< Ieremia 51 >

1 Astfel spune DOMNUL: Iată, voi ridica împotriva Babilonului și împotriva celor ce locuiesc în mijlocul celor ce se ridică împotriva mea, un vânt nimicitor;
Ohùn ti Olúwa wí nìyìí: “Wò ó èmi yóò ru afẹ́fẹ́ apanirun sókè sí Babeli àti àwọn ènìyàn Lebikamai,
2 Și voi trimite în Babilon vânturători, care îl vor vântura și îi vor goli țara, pentru că în ziua tulburării ei vor fi împotriva lui de jur împrejur.
Èmi yóò rán àwọn àjèjì ènìyàn sí Babeli láti fẹ́ ẹ, tí yóò sì sọ ilẹ̀ rẹ̀ di òfo; wọn yóò takò ó ní gbogbo ọ̀nà ní ọjọ́ ìparun rẹ̀.
3 Împotriva celui ce încordează arcul, arcașul să își întindă arcul și împotriva celui care se înalță în cămașa lui de zale; și nu cruțați pe tinerii lui; nimiciți în întregime toată oștirea lui.
Má ṣe jẹ́ kí tafàtafà yọ ọfà rẹ̀, jáde tàbí kí ó di ìhámọ́ra rẹ̀. Má ṣe dá àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sí; pátápátá ni kí o pa àwọn ọmọ-ogun rẹ̀.
4 Astfel, cei uciși vor cădea în țara caldeenilor și cei care sunt străpunși pe străzile ei.
Gbogbo wọn ni yóò ṣubú ní Babeli, tí wọn yóò sì fi ara pa yánnayànna ní òpópónà.
5 Pentru că Israel nu a fost părăsit, nici Iuda de Dumnezeul său, de DOMNUL oștirilor; deși țara lor a fost umplută cu păcat împotriva Celui Sfânt al lui Israel.
Nítorí pé Juda àti Israẹli ni Ọlọ́run wọn tí í ṣe Olúwa àwọn ọmọ-ogun, kò gbàgbọ́ bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ilé wọn kún fún kìkì ẹ̀bi níwájú ẹni mímọ́ Israẹli.
6 Fugiți din mijlocul Babilonului și să își scape fiecare om sufletul său; nu fiți stârpiți în nelegiuirea lui, pentru că acesta este timpul răzbunării DOMNULUI; el îi va întoarce o răsplată.
“Sá kúrò ní Babeli! Sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ! Má ṣe ṣègbé torí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ. Àsìkò àti gbẹ̀san Olúwa ni èyí; yóò sán fún òun gẹ́gẹ́ bí ó ti tọ́.
7 Babilonul a fost un pahar de aur în mâna DOMNULUI, care a îmbătat tot pământul; națiunile au băut din vinul lui; de aceea națiunile au înnebunit.
Ife wúrà ni Babeli ní ọwọ́ Olúwa; ó sọ gbogbo ayé di ọ̀mùtí. Gbogbo orílẹ̀-èdè mu ọtí rẹ̀, wọ́n sì ti ya òmùgọ̀ kalẹ̀.
8 Babilonul a căzut dintr-odată și este distrus; urlați pentru el; luați balsam pentru durerea lui, dacă astfel s-ar putea vindeca.
Babeli yóò ṣubú lójijì, yóò sì fọ́. Ẹ hu fun un! Ẹ mú ìkunra fún ìrora rẹ, bóyá yóò le wo ọ́ sàn.
9 Am căutat să vindecăm Babilonul, dar nu s-a vindecat; părăsiți-l și să mergem fiecare în țara sa, pentru că judecata lui ajunge până la cer și este înălțată până la ceruri.
“‘À bá ti wo Babeli sàn, ṣùgbọ́n kò lè sàn, ẹ jẹ́ kí a fi sílẹ̀, kí oníkálùkù lọ sí ilẹ̀ rẹ̀ torí ìdájọ́ rẹ̀ tó gòkè, ó ga àní títí dé òfúrufú.’
