< Iov 13 >

1 Iată, ochiul meu le-a văzut toate acestea, urechea mea a auzit și le-a înțeles.
“Wò ó, ojú mi ti rí gbogbo èyí rí, etí mí sì gbọ́, ó sì ti yé mi.
2 Ce cunoașteți voi, cunosc și eu; nu vă sunt inferior.
Ohun tí ẹ̀yin mọ̀, èmi mọ̀ pẹ̀lú, èmi kò kéré sí i yin.
3 Cu siguranță aș vorbi celui Atotputernic și doresc să mă judec cu Dumnezeu.
Nítòótọ́ èmi ó bá Olódùmarè sọ̀rọ̀, èmi sì ń fẹ́ bá Ọlọ́run sọ àsọyé.
4 Dar voi sunteți făuritori de minciuni, toți sunteți doctori de nimic.
Ẹ̀yin fi irọ́ bá mi sọ̀rọ̀, oníṣègùn lásán ni gbogbo yín.
5 O, de ați tăcea de tot! Aceasta v-ar fi înțelepciunea.
Háà! ẹ̀yin kì bá kúkú dákẹ́! Èyí ni kì bá sì ṣe ọgbọ́n yín.
6 Auziți acum întâmpinarea mea și dați ascultare la pledoariile buzelor mele.
Ẹ gbọ́ àwíyé mi nísinsin yìí; ẹ sì fetísílẹ̀ sí àròyé ẹnu mi.
7 Veți vorbi stricat pentru Dumnezeu? Și veți vorbi înșelător pentru el?
Ẹ̀yin fẹ́ sọ ìsọkúsọ fún Ọlọ́run? Ki ẹ sì fi ẹ̀tàn sọ̀rọ̀ gbè é?
8 Veți fi părtinitorii lui? Vă veți lupta de partea lui Dumnezeu?
Ẹ̀yin fẹ́ ṣe ojúsàájú rẹ̀? Ẹ̀yin fẹ́ gbèjà fún Ọlọ́run?
9 Este bine ca el să vă cerceteze? Sau așa cum un om batjocorește pe altul, îl batjocoriți pe el?
Ó ha dára to tí yóò hú àṣírí yín síta, tàbí kí ẹ̀yin tàn án bí ẹnìkan ti í tan ẹnìkejì?
10 El cu siguranță vă va mustra, dacă părtiniți în ascuns.
Yóò máa bá yín wí nítòótọ́, bí ẹ̀yin bá ṣe ojúsàájú ènìyàn níkọ̀kọ̀.
11 Nu vă va înfrica măreția lui? Și nu va cădea peste voi groaza lui?
Ìwà ọlá rẹ̀ kì yóò bà yín lẹ́rù bí? Ìpayà rẹ̀ kì yóò pá yín láyà?
12 Amintirile voastre sunt ca cenușa, trupurile voastre ca trupuri de lut.
Àwọn òwe yín dàbí eérú, bẹ́ẹ̀ ni àwọn odi ìlú yin dàbí amọ̀.
13 Tăceți, lăsați-mă în pace, ca să vorbesc și să vină peste mine ce va veni.
“Ẹ pa ẹnu yín mọ́ kúrò lára mi, kí èmi kí ó lè sọ̀rọ̀, ki ohun tí ń bọ̀ wá í bá mi, le è máa bọ̀.
14 Pentru ce să îmi iau carnea în dinți și să îmi pun viața în mâna mea?
Ǹjẹ́ nítorí kí ni èmi ṣe ń fi eyín mi bu ẹran-ara mi jẹ, tí mo sì gbé ẹ̀mí mi lé ara mi lọ́wọ́?
15 Chiar dacă m-ar ucide, totuși mă voi încrede în el; dar îmi voi apăra căile înaintea lui.
Bí ó tilẹ̀ pa mí, síbẹ̀ èmi ó máa gbẹ́kẹ̀lé e, èmi ó máa tẹnumọ́ ọ̀nà mi níwájú rẹ̀.
