< Joshua 18 >

1 Și toată adunarea copiilor lui Israel s-a adunat la Șilo și au așezat acolo tabernacolul întâlnirii. Și țara era supusă înaintea lor.
Gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli péjọ ní Ṣilo, wọ́n si kọ́ àgọ́ ìpàdé ní ibẹ̀. Gbogbo ilẹ̀ náà sì wà ní abẹ́ àkóso wọn,
2 Și au rămas între copiii lui Israel șapte triburi care nu își primiseră încă moștenirea.
ṣùgbọ́n ó ku ẹ̀yà méje nínú àwọn ọmọ Israẹli tí kò tí ì gba ogún ìní wọn.
3 Și Iosua a spus copiilor lui Israel: Până când vă veți lenevi să mergeți să luați în stăpânire țara pe care v-a dat-o DOMNUL Dumnezeul părinților voștri?
Báyìí ni Joṣua sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, “Báwo ni ẹ̀yin yóò ṣe dúró pẹ́ tó, kí ẹ tó gba ilẹ̀ ìní tí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín ti fi fún yín?
4 Dați dintre voi trei oameni de fiecare trib și îi voi trimite și să se ridice și să meargă prin țară și să o descrie conform moștenirii lor și să vină la mine.
Ẹ yan àwọn ọkùnrin mẹ́ta nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan. Èmi yóò rán wọn jáde láti lọ bojú wo ilẹ̀ náà káàkiri, wọn yóò sì ṣe àpèjúwe rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìní ẹni kọ̀ọ̀kan. Nígbà náà ni wọn yóò padà tọ̀ mí wá.
5 Și să o împartă în șapte părți; Iuda să rămână în ținutul său spre sud, iar casa lui Iosif să rămână în ținutul său spre nord.
Ẹ̀yin yóò sì pín ilẹ̀ náà sí ọ̀nà méje kí Juda dúró sí ilẹ̀ rẹ̀ ni ìhà gúúsù àti ilé Josẹfu ní ilẹ̀ rẹ̀ ní ìhà àríwá.
6 Să faceți așadar o descriere a țării în șapte părți și să o aduceți aici, la mine, ca să arunc aici sorț pentru voi înaintea DOMNULUI Dumnezeul nostru.
Lẹ́yìn ìgbà tí ẹ bá kọ àpèjúwe ọ̀nà méjèèje ilẹ̀ náà, ẹ mú wọn wá sí ọ̀dọ̀ mi ní ibí, èmi ó sì ṣẹ́ kèké fún yín ní iwájú Olúwa Ọlọ́run wa.
7 Dar leviții nu au parte între voi, fiindcă preoția DOMNULUI este moștenirea lor. Și Gad, Ruben și jumătate din tribul lui Manase și-au primit dincolo de Iordan, la est, moștenirea pe care le-a dat-o Moise, servitorul DOMNULUI.
Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Lefi kò ní ìpín ní àárín yín, nítorí iṣẹ́ àlùfáà. Olúwa ni ìní wọ́n. Gadi, Reubeni àti ìdajì ẹ̀yà Manase, ti gba ìní wọn ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani. Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti fi fún wọn.”
8 Și bărbații s-au ridicat și au plecat; și Iosua a poruncit celor care s-au dus să descrie țara, spunând: Mergeți și umblați prin țară și faceți o descriere a ei și întoarceți-vă la mine, ca să arunc sorț pentru voi, înaintea DOMNULUI, aici la Șilo.
Bí àwọn ọkùnrin náà ti bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn láti fojú díwọ̀n ilẹ̀ náà, Joṣua pàṣẹ fún wọn pé, “Ẹ lọ kí ẹ sì fojú díwọ̀n ilẹ̀ náà káàkiri, kí ẹ sì kọ àpèjúwe rẹ̀. Lẹ́yìn náà kí ẹ padà tọ̀ mí wá, kí èmi kí ò lè ṣẹ́ kèké fún yin ní ibí ní Ṣilo ní iwájú Olúwa.”
9 Și bărbații s-au dus și au trecut prin țară și au descris-o într-o carte, în șapte părți, după cetăți; și au venit din nou la Iosua în tabără, la Șilo.
Báyìí ni àwọn ọkùnrin náà lọ, wọ́n sì la ilẹ̀ náà já. Wọ́n sì kọ àpèjúwe rẹ̀ sí orí ìwé kíká ní ìlú, ní ọ̀nà méje, wọ́n sì padà tọ Joṣua lọ ní ibùdó ní Ṣilo.
10 Și Iosua a aruncat sorț pentru ei la Șilo, înaintea DOMNULUI; și Iosua a împărțit acolo țara copiilor lui Israel, conform împărțirilor lor.
Joṣua sì ṣẹ́ gègé fún wọn ní Ṣilo ní iwájú Olúwa, Joṣua sì pín ilẹ̀ náà fún àwọn Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìpín ẹ̀yà wọn ní ibẹ̀.
11 Și a ieșit sorțul tribului copiilor lui Beniamin, după familiile lor, și ținutul sorțului lor a ieșit între copiii lui Iuda și copiii lui Iosif.
Ìbò náà sì wá sórí ẹ̀yà Benjamini, ní agbo ilé, agbo ilé. Ilẹ̀ ìpín wọn sì wà láàrín ti ẹ̀yà Juda àti Josẹfu.
12 Și granița lor dinspre partea de nord era de la Iordan; și granița urca spre latura Ierihonului spre nord și se urca prin munți spre vest; și ieșirile lui erau la pustiul Bet-Aven.
