< Ieremia 11 >
1 Cuvântul care a venit la Ieremia de la DOMNUL, spunând:
Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Jeremiah wá:
2 Ascultați cuvintele acestui legământ și vorbiți bărbaților lui Iuda și locuitorilor Ierusalimului;
“Fetísílẹ̀ sí ọ̀rọ̀ májẹ̀mú yìí, kí o sì sọ wọ́n fún àwọn ènìyàn Juda, àti gbogbo àwọn tó ń gbé ni Jerusalẹmu.
3 Și spune-le: Astfel spune DOMNUL Dumnezeul lui Israel: Blestemat fie omul care nu ascultă de cuvintele acestui legământ,
Sọ fún wọn wí pé èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Ègbé ni fún ẹni náà tí kò pa ọ̀rọ̀ májẹ̀mú yìí mọ́.
4 Pe care l-am poruncit părinților voștri în ziua în care i-am scos din țara Egiptului, din cuptorul de fier, spunând: Ascultați de vocea mea și faceți-le, conform cu toate cele ce vă poruncesc, astfel veți fi poporul meu și eu voi fi Dumnezeul vostru;
Àwọn májẹ̀mú tí mo pàṣẹ fún àwọn baba ńlá yín, nígbà tí mo mú wọn jáde láti Ejibiti, láti inú iná alágbẹ̀dẹ wá.’ Mo wí pé, ‘Ẹ gbọ́ tèmi, kí ẹ sì ṣe ohun gbogbo tí mo pàṣẹ fún un yín. Ẹ̀yin ó sì jẹ́ ènìyàn mi, Èmi ó sì jẹ́ Ọlọ́run yín.
5 Ca să împlinesc jurământul pe care l-am jurat părinților voștri, să le dau o țară în care curge lapte și miere, precum este în această zi. Atunci am răspuns și am spus: Așa să fie, DOAMNE.
Nígbà náà ni Èmi ó sì mú ìlérí tí mo búra fún àwọn baba ńlá yín ṣẹ; láti fún wọn ní ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti fún oyin,’ ilẹ̀ tí ẹ ní lónìí.” Mo sì dáhùn wí pé, “Àmín, Olúwa.”
6 Atunci DOMNUL mi-a spus: Vestește toate aceste cuvinte în cetățile lui Iuda și pe străzile Ierusalimului, spunând: Ascultați cuvintele acestui legământ și faceți‑le.
Olúwa wí fún mi pé, “Kéde gbogbo ọ̀rọ̀ yìí ní àwọn ìlú Juda àti ní gbogbo òpópónà ìgboro Jerusalẹmu pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ májẹ̀mú yìí, kí ẹ sì se wọn.
7 Pentru că i-am avertizat cu stăruință pe părinții voștri în ziua în care i-am scos din țara Egiptului, până în această zi, sculându-mă devreme și avertizându‑i, spunând: Ascultați de vocea mea.
Láti ìgbà tí mo ti mú àwọn baba yín jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá títí di òní, mo kìlọ̀ fún wọn lọ́pọ̀ ìgbà wí pé, “Ẹ gbọ́ tèmi.”
8 Totuși ei nu au ascultat de mine, nici nu și-au plecat urechea, ci fiecare a umblat în închipuirea inimii lui rele; de aceea voi aduce asupra lor toate cuvintele acestui legământ, pe care li le-am poruncit să le facă; dar nu le-au făcut.
Ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò kọbi ara sí i dípò èyí wọ́n tẹ̀síwájú ni agídí ọkàn wọn. Mo sì mú gbogbo ègún inú májẹ̀mú tí mo ti ṣèlérí, tí mo sì ti pàṣẹ fún wọn láti tẹ̀lé, tí wọn kò tẹ̀lé wa sórí wọn.’”
9 Și DOMNUL mi-a spus: S-a găsit o uneltire printre bărbații lui Iuda și printre locuitorii Ierusalimului.
Olúwa sì wí fún mi pé, “Ọ̀tẹ̀ kan wà láàrín àwọn ará Juda àti àwọn tí ń gbé ní Jerusalẹmu.
10 Ei s-au întors la nelegiuirile strămoșilor lor, care au refuzat să asculte cuvintele mele; și au mers după alți dumnezei, pentru a le servi; casa lui Israel și casa lui Iuda au rupt legământul meu pe care l-am făcut cu părinții lor.
Wọ́n ti padà sí ìdí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba ńlá wọn tí wọn kọ̀ láti tẹ́tí sí ọ̀rọ̀ mi, wọ́n ti tẹ̀lé àwọn ọlọ́run mìíràn láti sìn wọ́n. Ilé Israẹli àti ilé Juda ti ba májẹ̀mú tí mo dá pẹ̀lú àwọn baba ńlá wọn jẹ́.
11 De aceea astfel spune DOMNUL: Iată, voi aduce asupra lor răul de care nu vor fi în stare să scape; și chiar dacă vor striga către mine, eu nu le voi da ascultare.
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa wí: ‘Èmi yóò mu ibi tí wọn kò ní le è yẹ̀ wá sórí wọn, bí wọ́n tilẹ̀ ké pè mí èmi kì yóò fetí sí igbe wọn.
12 Atunci cetățile lui Iuda și locuitorii Ierusalimului vor merge și vor striga către dumnezeii cărora le oferă tămâie; dar nicidecum ei nu îi vor salva în timpul tulburării lor.
Àwọn ìlú Juda àti àwọn ará Jerusalẹmu yóò lọ kégbe sí àwọn òrìṣà tí wọ́n ń sun tùràrí sí; àwọn òrìṣà náà kò ní ràn wọ́n lọ́wọ́ ní ìgbà tí ìpọ́njú náà bá dé.
