< Judecătorii 11 >

1 Și Iefta galaaditul era un războinic viteaz și era fiul unei curve; și Galaad născuse pe Iefta.
Jefta ará Gileadi jẹ́ akọni jagunjagun. Gileadi ni baba rẹ̀; ṣùgbọ́n ìyá rẹ̀ jẹ́ panṣágà.
2 Și soția lui Galaad i-a născut fii; și fiii soției lui au crescut și au aruncat afară pe Iefta și i-au spus: Tu nu vei moșteni în casa tatălui nostru, pentru că ești fiul unei femei străine.
Ìyàwó Gileadi sì bí àwọn ọmọkùnrin fún un, nígbà tí àwọn ọmọkùnrin wọ̀nyí dàgbà, wọ́n rán Jefta jáde kúrò nílé, wọ́n wí pé, “Ìwọ kì yóò ní ogún kankan ní ìdílé wa, nítorí pé ìwọ jẹ́ ọmọ obìnrin mìíràn.”
3 Atunci Iefta a fugit de frații săi și a locuit în țara lui Tob; și acolo s-au adunat bărbați de nimic la Iefta și au ieșit cu el.
Jefta sì sá kúrò lọ́dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀, ó sì pàgọ́ sí ilẹ̀ Tobu, ó sì ń gbé níbẹ̀, níbẹ̀ ni àwọn ènìyàn kan ti ń tẹ òfin lójú parapọ̀ láti máa tẹ̀lé e kiri.
4 Și s-a întâmplat, după un timp, că de asemenea copiii lui Amon au făcut război cu Israel.
Ní àsìkò kan, nígbà tí àwọn ará Ammoni dìde ogun sí àwọn Israẹli,
5 Și s-a întâmplat, când copiii lui Amon au făcut război cu Israel, că bătrânii Galaadului au mers să îl aducă pe Iefta din țara lui Tob,
Ó sì ṣe nígbà tí àwọn Ammoni bá Israẹli jagun, àwọn àgbàgbà Gileadi tọ Jefta lọ láti pè é wá láti ilẹ̀ Tobu.
6 Și i-au spus lui Iefta: Vino și fii căpetenia noastră, ca să luptăm cu copiii lui Amon.
Wọ́n wí fún Jefta wí pé, “Wá kí o sì jẹ́ olórí ogun wa kí a lè kọjú ogun sí àwọn ará Ammoni.”
7 Și Iefta a spus bătrânilor Galaadului: Nu m-ați urât și nu m-ați alungat voi din casa tatălui meu, de ce ați venit acum la mine, când sunteți în strâmtorare?
Jefta sì wí fún àwọn àgbàgbà Gileadi pé, “Ṣé kì í ṣe pé ẹ kórìíra mi tí ẹ sì lé mi kúrò ní ilé baba mi? Kí ló dé tí ẹ fi tọ̀ mí wá báyìí nígbà tí ẹ wà nínú wàhálà?”
8 Și bătrânii Galaadului i-au spus lui Iefta: De aceea ne-am întors la tine acum, ca să mergi cu noi și să lupți cu copiii lui Amon și să fii capul nostru peste toți locuitorii Galaadului.
Àwọn àgbà Gileadi sì wí fún Jefta pé, “Nítorí rẹ̀ ni àwa fi yípadà sí ọ báyìí: tẹ̀lé wa, kí a lè dojú ìjà kọ àwọn ará Ammoni, ìwọ yóò sì jẹ olórí wa àti gbogbo àwa tí ń gbé ní Gileadi.”
9 Și Iefta a spus bătrânilor Galaadului: Dacă mă aduceți din nou acasă ca să lupt cu copiii lui Amon și DOMNUL îi va da înaintea mea, voi fi eu capul vostru?
Jefta sì wí fún àwọn àgbàgbà Gileadi pé, “Bí ẹ̀yin bá mú mi padà láti bá àwọn ará Ammoni jà àti tí Olúwa bá fi wọ́n lé mi lọ́wọ́: ṣe èmi yóò jẹ́ olórí yín nítòótọ́?”
10 Și bătrânii Galaadului i-au spus lui Iefta: DOMNUL să fie martor între noi, dacă nu vom face conform cuvintelor tale.
Àwọn àgbàgbà Gileadi sì wí fún Jefta pé, “Àwa fi Olúwa ṣe ẹlẹ́rìí: àwa yóò ṣe ohunkóhun tí o bá wí.”
11 Atunci Iefta a mers cu bătrânii Galaadului și poporul l-a pus cap și căpetenie peste ei, și Iefta și-a rostit toate cuvintele înaintea DOMNULUI în Mițpa.
