< Iov 3 >

1 După aceasta, Iov și-a deschis gura și și-a blestemat ziua.
Ẹ̀yìn èyí ní Jobu yanu, ó sì fi ọjọ́ ìbí rẹ̀ ré
2 Și Iov a vorbit și a spus:
Jobu sọ, ó sì wí pé,
3 Să piară ziua în care m-am născut și noaptea în care a fost spus: Un copil de parte bărbătească este conceput.
“Kí ọjọ́ tí a bí mi kí ó di ìgbàgbé, àti òru ni, nínú èyí tí a wí pé, ‘A lóyún ọmọkùnrin kan!’
4 Să fie acea zi întuneric; Dumnezeu să nu îi dea atenție din înalt și să nu strălucească lumina peste ea.
Kí ọjọ́ náà kí ó já si òkùnkùn, kí Ọlọ́run kí ó má ṣe kà á sí láti ọ̀run wá; bẹ́ẹ̀ ni kí ìmọ́lẹ̀ kí ó má ṣe mọ́ sí i.
5 Să o întineze întunericul și umbra morții; să locuiască un nor peste ea; să o înspăimânte întunecimea zilei.
Kí òkùnkùn àti òjìji ikú fi ṣe ti ara wọn; kí àwọsánmọ̀ kí ó bà lé e; kí ìṣúdudu ọjọ́ kí ó pa láyà.
6 Cât despre acea noapte, întunericul să o apuce; să nu fie alăturată zilelor anului, să nu vină la numărul lunilor.
Kí òkùnkùn kí ó ṣú bo òru náà biribiri, kí ó má ṣe yọ pẹ̀lú ọjọ́ ọdún náà: kí a má ṣe kà a mọ́ iye ọjọ́ oṣù.
7 Iată, acea noapte să fie solitară, nicio voce de bucurie să nu intre în ea.
Kí òru náà kí ó yàgàn; kí ohun ayọ̀ kan kí ó má ṣe wọ inú rẹ̀ lọ.
8 Să o blesteme cei ce blestemă ziua, care sunt gata să își înalțe jelirea.
Kí àwọn tí í fi ọjọ́ gégùn ún kí o fi gégùn ún, tí wọ́n mura tán láti ru Lefitani sókè.
9 Stelele amurgului acesteia să fie întuneric; să caute lumină, dar să nu găsească; nici să nu vadă răsăritul zilei,
Kí ìràwọ̀ òwúrọ̀ ọjọ́ rẹ̀ kí ó ṣókùnkùn; kí ó má wá ìmọ́lẹ̀, ṣùgbọ́n kí ó máa mọ́ sí i, bẹ́ẹ̀ ni kí ó má ṣe rí àfẹ̀mọ́júmọ́
10 Pentru că nu a închis ușile pântecelui mamei mele, nici nu a ascuns întristare de la ochii mei.
nítorí tí kò sé ìlẹ̀kùn inú ìyá mi, láti pa ìbànújẹ́ rẹ́ ní ojú mi.
11 De ce nu am murit eu din pântece? De ce nu mi-am dat eu duhul când am ieșit din pântece?
“Èéṣe tí èmi kò fi kú láti inú wá, tàbí tí èmi kò kú ní ìgbà tí mo ti inú jáde wá?
12 De ce m-au întâmpinat genunchii? Sau sânii ca să îi sug?
Èéṣe tí orúnkún wá pàdé mi, tàbí ọmú tí èmi yóò mu?
13 Căci acum aș zace și aș tăcea, aș dormi, atunci aș fi avut odihnă,
Ǹjẹ́ nísinsin yìí èmi ìbá ti dùbúlẹ̀ jẹ́ẹ́; èmi ìbá ti sùn, èmi ìbá ti sinmi
14 Cu împărați și sfătuitori ai pământului, care și-au zidit locuri pustii;
pẹ̀lú àwọn ọba àti ìgbìmọ̀ ayé tí wọ́n mọ ilé fún ara wọn wá dùbúlẹ̀ nínú ìsọdahoro.
15 Sau cu prinți care au avut aur, care și-au umplut casele cu argint;
Tàbí pẹ̀lú àwọn ọmọ-aládé tí ó ní wúrà, tí wọ́n sì fi fàdákà kun ilé wọn.
16 Sau ca o naștere ascunsă, nelatimp, nu aș mai fi fost; ca prunci care nu au văzut niciodată lumina.
Tàbí bí ọlẹ̀ tí a sin, èmi kì bá ti sí: bí ọmọ ìṣunú tí kò rí ìmọ́lẹ̀?
17 Acolo cei stricați încetează a tulbura; și acolo cei obosiți au odihnă.
Níbẹ̀ ni ẹni búburú ṣíwọ́ ìyọnilẹ́nu, níbẹ̀ ni ẹni àárẹ̀ wà nínú ìsinmi.
18 Acolo prizonierii se odihnesc împreună; nu aud vocea opresorului.
Níbẹ̀ ni àwọn ìgbèkùn sinmi pọ̀, wọn kò gbóhùn amúnisìn mọ́.
19 Cei mici și cei mari sunt acolo; și servitorul este liber de stăpânul lui.
Àti èwe àti àgbà wà níbẹ̀, ẹrú sì di òmìnira kúrò lọ́wọ́ olówó rẹ̀.
20 Pentru ce se dă lumină celui în nefericire și viață celui amărât în suflet,
“Nítorí kí ni a ṣe fi ìmọ́lẹ̀ fún òtòṣì, àti ìyè fún ọlọ́kàn kíkorò,
21 Care tânjesc după moarte, dar ea nu vine; și sapă după ea mai mult decât după tezaure ascunse;
tí wọ́n dúró de ikú, ṣùgbọ́n òun kò wá, tí wọ́n wá a jù ìṣúra tí a bò mọ́lẹ̀ pamọ́ lọ.
22 Care se bucură peste măsură și se veselesc când pot găsi mormântul?
Ẹni tí ó yọ̀ gidigidi, tí inú wọ́n sì dùn nígbà tí wọ́n wá ibojì òkú rí?
23 De ce se dă lumină unui om a cărui cale este ascunsă și pe care Dumnezeu l-a îngrădit?
Kí ni a fi ìmọ́lẹ̀ fún ẹni tí ọ̀nà rẹ̀ fi ara pamọ́ fún, tí Ọlọ́run sì ṣọgbà dí mọ́ ká?
24 Căci suspinul meu vine înainte să mănânc și răcnetele mele sunt turnate ca apele.
Nítorí pé èémí-ẹ̀dùn wà ṣáájú oúnjẹ mi; ìkérora mi sì tú jáde bí omi.
25 Pentru că lucrul de care m-am temut foarte mult a venit asupra mea și de ceea ce m-am temut m-a ajuns.
Nítorí pé ohun náà tí mo bẹ̀rù gidigidi ni ó dé bá mi yìí, àti ohun tí mo fòyà rẹ̀ bá mi ó sì ṣubú lù mí.
26 Nu am avut nici siguranță, nici odihnă, nici tăcere; totuși tulburarea a venit asupra mea.
Èmi wà láìní àlàáfíà, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò ní ìsinmi; bẹ́ẹ̀ ni èmi kò ni ìfàyàbalẹ̀, bí kò ṣe ìdààmú.”

< Iov 3 >