< Iov 30 >

1 Dar acum cei ce sunt mai tineri decât mine mă iau în derâdere, pe ai căror părinți i-aș fi disprețuit încât să îi așez cu câinii turmei mele.
“Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, àwọn tí mo gbà ní àbúrò ń fi mí ṣe ẹlẹ́yà baba ẹni tí èmi kẹ́gàn láti tò pẹ̀lú àwọn ajá nínú agbo ẹran mi.
2 Da, la ce mi-ar folosi tăria mâinilor lor, în cei care bătrânețea a pierit?
Kí ni ìwúlò agbára ọwọ́ wọn sí mi, níwọ̀n ìgbà tí agbára wọn ti fi wọ́n sílẹ̀?
3 Singuri, din lipsă și foamete, fugind în pustie de mult pustiită și secătuită.
Wọ́n rù nítorí àìní àti ìyàn wọ́n ń rìn káàkiri ní ilẹ̀ gbígbẹ ní ibi ìkọ̀sílẹ̀ ní òru.
4 Care taie nalbă de pe lângă tufișuri și rădăcini de ienupăr ca hrană a lor.
Àwọn ẹni tí ń já ewé iyọ̀ ní ẹ̀bá igbó; gbogbo igikígi ni oúnjẹ jíjẹ wọn.
5 Ei au fost alungați dintre oameni, (care au strigat după ei ca după un hoț);
A lé wọn kúrò láàrín ènìyàn, àwọn ènìyàn sì pariwo lé wọn lórí bí ẹní pariwo lé olè lórí.
6 Ca să locuiască în coastele văilor, în peșteri ale pământului și în stânci.
A mú wọn gbe inú pàlàpálá òkúta àfonífojì, nínú ihò ilẹ̀ àti ti òkúta.
7 Printre tufișuri au zbierat; sub urzici s-au adunat.
Wọ́n ń dún ní àárín igbó wọ́n kó ara wọn jọ pọ̀ ní abẹ́ ẹ̀gún neteli.
8 Erau copii de nebuni, da, copii de oameni josnici; erau mai ticăloși decât pământul.
Àwọn ọmọ ẹni tí òye kò yé, àní àwọn ọmọ lásán, a sì lé wọn jáde kúrò ní orí ilẹ̀.
9 Și acum sunt cântecul lor, da, sunt zicătoarea lor.
“Ǹjẹ́ nísinsin yìí, àwọn ọmọ wọn ń fi mí ṣe ẹlẹ́yà nínú orin; àní èmi di ẹni ìṣọ̀rọ̀ sí láàrín wọn.
10 Ei mă detestă, fug departe de mine și nu se abțin să mă scuipe în față.
Wọ́n kórìíra mi; wọ́n sá kúrò jìnnà sí mi, wọn kò sì bìkítà láti tutọ́ sí mi lójú.
11 Pentru că mi-a dezlegat frânghia și m-a chinuit, ei de asemenea și-au dat frâu liber înaintea mea.
Nítorí Ọlọ́run ti tú okùn ìyè mi, ó sì pọ́n mi lójú; àwọn pẹ̀lú sì dẹ ìdẹ̀kùn níwájú mi.
12 Tinerii se ridică peste dreapta mea; ei îmi împing deoparte picioarele și își ridică împotriva mea căile nimicirii lor.
Àwọn ènìyàn lásán dìde ní apá ọ̀tún mi; wọ́n tì ẹsẹ̀ mi kúrò, wọ́n sì la ipa ọ̀nà ìparun sílẹ̀ dè mí.
13 Ei îmi distrug cărarea, profită de nenorocirea mea, nu au ajutor.
Wọ́n da ipa ọ̀nà mi rú; wọ́n sì sọ ìparun mi di púpọ̀, àwọn tí kò ní olùrànlọ́wọ́.
14 Au venit peste mine ca apele printr-o spărtură largă, în pustiire s-au rostogolit peste mine.
Wọ́n ya sí mi bí i omi tí ó ya gbuuru; ní ariwo ńlá ni wọ́n rọ́ wá.
15 Terori s-au întors asupra mea, ei îmi urmăresc sufletul ca vântul; și bunăstarea mea trece ca un nor.
Ẹ̀rù ńlá bà mí; wọ́n lépa ọkàn mi bí ẹ̀fúùfù, àlàáfíà mi sì kọjá lọ bí àwọ̀ sánmọ̀.