10 DOMNUL a scos la lumină dreptatea noastră; veniți, și să vestim în Sion lucrarea DOMNULUI Dumnezeul nostru.
“‘Olúwa ti dá wa láre, wá jẹ́ kí a sọ ọ́ ní Sioni ohun tí Olúwa Ọlọ́run wa ti ṣe.’
11 Lustruiți săgețile; adunați scuturile; DOMNUL a ridicat duhul împăraților mezilor, pentru că planul său este împotriva Babilonului, pentru a-l nimici; deoarece aceasta este răzbunarea DOMNULUI, răzbunarea templului său.
“Ṣe ọfà rẹ ní mímú, mú àpáta! Olúwa ti ru ọba Media sókè, nítorí pé ète rẹ̀ ni láti pa Babeli run. Olúwa yóò gbẹ̀san, àní ẹ̀san fún tẹmpili rẹ̀.
12 Ridicați steagul împotriva zidurilor Babilonului, întăriți garda, puneți paznici, pregătiți ambuscadele, pentru că DOMNUL deopotrivă a plănuit și a făcut ceea ce a vorbit împotriva locuitorilor Babilonului.
Gbé àsíá sókè sí odi Babeli! Ẹ ṣe àwọn ọmọ-ogun gírí, ẹ pín àwọn olùṣọ́ káàkiri, ẹ ṣètò àwọn tí yóò sá pamọ́ Olúwa! Yóò gbé ète rẹ̀ jáde, òfin rẹ̀ sí àwọn ará Babeli.
13 Tu, cel care locuiești pe multe ape, bogat în comori, ți-a venit sfârșitul, măsura lăcomiei tale.
Ìwọ tí o gbé lẹ́bàá odò púpọ̀, tí o sì ni ọ̀rọ̀ púpọ̀; ìgbẹ̀yìn rẹ ti dé, àní àsìkò láti ké ọ kúrò!
14 DOMNUL oștirilor a jurat pe sine însuși, spunând: Cu siguranță te voi umple cu oameni, precum cu omizi; și ei vor înălța un strigăt împotriva ta.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti búra fún ara rẹ̀, Èmi yóò fún ọ ní ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ eṣú, wọn yóò yọ ayọ̀, ìṣẹ́gun lórí rẹ.
15 El a făcut pământul prin puterea lui, a întemeiat lumea prin înțelepciunea lui și a întins cerul prin înțelegerea lui.
“Ó dá ilẹ̀ nípa agbára rẹ̀, o dá ilẹ̀ ayé pẹ̀lú ọgbọ́n rẹ̀, o sì tẹ́ ọ̀run pẹ̀lú ìmọ̀ rẹ̀.
16 Când își înalță vocea, o mulțime de ape sunt în ceruri, și el face aburii să se înalțe de la marginile pământului; el face fulgere împreună cu ploaia și scoate vântul din tezaurele lui.
Nígbà tí ará omi ọ̀run hó ó mú kí òfúrufú ru sókè láti ìpẹ̀kun ayé. Ó rán mọ̀nàmọ́ná pẹ̀lú òjò, ó sì mú afẹ́fẹ́ jáde láti ilé ìṣúra rẹ̀.
17 Fiecare om este neghiob prin cunoașterea lui; fiecare topitor este încurcat prin chipul cioplit; deoarece chipul lui turnat este falsitate și nu este suflare în ele.
“Olúkúlùkù ènìyàn ni kò lọ́pọlọ tí kò sì ní ìmọ̀, olúkúlùkù alágbẹ̀dẹ ni a kó ìtìjú bá nípa òrìṣà rẹ̀. Àwọn ère rẹ jẹ́ ẹ̀tàn; wọn kò ní èémí nínú.
18 Ele sunt zădărnicie, lucrarea înșelătoriilor; vor pieri la timpul cercetării lor.
Asán ni wọ́n, àti iṣẹ́ ìsìnà, nígbà ìbẹ̀wò wọn, wọn ó ṣègbé.
19 Partea lui Iacob nu este ca ei, pentru că el este făuritorul a toate lucrurile; și Israel este toiagul moștenirii lui: DOMNUL oștirilor este numele lui.
