< Ioan 10 >
1 Adevărat, adevărat vă spun: Cel care nu intră pe ușă în staulul oilor, ci se cațără pe altă parte, acela este hoț și tâlhar.
“Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ẹni tí kò bá gba ẹnu-ọ̀nà wọ inú agbo àgùntàn, ṣùgbọ́n tí ó bá gba ibòmíràn gun òkè, òun náà ni olè àti ọlọ́ṣà.
2 Dar cel care intră pe ușă este păstorul oilor.
Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ti ẹnu-ọ̀nà wọlé, Òun ni olùṣọ́ àwọn àgùntàn.
3 Portarul îi deschide și oile aud vocea lui; iar el își cheamă oile pe nume și le conduce afară.
Òun ni aṣọ́nà yóò ṣílẹ̀kùn fún; àwọn àgùntàn gbọ́ ohùn rẹ̀, ó sì pe àwọn àgùntàn tirẹ̀ lórúkọ, ó sì ṣe amọ̀nà wọn jáde.
4 Și după ce își scoate oile, merge înaintea lor și oile îl urmează, pentru că ele îi cunosc vocea.
Nígbà tí ó bá sì ti mú àwọn àgùntàn tirẹ̀ jáde, yóò síwájú wọn, àwọn àgùntàn yóò sì máa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, nítorí tí wọ́n mọ ohùn rẹ̀.
5 Și nu vor urma nicidecum un străin, ci vor fugi de el, pentru că nu cunosc vocea străinilor.
Wọn kò jẹ́ tọ àlejò lẹ́yìn, ṣùgbọ́n wọn a sá kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀, nítorí tí wọn kò mọ ohùn àlejò.”
6 Isus le-a spus această parabolă, dar ei nu au înțeles cele ce le vorbea.
Òwe yìí ni Jesu pa fún wọn, ṣùgbọ́n òye ohun tí nǹkan wọ̀nyí tí ó ń sọ fún wọn kò yé wọn.
7 Atunci Isus le-a spus din nou: Adevărat, adevărat vă spun: Eu sunt ușa oilor.
Nítorí náà Jesu tún wí fún wọn pé, “Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, Èmi ni ìlẹ̀kùn àwọn àgùntàn.
8 Toți cei ce au venit înainte de mine, sunt hoți și tâlhari; dar oile nu i-au ascultat.
Olè àti ọlọ́ṣà ni gbogbo àwọn tí ó ti wà ṣáájú mi, ṣùgbọ́n àwọn àgùntàn kò gbọ́ tiwọn.
9 Eu sunt ușa; dacă intră cineva prin mine va fi salvat și va intra și va ieși și va găsi pășune.
Èmi ni ìlẹ̀kùn, bí ẹnìkan bá bá ọ̀dọ̀ mi wọlé, òun ni a ó gbàlà, yóò wọlé, yóò sì jáde, yóò sì rí koríko.
10 Hoțul nu vine decât pentru a fura și a ucide și a nimici. Eu am venit ca ele să aibă viață și să o aibă din abundență.
Olè kì í wá bí kò ṣe láti jalè, láti pa, àti láti parun; èmi wá kí wọn lè ní ìyè, àní kí wọn lè ní i lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
11 Eu sunt păstorul cel bun; păstorul cel bun își dă viața pentru oi.
“Èmi ni olùṣọ́-àgùntàn rere, olùṣọ́-àgùntàn rere fi ọkàn rẹ̀ lélẹ̀ nítorí àwọn àgùntàn.
12 Dar cel angajat și care nu este păstor, ale cărui oi nu sunt ale lui, vede lupul venind și lasă oile și fuge; și lupul le apucă și risipește oile.
Ṣùgbọ́n alágbàṣe, tí kì í ṣe olùṣọ́-àgùntàn, ẹni tí àwọn àgùntàn kì í ṣe tirẹ̀, ó rí ìkookò ń bọ̀, ó sì fi àgùntàn sílẹ̀, ó sì fọ́n wọn ká kiri.
13 Cel angajat fuge, pentru că este angajat și nu îi pasă de oi.
Òun sálọ nítorí tí ó jẹ́ alágbàṣe, kò sì náání àwọn àgùntàn.
14 Eu sunt păstorul cel bun și le cunosc pe ale mele și sunt cunoscut de ale mele.
“Èmi ni olùṣọ́-àgùntàn rere, mo sì mọ àwọn tèmi, àwọn tèmi sì mọ̀ mí.
15 Așa cum mă cunoaște Tatăl, tot așa îl cunosc și eu pe Tatăl; și îmi dau viața pentru oi.
Gẹ́gẹ́ bí Baba ti mọ̀ mí, tí èmi sì mọ Baba, mo sì fi ọkàn mi lélẹ̀ nítorí àwọn àgùntàn.
