< Ieremia 25 >

1 Cuvântul care a venit la Ieremia referitor la tot poporul lui Iuda în anul al patrulea al lui Ioiachim, fiul lui Iosia, împăratul lui Iuda, care a fost anul întâi al lui Nebucadnețar, împăratul Babilonului;
Ọ̀rọ̀ sì tọ Jeremiah wá nípa àwọn ènìyàn Juda ní ọdún kẹrin Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda, èyí tí ó jẹ́ ọdún kìn-ín-ní Nebukadnessari ọba Babeli.
2 Cuvânt pe care profetul Ieremia l-a vorbit către tot poporul lui Iuda și către toți locuitorii Ierusalimului, spunând:
Nítorí náà, Jeremiah wòlíì sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn Juda àti sí àwọn olùgbé Jerusalẹmu.
3 Din anul al treisprezecelea al lui Iosia, fiul lui Amon, împăratul lui Iuda, chiar până în această zi, al douăzeci și treilea an, cuvântul DOMNULUI a venit la mine și eu v-am vorbit, ridicându-mă devreme și vorbind; dar voi nu ați dat ascultare.
Fún odidi ọdún mẹ́tàlélógún, bẹ̀rẹ̀ láti ọdún kẹtàlá Josiah, ọmọ Amoni ọba Juda, títí di ọjọ́ yìí, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, mo sì ti sọ ọ́ fún un yín láti ìgbà dé ìgbà, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetísílẹ̀.
4 Și DOMNUL i-a trimis la voi pe toți servitorii săi, profeții, ridicându-i devreme și trimițându-i; dar voi nu ați dat ascultare, nici nu v-ați aplecat urechea să ascultați.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa ti rán gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn wòlíì sí i yín láti ìgbà dé ìgbà, ẹ̀yin kò fetísílẹ̀.
5 Ei au spus: Întoarceți-vă acum, din nou, fiecare de la calea lui cea rea și de la răutatea facerilor voastre și locuiți în țara pe care DOMNUL v-a dat-o vouă și părinților voștri pentru totdeauna și întotdeauna;
Wọ́n sì wí pé, “Ẹ yípadà olúkúlùkù yín kúrò ní inú ibi rẹ̀ àti ní ọ̀nà ibi rẹ̀, ẹ̀yin yóò sì lè dúró ní ilẹ̀ tí Olúwa fún un yín àti àwọn baba yín títí láéláé.
6 Și nu mergeți după alți dumnezei pentru a le servi și a vă închina lor și nu mă provocați la mânie cu lucrările mâinilor voastre; iar eu nu vă voi vătăma.
Má ṣe tọ àwọn ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn láti sìn wọ́n tàbí bọ wọ́n; ẹ má ṣe mú inú bí mi pẹ̀lú ohun tí ẹ ti fi ọwọ́ yín ṣe. Nígbà náà ni Èmi kò ní ṣe yín ní ibi.”
7 Totuși, voi nu mi-ați dat ascultare, spune DOMNUL; ca să mă provocați la mânie cu lucrările mâinilor voastre spre vătămarea voastră.
“Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetí sí mi,” ni Olúwa wí; “bẹ́ẹ̀ ni ẹ sì ti mú inú bí mi pẹ̀lú ohun tí ẹ fi ọwọ́ yín ṣe, ẹ sì ti mú ibi wá sórí ara yín.”
8 De aceea astfel spune DOMNUL oștirilor: Pentru că nu ați ascultat cuvintele mele,
Nítorí náà, Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ èyí: “Nítorí wí pé ẹ̀yin kò fetí sí ọ̀rọ̀ mi,
9 Iată, voi trimite și voi lua toate familiile din nord, spune DOMNUL, și pe Nebucadnețar împăratul Babilonului, servitorul meu, și îi voi aduce împotriva acestei țări și împotriva locuitorilor ei și împotriva tuturor acestor națiuni de jur împrejur și le voi nimici cu totul și le voi face o înmărmurire și un motiv de șuierare și pustiiri veșnice.
