< Joshua 5 >

1 Și s-a întâmplat, când au auzit toți împărații amoriților, care erau pe partea de vest a Iordanului și toți împărații canaaniților, care erau lângă mare, că DOMNUL a secat apele Iordanului dinaintea copiilor lui Israel, până am trecut, că li s-a topit inima și nu mai era suflare în ei, din cauza copiilor lui Israel.
Nígbà tí gbogbo àwọn ọba Amori ti ìlà-oòrùn Jordani àti gbogbo àwọn ọba Kenaani tí ń bẹ létí òkun gbọ́ bí Olúwa ti mú Jordani gbẹ ní iwájú àwọn ọmọ Israẹli títí ti a fi kọjá, ọkàn wọn pami, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò ní ìgboyà mọ́ láti dojúkọ àwọn ọmọ Israẹli.
2 În timpul acela, DOMNUL i-a spus lui Iosua: Fă-ți cuțite ascuțite și circumcide din nou pe copiii lui Israel a doua oară.
Nígbà náà ni Olúwa wí fún Joṣua pé, “Fi akọ òkúta ṣe abẹ kí o sì kọ àwọn ọmọ Israẹli ní ilà ní ìgbà ẹ̀ẹ̀kejì.”
3 Și Iosua și-a făcut cuțite ascuțite și a circumcis pe copiii lui Israel pe dealul prepuțurilor.
Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua sì ṣe abẹ akọ òkúta, ó sì kọ àwọn ọmọ Israẹli ní ilà, ní Gibiati-Haralotu.
4 Și acesta este motivul pentru care Iosua i-a circumcis: Tot poporul care a ieșit din Egipt, cei de parte bărbătească, adică toți bărbații de război, au murit în pustiu, pe drum, după ce au ieșit din Egipt.
Wàyí o, ìdí tí Joṣua fi kọ wọ́n nílà nìyìí. Gbogbo àwọn ọkùnrin tí ó ti Ejibiti jáde wá, gbogbo àwọn ọkùnrin ogun kú ní aginjù ní ọ̀nà lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.
5 Iar tot poporul care ieșise era circumcis, dar tot poporul care se născuse în pustiu, pe drum, pe când au ieșit din Egipt, nu fuseseră circumciși.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, gbogbo àwọn ọkùnrin tó jáde láti Ejibiti ni a ti kọ ní ilà, síbẹ̀ gbogbo ènìyàn tí a bí nínú aginjù lẹ́yìn tí wọ́n jáde ní Ejibiti ni wọn kò kọ ní ilà.
6 Deoarece copiii lui Israel au umblat patruzeci de ani prin pustie, până au fost nimiciți toți oamenii care erau bărbați de război ieșiți din Egipt, pentru că nu au ascultat de vocea DOMNULUI, cărora DOMNUL le-a jurat că nu le va arăta țara pe care DOMNUL a jurat părinților lor că ne-o va da, țară în care curge lapte și miere.
Àwọn ará Israẹli rìn ní aginjù fún ogójì ọdún títí gbogbo àwọn ọkùnrin tí ó tó ogun n jà nígbà tí wọ́n kúrò ni Ejibiti fi kú, nítorí wọn kò gbọ́rọ̀ sí Olúwa. Nítorí Olúwa ti búra fún wọn pé wọn kò ní rí ilẹ̀ tí òun ṣe ìlérí fún àwọn baba wọn láti fi fun wa, ilẹ̀ tí ń sàn fún wàrà àti fún oyin.
7 Și copiii lor, pe care i-a ridicat în locul lor, pe aceia i-a circumcis Iosua, fiindcă erau necircumciși, pentru că nu i-au circumcis pe drum.
Bẹ́ẹ̀ ni ó gbé àwọn ọmọ wọn dìde dípò wọn, àwọn wọ̀nyí sì ni Joṣua kọ ní ilà. Wọ́n wà ní aláìkọlà nítorí a kò tí ì kọ wọ́n ní ilà ní ojú ọ̀nà.