16 Mai am și alte oi, care nu sunt din acest staul; și pe acelea trebuie să le aduc, și ele vor auzi vocea mea; și va fi un [singur] staul și un [singur] păstor.
Èmi sì ní àwọn àgùntàn mìíràn, tí kì í ṣe agbo yìí: àwọn ni èmi yóò mú wá pẹ̀lú, wọn yóò sì gbọ́ ohùn mi; wọn ó sì jẹ́ agbo kan, olùṣọ́-àgùntàn kan.
17 Din această cauză Tatăl mă iubește, pentru că eu îmi dau viața, ca iarăși să o iau.
Nítorí náà ni Baba mi ṣe fẹ́ràn mi, nítorí tí mo fi ẹ̀mí mi lélẹ̀, kí èmi lè tún gbà á.
18 Nimeni nu o ia de la mine, ci eu o dau de la mine. Am putere să o dau și am putere să o iau din nou. Această poruncă am primit-o de la Tatăl meu.
Ẹnìkan kò gbà á lọ́wọ́ mi, ṣùgbọ́n mo fi í lélẹ̀, mo sì lágbára láti tún gbà á. Àṣẹ yìí ni mo ti gbà wá láti ọ̀dọ̀ Baba mi.”
19 De aceea din cauza acestor cuvinte din nou a fost dezbinare între iudei.
Nítorí náà ìyapa tún wà láàrín àwọn Júù nítorí ọ̀rọ̀ wọ̀nyí.
20 Și mulți dintre ei au spus: Are drac și este nebun; de ce îl ascultați?
Ọ̀pọ̀ nínú wọn sì wí pé, “Ó ní ẹ̀mí èṣù, orí rẹ̀ sì dàrú; èéṣe tí ẹ̀yin fi ń gbọ́rọ̀ rẹ̀?”
21 Alții au spus: Acestea nu sunt cuvintele unuia care are drac. Poate un drac să deschidă ochii orbilor?
Àwọn mìíràn wí pé, “Ìwọ̀nyí kì í ṣe ọ̀rọ̀ ẹni tí ó ní ẹ̀mí èṣù. Ẹ̀mí èṣù lè la ojú àwọn afọ́jú bí?”
22 Și la Ierusalim era sărbătoarea dedicării și era iarnă.
Àkókò náà sì jẹ́ àjọ̀dún ìyàsímímọ́ ní Jerusalẹmu, ni ìgbà òtútù.
23 Și Isus se plimba prin templu, în porticul lui Solomon.
Jesu sì ń rìn ní tẹmpili, ní ìloro Solomoni.
24 Atunci iudeii l-au înconjurat și i-au spus: Până când ne faci să ne îndoim? Dacă tu ești Cristosul, spune-ne pe față.
Nítorí náà àwọn Júù wá dúró yí i ká, wọ́n sì wí fún un pé, “Ìwọ ó ti mú wa ṣe iyèméjì pẹ́ tó? Bí ìwọ bá ni Kristi náà, wí fún wa gbangba.”
25 Isus le-a răspuns: V-am zis și nu ați crezut; faptele pe care le fac eu în numele Tatălui meu, ele aduc mărturie despre mine.
Jesu dá wọn lóhùn pé, “Èmi ti wí fún yín, ẹ̀yin kò sì gbàgbọ́; iṣẹ́ tí èmi ń ṣe lórúkọ Baba mi, àwọn ni ó ń jẹ́rìí mi.
26 Dar voi nu credeți, fiindcă nu sunteți dintre oile mele, după cum v-am spus.
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbàgbọ́, nítorí ẹ̀yin kò sí nínú àwọn àgùntàn mi, gẹ́gẹ́ bí mo tí wí fún yín.
27 Oile mele aud vocea mea și eu le cunosc și ele mă urmează;
Àwọn àgùntàn mi ń gbọ́ ohùn mi, èmi sì mọ̀ wọ́n, wọn a sì máa tọ̀ mí lẹ́yìn.
28 Și eu le dau viață eternă; și nicidecum nu vor pieri niciodată și nimeni nu le va smulge din mâna mea. (aiōn , aiōnios )
Èmi sì fún wọn ní ìyè àìnípẹ̀kun; wọn kì yóò sì ṣègbé láéláé, kò sí ẹni tí ó lè já wọn gbà kúrò lọ́wọ́ mi. (aiōn , aiōnios )
29 Tatăl meu, care mi le-a dat, este mai mare decât toți; și nimeni nu le poate smulge din mâna Tatălui meu.
Baba mi, ẹni tí ó fi wọ́n fún mi pọ̀ ju gbogbo wọn lọ; kò sì ṣí ẹni tí ó lè já wọn gbà kúrò lọ́wọ́ Baba mi.