Jefta sì tẹ̀lé àwọn àgbàgbà Gileadi lọ, àwọn ènìyàn náà sì fi ṣe olórí àti ọ̀gágun wọn. Jefta sì tún sọ gbogbo àwọn ọ̀rọ̀ tí ó ti sọtẹ́lẹ̀ níwájú Olúwa ní Mispa.
12 Și Iefta a trimis mesageri la împăratul fiilor lui Amon, spunând: Ce ai a face cu mine, de ai venit împotriva mea să lupți în țara mea?
Jefta sì rán àwọn oníṣẹ́ sí ọba àwọn ará Ammoni pé, “Kí ni ẹ̀sùn tí o ní sí wa láti fi kàn wá tí ìwọ fi dojú ìjà kọ ilẹ̀ wa?”
13 Și împăratul fiilor lui Amon a răspuns mesagerilor lui Iefta: Pentru că Israel mi-a luat țara, când a ieșit din Egipt, de la Arnon până la Iaboc și până la Iordan; acum de aceea înapoiază acele pământuri în pace.
Ọba àwọn Ammoni dá àwọn oníṣẹ́ Jefta lóhùn pé, “Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli jáde ti Ejibiti wá. Wọ́n gba ilẹ̀ mi láti Arnoni dé Jabbok, àní dé Jordani, nítorí náà dá wọn padà lọ ní àlàáfíà àti ní pẹ̀lẹ́ kùtù.”
14 Și Iefta a trimis din nou mesageri la împăratul fiilor lui Amon;
Jefta sì tún ránṣẹ́ padà sí ọba àwọn ará Ammoni
15 Și i-a spus: Astfel spune Iefta: Israel nu a luat țara Moabului, nici țara copiilor lui Amon,
ó sì wí fún un pé, “Báyìí ni Jefta wí: àwọn ọmọ Israẹli kò gba ilẹ̀ Moabu tàbí ilẹ̀ àwọn ará Ammoni.
16 Ci când Israel a ieșit din Egipt și a umblat prin pustie până la Marea Roșie și a venit la Cades,
Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n jáde kúrò ní Ejibiti àwọn ọmọ Israẹli la aginjù kọjá lọ sí ọ̀nà Òkun Pupa wọ́n sì lọ sí Kadeṣi.
17 Atunci Israel a trimis mesageri la împăratul Edomului, spunând: Te rog, lasă-mă să trec prin țara ta, dar împăratul Edomului a refuzat să le dea ascultare. Și la fel au trimis la împăratul Moabului, dar a refuzat și el; și Israel a rămas în Cades.
Nígbà náà Israẹli rán àwọn oníṣẹ́ sí ọba Edomu pé, ‘Gbà fún wa láti gba ilẹ̀ rẹ̀ kọjá,’ ṣùgbọ́n ọba Edomu kò fetí sí wọn. Wọ́n tún ránṣẹ́ sí ọba Moabu bákan náà òun náà kọ̀. Nítorí náà Israẹli dúró sí Kadeṣi.
18 Atunci au umblat prin pustie și au ocolit țara Edomului și țara Moabului și au venit în partea dinspre est a țării Moabului și au tăbărât dincolo de Arnon, dar nu au intrat în hotarul Moabului, pentru că Arnonul era hotarul Moabului.
“Wọ́n rin aginjù kọjá, wọ́n pẹ́ àwọn ilẹ̀ Edomu àti ti Moabu sílẹ̀, nígbà tí wọ́n gba apá ìlà-oòrùn Moabu, wọ́n sì tẹ̀dó sí apá kejì Arnoni. Wọn kò wọ ilẹ̀ Moabu, nítorí pé ààlà rẹ̀ ni Arnoni wà.
19 Și Israel a trimis mesageri la Sihon, împăratul amoriților, împăratul Hesbonului, și Israel i-a spus: Lasă-ne, te rugăm, să trecem prin țara ta până la locul meu.
“Nígbà náà ni Israẹli rán àwọn oníṣẹ́ sí Sihoni ọba àwọn ará Amori, ẹni tí ń ṣe àkóso ní Heṣboni, wọ́n sì wí fún un pé, ‘Jẹ́ kí a la ilẹ̀ rẹ kọjá lọ sí ibùgbé wa.’
20 Dar Sihon nu a avut încredere în Israel ca să îl lase să treacă prin ținutul său, ci Sihon a adunat tot poporul său și a tăbărât în Iahaț și a luptat împotriva lui Israel.
Ṣùgbọ́n Sihoni kò gba Israẹli gbọ́ (kò fọkàn tán an) láti jẹ́ kí ó kọjá. Ó kó gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀ jọ, ó sì tẹ̀dó sí Jahisa láti bá Israẹli jagun.
21 Și DOMNUL Dumnezeul lui Israel a dat pe Sihon și pe tot poporul lui în mâna lui Israel și i-au bătut; și Israel a luat în stăpânire toată țara amoriților, locuitorii acelei țări.