16 Și acum sufletul meu este turnat peste mine; zilele nenorocirii m-au apucat.
“Àti nísinsin yìí, ayé mi n yòrò lọ díẹ̀díẹ̀; ọjọ́ ìpọ́njú mi dì mímú.
17 Oasele îmi sunt străpunse în mine pe timpul nopții și tendoanele mele nu au odihnă.
Òru gún mi nínú egungun mi, èyí tí ó bù mí jẹ kò sì sinmi.
18 Prin marea forță a bolii mele este îmbrăcămintea mea schimbată, mă leagă împrejur ca gulerul cămășii mele.
Nípa agbára ńlá rẹ̀ Ọlọ́run wà bí aṣọ ìbora fún mi, ó sì lẹ̀ mọ́ mi ní ara yíká bí aṣọ ìlekè mi.
19 El m-a aruncat în mocirlă și am devenit ca țărâna și cenușa.
Ọlọ́run ti mú mi lọ sínú ẹrẹ̀, èmi sì dàbí eruku àti eérú.
20 Strig către tine și nu mă asculți; mă ridic în picioare și nu iei aminte la mine.
“Èmi ké pè ọ́ ìwọ Ọlọ́run, ṣùgbọ́n ìwọ kò dá mi lóhùn; èmi dìde dúró ìwọ sì wò mí lásán.
21 Ai devenit crud față de mine, cu mâna ta puternică mi te opui.
Ìwọ padà di ẹni ìkà sí mi; ọwọ́ agbára rẹ ni ìwọ fi dè mí ní ọ̀nà.
22 Tu mă ridici spre vânt, mă faci să călăresc pe el și îmi topești ființa.
Ìwọ gbé mi sókè sí inú ẹ̀fúùfù, ìwọ mú mi fò lọ, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ sì sọ mí di asán pátápátá.
23 Fiindcă știu că mă vei aduce la moarte și la casa rânduită pentru toți cei vii.
Èmi sá à mọ̀ pé ìwọ yóò mú mi lọ sínú ikú, sí ilé ìpéjọ tí a yàn fún gbogbo alààyè.
24 Totuși el nu își va întinde mâna spre mormânt, deși ei strigă la nimicirea lui.
“Bí ó ti wù kí ó rí, ẹnìkan kí yóò ha nawọ́ rẹ̀ nígbà ìṣubú rẹ̀, tàbí kì yóò ké nínú ìparun rẹ̀.
25 Nu am plâns pentru cel ce era în necaz? Nu a fost sufletul meu întristat pentru cel sărac?
Èmi kò ha sọkún bí fún ẹni tí ó wà nínú ìṣòro? Ọkàn mi kò ha bàjẹ́ fún tálákà bí?
26 Când căutam binele, atunci răul a venit; și când am așteptat lumina, a venit întunericul.
Nígbà tí mo fojú ṣọ́nà fún àlàáfíà, ibi sì dé; nígbà tí mo dúró de ìmọ́lẹ̀, òkùnkùn sì dé.
27 Adâncurile mele fierbeau și nu se odihneau; zilele necazului mă întâmpinau.
Ikùn mí n ru kò sì sinmi, ọjọ́ ìpọ́njú ti dé bá mi.
28 Umblam jelind, fără soare; m-am ridicat în picioare și am strigat în adunare.
Èmí ń rìn kiri nínú ọ̀fọ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe nínú oòrùn; èmi dìde dúró ní àwùjọ mo sì kígbe fún ìrànlọ́wọ́.
29 Sunt frate dragonilor și însoțitor bufnițelor.
Èmi ti di arákùnrin ìkookò, èmi di ẹgbẹ́ àwọn ògòǹgò.
30 Pielea mi se înnegrește pe mine și oasele mi se ard de arșiță.
Àwọ̀ mi di dúdú ní ara mi; egungun mi sì jórun fún ooru.
31 Harpa de asemenea mi s-a prefăcut în jelire și instrumentul meu de suflat în vocea celor ce plâng.
Ohun èlò orin mi pẹ̀lú sì di ti ọ̀fọ̀, àti ìpè orin mi sì di ohùn àwọn tí ń sọkún.

< Iov 30 >