< Judecătorii 19 >

1 Și s-a întâmplat, în zilele acelea când nu era împărat în Israel, că era un levit, care locuia temporar într-o parte a muntelui Efraim, și el și-a luat o concubină din Betleem-Iuda.
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì Israẹli kò ní ọba. Ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Lefi tí ń gbé ibi tí ó sá pamọ́ nínú àwọn agbègbè òkè Efraimu, mú àlè kan láti Bẹtilẹhẹmu ní Juda.
2 Și concubina lui a curvit împotriva lui și a plecat de la el la casa tatălui ei, în Betleem-Iuda, și a rămas acolo patru luni întregi.
Ṣùgbọ́n àlè rẹ̀ náà sì ṣe panṣágà sí i, òun fi sílẹ̀, ó sì padà lọ sí ilé baba rẹ̀ ní Bẹtilẹhẹmu ti Juda, ó sì wà ní ibẹ̀ ní ìwọ̀n oṣù mẹ́rin,
3 Și soțul ei s-a ridicat și a mers după ea, să îi vorbească prietenește și să o aducă înapoi, având pe servitorul lui cu el și doi măgari; și ea l-a adus în casa tatălui ei; și când tatăl fetei l-a văzut, s-a bucurat să îl întâlnească.
ọkọ rẹ̀ lọ sí ibẹ̀ láti rọ̀ ọ́ pé kí ó padà sí ọ̀dọ̀ òun. Nígbà tí ó ń lọ ó mú ìránṣẹ́ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ méjì lọ́wọ́, obìnrin náà mú un wọ inú ilé baba rẹ̀ lọ, nígbà tí baba obìnrin náà rí i ó fi tayọ̀tayọ̀ gbà á.
4 Și socrul său, tatăl fetei, l-a reținut; iar el a rămas cu el trei zile; astfel au mâncat și au băut și au găzduit acolo.
Àna rẹ̀, baba ọmọbìnrin náà rọ̀ ọ́, ó sì borí rẹ̀ láti dá a dúró fún ìgbà díẹ̀, òun sì dúró fún ọjọ́ mẹ́ta, ó ń jẹ, ó ń mu, ó sì ń sùn níbẹ̀.
5 Și s-a întâmplat, în ziua a patra când s-au sculat dis-de-dimineață, că el s-a ridicat să plece și tatăl fetei a spus ginerelui său: Întărește-ți inima cu o bucată de pâine și după aceea mergeți pe drumul vostru.
Ní ọjọ́ kẹrin, wọ́n dìde ní òwúrọ̀ kùtùkùtù òun sì múra láti padà lọ, ṣùgbọ́n baba ọmọbìnrin náà wí fún àna rẹ̀ pé, “Fi ohun jíjẹ díẹ̀ gbé inú ró nígbà náà kí ìwọ máa lọ.”
6 Și s-au așezat și au mâncat și au băut amândoi împreună, fiindcă tatăl fetei a spus bărbatului: Binevoiește, te rog, și rămâi toată noaptea și să ți se veselească inima.
Àwọn méjèèjì sì jùmọ̀ jókòó láti jọ jẹun àti láti jọ mu. Lẹ́yìn èyí ni baba ọmọbìnrin wí pé, “Jọ̀wọ́ dúró ní alẹ́ yìí kí o sì gbádùn ara rẹ.”
7 Și când bărbatul s-a ridicat să plece, socrul său l-a constrâns; de aceea el a găzduit din nou acolo.
Nígbà tí ọkùnrin náà dìde láti máa lọ, baba ìyàwó rẹ̀ rọ̀ ọ́, torí náà ó sùn níbẹ̀ ní alẹ́ ọjọ́ náà.
8 Și s-a sculat dis-de-dimineață în ziua a cincea ca să plece; și tatăl fetei a spus: Întărește-ți inima, te rog. Și au rămas până după-amiază și au mâncat amândoi.
Ní òwúrọ̀ ọjọ́ karùn-ún nígbà tí ó dìde láti lọ, baba ọmọbìnrin wí pé, “Fi oúnjẹ gbé ara ró. Dúró de ọ̀sán!” Àwọn méjèèjì sì jùmọ̀ jọ jẹun.
