< Ieremia 20 >

1 Și Pașhur, fiul lui Imer, preotul, care era de asemenea marele guvernator al casei DOMNULUI, a auzit că Ieremia a profețit aceste lucruri.
Ní ìgbà tí àlùfáà Paṣuri ọmọkùnrin Immeri olórí àwọn ìjòyè tẹmpili Olúwa gbọ́ tí Jeremiah ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ nǹkan wọ̀nyí.
2 Atunci Pașhur l-a lovit pe Ieremia, profetul, și l-a pus în butucii care erau la poarta înaltă a lui Beniamin, care era lângă casa DOMNULUI.
Ó mú kí wọ́n lù wòlíì Jeremiah, kí wọ́n sì fi sínú túbú tí ó wà ní òkè ẹnu-ọ̀nà ti Benjamini ní tẹmpili Olúwa.
3 Și s-a întâmplat a doua zi, că Pașhur l-a scos pe Ieremia din butuci. Atunci Ieremia i-a spus: DOMNUL nu ți-a pus numele Pașhur, ci Magor-Misabib.
Ní ọjọ́ kejì tí Paṣuri tú u sílẹ̀ nínú túbú, Jeremiah sì sọ fún un wí pé, “Orúkọ Olúwa fun ọ kì í ṣe Paṣuri bí kò ṣe ìpayà.
4 Pentru că astfel spune DOMNUL: Iată, te voi face o teroare pentru tine însuți și pentru toți prietenii tăi: și ei vor cădea prin sabia dușmanilor lor și ochii tăi vor privi aceasta; și voi da pe tot Iuda în mâna împăratului Babilonului și el îi va duce captivi în Babilon și îi va ucide cu sabia.
Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa sọ. Èmi yóò mú ọ di ẹ̀rùjẹ̀jẹ̀ sí ara rẹ àti sí gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ rẹ. Ní ojú ara rẹ, ìwọ yóò sì rí tí wọ́n ṣubú nípa idà ọ̀tá wọn. Èmi yóò fi gbogbo àwọn ọ̀tá Juda lé ọba Babeli lọ́wọ́, òun yóò sì kó wọn lọ sí Babeli tàbí kí ó pa wọ́n.
5 Mai mult, eu voi da toată tăria acestei cetăți și toată munca ei și toate lucrurile prețioase ale ei și toate tezaurele împăraților lui Iuda le voi da în mâna dușmanilor lor, care îi vor prăda și îi vor lua și îi vor duce în Babilon.
Èmi yóò jọ̀wọ́ gbogbo ọrọ̀ inú ìlú yìí fún ọ̀tá wọn. Gbogbo ìní wọ́n gbogbo ọlá ọba Juda. Wọn yóò sì ru ìkógun lọ sí Babeli.
6 Și tu, Pașhur, și toți cei ce locuiesc în casa ta veți merge în captivitate; și tu vei veni în Babilon și acolo vei muri și acolo vei fi îngropat, tu și toți prietenii tăi, cărora le-ai profețit minciuni.
Àti ìwọ Paṣuri, gbogbo ènìyàn inú ilé rẹ yóò sì lọ ṣe àtìpó ní Babeli. Níbẹ̀ ni ìwọ yóò sì kú sí, tí wọn yóò sì sin ọ́ síbẹ̀, ìwọ àti gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ rẹ tí ìwọ ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ irọ́ fún.”
7 DOAMNE, tu m-ai înșelat și eu am fost înșelat; tu ești mai tare decât mine și ai învins; zilnic, eu sunt un lucru de râs, fiecare mă batjocorește.
Olúwa, o tàn mí jẹ́, o sì ṣẹ́gun. Mo di ẹni ẹ̀gàn ní gbogbo ọjọ́, gbogbo ènìyàn fi mí ṣẹlẹ́yà.
8 Pentru că de când am vorbit, am strigat, am strigat violență și pradă; căci cuvântul DOMNULUI a fost făcut o ocară pentru mine și, zilnic, un lucru de râs.
Nígbàkígbà tí mo bá sọ̀rọ̀, èmi sì kígbe síta èmi á sọ nípa ipá àti ìparun. Nítorí náà, ọ̀rọ̀ Olúwa ti mú àbùkù àti ẹ̀gàn bá mi ni gbogbo ìgbà.
9 Atunci am spus: Nu voi aminti despre el, nici nu voi mai vorbi în numele lui. Dar cuvântul lui a fost în inima mea ca un foc arzând, închis în oasele mele, și am obosit purtându-l și nu mai puteam.
