< Joshua 6 >
1 Și Ierihonul era cu totul închis din cauza copiilor lui Israel; nimeni nu ieșea și nimeni nu intra.
Wàyí o, a ti há Jeriko mọ́lé gágá nítorí àwọn ọmọ Israẹli, ẹnikẹ́ni kò jáde, ẹnikẹ́ni kò sì wọlé.
2 Și DOMNUL i-a spus lui Iosua: Vezi, am dat în mâna ta Ierihonul și pe împăratul său și pe cei viteji la luptă.
Nígbà náà ni Olúwa wí fún Joṣua pé, “Wò ó, mo ti fi Jeriko lé ọ lọ́wọ́ pẹ̀lú ọba rẹ̀ àti àwọn jagunjagun rẹ̀.
3 Și să înconjurați cetatea, toți bărbații de război, și să mergeți în jurul cetății o dată. Astfel să faci șase zile.
Ẹ wọ́de ogun yí ìlú náà ká lẹ́ẹ̀kan pẹ̀lú gbogbo àwọn jagunjagun. Ẹ ṣe èyí fún ọjọ́ mẹ́fà.
4 Și șapte preoți să poarte înaintea chivotului șapte trâmbițe din coarne de berbec; și în ziua a șaptea să înconjurați cetatea de șapte ori și preoții să sufle din trâmbițe.
Jẹ́ kí àwọn àlùfáà méje gbé fèrè ìwo àgbò ní iwájú àpótí ẹ̀rí. Ní ọjọ́ keje, ẹ wọ́de ogun yí ìlú náà ká ní ìgbà méje, pẹ̀lú àwọn àlùfáà tí ń fọn fèrè.
5 Și se va întâmpla, când vor sufla lung cu coarnele de berbec și când veți auzi sunetul trâmbiței, că tot poporul va striga cu un strigăt mare; și zidul cetății se va prăbuși pe loc și poporul va urca fiecare drept înaintea lui.
Nígbà tí ẹ bá gbọ́ ohùn fèrè náà, kí àwọn ènìyàn hó yèè ní igbe ńlá, nígbà náà ni odi ìlú náà yóò sì wó lulẹ̀, àwọn ènìyàn yóò sì lọ sí òkè, olúkúlùkù yóò sì wọ inú rẹ̀ lọ tààrà.”
6 Și Iosua, fiul lui Nun, a chemat preoții și le-a spus: Ridicați chivotul legământului și lăsați șapte preoți să poarte șapte trâmbițe din coarne de berbec înaintea chivotului DOMNULUI.
Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua ọmọ Nuni pe àwọn àlùfáà ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa náà kí àwọn àlùfáà méje tí ó ru fèrè ìwo wà ní iwájú u rẹ̀.”
7 Și a spus poporului: Treceți și înconjurați cetatea și lăsați pe cel înarmat să treacă înaintea chivotului DOMNULUI.
Ó sì pàṣẹ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ lọ, kí ẹ sì yí ìlú náà ká pẹ̀lú àwọn olùṣọ́ tí ó hámọ́ra kọjá ní iwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa.”
8 Și s-a întâmplat, când Iosua a vorbit poporului, cei șapte preoți, purtând cele șapte trâmbițe din coarne de berbec, au trecut înaintea DOMNULUI și au suflat din trâmbițe; și chivotul legământului DOMNULUI îi urma.
Nígbà tí Joṣua ti bá àwọn ènìyàn sọ̀rọ̀ tán, àwọn àlùfáà méje tí wọ́n gbé fèrè méje ní iwájú Olúwa kọjá sí iwájú, wọ́n sì fọn fèrè wọn, àpótí ẹ̀rí Olúwa sì tẹ̀lé wọn.
9 Și bărbații înarmați mergeau înaintea preoților care suflau din trâmbițe și ariergarda oștirii venea după chivot, preoții mergând și suflând din trâmbițe.
Àwọn olùṣọ tí ó hámọ́ra sì lọ níwájú àwọn àlùfáà tí ń fọn fèrè, olùṣọ́ ẹ̀yìn sì tẹ̀lé àpótí ẹ̀rí náà. Ní gbogbo àsìkò yìí fèrè sì ń dún.
10 Și Iosua a poruncit poporului, spunând: Să nu strigați, nici să nu vi se audă vocea și niciun cuvânt să nu vă iasă din gură, până în ziua în care vă voi spune să strigați; atunci să strigați.
Ṣùgbọ́n Joṣua tí pàṣẹ fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ kò gbọdọ̀ kígbe ogun, ẹ kò gbọdọ̀ gbé ohùn yín sókè, ẹ má ṣe sọ ọ̀rọ̀ kan títí ọjọ́ tí èmi yóò sọ fún un yín pé kí ẹ hó. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò sì hó!”
