< Ieremia 8 >
1 În acel timp, spune DOMNUL, vor scoate oasele împăraților lui Iuda și oasele prinților lui și oasele preoților și oasele profeților și oasele locuitorilor Ierusalimului, din mormintele lor;
“‘Ní ìgbà náà ni Olúwa wí pé, wọn yóò mú egungun àwọn ọba Juda àti egungun àwọn ìjòyè, egungun àwọn àlùfáà àti egungun àwọn wòlíì àti egungun àwọn olùgbé Jerusalẹmu kúrò nínú ibojì.
2 Și le vor întinde înaintea soarelui și a lunii și a întregii oștiri a cerului, pe care le-au iubit și cărora le-au servit și după care au umblat și pe care le-au căutat și cărora li s-au închinat; nu vor fi adunate nici nu vor fi îngropate; vor fi ca balegă pe fața pământului.
A ó yọ wọ́n síta fún oòrùn àti òṣùpá àti gbogbo àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run tí wọ́n ti fẹ́ràn tí wọ́n sì ti sìn, àti àwọn tí wọ́n ti tọ̀ lẹ́yìn tí wọ́n ti wá tí wọ́n sì ti foríbalẹ̀ fún. Kì yóò ṣà wọ́n jọ tàbí sìn wọ́n, wọn yóò dàbí ìdọ̀tí tó wà lórí ilẹ̀.
3 Și moartea va fi aleasă, mai degrabă decât viața, de toată rămășița celor care rămân din această familie rea, de cei care rămân în toate locurile unde îi vor fi alungat, spune DOMNUL oștirilor.
Níbikíbi tí mo bá lé wọn lọ, gbogbo àwọn ìyókù wọn yóò fẹ́ ikú ju ìyè lọ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.’
4 Mai mult, tu să le spui: Astfel spune DOMNUL: Vor cădea ei și nu se vor ridica? Se va abate el și nu se va întoarce?
“Wí fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Bí ènìyàn bá ṣubú lulẹ̀, wọn kì í padà dìde bí? Nígbà tí ènìyàn bá yà kúrò ní ọ̀nà rẹ, kì í yí padà bí?
5 De ce atunci, acest popor al Ierusalimului, a decăzut printr-o continuă decădere? Ei țin tare înșelăciunea, refuză să se întoarcă.
Èéṣe nígbà náà àwọn ènìyàn wọ̀nyí fi yà kúrò lọ́nà rẹ̀? Kí ló dé tí Jerusalẹmu fi yà kúrò ní gbogbo ìgbà? Wọ́n rọ̀ mọ́ ẹ̀tàn; wọ́n kọ̀ láti yípadà.
6 Eu am dat ascultare și am auzit, dar ei nu au vorbit drept; nimeni nu s-a pocăit de stricăciunea lui, spunând: Ce am făcut? Fiecare s-a întors la alergarea lui, precum calul se aruncă în bătălie.
Mo ti fetísílẹ̀ dáradára, wọn kò sọ ohun tí ó tọ́. Kò sí ẹnìkan tó ronúpìwàdà nínú ìwà búburú rẹ̀, kí ó wí pé, “Kí ni mo ṣe?” Olúkúlùkù ń tọ ọ̀nà rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹṣin tó ń lọ sójú ogun.
7 Da, barza în cer cunoaște timpurile ei rânduite; și turturica și cocorul și rândunica păzesc timpul venirii lor; dar poporul meu nu cunoaște judecata DOMNULUI.
Kódà, ẹyẹ àkọ̀ ojú ọ̀run mọ ìgbà tirẹ̀, àdàbà, alápáǹdẹ̀dẹ̀ àti lékèélékèé mọ àkókò ìṣípò padà wọn. Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi kò mọ ohun tí Olúwa wọn fẹ́.
8 Cum ziceți: Noi suntem înțelepți și legea DOMNULUI este cu noi? Iată, într‑adevăr, în zadar a făcut-o; tocul scribilor este în zadar.
“‘Báwo ni ẹ̀yin ṣe lè wí pé, “Àwa gbọ́n, nítorí a ní òfin Olúwa,” nígbà tí ó jẹ́ pé kálámù èké àwọn akọ̀wé ti àwọn sọ ọ́ di ẹ̀tàn.
9 Înțelepții sunt rușinați, ei sunt descurajați și prinși; iată, au respins cuvântul DOMNULUI; și ce înțelepciune este în ei?
Ojú yóò ti àwọn ọlọ́gbọ́n, a ó dà wọ́n láàmú, wọn yóò sì kó sí ìgbèkùn. Nítorí wọ́n ti kọ ọ̀rọ̀ Olúwa, irú ọgbọ́n wo ló kù tí wọ́n ní?
10 De aceea voi da pe soțiile lor altora și câmpurile lor celor care le vor moșteni, pentru că fiecare, de la cel mai mic până la cel mai mare, este dedat la lăcomie, de la profet până la preot, fiecare se poartă fals.
Nítorí náà, èmi yóò fi ìyàwó wọn fún àwọn ọkùnrin mìíràn àti ilẹ̀ wọn fún àwọn ẹlòmíràn. Láti èyí tó kéré jù dé èyí tó dàgbà jù, gbogbo wọn ni èrè àjẹjù ń jẹ lógún; àwọn wòlíì àti àwọn àlùfáà pẹ̀lú ń hùwà ẹ̀tàn.
