< Judecătorii 6 >

1 Și copiii lui Israel au făcut ce este rău în ochii DOMNULUI, și DOMNUL i-a dat în mâna lui Madian, șapte ani.
Àwọn ọmọ Israẹli sì túnṣe ohun tí ó burú ní ojú Olúwa, Ó sì fi wọ́n lé àwọn ará Midiani lọ́wọ́ fún ọdún méje.
2 Și mâna lui Madian a învins pe Israel; și din cauza madianiților copiii lui Israel și-au făcut vizuinile care sunt în munți și peșteri și întărituri.
Agbára àwọn ará Midiani sì pọ̀ púpọ̀ lórí àwọn Israẹli, wọ́n sì hùwà ipá sí wọn, nítorí ìdí èyí, àwọn Israẹli sálọ sí àwọn orí òkè, wọ́n sì kọ́ àgọ́ fún ara wọn nínú ihò àpáta, àti nínú ọ̀gbun àti ní ibi agbára nínú àpáta.
3 Și era astfel, când semăna Israel, madianiții și amaleciții și copiii estului se urcau; da, ei se urcau împotriva lor;
Ní ìgbàkúgbà tí àwọn ọmọ Israẹli bá ti gbin ọ̀gbìn wọn, àwọn ará Midiani, àwọn ará Amaleki àti àwọn ará ìlà-oòrùn mìíràn yóò wá láti bá wọn jà.
4 Și își așezau tabăra împotriva lor și distrugeau venitul pământului cum vii la Gaza și nu lăsau merinde pentru Israel, nici oaie, nici bou, nici măgar.
Wọn yóò tẹ̀dó sí orí ilẹ̀ náà, wọn a sì bá irúgbìn wọ̀nyí jẹ́ títí dé Gasa, wọn kì í sì í fi ohun alààyè kankan sílẹ̀ fún àwọn ọmọ Israẹli, kì bá à ṣe àgùntàn, màlúù tàbí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
5 Pentru că se urcau cu vitele lor și corturile lor și veneau o mulțime ca și cosașele; căci deopotrivă ei și cămilele lor erau fără număr și intrau în țară să o distrugă.
Wọn a máa wá pẹ̀lú ohun ọ̀sìn wọn àti àwọn àgọ́ wọn, wọn a sì dàbí eṣú nítorí i púpọ̀ wọn. Ènìyàn kò sì lè ka iye àwọn ènìyàn náà bẹ́ẹ̀ ni àwọn ìbákasẹ, wọ́n pọ̀ dé bi pé wọn kò ṣe é kà ní iye, wọn a bo ilẹ̀ náà wọn a sì jẹ ẹ́ run.
6 Și Israel era foarte sărăcit din cauza madianiților; și copiii lui Israel au strigat către DOMNUL.
Àwọn ará Midiani sì pọ́n àwọn ọmọ Israẹli lójú, wọ́n sọ wọ́n di òtòṣì àti aláìní, fún ìdí èyí wọ́n ké pe Olúwa nínú àdúrà fún ìrànlọ́wọ́.
7 Și s-a întâmplat, când copiii lui Israel au strigat către DOMNUL din cauza madianiților,
Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli ké pe Olúwa nítorí àwọn ará Midiani.
8 Că DOMNUL a trimis un profet la copiii lui Israel, care le-a spus: Astfel spune DOMNUL Dumnezeul lui Israel: Eu v-am adus din Egipt și v-am scos din casa robiei;
Olúwa fi etí sí igbe wọn, ó sì rán wòlíì kan sí wọn, ẹni tí ó wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: mo mú yín gòkè ti Ejibiti wá, láti oko ẹrú.
9 Și v-am eliberat din mâna egiptenilor și din mâna tuturor celor ce vă oprimau și i-am alungat dinaintea voastră și v-am dat țara lor;
Mo gbà yín kúrò nínú agbára Ejibiti àti kúrò ní ọwọ́ gbogbo àwọn aninilára yín. Mo lé wọn kúrò ní iwájú yín, mo sì fi ilẹ̀ wọn fún yín.