11 Astfel chivotul DOMNULUI a înconjurat cetatea, mergând împrejurul ei o dată; și au intrat în tabără și s-au adăpostit în tabără.
Bẹ́ẹ̀ ni ó mú kí àpótí ẹ̀rí Olúwa yí ìlú náà ká, ó sì yí i ká lẹ́ẹ̀kan. Nígbà náà ni àwọn ènìyàn náà padà sí ibùdó, wọ́n sì gbé ibẹ̀ fún alẹ́ náà.
12 Și Iosua s-a sculat dis-de-dimineață și preoții au luat chivotul DOMNULUI.
Joṣua sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, àwọn àlùfáà sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa.
13 Și șapte preoți, purtând șapte trâmbițe din coarne de berbec înaintea chivotului DOMNULUI, mergeau și suflau din trâmbițe și bărbații înarmați au mers înaintea lor; dar ariergarda a venit după chivotul DOMNULUI, preoții mergând și suflând din trâmbițe.
Àwọn àlùfáà méje tí ó gbé ìpè ìwo àgbò méje ń lọ níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa, wọ́n sì ń fọ́n àwọn ìpè: àwọn tí ó hámọ́ra ogun ń lọ níwájú u wọn; àwọn ọmọ tó wà lẹ́yìn sì ń tọ àpótí ẹ̀rí Olúwa lẹ́yìn, àwọn àlùfáà sì ń fọn ìpè bí wọ́n ti ń lọ.
14 Și a doua zi au înconjurat cetatea o dată și s-au întors în tabără: astfel au făcut șase zile.
Ní ọjọ́ kejì, wọ́n yí ìlú náà ká lẹ́ẹ̀kan wọ́n sì padà sí ibùdó. Wọ́n sì ṣe èyí fún ọjọ́ mẹ́fà.
15 Și s-a întâmplat, în a șaptea zi, că s-au sculat devreme, în zori de zi și au înconjurat cetatea în același fel de șapte ori; doar în acea zi au înconjurat cetatea de șapte ori.
Ní ọjọ́ keje, wọ́n dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ní àfẹ̀mọ́júmọ́, wọ́n sì wọ́de ogun yí ìlú náà ká ní ìgbà méje, gẹ́gẹ́ bí i ti ìṣáájú, ní ọjọ́ keje nìkan ṣoṣo ni wọ́n wọ́de ogun yí ìlú náà ká nígbà méje.
16 Și s-a întâmplat, la a șaptea oară, când preoții au suflat din trâmbițe, că Iosua a spus poporului: Strigați, fiindcă DOMNUL v-a dat cetatea!
Ní ìgbà keje, nígbà tí àwọn àlùfáà fọn fèrè, Joṣua pàṣẹ fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ hó! Nítorí pé Olúwa ti fún un yín ní ìlú náà.
17 Și cetatea va fi blestemată de la DOMNUL, ea și toți câți sunt înăuntru; doar curva Rahab va trăi, ea și toți care sunt cu ea în casă, pentru că a ascuns pe mesagerii pe care noi i-am trimis.
Ìlú náà àti gbogbo ohun tí ó wà níbẹ̀ ni yóò jẹ́ ìyàsọ́tọ̀ fún Olúwa. Rahabu tí ó jẹ́ panṣágà nìkan àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú u rẹ̀ ni a ó dá sí; nítorí tí ó pa àwọn ayọ́lẹ̀wò tí á rán mọ́.
18 Și voi, în orice fel, păziți-vă de lucrul blestemat, ca nu cumva să vă faceți blestemați, când luați din lucrul blestemat și faceți tabăra lui Israel un blestem și o tulburați.
Ẹ pa ara yín mọ́ kúrò nínú ohun ìyàsọ́tọ̀ fún ìparun, kí ẹ̀yin kí ó má ba à ṣojú kòkòrò nípa mímú nínú àwọn ohun ìyàsọ́tọ̀. Bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ ẹ ó sọ ibùdó Israẹli di ìparun. Kí ẹ sì mú wàhálà wá sórí i rẹ̀.
19 Dar tot argintul și aurul și vasele de aramă și fier, sunt consacrate DOMNULUI; vor intra în trezoreria DOMNULUI.
Gbogbo fàdákà àti wúrà àti ohun èlò idẹ àti irin jẹ́ mímọ́ fún Olúwa, wọ́n yóò wá sínú ìṣúra Olúwa.”