Èmi yóò pe gbogbo àwọn ènìyàn àríwá, àti ìránṣẹ́ mi Nebukadnessari ọba Babeli,” ni Olúwa wí. “Èmi yóò sì mú wọn dìde lòdì sí ilẹ̀ náà àti àwọn olùgbé rẹ̀ àti sí gbogbo orílẹ̀-èdè àyíká rẹ̀. Èmi yóò pa wọ́n run pátápátá, Èmi yóò sọ wọ́n di nǹkan ẹ̀rù àti yẹ̀yẹ́ àti ìparun ayérayé.
10 Mai mult, voi lua de la ei vocea bucuriei și vocea veseliei, vocea mirelui și vocea miresei, sunetul pietrelor de moară și lumina lămpii.
Èmi yóò sì mú ìró ayọ̀ àti inú dídùn kúrò lọ́dọ̀ wọn; ohùn ìyàwó àti ọkọ ìyàwó, ìró ọlọ òkúta àti ìmọ́lẹ̀ fìtílà.
11 Și toată această țară va fi o pustiire și o înmărmurire; și aceste națiuni vor servi împăratului Babilonului șaptezeci de ani.
Gbogbo orílẹ̀-èdè yìí yóò sì di ahoro, orílẹ̀-èdè yìí yóò sì sìn ọba Babeli ní àádọ́rin ọdún.
12 Și se va întâmpla, după ce se vor împlini șaptezeci de ani, că voi pedepsi pe împăratul Babilonului și acea națiune, spune DOMNUL, pentru nelegiuirea lor și țara caldeenilor și o voi face pustiiri veșnice.
“Ṣùgbọ́n, nígbà tí àádọ́rin ọdún náà bá pé, Èmi yóò fi ìyà jẹ ọba Babeli àti orílẹ̀-èdè rẹ, ilẹ̀ àwọn ará Babeli nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn,” ni Olúwa wí; “bẹ́ẹ̀ ni Èmi yóò sọ ọ́ di ahoro títí láé.
13 Și voi aduce asupra acelei țări toate cuvintele mele pe care le-am rostit împotriva ei, tot ce este scris în această carte, pe care Ieremia a profețit-o împotriva tuturor națiunilor.
Èmi yóò sì mú gbogbo ohun tí mo ti sọ wọ̀nyí wá sórí ilẹ̀ náà, gbogbo ohun tí a ti sọ àní gbogbo èyí tí a ti kọ sínú ìwé yìí, èyí tí Jeremiah ti sọtẹ́lẹ̀ sí gbogbo orílẹ̀-èdè.
14 Pentru că multe națiuni și împărați mari le vor servi de asemenea; și eu le voi răsplăti conform cu faptele lor și conform cu lucrările propriilor mâini.
Àwọn fúnra wọn yóò sì sin orílẹ̀-èdè púpọ̀ àti àwọn ọba ńlá. Èmi yóò sì sán fún oníkálùkù gẹ́gẹ́ bí ìṣe àti iṣẹ́ ọwọ́ wọn.”
15 Pentru că astfel îmi spune mie DOMNUL Dumnezeul lui Israel: Ia paharul vinului acestei furii din mâna mea și fă toate națiunile la care te voi trimite, să îl bea.
Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí fún mi: “Gba ago yìí ní ọwọ́ mí tí ó kún fún ọtí wáìnì ìbínú mi, kí o sì mú gbogbo orílẹ̀-èdè ti mo rán ọ sí mu ún.
16 Și ele vor bea și se vor clătina și vor înnebuni din cauza sabiei pe care o voi trimite printre ele.
Nígbà tí wọ́n bá mu ún, wọn yóò ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n: bẹ́ẹ̀ ni kí wọ́n di aṣiwèrè nítorí idà tí yóò ránṣẹ́ sí àárín wọn.”
17 Atunci am luat paharul din mâna DOMNULUI și am făcut toate națiunile, la care DOMNUL m-a trimis, să îl bea;
Mo sì gba ago náà lọ́wọ́ Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni mo sì mú gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó rán mi sí mu ún.