10 Și v-am spus: Eu sunt DOMNUL Dumnezeul vostru; nu vă temeți de dumnezeii amoriților, în a căror țară locuiți; dar nu ați ascultat de vocea mea.
Mo wí fún un yín pé, ‘Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín; ẹ má ṣe sin àwọn òrìṣà àwọn ará Amori, ní ilẹ̀ ẹni tí ẹ̀yin ń gbé.’ Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọ́rọ̀ sí ohun tí mo sọ.”
11 Și a venit un înger al DOMNULUI și a șezut sub un stejar care era în Ofra, care era al lui Ioas abiezeritul. Și fiul său Ghedeon bătea grâu în teasc, ca să îl ascundă de madianiți.
Ní ọjọ́ kan angẹli Olúwa wá, ó sì jókòó ní abẹ́ igi óákù Ofira èyí ti ṣe ti Joaṣi ará Abieseri, níbi tí Gideoni ọmọ rẹ̀ ti ń lu ọkà jéró, níbi ìpọntí wáìnì láti fi pamọ́ kúrò níwájú àwọn ará Midiani.
12 Și îngerul DOMNULUI i s-a arătat și i-a spus: DOMNUL este cu tine, războinic viteaz!
Nígbà tí angẹli Olúwa fi ara han Gideoni, ó wí fún un pé, “Olúwa wà pẹ̀lú rẹ, akọni ológun.”
13 Și Ghedeon i-a spus: O, Domnul meu, dacă este DOMNUL cu noi, de ce au venit toate acestea asupra noastră? Și unde sunt toate miracolele sale pe care ni le-au povestit părinții noștri, spunând: Nu ne-a scos DOMNUL din Egipt? Dar acum DOMNUL ne-a părăsit și ne-a dat în mâinile madianiților.
Gideoni dáhùn pé, “Alàgbà, bí Olúwa bá wà pẹ̀lú wa, kí ló dé tí gbogbo ìwọ̀nyí fi ń ṣẹlẹ̀ sí wa? Níbi gbogbo àwọn iṣẹ́ ìyanu rẹ tí àwọn baba wa ròyìn rẹ̀ fún wa nígbà tí wọ́n wí pé, ‘Olúwa kò ha mú wa gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá?’ Ṣùgbọ́n nísinsin yìí Olúwa ti kọ̀ wá sílẹ̀, ó sì ti fi wá lé àwọn ará Midiani lọ́wọ́.”
14 Și DOMNUL a privit spre el și a spus: Du-te cu această putere a ta și vei salva pe Israel din mâna madianiților; nu te-am trimis eu?
Olúwa sì yípadà sí i, ó sì wí fún un pé, “Lọ nínú agbára tí o ní yìí, kí o sì gba àwọn ará Israẹli sílẹ̀ kúrò lọ́wọ́ àwọn ará Midiani. Èmi ni ó ń rán ọ lọ.”
15 Iar el i-a spus: O, Domnul meu, prin ce voi salva eu pe Israel? Iată, familia mea este săracă în Manase și eu sunt cel mai mic în casa tatălui meu.
Gideoni sì dáhùn pé, “Yéè olúwa mi, ọ̀nà wo ni èmi yóò fi gba Israẹli là? Ìdílé mi ni ó jẹ́ aláìlera jù ní Manase, àti pé èmi ni ó sì kéré jù ní ìdílé baba mi.”
16 Și DOMNUL i-a spus: Negreșit eu voi fi cu tine și tu vei lovi pe madianiți ca pe un singur om.
Olúwa sì dáhùn pé, “Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ, ìwọ yóò sì pa gbogbo àwọn ará Midiani láì ku ẹnìkankan.”
17 Iar el i-a spus: Acum, dacă am găsit har în ochii tăi, atunci arată-mi un semn că tu vorbești cu mine.
Gideoni sì dáhùn pé, nísinsin yìí tí mo bá bá ojúrere rẹ pàdé, fún mi ní àmì pé ìwọ ni ń bá mi sọ̀rọ̀.