Ṣùgbọ́n bí mo bá sọ pé, “Èmi kì yóò dárúkọ rẹ tàbí sọ nípa orúkọ rẹ̀ mọ́, ọ̀rọ̀ rẹ̀ ń bẹ bi iná tí ń jó nínú mi nínú egungun mi, agara dá mi ní inú mi nítòótọ́ èmi kò lè ṣe é.
10 Pentru că am auzit defăimarea multora, frică de fiecare parte. Vestiți, spun ei, și noi o vom vesti. Toți cunoscuții mei au căutat șchiopătarea mea, spunând: Poate că va fi ademenit și îl vom învinge și ne vom răzbuna pe el.
Mo gbọ́ sísọ ọ̀rọ̀ kẹ́lẹ́kẹ́lẹ́, ìbẹ̀rù ni ibi gbogbo. Fi í sùn! Jẹ́ kí a fi sùn! Gbogbo àwọn ọ̀rẹ́ mi ń dúró kí èmi ṣubú, wọ́n sì ń sọ pé, bóyá yóò jẹ́ di títàn, nígbà náà ni àwa yóò borí rẹ̀, àwa yóò sì gba ẹ̀san wa lára rẹ̀.”
11 Dar DOMNUL este cu mine ca un viteaz puternic; de aceea persecutorii mei se vor poticni și nu vor învinge; ei vor fi foarte rușinați, pentru că nu vor prospera; disprețuirea lor veșnică nu va fi niciodată uitată.
Ṣùgbọ́n Olúwa ń bẹ pẹ̀lú mi gẹ́gẹ́ bí akọni ẹlẹ́rù. Nítorí náà, àwọn tí ó ń lépa mi yóò kọsẹ̀, wọn kì yóò sì borí. Wọn yóò kùnà, wọn yóò sì gba ìtìjú púpọ̀. Àbùkù wọn kì yóò sì di ohun ìgbàgbé.
12 Dar, DOAMNE al oștirilor, tu care încerci pe cel drept și vezi rărunchii și inima, lasă-mă să văd răzbunarea ta asupra lor, pentru că ție ți-am arătat cauza mea.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ìwọ tí ó ń dán olódodo wò tí o sì ń ṣe àyẹ̀wò ọkàn àti ẹ̀mí fínní fínní, jẹ́ kí èmi kí ó rí ìgbẹ̀san rẹ lórí wọn, nítorí ìwọ ni mo gbé ara mi lé.
13 Cântați DOMNULUI, lăudați pe DOMNUL, pentru că el a eliberat sufletul celui sărac din mâna făcătorilor de rău.
Kọrin sí Olúwa! Fi ìyìn fún Olúwa! Ó gba ẹ̀mí àwọn aláìní lọ́wọ́ àwọn ẹni búburú.
14 Blestemată fie ziua în care am fost născut; să nu fie binecuvântată ziua în care mama mea m-a născut.
Ègbé ni fún ọjọ́ tí a bí mi! Kí ọjọ́ tí ìyá mi bí mi má ṣe di ti ìbùkún.
15 Blestemat fie omul care a adus vești tatălui meu, spunând: Un copil de parte bărbătească ți s-a născut; înveselindu-l.
Ègbé ni fún ọkùnrin tí ó mú ìròyìn wá fún baba mi, tí ó mú kí ó yọ̀, tí ó sì sọ wí pé, “A bí ọmọ kan fún ọ—ọmọkùnrin!”
16 Și acel om să fie ca cetățile pe care DOMNUL le-a dărâmat și nu s-au pocăit. Și să audă el plânset dimineața și strigare la amiază;
Kí ọkùnrin náà dàbí ìlú tí Olúwa gbàkóso lọ́wọ́ rẹ̀ láìkáàánú Kí o sì gbọ́ ariwo ọ̀fọ̀ ní àárọ̀, ariwo ogun ní ọ̀sán.
17 Pentru că nu m-a ucis din pântece; și mama mea mi-ar fi fost mormântul și pântecele ei însărcinat întotdeauna cu mine.
Nítorí kò pa mí nínú, kí ìyá mi sì dàbí títóbi ibojì mi, kí ikùn rẹ̀ sì di títí láé.
18 Pentru ce am ieșit din pântece, ca să văd osteneală și întristare, ca zilele mele să fie mistuite cu rușine?
Èéṣe tí mo jáde nínú ikùn, láti rí wàhálà àti ọ̀fọ̀ àti láti parí ayé mi nínú ìtìjú?

< Ieremia 20 >