Ẹni tí ó jẹ́ ìpín Jakọbu kó rí bí ìwọ̀nyí; nítorí òun ni ó dá ohun gbogbo, àti gbogbo àwọn ẹ̀yà ajogún, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
20 Tu ești securea mea de bătălie și armele de război; fiindcă cu tine voi zdrobi în bucăți națiunile și cu tine voi distruge împărățiile;
“Ìwọ ni kùmọ̀ ogun ohun èlò ogun mi, ohun èlò ìjà mi, pẹ̀lú rẹ èmi ó fọ́ orílẹ̀-èdè túútúú, èmi ó bà àwọn ilé ọba jẹ́.
21 Și cu tine voi zdrobi în bucăți calul și călărețul lui; și cu tine voi zdrobi în bucăți carul și pe conducătorul lui;
Pẹ̀lú rẹ, èmi ó pa ẹṣin àti ẹni tí ó gùn ún pẹ̀lú rẹ̀; èmi ó ba kẹ̀kẹ́ ogun jẹ́ pẹ̀lú èmi ó pa awakọ̀,
22 Cu tine de asemenea voi zdrobi în bucăți pe bărbat și pe femeie; și cu tine voi zdrobi în bucăți pe bătrân și pe tânăr; și cu tine voi zdrobi în bucăți pe tânăr și pe tânără;
pẹ̀lú rẹ, mo pa ọkùnrin àti obìnrin, pẹ̀lú rẹ, mo pa àgbàlagbà àti ọmọdé, pẹ̀lú rẹ, mo pa ọ̀dọ́mọkùnrin àti ọ̀dọ́mọbìnrin.
23 De asemenea, cu tine, voi zdrobi în bucăți pe păstor și turma lui; și cu tine voi zdrobi în bucăți pe agricultor și perechea lui de boi; și cu tine voi zdrobi în bucăți căpetenii și conducători.
Èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ olùṣọ́-àgùntàn, àti agbo àgùntàn rẹ̀ túútúú, èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ àgbẹ̀ àti àjàgà màlúù túútúú, èmi yóò sì fi ọ́ fọ́ baálẹ̀ àti àwọn ìjòyè rẹ̀ túútúú.
24 Și voi întoarce Babilonului și tuturor locuitorilor din Caldeea tot răul lor pe care l-au făcut în Sion înaintea ochilor voștri, spune DOMNUL.
“Ní ojú rẹ, èmi yóò san án fún Babeli àti gbogbo àwọn olùgbé inú rẹ̀ fún gbogbo ibi tí wọ́n ti ṣe ní Sioni,” ni Olúwa wí.
25 Iată, spune DOMNUL, eu sunt împotriva ta, munte distrugător, tu care distrugi tot pământul; și eu îmi voi întinde mâna asupra ta și te voi rostogoli de pe stânci și te voi face un munte ars.
“Mo lòdì sí ọ, ìwọ òkè apanirun ìwọ ti ba gbogbo ayé jẹ́,” ni Olúwa wí. “Èmi ó na ọwọ́ mi sí ọ, èmi yóò yí ọ kúrò lórí àpáta, Èmi yóò sọ ọ́ dàbí òkè tí a ti jó.
26 Și ei nu vor lua din tine piatră pentru colț, nici piatră pentru temelii, ci vei fi pustiit pentru totdeauna, spune DOMNUL.
A kò ní mú òkúta kankan láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ lò gẹ́gẹ́ bí igun ilé tàbí fún ìpínlẹ̀ nítorí pé ìwọ yóò di ahoro títí ayé,” ní Olúwa wí.
27 Înălțați un steag în țară, sunați trâmbița printre națiuni, pregătiți națiunile împotriva lui, chemați împotriva lui împărățiile din Ararat, Miniu și Așchenaz; rânduiți o căpetenie împotriva lui; faceți caii să urce ca omizile zburlite.
“Gbé àsíá sókè ní ilẹ̀ náà! Fọn ìpè láàrín àwọn orílẹ̀-èdè! Sọ àwọn orílẹ̀-èdè di mímọ́ sórí rẹ̀, pe àwọn ìjọba yìí láti dojúkọ ọ́: Ararati, Minini àti Aṣkenasi. Yan olùdarí ogun láti kọlù ú, rán àwọn ẹṣin sí i bí ọ̀pọ̀ eṣú.