20 Astfel poporul a strigat când preoții au suflat din trâmbițe; și s-a întâmplat, când poporul a auzit sunetul trâmbiței și poporul a strigat cu un mare strigăt, că zidul s-a prăbușit pe loc, astfel încât poporul a intrat în cetate, fiecare om drept înaintea lui și au luat cetatea.
Nígbà tí àwọn àlùfáà fọn ìpè, àwọn ènìyàn náà sì hó. Ó sì ṣe, bí àwọn ènìyàn ti gbọ́ ìró ìpè, tí àwọn ènìyàn sì hó ìhó ńlá, odi ìlú náà wó lulẹ̀ bẹẹrẹ; bẹ́ẹ̀ ni olúkúlùkù ya wọ inú ìlú náà lọ tààrà, wọ́n sì kó ìlú náà.
21 Și au nimicit în întregime tot ce era în cetate, deopotrivă bărbat și femeie, tânăr și bătrân și bou și oaie și măgar, cu ascuțișul sabiei.
Wọ́n ya ìlú náà sọ́tọ̀ fún Olúwa àti fún ìparun, wọ́n sì fi idà run gbogbo ohun alààyè ní ìlú náà—ọkùnrin àti obìnrin, ọ́mọdé, àti àgbà, màlúù, àgùntàn àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
22 Dar Iosua le spusese celor doi bărbați care spionaseră țara: Intrați în casa curvei și scoateți afară de acolo femeia și tot ce are, precum i-ați jurat.
Joṣua sì sọ fún àwọn ọkùnrin méjì tí wọ́n ti wá ṣe ayọ́lẹ̀wò ilẹ̀ náà pé, “Ẹ lọ sí ilé panṣágà nì, kí ẹ sì mu jáde àti gbogbo ohun tí í ṣe tirẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹ tí búra fún un.”
23 Și tinerii care erau spioni au intrat și au scos afară pe Rahab și pe tatăl ei și pe mama ei și pe frații ei și tot ce avea ea; și au scos toate rudele ei și i-au lăsat în afara taberei lui Israel.
Bẹ́ẹ̀ ní àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó lọ ṣe ayọ́lẹ̀wò wọlé lọ, wọ́n sì mú Rahabu jáde, baba rẹ̀, ìyá rẹ̀, àwọn arákùnrin rẹ̀ àti ohun gbogbo tí ó ní. Wọ́n sì mú gbogbo ìdílé rẹ̀ jáde, wọ́n sì fi wọ́n sí ibìkan ní ìta ibùdó àwọn ará Israẹli.
24 Și au ars cetatea cu foc și tot ce era în ea; doar argintul, aurul și vasele de aramă și de fier, le-au pus în trezoreria casei DOMNULUI.
Nígbà náà ni wọ́n sun gbogbo ìlú náà àti gbogbo ohun tí ó wà nínú u rẹ̀, ṣùgbọ́n wọ́n fi fàdákà, wúrà ohun èlò idẹ àti irin sínú ìṣúra ilé Olúwa.
25 Și Iosua a lăsat în viață pe curva Rahab și casa tatălui ei și tot ce avea ea; și ea a locuit în Israel până în această zi, deoarece a ascuns pe mesagerii pe care Iosua i-a trimis să spioneze Ierihonul.
Ṣùgbọ́n Joṣua dá Rahabu panṣágà pẹ̀lú gbogbo ìdílé e rẹ̀ àti gbogbo ẹni tí í ṣe tirẹ̀ sí nítorí pé, ó pa àwọn ọkùnrin tí Joṣua rán gẹ́gẹ́ bí ayọ́lẹ̀wò sí Jeriko mọ́. Ó sì ń gbé láàrín ará Israẹli títí di òní yìí.
26 Și Iosua i-a conjurat în acel timp, spunând: Blestemat fie înaintea DOMNULUI, omul care se ridică și construiește această cetate Ierihon; el va pune temelia acesteia pe întâiul lui născut și pe cel mai tânăr fiu al său va ridica porțile ei.
Ní àkókò náà Joṣua sì búra pé, “Ègún ni fún ẹni náà níwájú Olúwa tí yóò dìde, tí yóò sì tún ìlú Jeriko kọ́: “Pẹ̀lú ikú àkọ́bí ọmọ rẹ̀ ni yóò fi pilẹ̀ rẹ̀; ikú àbíkẹ́yìn rẹ̀ ní yóò fi gbé ìlẹ̀kùn bodè rẹ̀ ró.”
27 Astfel DOMNUL a fost cu Iosua; și faima lui s-a răspândit în toată țara.
Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wà pẹ̀lú Joṣua; òkìkí rẹ̀ sì kàn ká gbogbo ilẹ̀ náà.