< Ieremia 39 >

1 În anul al nouălea al lui Zedechia, împăratul lui Iuda, în luna a zecea, a venit Nebucadnețar, împăratul Babilonului, și toată armata lui împotriva Ierusalimului și l-au asediat.
Ó sì ṣe, nígbà tí a kó Jerusalẹmu, ní ọdún kẹsànán Sedekiah, ọba Juda, nínú oṣù kẹwàá, Nebukadnessari ọba Babeli gbógun ti Jerusalẹmu pẹ̀lú gbogbo ogun rẹ̀, wọ́n sì dó tì í.
2 Și în anul al unsprezecelea al lui Zedechia, în luna a patra, în a noua zi a lunii, cetatea a fost spartă.
Ní ọjọ́ kẹsànán, oṣù kẹrin ọdún kọkànlá Sedekiah, ni a wó odi ìlú náà.
3 Și toți prinții împăratului Babilonului au intrat și au șezut la poarta din mijloc, chiar Nergal-Șarețer, Samgar-Nebu, Sarsechim, Rabsaris, Nergal-Șarețer, Rabmag, cu toată rămășița prinților împăratului Babilonului.
Nígbà náà ni gbogbo àwọn ìjòyè ọba Babeli wá, wọ́n sì jókòó ní àárín ẹnu ibodè, àní Nergali-Ṣareseri ti Samgari, Nebo-Sarsikimu olórí ìwẹ̀fà, Nergali-Ṣareseri, olórí amòye, pẹ̀lú gbogbo àwọn ìjòyè ọba Babeli yóò kú.
4 Și s-a întâmplat, când i-a văzut Zedechia, împăratul lui Iuda, și toți bărbații de război, că au fugit și au ieșit din cetate noaptea, pe calea grădinii împăratului, prin poarta dintre cele două ziduri; și el a ieșit pe calea câmpiei.
Nígbà tí Sedekiah ọba Juda àti àwọn ọmọ-ogun rí wọn, wọ́n sá, wọ́n kúrò ní ìlú ní alẹ́, wọ́n gba ọ̀nà ọgbà ọba lọ láàrín ẹnu ibodè pẹ̀lú odi méjì, wọ́n dojúkọ aginjù.
5 Dar armata caldeenilor i-a urmărit și l-a ajuns pe Zedechia în câmpiile Ierihonului; și după ce l-au prins, l-au adus la Nebucadnețar, împăratul Babilonului, la Ribla în țara Hamatului, unde el a dat judecată asupra lui.
Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ọmọ-ogun Babeli lé wọn, wọ́n bá Sedekiah láàrín aginjù Jeriko. Wọ́n mú un ní ìgbèkùn, wọ́n sì mú u tọ Nebukadnessari ọba Babeli àti Ribla ní ilẹ̀ Hamati, níbi tí wọ́n ti ṣe ìdájọ́ rẹ̀.
6 Atunci împăratul Babilonului i-a ucis pe fiii lui Zedechia, în Ribla, înaintea ochilor lui; de asemenea împăratul Babilonului a ucis pe toți nobilii lui Iuda.
Níbẹ̀ ní Ribla, ni ọba Babeli ti dúńbú àwọn ọmọ Sedekiah lójú rẹ̀, tí ó sì tún pa gbogbo àwọn ọlọ́lá ilẹ̀ Juda.
7 Mai mult, el i-a scos ochii lui Zedechia și l-a legat cu lanțuri, pentru a-l duce în Babilon.
Nígbà náà ni ó fọ́ ojú Sedekiah, ó sì dè é pẹ̀lú ẹ̀wọ̀n láti gbé e lọ sí ilẹ̀ Babeli.
8 Și caldeenii au ars casa împăratului și casele poporului cu foc și au dărâmat zidurile Ierusalimului.
Àwọn Babeli dáná sun ààfin ọba àti ilé àwọn ènìyàn, wọ́n sì wó odi Jerusalẹmu.
9 Atunci Nebuzaradan, căpetenia gărzii, a dus captivă în Babilon, rămășița poporului care rămăsese în cetate și pe cei care fugiseră, care căzuseră în mâinile lui, împreună cu restul poporului care rămăsese.