28 Pregătiți împotriva lui națiunile împreună cu împărații mezilor, pe căpeteniile lor și pe toți conducătorii lor și toată țara stăpânirii lui.
Sọ àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú àwọn ọba Media di mímọ́ sórí rẹ̀, àwọn baálẹ̀ rẹ̀, àti gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀, àti gbogbo orílẹ̀-èdè tí wọ́n jẹ ọba lé lórí.
29 Și țara se va cutremura și va fi chinuită, pentru că fiecare hotărâre a DOMNULUI se va împlini împotriva Babilonului, pentru a face țara Babilonului o pustiire fără locuitor.
Ilẹ̀ wárìrì síyìn-ín sọ́hùn-ún, nítorí pé ète Olúwa, sí Babeli dúró, láti ba ilẹ̀ Babeli jẹ́ lọ́nà tí ẹnikẹ́ni kò ní lè gbé inú rẹ̀ mọ́.
30 Războinicii Babilonului au încetat să lupte, au rămas în întăriturile lor, puterea lor s-a sfârșit; au devenit ca femeile; au ars locuințele lui; zăvoarele lui sunt sparte.
Gbogbo àwọn jagunjagun Babeli tó dáwọ́ ìjà dúró sínú àgọ́ wọn. Agbára wọn ti tán, wọ́n ti dàbí obìnrin. Ibùgbé rẹ̀ ni a ti dáná sun, gbogbo irin ẹnu-ọ̀nà wọn ti di fífọ́.
31 Un alergător va alerga să întâlnească pe un altul, și un mesager să întâlnească pe un altul, pentru a arăta împăratului Babilonului că cetatea lui este luată până la margine,
Ìránṣẹ́ kan ń tẹ̀lé òmíràn láti sọ fún ọba Babeli pé gbogbo ìlú rẹ̀ ni a ti kó ní ìgbèkùn.
32 Și că trecătorile sunt astupate și trestiile le-au ars cu foc și bărbații de război sunt înspăimântați.
Odò tí ó sàn kọjá kò sàn mọ́ ilẹ̀ àbàtà gbiná, àwọn jagunjagun sì wárìrì.”
33 Pentru că astfel spune DOMNUL oștirilor, Dumnezeul lui Israel: Fiica Babilonului este ca o arie de vânturat, este timpul să o vântur; încă puțin și timpul secerișului ei va veni.
Ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run àwọn ọmọ Israẹli sọ nìyìí: “Ọmọbìnrin Babeli dàbí ìpakà àsìkò láti kórè rẹ̀ kò ní pẹ́ dé mọ́.”
34 Nebucadnețar, împăratul Babilonului, m-a mâncat, m-a zdrobit, m-a făcut un vas gol, m-a înghițit ca un dragon, el și-a umplut pântecele cu desfătările mele, m-a alungat.
“Nebukadnessari ọba Babeli tó jẹ wá run, ó ti mú kí ìdààmú bá wa, ó ti sọ wá di àgbá òfìfo. Gẹ́gẹ́ bí ejò, ó ti gbé wa mì. Ó fi oúnjẹ àdídùn wa kún inú rẹ̀, lẹ́yìn náà ni ó pọ̀ wá jáde.
35 Violența făcută mie și cărnii mele să fie asupra Babilonului, va spune locuitorul Sionului; și sângele meu asupra locuitorilor din Caldeea, va spune Ierusalimul.
Kí gbogbo ìparun tí ó ṣe sí ẹran-ara wa wà lórí Babeli,” èyí tí àwọn ibùgbé Sioni wí. “Kí ẹ̀jẹ̀ wa wà lórí gbogbo àwọn tí ń gbé Babeli,” ni Jerusalẹmu wí.
36 De aceea astfel spune DOMNUL: Iată, eu voi pleda cauza ta și te voi răzbuna; și îi voi usca marea și îi voi seca izvoarele.