18 Te rog, nu te depărta de aici, până voi veni la tine și îmi voi aduce darul și îl voi pune înaintea ta. Iar el a spus: Voi rămâne până te vei întoarce.
Jọ̀wọ́ má ṣe kúrò níbí títí èmi yóò fi mú ọrẹ wá fún ọ kí n sì gbé e sí iwájú rẹ. Olúwa sì wí pé, “Èmi yóò dúró títí ìwọ yóò fi dé.”
19 Și Ghedeon a intrat și a pregătit un ied și azime, dintr-o efă de făină, carnea a pus-o într-un coș și zeama a pus-o într-o oală și i le-a adus afară sub stejar și i le-a prezentat.
Gideoni sì yára wọ ilé lọ, ó sì pa ọ̀dọ́ ewúrẹ́ kan, wọ́n sì sè é, ó sì mú ìyẹ̀fun efa kan, ó fi ṣe àkàrà aláìwú. Ó gbé ẹran náà sínú agbọ̀n, ṣùgbọ́n ó fi ọbẹ̀ rẹ̀ sínú ìkòkò, ó gbé wọn jáde tọ angẹli náà wá bí ọrẹ lábẹ́ igi óákù.
20 Și îngerul lui Dumnezeu i-a spus: Ia carnea și azimele și pune-le pe această stâncă și varsă zeama. Și el a făcut astfel.
Angẹli Ọlọ́run náà sì wí fún un pé, “Gbé ẹran náà àti àkàrà àìwú náà, sí orí àpáta yìí, kí o sì da omi ọbẹ̀ rẹ̀ sí orí rẹ̀.” Gideoni sì ṣe bẹ́ẹ̀.
21 Atunci îngerul DOMNULUI a întins vârful toiagului care era în mâna lui și a atins carnea și azimele; și s-a ridicat foc din stâncă și a mistuit carnea și azimele. Atunci îngerul DOMNULUI s-a depărtat dinaintea ochilor lui.
Angẹli Olúwa sì fi orí ọ̀pá tí ó wà ní ọwọ́ rẹ̀ kan ẹran àti àkàrà àìwú náà. Iná sì jáde láti inú àpáta, ó sì jó ẹran àti àkàrà náà, kò sì rí angẹli náà mọ́.
22 Și după ce Ghedeon a văzut că a fost un înger al DOMNULUI, Ghedeon a spus: Vai, Doamne DUMNEZEULE! Pentru că am văzut un înger al DOMNULUI față în față.
Nígbà tí Gideoni sì ti mọ̀ dájúdájú pé angẹli Olúwa ni, ó ké wí pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Mo ti rí angẹli Olúwa ní ojúkorojú!”
23 Și DOMNUL i-a spus: Pace ție, nu te teme, nu vei muri.
Ṣùgbọ́n Olúwa wí fún un pé, “Àlàáfíà! Má ṣe bẹ̀rù, ìwọ kì yóò kùú.”
24 Atunci Ghedeon a zidit acolo un altar DOMNULUI și l-a numit Iehova-Șalom; până în ziua aceasta el este încă în Ofra abiezriților.
Báyìí ni Gideoni mọ pẹpẹ kan fún Olúwa níbẹ̀, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní “Àlàáfíà ni Olúwa.” Ó sì wà ní Ofira ti Abieseri títí di òní.
25 Și s-a întâmplat, în aceeași noapte, că DOMNUL i-a spus: Ia taurul tânăr al tatălui tău, al doilea taur de șapte ani și dărâmă altarul lui Baal, pe care îl are tatăl tău, și retează dumbrava care este lângă el;
Ní òru ọjọ́ náà Olúwa wí fún un pé, mú akọ màlúù baba rẹ, àní akọ màlúù kejì ọlọ́dún méje. Wó pẹpẹ Baali baba rẹ lulẹ̀, kí o sì bẹ́ igi ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ lulẹ̀.
