< Ieremia 44 >

1 Cuvântul care a venit la Ieremia referitor la toți iudeii care locuiau în țara Egiptului, care locuiau la Migdol și la Tahpanes și la Nof și în ținutul Patros, spunând:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá nípa àwọn Júù tí ń gbé ní ìsàlẹ̀ Ejibiti ní Migdoli, Tafanesi àti Memfisi àti ní apá òkè Ejibiti:
2 Astfel spune DOMNUL oștirilor, Dumnezeul lui Israel: Ați văzut tot răul pe care l-am adus asupra Ierusalimului și asupra tuturor cetăților lui Iuda; și, iată, în această zi ele sunt o pustiire și nimeni nu locuiește în ele,
“Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: Wo ibi tí mo mú bá Jerusalẹmu àti gbogbo ìlú Juda. Lónìí, wọ́n wà ní ìyapa àti ìparun.
3 Din cauza stricăciunii lor, pe care au făcut-o pentru a mă provoca la mânie, în aceea că s-au dus să ardă tămâie și să servească altor dumnezei, pe care nu i-au cunoscut nici ei, nici voi, nici părinții voștri.
Nítorí pé ibi tí wọ́n ti ṣe. Wọ́n mú mi bínú nípa tùràrí fínfín àti nípa bíbọ àwọn òrìṣà, yálà èyí tí ìwọ tàbí àwọn baba rẹ kò mọ̀.
4 Totuși eu am trimis la voi pe toți servitorii mei profeții, ridicându-mă devreme și trimițându-i, spunând: Oh, nu faceți acest lucru scârbos, pe care eu îl urăsc.
Ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìgbà ní mo rán wòlíì mi, èyí tí ó wí báyìí pé, ‘Má ṣe àwọn ohun ìríra yìí tí èmi kórìíra.’
5 Dar ei nu au dat ascultare, nici nu și-au plecat urechea pentru a se întoarce de la stricăciunea lor, pentru a se opri să ardă tămâie altor dumnezei.
Ṣùgbọ́n wọn kò fetísílẹ̀ láti fi ọkàn si. Wọn kò sì yípadà kúrò nínú búburú wọn tàbí dáwọ́ ẹbọ sísun sí àwọn òrìṣà dúró.
6 Pentru aceea furia mea și mânia mea au fost turnate și s-au aprins în cetățile lui Iuda și pe străzile Ierusalimului; și ele sunt risipite și pustiite, precum în această zi.
Fún ìdí èyí, ìbínú gbígbóná mi ni èmi yóò yọ sí àwọn ìlú Juda àti òpópó Jerusalẹmu àti sísọ wọ́n di ìparun bí ó ṣe wà lónìí yìí.
7 De aceea acum, astfel spune DOMNUL Dumnezeul oștirilor, Dumnezeul lui Israel: Pentru ce faceți acest mare rău împotriva sufletelor voastre, pentru a stârpi dintre voi bărbat și femeie, prunc și sugar, din Iuda, pentru a nu lăsa pe nimeni să rămână;
“Báyìí tún ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Israẹli wí, kí ló dé tí ẹ fi ń mu ibi ńlá yìí wá sí orí ara yín nípa yíyapa kúrò lára Juda ọkùnrin àti obìnrin, ọmọdé àti èwe, tí ẹ kò sì ku ọ̀kankan?
8 În aceea că voi mă provocați la mânie cu lucrările mâinilor voastre, arzând tămâie altor dumnezei în țara Egiptului, unde ați mers să locuiți, ca să vă stârpiți și ca să ajungeți un blestem și o ocară printre toate națiunile pământului?
Èéṣe tí ẹ fi mú mi bínú pẹ̀lú ohun tí ọwọ́ yín ṣe pẹ̀lú ẹbọ sísun sí àwọn òrìṣà Ejibiti, níbi tí ẹ wá láti máa gbé? Ẹ̀ ò pa ara yín run, ẹ̀ ó sì sọ ara yín di ẹni ìfiré àti ẹ̀gàn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè ayé gbogbo.
9 Ați uitat voi stricăciunea părinților voștri și stricăciunea împăraților lui Iuda și stricăciunea soțiilor lor și propria voastră stricăciune și stricăciunea soțiilor voastre, pe care au făcut-o în țara lui Iuda și pe străzile Ierusalimului?