9 Și când bărbatul s-a ridicat să plece, el și concubina lui și servitorul său, socrul său, tatăl fetei, i-a spus: Iată, ziua se lasă spre seară; vă rog să rămâneți toată noaptea; iată, ziua se apropie de sfârșit, găzduiește aici, ca să ți se veselească inima; și mâine plecați de dimineață pe calea voastră, să te duci acasă.
Nígbà tí ọkùnrin náà, pẹ̀lú àlè àti ìránṣẹ́ rẹ̀, dìde láti máa lọ, àna rẹ̀, baba ọmọbìnrin náà ní, “Wò ó ilẹ̀ ti ń ṣú lọ, dúró níbí, ọjọ́ ti lọ. Dúró kí o sì gbádùn ara rẹ. Ìwọ lè jí ní àárọ̀ kùtùkùtù ọ̀la kí ìwọ sì máa lọ ilé.”
10 Dar bărbatul nu a dorit să rămână acea noapte, ci s-a ridicat și a plecat și a ajuns înaintea Iebusului, care este Ierusalimul; și cu el erau doi măgari înșeuați, concubina lui de asemenea fiind cu el.
Ṣùgbọ́n nítorí pé òun kò fẹ́ dúró mọ́ níbẹ̀ ní òru náà ọkùnrin náà kúrò ó sì gba ọ̀nà Jebusi: ọ̀nà Jerusalẹmu pẹ̀lú àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ méjèèjì tí ó fi dì í ní gàárì àti àlè rẹ̀.
11 Și când erau lângă Iebus, ziua trecuse de mult; și servitorul a spus stăpânului său: Vino, te rog, să ne abatem în această cetate a iebusiților și să găzduim în ea.
Nígbà tí wọ́n súnmọ́ Jebusi tí ilẹ̀ ti fẹ́ ṣú tan, ìránṣẹ́ náà sọ fún ọ̀gá rẹ̀ pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a dúró ní ìlú yìí tí í ṣe ti àwọn ará Jebusi kí a sì sùn níbẹ̀.”
12 Și stăpânul său i-a spus: Nu ne vom abate pe aici în cetatea unui străin, care nu este a copiilor lui Israel; vom trece la Ghibea.
Ọ̀gá rẹ̀ dá a lóhùn pé, “Rárá o, àwa kì yóò wọ ìlú àwọn àjèjì, àwọn tí olùgbé ibẹ̀ kì í ṣe ọmọ Israẹli, a yóò dé Gibeah.”
13 Și a spus servitorului său: Vino și să ne apropiem de unul din aceste locuri pentru a găzdui toată noaptea în Ghibea, sau în Rama.
Ó fi kún un pé, ẹ wá ẹ jẹ́ kí a gbìyànjú kí a dé Gibeah tàbí Rama kí a sùn ní ọ̀kan nínú wọn.
14 Și au trecut și au mers pe calea lor; și soarele a apus asupra lor pe când erau lângă Ghibea, care aparține lui Beniamin.
Wọ́n sì tẹ̀síwájú nínú ìrìnàjò wọn, oòrùn wọ̀ bí wọ́n ti súnmọ́ Gibeah tí ṣe ti àwọn Benjamini.
15 Și s-au abătut acolo, pentru a intra și a găzdui în Ghibea; și când a intrat, s-a așezat jos într-o stradă a cetății, fiindcă nimeni nu i-a primit în casa lui, ca să găzduiască.
Wọ́n yípadà wọ́n lọ sí inú ìlú Gibeah láti wọ̀ síbẹ̀ ní òru náà, wọ́n lọ wọ́n sì jókòó níbi gbọ̀ngàn ìlú náà, ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí ó gbà wọ́n sínú ilé rẹ̀ láti wọ̀ sí.
16 Și, iată, un om bătrân venea de la lucrul său de la câmp, seara, care era de asemenea din muntele Efraim, și el locuia temporar în Ghibea; dar oamenii locului erau beniamiți.
Ní alẹ́ ọjọ́ náà ọkùnrin arúgbó kan láti àwọn òkè Efraimu, ṣùgbọ́n tí ń gbé ní Gibeah (ibẹ̀ ni àwọn ẹ̀yà Benjamini ń gbé) ń ti ibi iṣẹ́ rẹ̀ bọ̀ láti inú oko.