18 Adică, Ierusalimul și cetățile lui Iuda și pe împărații lui și pe prinții lui, pentru a‑i face o pustiire, o înmărmurire, o șuierare și un blestem; precum este în această zi;
Jerusalẹmu àti àwọn ìlú Juda, àwọn ọba wọn pẹ̀lú àwọn aláṣẹ wọn, láti sọ wọ́n di ohun ìparun, ohun ẹ̀rù, ẹ̀sìn àti ègún, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti rí lónìí yìí.
19 Pe Faraon împăratul Egiptului și pe servitorii lui și pe prinții lui și pe tot poporul lui;
Farao ọba Ejibiti, àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn aláṣẹ rẹ̀ àti àwọn ènìyàn rẹ̀.
20 Și pe tot poporul amestecat și pe toți împărații din țara Uț și pe toți împărații din țara filistenilor și Ascalonul și Aza și Ecronul și rămășița Asdodului,
Àti gbogbo àwọn ènìyàn àjèjì tí ó wà níbẹ̀; gbogbo àwọn ọba Usi, gbogbo àwọn ọba Filistini, gbogbo àwọn ti Aṣkeloni, Gasa, Ekroni àti gbogbo àwọn ènìyàn tí ó kù sí Aṣdodu.
21 Edomul și Moabul și pe copiii lui Amon,
Edomu, Moabu àti Ammoni;
22 Și pe toți împărații Tirului și pe toți împărații Sidonului și pe împărații insulelor care sunt dincolo de mare,
gbogbo àwọn ọba Tire àti Sidoni; gbogbo àwọn ọba erékùṣù wọ̀n-ọn-nì tí ń bẹ ní ìkọjá Òkun.
23 Dedanul și Tema și Buzul și pe toți care sunt în colțurile cele mai îndepărtate,
Dedani, Tema, Busi àti gbogbo àwọn tí ń gbé lọ́nà jíjìn réré.
24 Și pe toți împărații Arabiei și pe toți împărații poporului amestecat care locuiesc în pustie,
Gbogbo àwọn ọba Arabia àti àwọn ọba àwọn àjèjì ènìyàn tí ń gbé inú aginjù.
25 Și pe toți împărații din Zimri și pe toți împărații Elamului și pe toți împărații mezilor,
Gbogbo àwọn ọba Simri, Elamu àti Media.
26 Și pe toți împărații din nord, de aproape și de departe, pe unul cu altul, și toate împărățiile lumii, care sunt pe fața pământului; și împăratul Șeșacului va bea după ei.
Àti gbogbo àwọn ọba àríwá ní tòsí àti lọ́nà jíjìn, ẹnìkínní lẹ́yìn ẹnìkejì; gbogbo àwọn ìjọba lórí orílẹ̀ ayé. Àti gbogbo wọn, ọba Ṣeṣaki náà yóò sì mu.
27 De aceea tu să le spui: Astfel spune DOMNUL oștirilor, Dumnezeul lui Israel: Beți și îmbătați-vă și vărsați și cădeți și să nu vă mai ridicați, din cauza sabiei pe care o voi trimite printre voi.
“Nígbà náà, sọ fún wọn, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára Israẹli wí. Mu, kí o sì mú àmuyó kí o sì bì, bẹ́ẹ̀ ni kí o sì ṣubú láì dìde mọ́ nítorí idà tí n ó rán sí àárín yín.
28 Și va fi astfel: dacă ei vor refuza să ia paharul din mâna ta pentru a bea, atunci să le spui: Astfel spune DOMNUL oștirilor: Să beți negreșit.
Ṣùgbọ́n bí wọ́n ba kọ̀ láti gba ago náà ní ọwọ́ rẹ kí wọ́n sì mu ún, sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: Ẹyin gbọdọ̀ mu ún!
29 Pentru că, iată, eu încep să aduc răul asupra cetății care se numește după numele meu; și voi să fiți cu totul nepedepsiți? Nu veți fi nepedepsiți, pentru că voi chema o sabie asupra tuturor locuitorilor pământului, spune DOMNUL oștirilor.
Wò ó, èmi ń mú ibi bọ̀ sí orí orílẹ̀-èdè tí ó ń jẹ́ orúkọ mi; ǹjẹ́ yóò ha a lè lọ láìjìyà? Ẹ̀yin ń pe idà sọ̀kalẹ̀ sórí gbogbo àwọn olùgbé ayé, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ.’