Ṣé ẹ̀yin ti gbàgbé ibi tí àwọn baba ńlá yín àti àwọn ọba; àwọn ayaba Juda, àti àwọn ibi tí ẹ ti ṣe àti àwọn ìyàwó yín ní ilẹ̀ Juda àti ní òpópó Jerusalẹmu?
10 Ei nu s-au umilit nici până în această zi, nici nu s-au temut, nici nu au umblat în legea mea, nici în statutele mele, pe care le-am pus înaintea voastră și înaintea părinților voștri.
Láti ìgbà náà sí àkókò yìí, wọn kò rẹ ara wọn sílẹ̀ tàbí fi ìtẹríba hàn tàbí kí wọn ó tẹ̀lé òfin àti àṣẹ tí mo pa fún un yín àti àwọn baba yín.
11 De aceea astfel spune DOMNUL oștirilor, Dumnezeul lui Israel: Iată, îmi voi întoarce fața împotriva voastră pentru rău și pentru a stârpi întreaga Iuda.
“Fún ìdí èyí, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn Israẹli wí: Mo ti pinnu láti mú ibi wá sí orí yín àti láti pa Juda run.
12 Și voi lua rămășița lui Iuda, care și-a întors fața pentru a merge în țara Egiptului, pentru a locui temporar acolo și ei vor fi cu toții mistuiți și vor cădea în țara Egiptului; vor fi mistuiți prin sabie și prin foamete; vor muri, de la cel mai mic până la cel mai mare, prin sabie și prin foamete; și vor fi detestați și o înmărmurire și un blestem și o ocară.
Èmi yóò sì mú àwọn èérún tí ó kù ní Juda, tí wọ́n ṣetán láti lọ Ejibiti. Wọn yóò ṣubú pẹ̀lú idà tàbí kí wọn kú pẹ̀lú ìyàn láti orí ọmọdé títí dé àgbà ni wọn yóò kú láti ọwọ́ ìyàn tàbí idà. Wọn yóò di ẹni ìfiré àti ìparun, ẹni ẹ̀kọ̀ àti ẹni ẹ̀gàn.
13 Fiindcă voi pedepsi pe cei care locuiesc în țara Egiptului, precum am pedepsit Ierusalimul, cu sabie, cu foamete și cu ciumă;
Èmi yóò fi ìyà jẹ ẹni tí ó bá ń gbé ní Ejibiti pẹ̀lú idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn bí mo ṣe fi ìyà jẹ Jerusalẹmu.
14 Astfel încât nimeni din rămășița lui Iuda, care a intrat în țara Egiptului pentru a locui temporar acolo, nu va scăpa nici nu va rămâne, ca să se poată întoarce în țara lui Iuda, spre care au dorința de a se întoarce și a locui acolo, pentru că nimeni nu se va întoarce decât cei care vor scăpa.
Kò sí èyí tí ó kéré jù nínú Juda tí ó kù, tí ó ń gbé ilẹ̀ Ejibiti tí yóò sá àsálà padà sórí ilẹ̀ Juda, èyí tí wọ́n nífẹ̀ẹ́ láti padà sí, àti láti máa gbé; àyàfi àwọn aṣàtìpó mélòó kan.”
15 Atunci toți bărbații care știau că soțiile lor ardeau tămâie altor dumnezei și toate femeile care stăteau de față în picioare, o mare mulțime, chiar tot poporul care locuia în țara Egiptului, în Patros, i-au răspuns lui Ieremia, spunând:
Lẹ́yìn èyí, gbogbo àwọn ọkùnrin tí ẹ bá mọ̀ pé, ìyàwó wọn sun tùràrí sí àwọn òrìṣà pẹ̀lú àwọn obìnrin tí ó bá wá àwọn ènìyàn púpọ̀, pàápàá àwọn ènìyàn tí wọ́n ń gbé ní òkè àti ìsàlẹ̀ Ejibiti, bẹ́ẹ̀ ni a wí fún Jeremiah.
16 Cât despre cuvântul pe care ni l-ai vorbit în numele DOMNULUI, nu îți vom da ascultare.
“Wọn sì wí pé, àwa kò ní fetísílẹ̀ ọ̀rọ̀ tí o bá bá wa sọ ní orúkọ Olúwa.
17 Ci vom face, într-adevăr, orice lucru care iese din gura noastră, pentru a arde tămâie împărătesei cerului și pentru a-i turna daruri de băutură, precum am făcut, noi și părinții noștri, împărații noștri și prinții noștri, în cetățile lui Iuda și pe străzile Ierusalimului, pentru că atunci aveam multe merinde și eram bine și nu am văzut niciun rău.