30 Eu și Tatăl una suntem.
Ọ̀kan ni èmi àti Baba mi.”
31 Atunci iudeii au luat din nou pietre ca să îl ucidă cu pietre.
Àwọn Júù sì tún mú òkúta, láti sọ lù ú.
32 Isus le-a răspuns: V-am arătat multe fapte bune de la Tatăl meu; pentru care din aceste fapte mă ucideți cu pietre?
Jesu dá wọn lóhùn pé, “Ọ̀pọ̀lọpọ̀ iṣẹ́ rere ni mo fihàn yín láti ọ̀dọ̀ Baba mi wá, nítorí èwo nínú iṣẹ́ wọ̀nyí ni ẹ̀yin ṣe sọ mí ní òkúta?”
33 Iudeii i-au răspuns, zicând: Nu pentru o lucrare bună te ucidem cu pietre, ci pentru blasfemie și pentru că tu, fiind om, te faci pe tine însuți Dumnezeu.
Àwọn Júù sì dá a lóhùn pé, “Àwa kò sọ ọ́ lókùúta nítorí iṣẹ́ rere, ṣùgbọ́n nítorí ọ̀rọ̀-òdì, àti nítorí ìwọ tí í ṣe ènìyàn ń fi ara rẹ pe Ọlọ́run.”
34 Isus le-a răspuns: Nu este scris în legea voastră: Eu am spus: Sunteți dumnezei?
Jesu dá wọn lóhùn pé, “A kò ha tí kọ ọ́ nínú òfin yín pé, ‘Mo ti wí pé, Ọlọ́run ni ẹ̀yin jẹ́’?
35 Dacă i-a numit dumnezei pe cei la care a venit cuvântul lui Dumnezeu și scriptura nu poate fi desființată,
Bí ó bá pè wọ́n ní ‘ọlọ́run,’ àwọn ẹni tí a fi ọ̀rọ̀ Ọlọ́run fún, a kò sì lè ba ìwé mímọ́ jẹ́.
36 Voi spuneți despre acela pe care Tatăl l-a sfințit și l-a trimis în lume: Tu blasfemiezi, pentru că am spus: Sunt Fiul lui Dumnezeu?
Kín ni ẹyin ha ń wí ní ti ẹni tí Baba yà sọ́tọ̀, tí ó sì rán sí ayé kín lo de ti ẹ fi ẹ̀sùn kàn mi pé mò ń sọ̀rọ̀-òdì nítorí pé mo sọ pé, ‘Èmi ni Ọmọ Ọlọ́run.’
37 Dacă nu fac faptele Tatălui meu, să nu mă credeți.
Bí èmi kò bá ṣe iṣẹ́ Baba mi, ẹ má ṣe gbà mí gbọ́.
38 Dar dacă le fac, chiar dacă nu mă credeți, credeți faptele ca să știți și să credeți că Tatăl este în mine și eu în el.
Ṣùgbọ́n bí èmi bá ṣe wọ́n, bí ẹ̀yin kò tilẹ̀ gbà mí gbọ́, ẹ gbà iṣẹ́ náà gbọ́, kí ẹ̀yin ba à lè mọ̀, kí ó sì lè yé yín pé, Baba wà nínú mi, èmi sì wà nínú rẹ̀.”
39 De aceea căutau din nou să îl prindă, dar el a scăpat din mâna lor.
Wọ́n sì tún ń wá ọ̀nà láti mú un: ó sì bọ́ lọ́wọ́ wọn.
40 Și s-a dus iarăși dincolo de Iordan, în locul unde boteza Ioan la început; și a rămas acolo.
Ó sì tún kọjá lọ sí apá kejì Jordani sí ibi tí Johanu ti kọ́kọ́ ń bamitiisi; níbẹ̀ ni ó sì jókòó.
41 Și mulți au venit la el și au spus: Ioan într-adevăr nu a făcut niciun miracol, dar tot ce a spus Ioan despre omul acesta, era adevărat.
Àwọn ènìyàn púpọ̀ sì wá sọ́dọ̀ rẹ̀, wọ́n sì wí pé, “Johanu kò ṣe iṣẹ́ àmì kan, Ṣùgbọ́n òtítọ́ ni ohun gbogbo tí Johanu sọ nípa ti ọkùnrin yìí.”
42 Și acolo mulți au crezut în el.
Àwọn ènìyàn púpọ̀ níbẹ̀ sì gbà á gbọ́.