< Iov 18 >
1 Atunci a răspuns Bildad șuhitul și a zis:
Ìgbà náà ni Bilidadi, ará Ṣuhi, dáhùn, ó sì wí pé,
2 Cât timp va trece până vei pune capăt vorbelor? Fă semn și apoi vom vorbi.
“Nígbà wo ni ẹ̀yin yóò tó fi ìdí ọ̀rọ̀ tì; ẹ rò ó, nígbẹ̀yìn rẹ̀ ni àwa ó tó máa sọ.
3 Pentru ce suntem socotiți ca fiare și considerați nemernici înaintea ta?
Nítorí kí ni a ṣe ń kà wá sí bí ẹranko, tí a sì ń kà wá si bí ẹni ẹ̀gàn ní ojú yín?
4 El însuși se sfâșie în mânia sa; va fi pământul părăsit pentru tine? Și va fi stânca mutată din locul său?
Ìwọ fa ara rẹ ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ nínú ìbínú rẹ̀; kí a ha kọ ayé sílẹ̀ nítorí rẹ̀ bi? Tàbí kí a sí àpáta kúrò ní ipò rẹ̀?
5 Da, lumina celui stricat va fi stinsă și scânteia focului său nu va străluci.
“Nítòótọ́ ìmọ́lẹ̀ ènìyàn búburú ni a ó pa kúrò, ọ̀wọ́-iná rẹ̀ kì yóò sì tan ìmọ́lẹ̀.
6 Lumina va fi întuneric în cortul său și candela sa va fi stinsă cu el.
Ìmọ́lẹ̀ yóò di òkùnkùn nínú àgọ́ rẹ̀, fìtílà ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ ni a ó sì pa pẹ̀lú.
7 Pașii tăriei lui vor fi strâmtorați și propriul său sfat îl va trânti.
Ìrìn ẹsẹ̀ agbára rẹ̀ yóò di fífọ; ète òun tìkára rẹ̀ ni yóò bí i ṣubú.
8 Fiindcă este aruncat într-o plasă prin propriile sale picioare și calcă pe o cursă.
Nípa ẹ̀ṣẹ̀ òun tìkára rẹ̀ ó ti bọ́ sínú àwọ̀n, ó sì rìn lórí okùn dídẹ.
9 Lațul îl va prinde de călcâi și tâlharul îl va învinge.
Tàkúté ni yóò mú un ní gìgísẹ̀, àwọn àwọ̀n tí a dẹ yóò sì ṣẹ́gun rẹ̀.
10 Cursa îi este întinsă în pământ și o capcană pentru el pe cale.
A dẹkùn sílẹ̀ fún un lórí ilẹ̀, a sì wà ọ̀fìn fún un lójú ọ̀nà.
11 Terori îl vor înspăimânta de fiecare parte și îl vor pune pe fugă.
Ẹ̀rù ńlá yóò bà á ní ìhà gbogbo, yóò sì lé e dé ẹsẹ̀ rẹ̀.
12 Puterea lui va fi înfometată și nimicire va fi gata lângă el.
Àìlera rẹ̀ yóò di púpọ̀ fún ebi, ìparun yóò dìde dúró sí i nígbà tí ó bá ṣubú.
13 Aceasta va mânca tăria pielii lui; întâiul născut al morții îi va mânca tăria.
Yóò jẹ ẹ̀yà ara rẹ̀; ikú àkọ́bí ni yóò jẹ agbára rẹ̀ run.
14 Încrederea sa va fi dezrădăcinată din cortul său și aceasta îl va aduce la împăratul terorilor.
A ó fà á tu kúrò nínú àgọ́ tí ó gbẹ́kẹ̀lé, a ó sì mú un tọ ọba ẹ̀rù ńlá nì lọ.
15 Se va locui în cortul său deoarece nu este al său; pucioasă va fi împrăștiată peste locuința sa.
Yóò sì máa jókòó nínú àgọ́ rẹ̀ èyí tí í ṣe tirẹ̀; sulfuru ti o jóná ni a ó fún káàkiri ibùgbé rẹ̀.
16 Rădăcinile lui vor fi uscate dedesubt și deasupra, ramura lui va fi retezată.
Gbòǹgbò rẹ̀ yóò gbẹ níṣàlẹ̀, a ó sì ké ẹ̀ka rẹ̀ kúrò lókè.
17 Amintirea sa va pieri de pe pământ și nu va avea un nume în stradă.
Ìrántí rẹ̀ yóò parun kúrò ni ayé, kì yóò sí orúkọ rẹ̀ ní ìgboro ìlú.
18 Va fi dus de la lumină în întuneric și alungat din lume.
A ó sì lé e láti inú ìmọ́lẹ̀ sí inú òkùnkùn, a ó sì lé e kúrò ní ayé.
19 El nu va avea nici fiu, nici nepot printre oamenii săi, nici cineva să rămână în locuințele lui.
Kì yóò ní ọmọ tàbí ọmọ ọmọ nínú àwọn ènìyàn rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹnikẹ́ni tí yóò kù nínú agbo ilé rẹ̀.
20 Cei ce vin după el vor fi înmărmuriți la ziua lui, așa cum au fost îngroziți cei dinainte.
Ẹnu yóò ya àwọn ìran ti ìwọ̀-oòrùn sí ìgbà ọjọ́ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rù ìwárìrì ti í bá àwọn ìran ti ìlà-oòrùn.
21 Cu adevărat astfel sunt locuințele celui stricat și acesta este locul celui ce nu cunoaște pe Dumnezeu.
Nítòótọ́ irú bẹ́ẹ̀ ni ibùgbé àwọn ènìyàn búburú, èyí sì ni ipò ẹni tí kò mọ̀ Ọlọ́run.”