“Olúwa Ọlọ́run Israẹli sì fi Sihoni àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ lé Israẹli lọ́wọ́, wọ́n sì ṣẹ́gun wọn. Israẹli sì gba gbogbo ilẹ̀ àwọn ará Amori tí wọ́n ń gbé ní agbègbè náà,
22 Și au luat în stăpânire toate ținuturile amoriților, de la Arnon până la Iaboc și de la pustie până la Iordan.
wọ́n gbà gbogbo agbègbè àwọn ará Amori, láti Arnoni tí ó fi dé Jabbok, àti láti aginjù dé Jordani.
23 Astfel că acum DOMNUL Dumnezeul lui Israel i-a alungat pe amoriți dinaintea poporului său Israel; și să îl stăpânești tu?
“Wàyí o, nígbà tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli, ti lé àwọn ará Amori kúrò níwájú àwọn ènìyàn rẹ̀; Israẹli, ẹ̀tọ́ wo ni ẹ ní láti gba ilẹ̀ náà?
24 Nu stăpânești tu ce ți-a dat în stăpânire Chemoș, dumnezeul tău? Astfel pe oricine DOMNUL Dumnezeul nostru îi va alunga dinaintea noastră, pe ei îi vom stăpâni.
Ǹjẹ́ ìwọ kì yóò ha gba èyí tí Kemoṣi òrìṣà rẹ fi fún ọ? Bákan náà àwa yóò gba èyíkéyìí tí Olúwa Ọlọ́run wa fi fún wa.
25 Și acum, ești tu cu ceva mai bun decât Balac, fiul lui Țipor, împăratul Moabului? S-a certat el vreodată cu Israel, sau a luptat el vreodată împotriva lor?
Ǹjẹ́ ìwọ ha sàn ju Balaki ọmọ Sippori, ọba Moabu lọ? Ǹjẹ́ òun ha ṣe gbólóhùn asọ̀ pẹ̀lú Israẹli bí? Tàbí òun dojú ìjà kọ wọ́n rí bí?
26 Cât timp a locuit Israel în Hesbon și în orașele lui, și în Aroer și în orașele lui, și în toate cetățile care sunt pe malurile Arnonului, trei sute de ani, de ce nu le-ați luat înapoi în acel timp?
Fún ọ̀ọ́dúnrún ọdún ni Israẹli fi ṣe àtìpó ní Heṣboni, Aroeri àti àwọn ìgbèríko àti àwọn ìlú tí ó yí Arnoni ká. Èéṣe tí ìwọ kò fi gbà wọ́n padà ní àsìkò náà?
27 De aceea nu eu am păcătuit împotriva ta, ci tu îmi faci rău, războindu-te împotriva mea; DOMNUL Judecătorul să fie judecător astăzi între copiii lui Israel și copiii lui Amon.
Èmi kọ́ ni ó ṣẹ̀ ọ́, ṣùgbọ́n ìwọ ni ó ṣẹ̀ mí nípa kíkógun tọ̀ mí wá. Jẹ́ kí Olúwa olùdájọ́, ṣe ìdájọ́ lónìí láàrín àwọn ọmọ Israẹli àti àwọn ará Ammoni.”
28 Cu toate acestea împăratul copiilor lui Amon nu a dat ascultare la cuvintele pe care i le-a trimis Iefta.
Ṣùgbọ́n ọba àwọn Ammoni kò fetí sí iṣẹ́ tí Jefta rán sí i.
29 Atunci Duhul DOMNULUI a venit peste Iefta și el a trecut prin Galaad și Manase și a trecut la Mițpa din Galaad și de la Mițpa din Galaad a trecut la copiii lui Amon.
Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé Jefta òun sì la Gileadi àti Manase kọjá. Ó la Mispa àti Gileadi kọjá láti ibẹ̀, ó tẹ̀síwájú láti bá àwọn ará Ammoni jà.
30 Și Iefta a făcut o promisiune DOMNULUI și a spus: Dacă vei da negreșit pe copiii lui Amon în mâinile mele,
Jefta sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa pé, “Bí ìwọ bá fi àwọn ará Ammoni lé mi lọ́wọ́,
31 Atunci va fi astfel, că ce va ieși pe ușile casei mele pentru a mă întâmpina, când mă voi întoarce în pace de la copiii lui Amon, va fi al DOMNULUI și îl voi oferi ca ofrandă arsă.
yóò sì ṣe, ohunkóhun tí ó bá jáde láti ẹnu-ọ̀nà ilé mi láti wá pàdé mi, nígbà tí èmi bá ń padà bọ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Ammoni ní àlàáfíà, yóò jẹ́ ti Olúwa, èmi yóò sì fi rú ẹbọ bí ọrẹ ẹbọ sísun.”