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí: “Wò ó, èmi yóò tì ọ́ lẹ́yìn lórí ohun tí o fẹ́ ṣe. Èmi ó sì gbẹ̀san, èmi yóò mú kí omi Òkun rẹ̀ àti orísun omi rẹ̀ gbẹ.
37 Și Babilonul va deveni ruine, o locuință pentru dragoni, o înmărmurire și o șuierare, fără locuitor.
Babeli yóò parun pátápátá, yóò sì di ihò àwọn akátá, ohun ẹ̀rù àti àbùkù, ibi tí ènìyàn kò gbé.
38 Ei vor răcni împreună ca leii; vor striga ca puii de lei.
Àwọn ènìyàn inú rẹ̀ bú ramúramù bí ọmọ kìnnìún.
39 În înfierbântarea lor le voi face ospețe și îi voi îmbăta, ca să se bucure și să doarmă un somn continuu și să nu se trezească, spune DOMNUL.
Ṣùgbọ́n nígbà tí ọkàn wọn bá ru sókè, èmi yóò ṣe àsè fún wọn, èmi yóò jẹ́ kí wọn mutí yó tí wọn yóò máa kọ fun ẹ̀rín, lẹ́yìn náà, wọn yóò sun oorun, wọn kì yóò jí,” ni Olúwa wí.
40 Îi voi coborî ca pe miei la măcel, ca pe berbeci cu țapi.
“Èmi yóò fà wọ́n lọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀dọ́-àgùntàn tí a fẹ́ pa, gẹ́gẹ́ bí àgbò àti ewúrẹ́.
41 Cum este Șeșacul luat! Și cum este luată prin surprindere lauda întregului pământ! Cum a devenit Babilonul o înmărmurire printre națiuni!
“Báwo ni Ṣeṣaki yóò ṣe dí mímú, ìfọ́nnu gbogbo àgbáyé. Irú ìpayà wo ni yóò bá Babeli láàrín àwọn orílẹ̀-èdè!
42 Marea a venit peste Babilon; el a fost acoperit de mulțimea valurilor ei.
Òkun yóò ru borí Babeli, gbogbo rírú rẹ̀ yóò borí Babeli.
43 Cetățile lui sunt o risipire, un pământ uscat și un pustiu, o țară în care nu trăiește nimeni, nici nu trece prin ea vreun fiu al omului.
Àwọn ìlú rẹ̀ yóò di ahoro, ilẹ̀ tí ó gbẹ, ilẹ̀ tí ènìyàn kò gbé tí ènìyàn kò sì rin ìrìnàjò.
44 Și voi pedepsi pe Bel în Babilon și voi scoate din gura lui ceea ce el a înghițit; și națiunile nu vor mai curge spre el; da, zidul Babilonului va cădea.
Èmi yóò fi ìyà jẹ Beli ti Babeli àti pé èmi yóò jẹ́ kí ó pọ gbogbo àwọn ohun tí ó gbé mì. Àwọn orílẹ̀-èdè kì yóò jùmọ̀ sàn lọ pọ̀ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ mọ́. Ní òótọ́ odi Babeli yóò sì wó.
45 Poporul meu, ieșiți din mijlocul lui și să își scape fiecare om sufletul de mânia înverșunată a DOMNULUI.
“Ẹ jáde kúrò nínú rẹ̀ ẹ̀yin ènìyàn mi! Sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ! Sá fún ìbínú ńlá Olúwa.
46 Și nu cumva inima voastră să leșine și să vă temeți de zvonul care va fi auzit în țară; un zvon va veni deopotrivă într-un an și după aceasta în alt an va veni un zvon și violență va fi în țară, conducător împotriva altui conducător.
Má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ dàrú tàbí kí o bẹ̀rù nígbà tí a bá gbọ́ àhesọ ọ̀rọ̀ ní ilẹ̀ wa; àhesọ ọ̀rọ̀ kan wá ní ọdún yìí, òmíràn ní ọdún mìíràn àhesọ ọ̀rọ̀ ni ti ìwà ipá ní ilẹ̀ náà àti tí aláṣẹ kan sí aláṣẹ kejì.
47 De aceea, iată, vin zilele, că voi face judecată asupra chipurilor cioplite ale Babilonului; și toată țara lui va fi încurcată și toți cei uciși ai lui vor cădea în mijlocul lui.