Nebusaradani olórí àwọn ọmọ-ogun mú lọ sí ìgbèkùn Babeli pẹ̀lú gbogbo àwọn tí ó ṣẹ́kù nínú ìlú.
10 Dar Nebuzaradan, căpetenia gărzii, a lăsat dintre cei săraci din popor, care nu aveau nimic, în țara lui Iuda; și în acel timp le-a dat vii și câmpuri.
Ṣùgbọ́n Nebusaradani olórí ogun fi àwọn aláìní sílẹ̀ ní Juda, àwọn tí kò ní ohun kankan ní àkókò náà, ó fún wọn ní ọgbà àjàrà àti oko.
11 Și Nebucadnețar, împăratul Babilonului, a dat poruncă, referitor la Ieremia, lui Nebuzaradan căpetenia gărzii, spunând:
Nísinsin yìí, Nebukadnessari ọba àwọn Babeli pàṣẹ lórí Jeremiah, láti ọ̀dọ̀ Nebusaradani olórí ogun wá wí pé:
12 Ia-l și ai grijă de el și să nu îi faci nicio vătămare; ci să îi faci precum îți va spune.
“Ẹ gbé e, kí ẹ sì bojútó o. Ẹ má ṣe ṣe ohun búburú fún un, ṣùgbọ́n ohunkóhun tó bá béèrè ni kí ẹ fi fún un.”
13 Astfel Nebuzaradan, căpetenia gărzii, a trimis, și Nebușazban, Rabsaris și Nergal-Șarețer, Rabmag, și toți prinții împăratului Babilonului;
Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ pẹ̀lú, Nebusaradani balógun ìṣọ́, àti Nebusaradani olórí ìwẹ̀fà, àti Nergali-Ṣareseri, olórí amòye àti gbogbo àwọn ìjòyè ọba Babeli,
14 Chiar ei au trimis și l-au luat pe Ieremia din curtea închisorii și l-au dat lui Ghedalia, fiul lui Ahicam, fiul lui Șafan, ca să îl ducă acasă; astfel el a locuit printre popor.
ránṣẹ́ láti mú Jeremiah kúrò nínú túbú. Wọ́n gbé e lọ fún Gedaliah ọmọ Ahikamu ọmọ Ṣafani láti mú padà lọ sí ilé àti máa wà pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ̀.
15 Și cuvântul DOMNULUI a venit la Ieremia, în timp ce el era închis în curtea închisorii, spunând:
Nígbà tí Jeremiah wà nínú túbú, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ ọ́ wá wí pé:
16 Du-te și vorbește-i lui Ebed-Melec etiopianul, spunând: Astfel spune DOMNUL oștirilor, Dumnezeul lui Israel: Iată, voi aduce cuvintele mele asupra acestei cetăți spre rău și nu spre bine; și ele vor fi împlinite în acea zi înaintea ta.
“Lọ sọ fún Ebedimeleki ará Kuṣi, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: Èmi ṣetán láti mú ọ̀rọ̀ mi ṣẹ lórí ìlú yìí nípa àjálù kì í ṣe àlàáfíà. Ní àkókò náà ni yóò ṣẹ lójú rẹ.
17 Dar pe tine te voi elibera în acea zi, spune DOMNUL; și nu vei fi dat în mâna oamenilor de care te temi.
Ṣùgbọ́n, Èmi yóò gbà ọ́ lọ́jọ́ náà ni Olúwa wí. A kò ní fi ọ́ lé ọwọ́ àwọn tí o bẹ̀rù.
18 Pentru că te voi elibera într-adevăr și tu nu vei cădea prin sabie, ci viața ta va fi ca pradă pentru tine; deoarece ți-ai pus încrederea în mine, spune DOMNUL.
Èmi yóò gbà ọ́ là; o kò ní ṣubú láti ipa idà; ṣùgbọ́n ìwọ yóò sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ, nítorí pé ìwọ ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú mi, ni Olúwa wí.’”

< Ieremia 39 >