26 Și zidește un altar DOMNULUI Dumnezeul tău pe vârful acestei stânci, în felul rânduit și ia al doilea taur și oferă un sacrificiu ars cu lemnele dumbrăvii, pe care o vei reteza.
Lẹ́yìn èyí kí o wá mọ pẹpẹ èyí tí ó yẹ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ lórí òkè yìí. Kí o sì mú akọ màlúù kejì, kí o sì mú igi ère òrìṣà Aṣerah tí ìwọ bẹ́ lulẹ̀ rú ẹbọ sísun sí Olúwa.
27 Atunci Ghedeon a luat zece bărbați dintre servitorii săi și a făcut precum îi spusese DOMNUL; și așa a fost, fiindcă s-a temut de casa tatălui său și de bărbații cetății, că a făcut acest lucru noaptea, nu ziua.
Gideoni mú mẹ́wàá nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, ó sì ṣe bí Olúwa ti pàṣẹ fún un ṣùgbọ́n, nítorí ó bẹ̀rù àwọn ará ilé baba rẹ̀ àti àwọn ènìyàn ìlú náà kò ṣe é ní ọ̀sán, òru ni ó ṣe.
28 Și când s-au trezit bărbații cetății dis-de-dimineață, iată, altarul lui Baal era dărâmat și dumbrava, care era lângă el, era retezată, și taurul al doilea era oferit pe altarul care era zidit.
Nígbà tí ilẹ̀ ọjọ́ kejì mọ́, tí àwọn ènìyàn ìlú náà jí, wọ́n rí i pé àti fọ́ pẹpẹ Baali àti pé a ti bẹ́ igi ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀, a sì ti fi akọ màlúù kejì rú ẹbọ lórí pẹpẹ tí a ṣẹ̀ṣẹ̀ mọ.
29 Și ei au spus unul către altul: Cine a făcut acest lucru? Și după ce au cercetat și au întrebat, au spus: Ghedeon, fiul lui Ioas, a făcut acest lucru.
Àwọn ènìyàn ìlú náà bi ara wọn wí pé, “Ta ni ó ṣe èyí?” Lẹ́yìn tí wọn fi ara balẹ̀ ṣe ìwádìí, wọ́n gbọ́ wí pé, “Gideoni ọmọ Joaṣi ni ó ṣe é.”
30 Atunci bărbații cetății i-au spus lui Ioas: Scoate afară pe fiul tău ca să moară, pentru că a dărâmat altarul lui Baal și pentru că a retezat dumbrava care era lângă el.
Àwọn ọkùnrin ìlú náà sì wí fún Joaṣi wí pé, “Mú ọmọ rẹ jáde wá. Ó ní láti kú nítorí pé ó ti wó pẹpẹ Baali lulẹ̀ ó sì ti ké ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀bá rẹ̀ lulẹ̀.”
31 Și Ioas a spus tuturor celor care stăteau împotriva lui: Veți pleda pentru Baal? Voiți să îl salvați? Cel care va pleda pentru el să fie dat la moarte cât timp este încă dimineață, dacă este dumnezeu, să pledeze pentru el însuși, pentru că i-a dărâmat altarul.
Ṣùgbọ́n Joaṣi bi àwọn èrò tí wọ́n fi ìbínú dúró tì í wí pé, “Ẹ̀yin yóò ha gbìjà Baali bí? Ẹ̀yin yóò ha gbà á sílẹ̀ bí? Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbìjà rẹ̀ kíkú ni olúwa rẹ̀ yóò kú ní òwúrọ̀. Bí Baali bá ṣe Ọlọ́run nítòótọ́ yóò jà fún ara rẹ̀ bí ẹnikẹ́ni bá wó pẹpẹ rẹ̀ lulẹ̀.”