16 El de asemenea va fi salvarea mea, căci un fățarnic nu va veni înaintea lui.
Èyí ni yóò sì ṣe ìgbàlà mi, àgàbàgebè kì yóò wá síwájú rẹ̀.
17 Cu urechile voastre, ascultați cu atenție cuvântul meu și vorbirea mea.
Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹnu mi ní ìfarabalẹ̀, jẹ́ kí ọ̀rọ̀ mí dún ni etí yín.
18 Priviți acum, mi-am rânduit cauza; știu că voi fi declarat drept.
Wò ó nísinsin yìí, èmi ti mura ọ̀ràn mi sílẹ̀; èmi mọ̀ pé a ó dá mi láre.
19 Cine este cel ce se va certa cu mine? Pentru că acum, dacă îmi țin limba, îmi voi da duhul.
Ta ni òun ti yóò bá mi ṣàròyé? Ǹjẹ́ nísinsin yìí, èmi fẹ́ pa ẹnu mi mọ́, èmi ó sì jọ̀wọ́ ẹ̀mí mi lọ́wọ́.
20 Numai două lucruri nu îmi face; atunci nu mă voi ascunde de tine.
“Ṣùgbọ́n, má ṣe ṣe ohun méjì yìí sí mi, nígbà náà ni èmi kì yóò sì fi ara mi pamọ́ kúrò fún ọ.
21 Retrage-ți mâna de la mine și să nu mă înspăimânte groaza ta.
Fa ọwọ́ rẹ sẹ́yìn kúrò lára mi, má sì jẹ́ kí ẹ̀rù rẹ kí ó pá mi láyà.
22 Atunci cheamă și voi răspunde; sau lasă-mă să vorbesc iar tu răspunde-mi.
Nígbà náà ni kí ìwọ kí ó pè, èmi o sì dáhùn, tàbí jẹ́ kí ń máa sọ̀rọ̀, ki ìwọ kí ó sì dá mi lóhùn.
23 Cât de multe sunt nelegiuirile și păcatele mele? Fă-mă să cunosc fărădelegea mea și păcatul meu.
Mélòó ní àìṣedéédéé àti ẹ̀ṣẹ̀ mi? Mú mi mọ̀ ìrékọjá àti ẹ̀ṣẹ̀ mi.
24 Pentru ce îți ascunzi fața și mă socotești ca dușmanul tău?
Nítorí kí ni ìwọ ṣe pa ojú rẹ mọ́, tí o sì yàn mí ní ọ̀tá rẹ?
25 Vei zdrobi o frunză purtată încoace și încolo? Și vei urmări tu miriștea uscată?
Ìwọ ó fa ewé ti afẹ́fẹ́ ń fẹ́ síyìn-ín sọ́hùn-ún ya bi? Ìwọ a sì máa lépa ìyàngbò?
26 Căci tu scrii lucruri amare împotriva mea și mă faci să moștenesc nelegiuirile tinereții mele.
Nítorí pé ìwọ kọ̀wé ohun kíkorò sí mi, o sì mú mi jogún àìṣedéédéé èwe mi.
27 De asemenea îmi pui picioarele în butuci și privești îndeaproape la toate cărările mele; tu pui o urmă pe călcâiele picioarelor mele.
Ìwọ kàn àbà mọ́ mi lẹ́sẹ̀ pẹ̀lú, ìwọ sì ń wò ipa ọ̀nà ìrìn mi ní àwòfín; nípa fífi ìlà yí gígísẹ̀ mi ká.
28 Și el, ca un lucru putred, se mistuie, ca o haină mâncată de molii.
“Bẹ́ẹ̀ ni ènìyàn ń ṣègbé bí ohun ìdíbàjẹ́, bi aṣọ tí kòkòrò jẹ.

< Iov 13 >