< Iov 24 >
1 De ce, văzând că timpurile nu sunt ascunse de cel Atotputernic, nu văd zilele lui cei ce îl cunosc?
“Ṣe bí ìgbà kò pamọ́ lọ́dọ̀ Olódùmarè fún ìdájọ́? Èéṣe tí ojúlùmọ̀ rẹ̀ kò fi rí ọjọ́ rẹ̀?
2 Unii mută pietrele de hotar; ei cu violență iau turme și pășunea lor.
Wọ́n a sún àmì ààlà ilẹ̀, wọ́n á fi agbára kó agbo ẹran lọ, wọ́n a sì bọ́ wọn.
3 Ei alungă măgarul celor fără tată, iau boul văduvei drept garanție.
Wọ́n á sì da kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ aláìní baba lọ, wọ́n a sì gba ọ̀dá màlúù opó ní ohun ògo.
4 Ei abat pe nevoiaș de pe cale; săracii pământului se ascund împreună.
Wọ́n á bi aláìní kúrò lójú ọ̀nà, àwọn tálákà ayé a fi agbára sá pamọ́.
5 Iată, asemenea măgarilor sălbatici în pustie, ei merg înainte să își facă lucrarea; sculându-se din timp pentru o pradă, pustia aduce hrană pentru ei și pentru copiii lor.
Kíyèsi i, bí i kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó nínú ijù ni àwọn tálákà jáde lọ sí iṣẹ́ wọn, wọ́n a tètè dìde láti wá ohun ọdẹ; ijù pèsè oúnjẹ fún wọn àti fún àwọn ọmọ wọn.
6 Ei își culeg fiecare nutrețul său în câmp și adună recolta viei celor stricați.
Olúkúlùkù a sì sá ọkà oúnjẹ ẹran rẹ̀ nínú oko, wọn a sì ká ọgbà àjàrà ènìyàn búburú.
7 Ei fac pe cei goi să găzduiască fără haină, încât nu au acoperământ pe frig.
Ní ìhòhò ni wọn máa sùn láìní aṣọ, tí wọn kò ní ìbora nínú òtútù.
8 Ei sunt uzi de aversele de ploaie ale munților și îmbrățișează stânca din lipsa unui adăpost.
Ọ̀wààrà òjò òkè ńlá sì pa wọ́n, wọ́n sì lẹ̀ mọ́ àpáta nítorí tí kò sí ààbò.
9 Ei smulg pe cel fără tată de la piept și iau garanție de la sărac.
Wọ́n já ọmọ aláìní baba kúrò ní ẹnu ọmú, wọ́n sì gbà ọmọ tálákà nítorí gbèsè.
10 Îl fac să meargă gol, fără haină, și iau snopul de la cel flămând.
Wọ́n rìn kiri ní ìhòhò láìní aṣọ; àwọn tí ebi ń pa rẹrù ìdì ọkà.
11 Ei fac ulei înăuntrul zidurilor lor și calcă teascurile lor de vin și suferă de sete.
Àwọn ẹni tí ń fún òróró nínú àgbàlá wọn, tí wọ́n sì ń tẹ ìfúntí àjàrà, síbẹ̀ òǹgbẹ sì ń gbẹ wọn.
12 Oamenii din cetate gem și sufletul celui rănit țipă; totuși Dumnezeu nu le pune la socoteală nebunia.
Àwọn ènìyàn ń kérora láti ìlú wá, ọkàn àwọn ẹni tí ó gbọgbẹ́ kígbe sókè fún ìrànlọ́wọ́ síbẹ̀ Ọlọ́run kò kíyèsi àṣìṣe náà.
13 Ei sunt dintre cei care se revoltă împotriva luminii, ei nu cunosc căile ei, nici nu locuiesc în cărările ei.
“Àwọn ni ó wà nínú àwọn tí ó ṣọ̀tẹ̀ sí ìmọ́lẹ̀, wọn kò mọ̀ ipa ọ̀nà rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò dúró nípa ọ̀nà rẹ̀.