32 De aceea l-au numit în ziua aceea Ierub-Baal, spunând: Să pledeze Baal împotriva lui, pentru că i-a dărâmat altarul.
Fún ìdí èyí ní ọjọ́ náà wọ́n pe Gideoni ní “Jerubbaali” wí pé, “Jẹ́ kí Baali bá a jà,” nítorí pé ó ti wó pẹpẹ Baali.
33 Atunci toți madianiții și amaleciții și copiii estului s-au adunat și au trecut și și-au ridicat corturile în valea lui Izreel.
Láìpẹ́ jọjọ, àwọn ogun àwọn Midiani, ti àwọn Amaleki àti ti àwọn ènìyàn ìhà ìlà-oòrùn yòókù kó ara wọn jọ pọ̀ ní ìṣọ̀kan, wọ́n sì kọjá Jordani wọ́n sì tẹ̀dó sí àfonífojì Jesreeli.
34 Dar Duhul DOMNULUI a venit peste Ghedeon și el a sunat din trâmbiță; și Abiezer s-a adunat după el.
Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé Gideoni, ó sì fun fèrè ìpè, láti pe àwọn ará Abieseri láti tẹ̀lé òun.
35 Și a trimis mesageri prin tot Manase, care de asemenea au fost chemați după el, și a trimis mesageri la Așer și la Zabulon și la Neftali, și ei s-au urcat să îi întâlnească.
Ó rán àwọn oníṣẹ́ la ilẹ̀ Manase já pé kí wọ́n dira ogun, àti sí Aṣeri, Sebuluni àti Naftali gbogbo pẹ̀lú sì lọ láti pàdé wọn.
36 Și Ghedeon i-a spus lui Dumnezeu: Dacă voiești să salvezi pe Israel prin mâna mea, precum ai spus,
Gideoni wí fún Ọlọ́run pé, “Bí ìwọ yóò bá gba Israẹli là nípasẹ̀ mi bí ìwọ ti ṣe ìlérí—
37 Iată, voi pune un val de lână în arie și dacă va fi rouă numai pe val și tot pământul de lângă va fi uscat, atunci voi cunoaște că vei salva pe Israel prin mâna mea, precum ai spus.
kíyèsi, èmi yóò fi awọ irun àgùntàn lé ilẹ̀ ìpakà ní alẹ́ òní. Bí ìrì bá sẹ̀ sí orí awọ yìí nìkan tí gbogbo ilẹ̀ yòókù sì gbẹ, nígbà náà ni èmi yóò mọ̀ lóòótọ́ pé ìwọ yóò gba Israẹli là nípasẹ̀ mi bí ìwọ ti sọ.”
38 Și a fost astfel, că s-a sculat a doua zi dis-de-dimineață și a strâns valul și a stors roua din val, un vas plin cu apă.
Èyí ni ó sì ṣẹlẹ̀. Nígbà tí Gideoni jí ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì fún irun àgùntàn náà, ọpọ́n omi kan sì kún.
39 Și Ghedeon i-a spus lui Dumnezeu: Să nu se aprindă mânia ta împotriva mea și voi vorbi numai de data aceasta, te rog, să mai încerc numai de data aceasta cu valul; să fie uscat peste val și peste tot pământul să fie rouă.
Gideoni sì tún wí fún Ọlọ́run pé, “Jọ̀wọ́ má ṣe bínú sí mi, ṣùgbọ́n jẹ́ kí n tún wá ìdánilójú kan sí i, èmi bẹ̀ ọ́ jẹ́ kí n fi awọ irun yìí ṣe ìdánwò kan sí i. Ní àsìkò yìí, jẹ́ kí awọ irun yìí gbẹ kí gbogbo ilẹ̀ sì tutù pẹ̀lú ìrì.”
40 Și Dumnezeu a făcut astfel în noaptea aceea, că a fost uscat numai valul și pe tot pământul a fost rouă.
Ní òru náà Ọlọ́run ṣe bẹ́ẹ̀, awọ irun àgùntàn nìkan ni ó gbẹ; gbogbo ilẹ̀ yòókù sì tutù nítorí ìrì.

< Judecătorii 6 >