Dumnezeul lor, care îi eliberase din mâinile tuturor dușmanilor lor, de jur împrejur,
Wọn kò sì rántí Olúwa Ọlọ́run wọn, ẹni tí ó gbà wọ́n kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn gbogbo tí ó wà ní gbogbo àyíká wọn.
35 Nici nu au arătat bunătate casei lui Ierubaal, adică lui Ghedeon, conform cu toată bunătatea pe care o arătase el lui Israel.
Wọ́n kùnà láti fi inú rere hàn sí ìdílé Jerubbaali (èyí ni Gideoni) fún gbogbo oore tí ó ṣe fún wọn.

< Judecătorii 8 >