14 Ucigașul, ridicându-se odată cu lumina, ucide pe sărac și pe nevoiaș și în timpul nopții este ca un hoț.
Apànìyàn a dìde ní àfẹ̀mọ́júmọ́, a sì pa tálákà àti aláìní, àti ní òru a di olè.
15 De asemenea ochiul celui adulter așteaptă amurgul, spunând: Niciun ochi nu mă va vedea; și își deghizează fața.
Ojú alágbèrè pẹ̀lú dúró kí ilẹ̀ ṣú díẹ̀; ‘Ó ní, ojú ẹnìkan kì yóò rí mi,’ ó sì fi ìbòjú bojú rẹ̀.
16 În întuneric ei sparg casele pe care le-au însemnat pentru ei în timpul zilei; ei nu cunosc lumina.
Ní òkùnkùn wọn á rúnlẹ̀ wọlé, tí wọ́n ti fi ojú sọ fún ara wọn ní ọ̀sán, wọn kò mọ̀ ìmọ́lẹ̀.
17 Căci dimineața este pentru ei întocmai ca umbra morții, dacă cineva îi cunoaște, ei sunt în terorile umbrei morții.
Nítorí pé bí òru dúdú ní òwúrọ̀ fún gbogbo wọn; nítorí tí wọn sì mọ̀ ìbẹ̀rù òkùnkùn.
18 El este iute ca apele; partea lor este blestemată pe pământ; nu privește calea viilor.
“Ó yára lọ bí ẹni lójú omi; ìpín wọn ní ilé ayé ni a ó parun; òun kò rìn lọ mọ́ ní ọ̀nà ọgbà àjàrà.
19 Secetă și arșiță mistuie apele zăpezilor; la fel mormântul celor care au păcătuit. (Sheol )
Gẹ́gẹ́ bi ọ̀dá àti òru ní í mú omi òjò-dídì yọ́, bẹ́ẹ̀ ní isà òkú í run àwọn tó dẹ́ṣẹ̀. (Sheol )
20 Pântecul îl va uita; viermele se va înfrupta din el; nu va mai fi amintit; și stricăciunea va fi frântă ca un pom.
Inú ìbímọ yóò gbàgbé rẹ̀, kòkòrò ní yóò máa fi adùn jẹun lára rẹ̀; a kì yóò rántí ènìyàn búburú mọ́; bẹ́ẹ̀ ní a ó sì ṣẹ ìwà búburú bí ẹní ṣẹ́ igi.
21 El se poartă rău cu cea stearpă care nu naște și nu face bine văduvei.
Ẹni tí o hù ìwà búburú sí àgàn tí kò ṣe rere sí opó.
22 El atrage de asemenea pe cel puternic cu puterea sa; se ridică și niciun om nu este sigur de viață.
Ọlọ́run fi ipá agbára rẹ̀ fa alágbára, bí wọ́n tilẹ̀ fìdímúlẹ̀, kò sí ìrètí ìyè fún wọn.
23 Deși îi este dat să fie în siguranță acolo unde se odihnește, totuși ochii lui sunt peste căile lor.
Ọlọ́run sì fi àìléwu fún un, àti nínú èyí ni a ó sì tì i lẹ́yìn, ojú rẹ̀ sì wà ní ipa ọ̀nà wọn.
24 Ei sunt înălțați pentru puțin timp, dar apoi sunt înjosiți; sunt scoși de pe cale ca toți ceilalți și retezați ca vârfurile spicelor.
A gbé wọn lékè nígbà díẹ̀, wọ́n kọjá lọ; a sì rẹ̀ wọ́n sílẹ̀, a sì mú wọn kúrò ní ọ̀nà bí àwọn ẹlòmíràn, a sì ké wọn kúrò bí orí síírí ọkà bàbà.
25 Și dacă nu este așa acum, cine mă va face mincinos și va face vorbirea mea fără valoare?
“Ǹjẹ́, bí kò bá rí bẹ́ẹ̀ nísinsin yìí, ta ni yóò mú mi ní èké, tí yóò sì sọ ọ̀rọ̀ mi di aláìníláárí?”