Dájúdájú, à ó ṣe gbogbo nǹkan tí a sọ pé à ò ṣe. A ó sun tùràrí sí ayaba ọ̀run, à ó sì da ohun mímu sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sí àwa àti àwọn baba wa, àwọn ọba àti àwọn aláṣẹ ti ṣe ní àwọn ìlú Juda àti ni àwọn ìgboro Jerusalẹmu. Nígbà náà àwa ní oúnjẹ púpọ̀, a sì ṣe rere a kò sì rí ibi.
18 Dar de când am încetat să ardem tămâie împărătesei cerului și să îi turnăm daruri de băutură, ne-au lipsit toate lucrurile și am fost mistuiți cu sabie și cu foamete.
Ṣùgbọ́n láti ìgbà tí a ti dáwọ́ tùràrí sísun sí Ayaba Ọ̀run àti láti da ẹbọ ohun mímu fún un, àwa ti ṣaláìní ohun gbogbo, a sì run nípa idà àti nípa ìyàn.”
19 Și după ce ardeam tămâie împărătesei cerului și îi turnam daruri de băutură, îi făceam turte pentru a ne închina ei, și îi turnam daruri de băutură, fără bărbații noștri?
Àwọn obìnrin náà fi kún un pé, “Nígbà tí à ń jó tùràrí sí ayaba ọ̀run, tí a sì ń fi ohun mímu rú ẹbọ si; ǹjẹ́ àwọn ọkọ wa kò mọ pé àwa ń ṣe àkàrà bí i, àwòrán rẹ, àti wí pé à ń da ọtí si gẹ́gẹ́ bi ohun ìrúbọ?”
20 Atunci Ieremia a spus întregului popor, bărbaților și femeilor și întregului popor care îi dăduse acest răspuns, spunând:
Wàyí o, Jeremiah sọ fún àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn náà, ọkùnrin àti obìnrin, tí wọn sì ń dáhùn pé,
21 Nu de tămâia pe care ați ars-o în cetățile lui Iuda și pe străzile Ierusalimului, voi și părinții voștri, împărații voștri și prinții voștri și poporul țării, și-a amintit DOMNUL și i-a venit în minte?
“Ṣe Olúwa kò rántí ẹbọ sísun ní ìlú Juda àti àwọn ìgboro Jerusalẹmu láti ọ̀dọ̀ rẹ àti ọ̀dọ̀ àwọn baba rẹ, àwọn ọba àti àwọn aláṣẹ àti àwọn ènìyàn ìlú.
22 Astfel încât DOMNUL nu v-a mai putut suferi, din cauza răutății facerilor voastre și din cauza urâciunilor pe care le-ați făcut; de aceea este țara voastră o pustiire și o înmărmurire și un blestem, fără locuitor, precum în această zi.
Nígbà tí Olúwa kò lè fi ara da ìwà búburú yín àti àwọn nǹkan ìríra gbogbo tí ẹ ṣe, ilẹ̀ yín sì di ohun ìfiré àti ìkọ̀sílẹ̀, láìsí olùgbé gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe wà lónìí.
23 Pentru că voi ați ars tămâie și pentru că ați păcătuit împotriva DOMNULUI și nu ați ascultat de vocea DOMNULUI, nici nu ați umblat în legea lui, nici în statutele lui, nici în mărturiile lui; de aceea acest rău vi s-a întâmplat, precum în această zi.
Nítorí pé ẹ ti sun ẹbọ, tí ẹ sì ti ṣẹ̀ sí Olúwa àti pé ẹ kò gbọ́rọ̀ sí i lẹ́nu, àti pé ẹ kò sì tẹ̀lé òfin rẹ̀ àti àwọn àṣẹ. Ibi náà yóò wá sórí rẹ àti bí o ṣe rí i.”
24 Mai mult, Ieremia a spus întregului popor și tuturor femeilor: Ascultați cuvântul DOMNULUI, tot Iuda, care sunteți în țara Egiptului;
Nígbà náà ni Jeremiah dáhùn pẹ̀lú obìnrin náà pé, “Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin ọmọ Juda tí ó wà ní Ejibiti.