Ní ìhà àríwá ààlà wọn bẹ̀rẹ̀ ní Jordani, ó kọjá lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ Jeriko ní ìhà àríwá, ó sì forí lé ìwọ̀-oòrùn sí ìlú òkè, jáde sí aginjù Beti-Afeni.
13 Și granița trecea de acolo spre Luz către latura de sud a Luzului, care este Betel; și granița cobora spre Atarot-Adar, de lângă dealul care este în partea de sud a Bet-Horonului de jos.
Láti ibẹ̀ ààlà náà tún kọjá lọ sí ìhà gúúsù ní ọ̀nà Lusi (tí í ṣe Beteli) ó sì dé Atarotu-Addari, ní orí òkè tí ó wà ní gúúsù Beti-Horoni.
14 Și granița a fost trasă de acolo și înconjura către colțul mării, spre sud de la dealul care este înaintea Bet-Horonului către sud; și ieșirile lui erau la Chiriat-Baal, care este Chiriat-Iearim, o cetate a copiilor lui Iuda; aceasta era partea dinspre vest.
Láti òkè tí ó kọjú sí Beti-Horoni ní gúúsù ààlà náà yà sí gúúsù ní ìhà ìwọ̀-oòrùn, ó sì jáde sí Kiriati-Baali (tí í ṣe Kiriati-Jearimu), ìlú àwọn ènìyàn Juda. Èyí ni ìhà ìwọ̀-oòrùn.
15 Și partea de sud era de la capătul Chiriat-Iearimului; și ținutul ieșea spre vest și ieșea spre izvorul apelor Neftoah.
Ìhà gúúsù bẹ̀rẹ̀ ní ìpẹ̀kun Kiriati-Jearimu ní ìwọ̀-oòrùn, ààlà náà wà ní ibi ìsun omi Nefitoa.
16 Și granița cobora la capătul muntelui care este înaintea văii fiului lui Hinom, care este în valea uriașilor spre nord și cobora până la valea lui Hinom, în latura de sud a iebusiților și cobora la En-Roguel;
Ààlà náà lọ sí ìsàlẹ̀ ẹsẹ̀ òkè tí ó kọjú sí àfonífojì Beni-Hinnomu, àríwá àfonífojì Refaimu. O sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí àfonífojì Hinnomu sí apá gúúsù gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè ìlú Jebusi, ó sì lọ bẹ́ẹ̀ títí dé En-Rogeli.
17 Și a fost trasă de la nord și ieșea la En-Șemeș și ieșea spre Ghelilot, care este în fața urcușului Adumim și cobora la piatra lui Bohan, fiul lui Ruben,
Nígbà náà ni ó yípo sí ìhà àríwá, ó sì lọ sí Ẹni-Ṣemeṣi, ó tẹ̀síwájú dé Geliloti tí ó kọjú sí òkè Adummimu, ó sì sọ̀kalẹ̀ sí ibi Òkúta Bohani ọmọ Reubeni.
18 Și trecea spre latura din dreptul Arabei spre nord și cobora până la Araba.
Ó tẹ̀síwájú títí dé gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè Beti-Araba, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí aginjù.
19 Și granița trecea spre latura Bet-Hoglei spre nord; și ieșirile ținutului erau la golful de nord al Mării Sărate, la capătul de sud al Iordanului; acesta era ținutul de sud.
Nígbà náà ni ó lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè Beti-Hogla, ó sì jáde ní àríwá etí bèbè Òkun Iyọ̀, ní ẹnu odò Jordani ní gúúsù. Èyí ni ààlà ti gúúsù.
20 Și Iordanul era granița lui în partea de est. Aceasta era moștenirea copiilor lui Beniamin, cu ținuturile ei de jur-împrejur, după familiile lor.
Odò Jordani sí jẹ́ ààlà ní ìhà ìlà-oòrùn. Ìwọ̀nyí ní àwọn ààlà ti ó sàmì sí ìní àwọn ìdílé Benjamini ní gbogbo àwọn àyíká wọn.
21 Și cetățile tribului copiilor lui Beniamin, după familiile lor, erau: Ierihon și Bet-Hogla și valea Chețiț,
Ẹ̀yà Benjamini ní agbo ilé, agbo ilé ni àwọn ìlú wọ̀nyí: Jeriko, Beti-Hogla, Emeki-Keṣiṣi,
22 Și Bet-Araba și Țemaraim și Betel,
Beti-Araba, Semaraimu, Beteli,
23 Și Avim și Para și Ofra,
Affimu, Para, Ofira
24 Și Chefar-Amonai și Ofni și Gaba; douăsprezece cetăți cu satele lor.
Kefari, Ammoni, Ofini àti Geba; àwọn ìlú méjìlá àti ìletò wọn.
25 Gabaon și Rama și Beerot,
Gibeoni, Rama, Beeroti,
26 Și Mițpa și Chefira și Moța,
Mispa, Kefira, Mosa,
27 Și Rechem și Iirpeel și Tareala,
Rekemu, Irpeeli, Tarala,
28 Și Țela și Elef și Iebus, care este Ierusalim, Ghibeat și Chiriat; paisprezece cetăți cu satele lor. Aceasta este moștenirea copiilor lui Beniamin, după familiile lor.
Ṣela, Haelefi, ìlú Jebusi (tí í ṣe Jerusalẹmu), Gibeah àti Kiriati, àwọn ìlú mẹ́rìnlá àti ìletò wọn. Èyí ni ìní Benjamini fún ìdílé rẹ̀.

< Joshua 18 >