Nítorí ìgbà náà yóò wá dandan nígbà tí èmi yóò fi ìyà jẹ àwọn òrìṣà Babeli; gbogbo ilẹ̀ rẹ̀ ni a ó dójútì gbogbo àwọn tí a pa yóò sì ṣubú ní àárín rẹ̀.
48 Atunci cerul și pământul și tot ce este în ele vor cânta pentru Babilon, pentru că jefuitorii vor veni asupra lui de la nord, spune DOMNUL.
Ọ̀run àti ayé àti gbogbo ohun tí ó wà nínú wọn, yóò sì kọrin lórí Babeli: nítorí àwọn afiniṣèjẹ yóò wá sórí rẹ̀ láti àríwá,” ni Olúwa wí.
49 Precum Babilonul a făcut pe cei uciși ai lui Israel să cadă, tot astfel la Babilon vor cădea cei uciși ai întregului pământ.
“Babiloni gbọdọ̀ ṣubú nítorí ìtàjẹ̀ sílẹ̀ ni Israẹli, gẹ́gẹ́ bí àwọn ti a pa ní gbogbo ayé nítorí Babeli.
50 Voi cei care ați scăpat de sabie, plecați, nu stați nemișcați; amintiți-vă de DOMNUL de departe și Ierusalimul să urce la mintea voastră.
Ẹ̀yin tí ó ti bọ́ lọ́wọ́ idà, ẹ lọ, ẹ má dúró. Ẹ rántí Olúwa ní òkèrè, ẹ sì jẹ́ kí Jerusalẹmu wá sí ọkàn yín.”
51 Noi suntem încurcați deoarece am auzit ocara; rușinea ne-a acoperit fețele, pentru că străinii au intrat în sanctuarele casei DOMNULUI.
“Ojú tì wá, nítorí pé àwa ti gbọ́ ẹ̀gàn: ìtìjú ti bò wá lójú nítorí àwọn àjèjì wá sórí ohun mímọ́ ilé Olúwa.”
52 De aceea, iată, vin zilele, spune DOMNUL, că voi face judecată asupra chipurilor lui cioplite; și în toată țara lui cei răniți vor geme.
“Nítorí náà, wò ó, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí èmi yóò ṣe ìbẹ̀wò lórí àwọn ère fínfín rẹ̀, àti àwọn tí ó gbọgbẹ́ yóò sì máa kérora já gbogbo ilẹ̀ rẹ̀.
53 De s-ar înălța Babilonul până la cer și de și-ar întări înălțimea tăriei lui, totuși de la mine vor veni jefuitori la el, spune DOMNUL.
Bí Babeli tilẹ̀ gòkè lọ sí ọ̀run, bí ó sì ṣe ìlú olódi ní òkè agbára rẹ, síbẹ̀ àwọn afiniṣèjẹ yóò ti ọ̀dọ̀ mi tọ̀ ọ́ wá,” ní Olúwa wí.
54 Sunetul unui strigăt vine din Babilon și mare distrugere din țara caldeenilor;
“Ìró igbe láti Babeli, àti ìparun láti ilẹ̀ àwọn ará Kaldea!
55 Pentru că DOMNUL a jefuit Babilonul și a nimicit din el acea voce mare; când valurile lui răcnesc ca niște ape mari, vuietul vocii lor este înălțat;
Nítorí pé Olúwa ti ṣe Babeli ní ìjẹ, ó sì ti pa ohun ńlá run kúrò nínú rẹ̀; àwọn ọ̀tá wọn sì ń hó bi omi púpọ̀, a gbọ́ ariwo ohùn wọn.
56 Pentru că prădătorul a venit împotriva lui, împotriva Babilonului și războinicii lui sunt luați, fiecare arc al lor este frânt, pentru că DOMNUL Dumnezeul recompenselor va răsplăti negreșit.
Nítorí pé afiniṣèjẹ dé sórí rẹ̀, àní sórí Babeli; a mú àwọn akọni rẹ̀, a ṣẹ́ gbogbo ọrun wọn: nítorí Ọlọ́run ẹ̀san ni Olúwa, yóò san án nítòótọ́.