17 Și când și-a ridicat ochii, a văzut pe bărbatul călător în strada cetății; și bătrânul a spus: Unde te duci și de unde vii?
Nígbà tí ó wòkè ó rí arìnrìn-àjò náà ní gbọ̀ngàn ìlú náà, ọkùnrin arúgbó yìí bi í léèrè pé, “Níbo ni ò ń lọ? Níbo ni o ti ń bọ̀?”
18 Iar el i-a spus: Noi trecem din Betleem-Iuda spre latura muntelui lui Efraim; de acolo sunt eu; și am mers la Betleem-Iuda, dar acum merg la casa DOMNULUI; și nu este nimeni să mă primească în casă.
Ọmọ Lefi náà dá a lóhùn pé, “Bẹtilẹhẹmu ti Juda ni àwa ti ń bọ̀, àwa sì ń lọ sí agbègbè tí ó sá pamọ́ ní àwọn òkè Efraimu níbi ti mo ń gbé. Mo ti lọ sí Bẹtilẹhẹmu ti Juda, èmi sì ń lọ sí ilé Olúwa nísinsin yìí. Kò sí ẹni tí ó gbà mí sí ilé rẹ̀.
19 Noi avem deopotrivă paie și nutreț pentru măgarii noștri; și este pâine și vin de asemenea pentru mine și pentru roaba ta și pentru tânărul care este cu servitorii tăi, nu este lipsă de nimic.
Àwa ní koríko àti oúnjẹ tó tó fún àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wa àti oúnjẹ àti wáìnì fún àwa ìránṣẹ́ rẹ—èmi, ìránṣẹ́bìnrin rẹ àti ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú wa. A ò ṣe aláìní ohun kankan.”
20 Și bătrânul a spus: Pace fie cu tine; totuși, să fie toate nevoile tale asupra mea; dar să nu rămâneți în stradă.
Ọkùnrin arúgbó náà sì wí pé. “Àlàáfíà fún ọ, bí ó ti wù kí ó rí, èmi yóò pèsè gbogbo ohun tí o nílò, kìkì pé kí ìwọ má ṣe sun ní ìgboro.”
21 Astfel l-a adus în casa lui și a dat nutreț măgarilor; și și-au spălat picioarele și au mâncat și au băut.
Òun sì mú wa sí ilé rẹ̀, ó ń bọ́ àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti wẹ ẹsẹ̀ wọn, àwọn àlejò náà jẹ, wọ́n mu.
22 Și pe când își veseleau inimile, iată, bărbații cetății, anumiți fii ai lui Belial, au înconjurat casa și au bătut la ușă; și au vorbit bătrânului, stăpânul casei, spunând: Scoate afară pe bărbatul care a intrat în casa ta, ca să îl cunoaștem.
Ǹjẹ́ bí wọ́n ti ń ṣe àríyá, kíyèsi i, àwọn ọkùnrin ìlú náà, àwọn ọmọ Beliali kan, yí ilé náà ká, wọ́n sì ń lu ìlẹ̀kùn; wọ́n sì sọ fún baálé ilé náà ọkùnrin arúgbó náà pé, “Mú ọkùnrin tí ó wọ̀ sínú ilé rẹ wá, kí àwa lè mọ̀ ọ́n.”
23 Și bărbatul, stăpânul casei, a ieșit la ei și le-a spus: Nu, frații mei, nu, vă rog, nu vă purtați atât de stricat; văzând că acest bărbat a intrat în casa mea, nu faceți această nebunie.
Ọkùnrin, baálé ilé náà sì jáde tọ̀ wọ́n lọ, ó sì wí fún un pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́ ẹ̀yin arákùnrin mi, èmi bẹ̀ yín, ẹ má ṣe hùwà búburú; nítorí tí ọkùnrin yìí ti wọ ilé mi, ẹ má ṣe hùwà òmùgọ̀ yìí.
24 Iată, aici este fiica mea, o fecioară și concubina lui; pe ele le voi aduce acum afară, și umiliți-le și faceți cu ele ce vi se pare bine; dar acestui bărbat nu faceți un astfel de lucru nemernic.