13 Căci conform cu numărul cetăților tale au fost dumnezeii tăi, Iudo; și conform cu numărul străzilor Ierusalimului ați ridicat voi altare acelui lucru rușinos, altare pentru a arde tămâie lui Baal.
Ìwọ Juda, bí iye àwọn ìlú rẹ, bẹ́ẹ̀ iye àwọn òrìṣà rẹ; bẹ́ẹ̀ ni iye pẹpẹ tí ẹ̀yin ti tẹ́ fún sísun tùràrí Baali ohun ìtìjú n nì ṣe pọ̀ bí iye òpópónà tí ó wà ní Jerusalẹmu.’
14 De aceea tu nu te ruga pentru acest popor, nici nu înălța strigăt sau rugăciune pentru ei, pentru că nu îi voi asculta în timpul în care vor striga către mine din cauza tulburării lor.
“Má ṣe gbàdúrà fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí tàbí kí o bẹ̀bẹ̀ fún wọn, nítorí pé, Èmi kì yóò dẹtí sí wọn nígbà tí wọ́n bá ké pè mí ní ìgbà ìpọ́njú.
15 Ce are preaiubita mea a face în casa mea, văzând că ea a lucrat cu desfrânare cu mulți și carnea cea sfântă este luată de la tine? Când faci răul, atunci te bucuri.
“Kí ni olùfẹ́ mi ní í ṣe ní tẹmpili mi, bí òun àti àwọn mìíràn ṣe ń hu oríṣìíríṣìí ìwà àrékérekè? Ǹjẹ́ ẹran tí a yà sọ́tọ̀ lè mú ìjìyà kúrò lórí rẹ̀? Nígbà tí ó bá ń ṣe iṣẹ́ búburú rẹ̀, nígbà náà jẹ́ kí inú rẹ̀ kí ó dùn.”
16 DOMNUL ți-a pus numele: Un măslin verde, frumos și cu rod plăcut; cu zgomotul unui mare tumult el a aprins focul peste el și ramurile lui sunt rupte.
Olúwa pè ọ́ ní igi olifi pẹ̀lú èso rẹ tí ó dára ní ojú. Ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ìjì líle ọ̀wọ́-iná ni yóò sun ún tí àwọn ẹ̀ka rẹ̀ yóò sì di gígé kúrò.
17 Pentru că DOMNUL oștirilor, care te-a sădit, a pronunțat răul împotriva ta, datorită răutății casei lui Israel și casei lui Iuda, pe care au făcut-o împotriva lor înșiși, pentru a mă provoca la mânie prin oferirea de tămâie lui Baal.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun tí ó dá ọ ti kéde ibi sí ọ, nítorí ilé Israẹli àti Juda ti ṣe ohun ibi, wọ́n sì ti mú inú bí mi, wọ́n ti ru ìbínú mi sókè nípa sísun tùràrí si Baali.
18 Și DOMNUL mi-a dat cunoașterea acesteia, și eu știu; atunci mi-ai arătat faptele lor.
Nítorí Olúwa fi ọ̀tẹ̀ wọn hàn mí mo mọ̀ ọ́n; nítorí ní àsìkò náà ó fi ohun tí wọ́n ń ṣe hàn mí.
19 Dar eu eram ca un miel sau un bou care este adus la măcelărire; și nu am știut că ei plănuiau planuri împotriva mea, spunând: Să distrugem pomul cu rodul lui și să îl stârpim din țara celor vii, ca numele lui să nu mai fie amintit.
Mo ti dàbí ọ̀dọ́-àgùntàn jẹ́ẹ́jẹ́ tí a mú lọ fún pípa; n kò mọ̀ pé wọ́n ti gbìmọ̀ búburú sí mi wí pé: “Jẹ́ kí a run igi àti èso rẹ̀; jẹ́ kí a gé e kúrò ní orí ilẹ̀ alààyè, kí a má lè rántí orúkọ rẹ̀ mọ́.”
20 Dar tu, DOAMNE al oștirilor, care judeci cu dreptate, care încerci rărunchii și inima, lasă-mă să văd răzbunarea ta asupra lor, pentru că ție ți-am descoperit cauza mea.
Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa àwọn ọmọ-ogun, tí ó ń ṣe ìdájọ́ òdodo, tí ó ń ṣe àyẹ̀wò ẹ̀mí àti ọkàn, jẹ́ kí n rí ẹ̀san rẹ lórí wọn; nítorí ìwọ ni mo fi ọ̀rọ̀ mi lé lọ́wọ́.
21 De aceea astfel spune DOMNUL despre bărbații din Anatot, care îți caută viața, spunând: Să nu profețești în numele DOMNULUI, ca să nu mori de mâna noastră;
“Nítorí náà, èyí ni ohun tí Ọlọ́run sọ nípa àwọn arákùnrin Anatoti tí wọ́n ń lépa ẹ̀mí rẹ̀, tí wọ́n ń wí pé, ‘Má ṣe sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní orúkọ Olúwa, bí bẹ́ẹ̀ kọ́ ìwọ ó kú láti ọwọ́ wa.’
22 De aceea astfel spune DOMNUL oștirilor: Iată, eu îi voi pedepsi; tinerii vor muri de sabie; fiii lor și fiicele lor vor muri de foamete;
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ pé, ‘Èmi yóò fì ìyà jẹ wọ́n, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wọn yóò tipasẹ̀ idà kú, ìyàn yóò pa àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn.
23 Și nu va fi nici[o] rămășiță din ei, pentru că voi aduce răul peste bărbații din Anatot, în anul cercetării lor.
Kò ní ṣẹ́kù ohunkóhun sílẹ̀ fún wọn nítorí èmi yóò mú ibi wá sórí àwọn ènìyàn Anatoti ní ọdún ìbẹ̀wò wọn.’”