8 Și s-a întâmplat, când au terminat de circumcis tot poporul, că au rămas la locurile lor în tabără, până s-au vindecat.
Lẹ́yìn ìgbà tí gbogbo orílẹ̀-èdè náà kọ ilà tan, wọ́n dúró ní ibi tí wọ́n wà ní ibùdó títí ilà wọn fi jinná.
9 Și DOMNUL i-a spus lui Iosua: Astăzi am îndepărtat ocara Egiptului de pe voi. De aceea numele locului este chemat Ghilgal până în această zi.
Nígbà náà ní Olúwa wí fún Joṣua pé, “Ní òní ni mo yí ẹ̀gàn Ejibiti kúrò ní orí yín.” Nítorí náà ni a ṣe ń pe orúkọ ibẹ̀ ní Gilgali títí ó fi di òní yìí.
10 Și copiii lui Israel au așezat tabăra în Ghilgal și au ținut paștele în a paisprezecea zi a lunii, către seară, în câmpiile Ierihonului.
Ní ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kẹrìnlá oṣù náà, nígbà tí wọ́n pàgọ́ ní Gilgali ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Jeriko, àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe ọdún àjọ ìrékọjá.
11 Și au mâncat din grâul vechi al țării a doua zi după paște, azimă și grâu prăjit, în aceeași zi.
Ní ọjọ́ kejì àjọ ìrékọjá, ní ọjọ́ náà gan an ni, wọ́n jẹ nínú àwọn ìre oko ilẹ̀ náà: àkàrà aláìwú, àti ọkà yíyan.
12 Și mana a încetat a doua zi după ce au mâncat din grâul vechi al țării; și copiii lui Israel nu au mai avut mană, ci au mâncat din rodul țării lui Canaan în acel an.
Manna náà sì tan ní ọjọ́ kejì tí wọ́n jẹ oúnjẹ tí ilẹ̀ náà mú jáde, kò sì sí manna kankan mọ́ fún àwọn ará Israẹli, ṣùgbọ́n ní ọdún náà wọ́n jẹ ìre oko ilẹ̀ Kenaani.
13 Și s-a întâmplat, când Iosua era lângă Ierihon, că și-a ridicat ochii și a privit și, iată, un om stătea în picioare înaintea lui cu sabia scoasă, în mână. Și Iosua a mers la el și i-a spus: Ești pentru noi sau pentru potrivnicii noștri?
Nígbà tí Joṣua súnmọ́ Jeriko, ó wo òkè ó sì rí ọkùnrin kan tí ó dúró ní iwájú rẹ̀ pẹ̀lú idà ní ọwọ́ rẹ̀. Joṣua sì tọ̀ ọ́ lọ, ó sì bi í pé, “Ǹjẹ́ ìwọ wà fún wa tàbí fún ọ̀tá a wa?”
14 Iar el a spus: Nu, ci am venit acum ca și căpetenie a oștirii DOMNULUI. Și Iosua a căzut cu fața la pământ și s-a închinat și i-a spus: Ce spune domnul meu servitorului său?
“Kì í ṣe fún èyíkéyìí ó fèsì, ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí olórí ogun Olúwa ni mo wá nísinsin yìí.” Nígbà náà ni Joṣua sì wólẹ̀ ní iwájú u rẹ̀ ní ìbẹ̀rù, ó sì bi í léèrè, “Kí ni Olúwa ní í sọ fún ìránṣẹ́ rẹ̀?”
15 Și căpetenia oștirii DOMNULUI i-a spus lui Iosua: Scoate-ți sandaua din picior, fiindcă locul pe care stai este sfânt. Și Iosua a făcut astfel.
Olórí ogun Olúwa sì dá a lóhùn pé, “Bọ́ sálúbàtà rẹ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ, nítorí pé ibi tí ìwọ dúró sí yìí, ilẹ̀ mímọ́ ni.” Joṣua sì ṣe bẹ́ẹ̀.

< Joshua 5 >