11 Fiindcă au vindecat vătămarea fiicei poporului meu cu ușurătate, spunând: Pace, pace! când nu este pace.
Wọ́n tọ́jú ọgbẹ́ àwọn ènìyàn mi gẹ́gẹ́ bí èyí tí kò jinlẹ̀. “Àlàáfíà, àlàáfíà,” ni wọ́n ń wí, nígbà tí kò sí àlàáfíà.
12 Au fost ei rușinați că au comis urâciune? Nu, nu au fost deloc rușinați, nici nu puteau să roșească; de aceea ei vor cădea printre cei care cad; la timpul când îi cercetez vor fi doborâți, spune DOMNUL.
Ǹjẹ́ wọ́n tijú fún ìṣe ìríra wọn? Bẹ́ẹ̀ kọ́, wọn kò ní ìtìjú rárá; wọn kò tilẹ̀ mọ bí wọ́n ti ṣe ń tì jú. Nítorí náà wọn yóò ṣubú pẹ̀lú àwọn tó ti ṣubú, a ó sì wó wọ́n lulẹ̀ nígbà tí a bá bẹ̀ wọ́n wò, ni Olúwa wí.
13 Îi voi mistui într-adevăr, spune DOMNUL; nu vor fi struguri în viță, nici smochine în smochin și frunza se va ofili; și lucrurile pe care le-am dat lor vor trece de la ei.
“‘Èmi yóò mú ìkórè wọn kúrò, ni Olúwa wí. Kì yóò sí èso lórí igi àjàrà. Kì yóò sí ọ̀pọ̀tọ́ lórí igi, ewé wọn yóò sì rẹ̀ sílẹ̀. Ohun tí mo ti fi fún wọn ni à ó gbà kúrò.’”
14 De ce ședem liniștiți? Adunați-vă și să intrăm în cetățile apărate și să tăcem acolo, pentru că DOMNUL Dumnezeul nostru ne-a amuțit și ne-a dat apă cu fiere să bem, pentru că am păcătuit împotriva DOMNULUI.
“Èéṣe tí àwa fi jókòó ní ibí yìí? A kó ara wa jọ! Jẹ́ kí a sálọ sí ìlú olódi kí a sì ṣègbé síbẹ̀. Nítorí tí Olúwa Ọlọ́run wa ti pinnu pé a ó ṣègbé. Yóò sì fún wa ní omi onímájèlé mu, nítorí àwa ti ṣẹ̀ sí i.
15 Am căutat pacea, dar nimic bun nu a venit; și am căutat un timp de sănătate dar, iată, tulburare.
Àwa ń retí àlàáfíà kò sí ìre kan, tí ó wá ní ìgbà ìmúláradá bí kò ṣe ìpayà nìkan.
16 Pufăitul cailor lui s-a auzit din Dan; toată țara a tremurat la sunetul nechezatului celor puternici ai lui; fiindcă au venit și au mâncat țara și tot ce este în ea; cetatea și pe cei care locuiau în ea.
Ìró ìfọn imú ẹṣin àwọn ọlọ̀tẹ̀ là ń gbọ́ láti Dani, yíyan àwọn akọ ẹṣin mú gbogbo ilẹ̀ wárìrì. Wọ́n wá láti pa ilẹ̀ náà run, gbogbo ohun tó wà níbẹ̀, ìlú náà àti gbogbo olùgbé ibẹ̀.
17 Căci, iată, voi trimite printre voi șerpi, năpârci, ce nu vor fi fermecate și vă vor mușca, spune DOMNUL.
“Wò ó, èmi yóò rán àwọn ejò olóró sí àárín yín, paramọ́lẹ̀ tí ẹ kò lè pa oró wọn, yóò sì bù yín jẹ,” ni Olúwa wí.
18 Când mă mângâi împotriva întristării mele, îmi este leșinată inima în mine.
Olùtùnú mi, nígbà tí ìbànújẹ́ ọkàn mi, rẹ̀wẹ̀sì nínú mi.
19 Iată, vocea strigătului fiicei poporului meu din cauza celor care locuiesc într-o țară îndepărtată: Nu este DOMNUL în Sion? Nu este împăratul lui în Sion? De ce m‑au mâniat cu chipurile lor cioplite și cu deșertăciuni străine?
Fetí sí ẹkún àwọn ènìyàn mi láti ilẹ̀ jíjìnnà wá: “Olúwa kò ha sí ní Sioni bí? Ọba rẹ̀ kò sí níbẹ̀ mọ́ ni?” “Èéṣe tí wọ́n fi mú mi bínú pẹ̀lú ère wọn, pẹ̀lú àwọn òrìṣà àjèjì tí wọn kò níláárí?”
20 Secerișul a trecut, vara s-a sfârșit și noi nu suntem salvați.
“Ìkórè ti rékọjá, ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn ti parí, síbẹ̀ a kò gbà wá là.”
21 Pentru vătămarea fiicei poporului meu sunt eu vătămat; sunt negru; m-a apucat înmărmurirea.
Níwọ́n ìgbà tí a pa àwọn ènìyàn mi run, èmi náà run pẹ̀lú, èmi ṣọ̀fọ̀, ìrora sì mú mi káká.
22 Nu este balsam în Galaad? Nu este un doctor acolo? De ce atunci, nu se face vindecare fiicei poporului meu?
Kò ha sí ìkunra ní Gileadi bí? Kò ha sí àwọn oníṣègùn níbẹ̀? Kí ló ha dé tí kò fi sí ìwòsàn fún ọgbẹ́ àwọn ènìyàn mi?