32 Astfel Iefta a trecut la copiii lui Amon să lupte împotriva lor, și DOMNUL i-a dat în mâinile lui.
Jefta sì jáde lọ láti bá àwọn ará Ammoni jagun, Olúwa sì fi wọ́n lé e lọ́wọ́.
33 Și i-a bătut de la Aroer până la Minit, douăzeci de cetăți, și până la câmpia viilor, cu un foarte mare măcel. Astfel copiii lui Amon au fost supuși înaintea copiilor lui Israel.
Òun sì ṣẹ́gun wọn, ó sì pa wọ́n ní à pa tán láti Aroeri títí dé agbègbè Minniti, ó jẹ́ ogún ìlú, títí dé Abeli-Keramimu. Báyìí ni Israẹli ti ṣẹ́gun àwọn ará Ammoni.
34 Și Iefta a venit la Mițpa, în casa lui, și, iată, fiica sa a ieșit afară pentru a-l întâmpina cu tamburine și cu dansuri, și ea era singurul lui copil; în afară de ea nu avea fiu sau fiică.
Nígbà tí Jefta padà sí ilé rẹ̀ ní Mispa, wò ó, ọmọ rẹ̀ obìnrin ń jáde bọ̀ wá pàdé rẹ̀ pẹ̀lú timbrili àti ijó. Òun ni ọmọ kan ṣoṣo tí ó ní: kò ní ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin mìíràn yàtọ̀ sí òun nìkan.
35 Și s-a întâmplat, când a văzut-o, că și-a sfâșiat hainele și a spus: Vai, fiica mea! Ce mult m-ai doborât; și tu ești dintre cei care mă tulbură, pentru că mi-am deschis gura către DOMNUL și nu mă pot întoarce.
Ní ìgbà tí ó rí i ó fa aṣọ rẹ̀ ya ní ìbànújẹ́, ó sì ké wí pé, “Háà! Ọ̀dọ́mọbìnrin mi, ìwọ fún mi ní ìbànújẹ́ ọkàn ìwọ sì rẹ̀ mí sílẹ̀ gidigidi, nítorí pé èmi ti ya ẹnu mi sí Olúwa ní ẹ̀jẹ́, èmi kò sì le sẹ́ ẹ̀jẹ́ mi.”
36 Iar ea i-a spus: Tatăl meu, dacă ți-ai deschis gura către DOMNUL, fă-mi conform cu ce a ieșit din gura ta, pentru că DOMNUL s-a răzbunat pentru tine pe dușmanii tăi, pe copiii lui Amon.
Ọmọ náà sì dáhùn pé, “Baba mi bí ìwọ bá ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa, ṣe sí mi gẹ́gẹ́ bí ìlérí rẹ, ní báyìí tí Olúwa ti gba ẹ̀san fún ọ lára àwọn ọ̀tá rẹ, àwọn ará Ammoni.
37 Și ea a spus tatălui său: Să mi se facă lucrul acesta: lasă-mă singură două luni, să urc și să cobor în munți și să îmi plâng fecioria, eu și tovarășele mele.
Ṣùgbọ́n yọ̀ǹda ìbéèrè kan yìí fún mi, gbà mí láààyè oṣù méjì láti rìn ká orí àwọn òkè, kí n sọkún pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ mi torí mo jẹ́ wúńdíá tí n kò sì ní lè ṣe ìgbéyàwó.”
38 Iar el a spus: Du-te. Și a trimis-o pentru două luni, și ea a mers cu însoțitoarele ei și și-a plâns fecioria pe munți.
Jefta dá lóhùn pé, “Ìwọ lè lọ.” Ó sì gbà á láààyè láti lọ fún oṣù méjì. Òun àti àwọn ọmọbìnrin yòókù lọ sí orí àwọn òkè, wọ́n sọkún nítorí pé kì yóò lè ṣe ìgbéyàwó.
39 Și s-a întâmplat, la sfârșitul a două luni, că ea s-a întors la tatăl ei, care i-a făcut conform cu promisiunea sa pe care o făcuse, și ea nu cunoscuse bărbat. Și a ajuns un obicei în Israel,
Lẹ́yìn oṣù méjì náà, ó padà tọ baba rẹ̀ wá òun sì ṣe sí i bí ẹ̀jẹ́ tí ó ti jẹ́. Ọmọ náà sì jẹ́ wúńdíá tí kò mọ ọkùnrin rí. Èyí sì bẹ̀rẹ̀ àṣà kan ní Israẹli
40 Că, din an în an, fiicele lui Israel mergeau să plângă pe fiica lui Iefta galaaditul, patru zile pe an.
wí pé ní ọjọ́ mẹ́rin láàrín ọdún àwọn obìnrin Israẹli a máa lọ láti ṣọ̀fọ̀ àti ṣe ìrántí ọmọbìnrin Jefta ti Gileadi.

< Judecătorii 11 >