57 Și îi voi îmbăta pe prinții lui și pe înțelepții lui, pe căpeteniile lui și pe conducătorii lui și pe războinicii lui; și ei vor dormi un somn veșnic și nu se vor trezi, spune Împăratul al cărui nume este DOMNUL oștirilor.
Èmi ó sì mú kí àwọn ìjòyè rẹ̀ yó bí ọ̀mùtí, àti àwọn ọlọ́gbọ́n rẹ̀ àti àwọn baálẹ̀ rẹ̀, àti àwọn akọni rẹ̀, wọn ó sì sun oorun láéláé, wọn kì ó sì jí mọ́,” ní ọba wí, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
58 Astfel spune DOMNUL oștirilor: Zidurile late ale Babilonului vor fi în întregime zdrobite și porțile lui înalte vor fi arse cu foc; și oamenii vor lucra în zadar și poporul va lucra în foc și vor obosi.
Báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Odi Babeli gbígbòòrò ní a ó wó lulẹ̀ pátápátá, ẹnu-bodè gíga rẹ̀ ní a ó sì fi iná sun: tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ènìyàn ti ṣiṣẹ́ lásán, àti àwọn orílẹ̀-èdè ti ṣiṣẹ́ fún iná, tí àárẹ̀ sì mú wọn.”
59 Cuvântul pe care profetul Ieremia l-a poruncit lui Seraia, fiul lui Neriia fiul, lui Mahseia, când a mers cu Zedechia, împăratul lui Iuda, în Babilon în al patrulea an al domniei lui. Și acest Seraia era un prinț liniștit.
Ọ̀rọ̀ tí Jeremiah wòlíì pàṣẹ fún Seraiah, ọmọ Neriah, ọmọ Maseiah, nígbà tí o ń lọ ni ti Sedekiah, ọba Juda, sí Babeli ní ọdún kẹrin ìjọba rẹ̀. Seraiah yìí sì ní ìjòyè ibùdó.
60 Astfel Ieremia a scris într-o carte tot răul care va veni asupra Babilonului, chiar toate aceste cuvinte care sunt scrise împotriva Babilonului.
Jeremiah sì kọ gbogbo ọ̀rọ̀ ibi tí yóò wá sórí Babeli sínú ìwé kan, àní gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí tí a kọ sí Babeli.
61 Și Ieremia i-a spus lui Seraia: Când vei veni în Babilon și vei vedea și vei citi toate aceste cuvinte;
Jeremiah sì sọ fún Seraiah pé, “Nígbà tí ìwọ bá dé Babeli, kí ìwọ kí ó sì wò, kí ìwọ kí ó sì ka gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí.
62 Atunci să spui: DOAMNE, tu ai vorbit împotriva acestui loc, pentru a-l stârpi, ca nimeni să nu rămână în el, nici om nici animal, ci acesta să fie pustiit pentru totdeauna.
Kí ìwọ kí ó sì wí pé, ‘Olúwa ìwọ ti sọ̀rọ̀ sí ibí yí, láti ké e kúrò, kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé inú rẹ̀, àti ènìyàn àti ẹran, nítorí pé yóò di ahoro láéláé.’
63 Și va fi așa: când vei termina de citit această carte, să legi de ea o piatră și să o arunci în mijlocul Eufratului;
Yóò sì ṣe, nígbà tí ìwọ bá parí kíka ìwé yìí tán kí ìwọ kí ó di òkúta mọ́ ọn, kí ó sì sọ ọ́ sí àárín odò Eufurate.
64 Și să spui: Astfel se va scufunda Babilonul și nu se va ridica din răul pe care îl voi aduce asupra lui; și vor obosi. Până aici sunt cuvintele lui Ieremia.
Kí ìwọ sì wí pé, ‘Báyìí ní Babeli yóò rì, kí yóò sì tún dìde kúrò nínú ibi tí èmi ó mú wá sórí rẹ̀: àárẹ̀ yóò sì mú wọn.’” Títí dé ìhín ni ọ̀rọ̀ Jeremiah.

< Ieremia 51 >