Kíyèsi i, ọmọbìnrin mi ni èyí, wúńdíá, àti àlè rẹ̀; àwọn ni èmi ó mú jáde wá nísinsin yìí, kí ẹ̀yin tẹ̀ wọ́n lógo, kí ẹ̀yin ṣe sí wọn bí ó ti tọ́ lójú yín: ṣùgbọ́n ọkùnrin yìí ni kí ẹ̀yin má ṣe hùwà òmùgọ̀ yìí sí.”
25 Dar bărbații nu au dorit să îi dea ascultare; astfel, bărbatul a luat pe concubina sa și a scos-o afară la ei; și ei au cunoscut-o și au abuzat-o toată noaptea până dimineața; și când se ivea dimineața, au lăsat-o să plece.
Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin náà kò fetí sí tirẹ̀. Nítorí náà ọkùnrin náà mú àlè rẹ̀ ó sì tari rẹ̀ jáde sí wọn, wọ́n sì bá a fi ipá lòpọ̀, wọ́n sì fi gbogbo òru náà bá a lòpọ̀, nígbà tí ó di àfẹ̀mọ́júmọ́ wọ́n jọ̀wọ́ rẹ̀ lọ́.
26 Atunci femeia a venit către ziuă și a căzut la ușa casei omului, unde era domnul ei, până s-a luminat.
Nígbà tí ojúmọ́ bẹ̀rẹ̀ sí là obìnrin náà padà lọ sí ilé tí ọ̀gá rẹ̀ wà, ó ṣubú lulẹ̀ lọ́nà, ó sì wà níbẹ̀ títí ó fi di òwúrọ̀.
27 Și domnul ei s-a ridicat dimineața și a deschis ușile casei și a ieșit afară să meargă pe calea sa; și, iată, femeia, concubina sa, era căzută la ușa casei și mâinile ei erau pe prag.
Nígbà tí ọ̀gá rẹ̀ jí tí ó sì dìde ní òwúrọ̀ tí ó sì ṣí ìlẹ̀kùn ilé náà, tí ó sì bọ́ sí òde láti tẹ̀síwájú nínú ìrìnàjò rẹ̀, kíyèsi i àlè rẹ̀ wà ní ṣíṣubú ní iwájú ilé, tí ọwọ́ rẹ̀ sì di òpó ẹnu-ọ̀nà ibẹ̀ mú,
28 Și el i-a spus: Sus și să mergem. Dar nimeni nu a răspuns. Atunci bărbatul a pus-o pe un măgar și bărbatul s-a ridicat și s-a dus spre locul său.
òun sì wí fún obìnrin náà pé, “Dìde jẹ́ kí a máa bá ọ̀nà wa lọ.” Ṣùgbọ́n òun kò dá a lóhùn. Nígbà náà ni ọkùnrin náà gbé e lé orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, ó sì kọjá lọ sí ilé e rẹ̀.
29 Și când a ajuns acasă, a luat un cuțit și a apucat pe concubina sa și a împărțit-o, după oasele ei, în douăsprezece bucăți și a trimis-o în toate ținuturile lui Israel.
Nígbà tí ó dé ilé, ó mú ọ̀bẹ ó sì gé àlè rẹ̀ ní oríkeríke sí ọ̀nà méjìlá, ó sì fi wọ́n ránṣẹ́ sí gbogbo agbègbè Israẹli.
30 Și a fost astfel, că toți cei care au văzut au spus: Nu a mai fost o astfel de faptă și nici nu s-a mai văzut din ziua când copiii lui Israel au ieșit din țara Egiptului până în ziua aceasta; gândiți-vă la aceasta, sfătuiți-vă și vorbiți.
Gbogbo ẹni tí ó rí i sì wí pé, “A kò ti rí i, bẹ́ẹ̀ a kò tí ì ṣe irú nǹkan yìí rí, kì í ṣe láti ọjọ́ tí Israẹli ti jáde tí Ejibiti wá títí di òní olónìí. Ẹ rò ó wò, ẹ gbìmọ̀ràn, kí ẹ sọ fún wa ohun tí a yóò ṣe!”

< Judecătorii 19 >