25 Astfel vorbește DOMNUL oștirilor, Dumnezeul lui Israel, spunând: Voi și soțiile voastre ați vorbit deopotrivă cu gura voastră și ați împlinit cu mâinile voastre, spunând: Vom împlini cu siguranță promisiunile noastre pe care le-am promis, pentru a arde tămâie împărătesei cerului și pentru a-i turna daruri de băutură; vă veți împlini într-adevăr promisiunile și într-adevăr vă veți termina promisiunile.
Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí. Ìwọ àti àwọn ìyàwó rẹ fihàn pẹ̀lú àwọn ìhùwà rẹ àti àwọn ohun tí ó ṣèlérí nígbà tí o wí pé, ‘Àwa yóò mú ẹ̀jẹ́ tí a jẹ́ ṣẹ lórí sísun tùràrí àti dída ẹbọ ohun mímu sí orí ère Ayaba Ọ̀run.’ “Tẹ̀síwájú nígbà náà, ṣe ohun tí o sọ, kí o sì mú ẹ̀jẹ́ rẹ ṣẹ.
26 De aceea ascultați cuvântul DOMNULUI, tot Iuda care locuiți în țara Egiptului: Iată, eu am jurat prin numele meu mare, spune DOMNUL, că numele meu nu va mai fi numit în gura niciunui om din Iuda în toată țara Egiptului, spunând: Domnul DUMNEZEU trăiește.
Ṣùgbọ́n gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè, gbogbo ẹ̀yin Júù tí ń gbé ilẹ̀ Ejibiti, mo gégùn ún: ‘Mo búra pẹ̀lú títóbi orúkọ mi,’ bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí, ‘pé kò sí ẹnikẹ́ni láti Juda tí ń gbé ibikíbi ní Ejibiti tí ó gbọdọ̀ ké pe orúkọ mi tàbí búra, “Gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run tí ó dá wa ti wà láààyè.”
27 Iată, voi veghea asupra lor spre rău, și nu spre bine; și toți bărbații lui Iuda care sunt în țara Egiptului vor fi mistuiți cu sabie și cu foamete, până va fi un sfârșit al lor.
Nítorí náà, èmi ó ṣọ wọ́n fún ibi, kì í ṣe fún rere. Àti gbogbo àwọn ọkùnrin Juda tí ó wà ní ilẹ̀ Ejibiti ni a ó parun pẹ̀lú idà àti ìyàn títí tí gbogbo wọn yóò fi tán.
28 Totuși, un număr mic ce va scăpa de sabie se vor întoarce din țara Egiptului în țara lui Iuda și toată rămășița lui Iuda care a mers în țara Egiptului pentru a locui temporar acolo, va cunoaște ale cui cuvinte vor sta în picioare, ale mele, sau ale lor.
Àwọn tí ó bá sá àsálà kúrò lọ́wọ́ ìparun idà àti pípadà sí ilẹ̀ Juda láti Ejibiti yóò kéré níye. Gbogbo àwọn tí ó bá kú ní ilẹ̀ Juda, tí ó wá gbé ilẹ̀ Ejibiti yóò mọ ọ̀rọ̀ ẹni tí yóò dúró yálà tèmi tàbí tiyín.
29 Și acesta vă va fi un semn, spune DOMNUL, că vă voi pedepsi în acest loc, ca să știți că cuvintele mele vor sta în picioare negreșit împotriva voastră spre rău;
“‘Èyí ni yóò jẹ́ àmì fún un yín pé èmi yóò fi ìyà jẹ yín níbi tí Olúwa ti sọ láti lè jẹ́ kí ẹ mọ̀ pé ìjìyà mi tí mo sọ pé ẹ̀ ó jẹ yóò ṣẹ.’
30 Astfel spune DOMNUL: Iată, îl voi da pe Faraon Hofra împăratul Egiptului în mâna dușmanilor lui și în mâna celor care îi caută viața; precum l-am dat pe Zedechia, împăratul lui Iuda, în mâna lui Nebucadnețar împăratul Babilonului, dușmanul său și cel care îi căuta viața.
Báyìí ni Olúwa wí: ‘Èmi yóò fi Farao Hofira ọba Ejibiti lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ lọ́wọ́, èyí tí ó lè pa ayé rẹ́; gẹ́gẹ́ bí mo ti fi Sedekiah ọba Juda lé Nebukadnessari ọba Babeli lọ́wọ́ ọ̀tá tó ń lépa ẹ̀mí rẹ̀.’”

< Ieremia 44 >