30 De aceea profețește împotriva lor toate aceste cuvinte și spune-le: DOMNUL va răcni din înălțime și își va înălța vocea din locuința lui sfântă; va răcni cu putere asupra locuinței lui; el va scoate un strigăt, asemenea celor care calcă strugurii, împotriva tuturor locuitorilor pământului.
“Nísinsin yìí, sọ àsọtẹ́lẹ̀ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí nípa wọn: “‘Kí o sì sọ pé, Olúwa yóò bú láti òkè wá, yóò sì bú kíkankíkan sí ilẹ̀ náà. Yóò parí gbogbo olùgbé ayé, bí àwọn tí ń tẹ ìfúntí.
31 Un zgomot va ajunge până la marginile pământului, pentru că DOMNUL are o neînțelegere cu națiunile, el, cu orice făptură, se va judeca; îi va da pe cei stricați sabiei, spune DOMNUL.
Ìrọ́kẹ̀kẹ̀ yóò wà títí dé òpin ilẹ̀ ayé, nítorí pé Olúwa yóò mú ìdààmú wá sí orí àwọn orílẹ̀-èdè náà, yóò mú ìdájọ́ wá sórí gbogbo ènìyàn, yóò sì fi àwọn olùṣe búburú fún idà,’” ni Olúwa wí.
32 Astfel spune DOMNUL oștirilor: Iată, răul va merge de la națiune la națiune și un mare vârtej de vânt va fi ridicat de la marginile pământului.
Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Wò ó! Ibi ń tànkálẹ̀ láti orílẹ̀-èdè kan sí òmíràn; ìjì ńlá yóò sì ru sókè láti òpin ayé.”
33 Și cei uciși de DOMNUL vor fi în acea zi de la o margine a pământului chiar până la cealaltă margine a pământului: ei nu vor fi plânși, nici adunați, nici îngropați; vor fi balegă pe pământ.
Nígbà náà, àwọn tí Olúwa ti pa yóò wà ní ibi gbogbo, láti ìpẹ̀kun kan sí òmíràn. A kì yóò ṣọ̀fọ̀ wọn, a kì yóò kó wọn jọ tàbí sin wọ́n; ṣùgbọ́n wọn yóò dàbí ààtàn lórí ilẹ̀.
34 Urlați, voi păstori, și strigați; și tăvăliți-vă în cenușă, voi, stăpâni ai turmei, pentru că zilele măcelului vostru și ale împrăștierii voastre sunt împlinite; și veți cădea ca un vas plăcut.
Ké, kí ẹ sì pohùnréré ẹkún ẹ̀yin olùṣọ́-àgùntàn, ẹ yí nínú eruku, ẹ̀yin olùdarí agbo ẹran. Nítorí pé ọjọ́ àti pa yín ti dé, ẹ̀yin ó sì ṣubú bí ohun èlò iyebíye.
35 Și păstorii nu vor avea cale să fugă, nici stăpânii turmei să scape.
Àwọn olùṣọ́-àgùntàn kì yóò rí ibi sálọ kì yóò sì ṣí àsálà fún olórí agbo ẹran.
36 O voce de strigăt a păstorilor și un urlet al stăpânilor turmei va fi auzit, pentru că DOMNUL le-a prădat pășunea.
Gbọ́ igbe àwọn olùṣọ́-àgùntàn, àti ìpohùnréré ẹkún àwọn olórí agbo ẹran; nítorí pé Olúwa ń pa pápá oko tútù wọn run.
37 Și locuințele pașnice sunt stârpite din cauza mâniei înverșunate a DOMNULUI.
Ibùgbé àlàáfíà yóò di ahoro, nítorí ìbínú ńlá Olúwa.
38 El și-a părăsit adăpostul, ca un leu, pentru că țara lor este pustiită din cauza înverșunării opresorului și din cauza înverșunării mâniei sale.
Gẹ́gẹ́ bí kìnnìún yóò fi ibùba rẹ̀ sílẹ̀, ilẹ̀ wọn yóò sì di ahoro, nítorí idà àwọn aninilára, àti nítorí ìbínú ńlá Olúwa.

< Ieremia 25 >