< Isaia 7 >
1 Şi s-a întâmplat în zilele lui Ahaz, fiul lui Iota, fiul lui Ozia, împăratul lui Iuda, că Rezin, împăratul Siriei, şi Peca, fiul lui Remalia, împăratul Israelului, s-au urcat la Ierusalim să se războiască împotriva lui, dar nu l-au învins.
Nígbà tí Ahasi ọmọ Jotamu ọmọ Ussiah jẹ́ ọba Juda, ọba Resini ti Aramu àti Peka ọmọ Remaliah ọba Israẹli gòkè wá láti bá Jerusalẹmu jà, ṣùgbọ́n wọn kò sì le è borí i rẹ̀.
2 Şi s-a spus casei lui David, zicând: Siria s-a unit cu Efraim. Şi inima lui şi inima poporului său a fost mişcată, precum copacii pădurii sunt mişcaţi de vânt.
Báyìí, a sọ fún ilé Dafidi pé, “Aramu mà ti lẹ̀dí àpò pọ̀ mọ́ Efraimu”; fún ìdí èyí, ọkàn Ahasi àti àwọn ènìyàn rẹ̀ wárìrì gẹ́gẹ́ bí igi oko ṣe ń wárìrì níwájú afẹ́fẹ́.
3 Atunci DOMNUL i-a spus lui Isaia: Du-te înainte acum să întâlneşti pe Ahaz, tu şi Şear-Iaşub, fiul tău, la marginea apeductului iazului superior, pe drumul mare al câmpului înălbitorului;
Lẹ́yìn èyí, Olúwa sọ fún Isaiah pé, “Jáde, ìwọ àti ọ̀dọ́mọkùnrin rẹ Ṣeari-Jaṣubu láti pàdé Ahasi ní ìpẹ̀kun ìṣàn omi ti adágún òkè, ní òpópó ọ̀nà tí ó lọ sí pápá Alágbàfọ̀.
4 Şi spune-i: Ia seama şi linişteşte-te; nu te teme, nici nu fi cu inima slabă din cauza celor două cozi ai acestor tăciuni care fumegă, din cauza mâniei înverşunate a lui Rezin cu Siria şi a fiului lui Remalia.
Sọ fún un, ‘Ṣọ́ra à rẹ, fi ọkàn balẹ̀, kí o má ṣe bẹ̀rù. Má ṣe ba ọkàn jẹ́ nítorí kùkùté igi ìdáná méjèèjì yìí, nítorí ìbínú gbígbóná Resini àti Aramu àti ti ọmọ Remaliah.
5 Pentru că Siria, Efraim şi fiul lui Remalia au ţinut sfat rău împotriva ta, spunând:
Aramu, Efraimu àti Remaliah ti dìtẹ̀ ìparun rẹ, wọ́n wí pé,
6 Să ne urcăm împotriva lui Iuda şi să îl chinuim şi să ne facem în el o spărtură şi să aşezăm un împărat în mijlocul lui, adică pe fiul lui Tabeal;
“Jẹ́ kí a kọlu Juda; jẹ́ kí a fà á ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ, kí a sì pín in láàrín ara wa, kí a sì fi ọmọ Tabeli jẹ ọba lórí i rẹ̀.”
7 Astfel spune Domnul DUMNEZEU: Nu va rămâne în picioare, nici nu se va întâmpla.
Síbẹ̀ èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èyí kò ní wáyé èyí kò le ṣẹlẹ̀,
8 Deoarece capul Siriei este Damascul şi capul Damascului este Rezin; şi în şaizeci şi cinci de ani Efraim va fi frânt, încât nu va fi un popor.
nítorí Damasku ni orí Aramu, orí Damasku sì ni Resini. Láàrín ọdún márùnlélọ́gọ́ta Efraimu yóò ti fọ́ tí kì yóò le jẹ́ ènìyàn mọ́.
9 Şi capul lui Efraim este Samaria şi capul Samariei este fiul lui Remalia. Dacă nu veţi crede, cu siguranţă nu veţi fi întemeiaţi.
Orí Efraimu sì ni Samaria, orí Samaria sì ni ọmọ Remaliah. Bí ẹ̀yin kí yóò bá gbàgbọ́, lóòtítọ́, a kì yóò fi ìdí yín múlẹ̀.’”
10 Mai mult, DOMNUL a vorbit din nou lui Ahaz, spunând:
Bákan náà Olúwa tún bá Ahasi sọ̀rọ̀,
11 Cere semn de la DOMNUL Dumnezeul tău; cere-l, fie în adânc, fie în înălţimea de deasupra. (Sheol )
“Béèrè fún àmì lọ́wọ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ, bóyá ní ọ̀gbun tí ó jì jùlọ tàbí àwọn òkè tí ó ga jùlọ.” (Sheol )
12 Dar Ahaz a spus: Nu cer, nici nu îl ispitesc pe DOMNUL.
Ṣùgbọ́n Ahasi sọ pé, “Èmi kì yóò béèrè; Èmi kò ní dán Olúwa wò.”
13 Iar el a spus: Ascultaţi acum, casa lui David. Este un lucru mic pentru voi să obosiţi oamenii, dar veţi obosi şi pe Dumnezeul meu?
Lẹ́yìn náà Isaiah sọ pé, “Gbọ́ ní ìsinsin yìí, ìwọ ilé Dafidi, kò ha tọ́ láti tán ènìyàn ní sùúrù, ìwọ yóò ha tan Ọlọ́run ní sùúrù bí?
14 De aceea Domnul însuşi vă va da un semn: Iată, o fecioară va rămâne însărcinată şi va naşte un fiu şi îi va pune numele, Emanuel.
Nítorí náà, Olúwa fúnra ara rẹ̀ ni yóò fún ọ ní àmì kan. Wúńdíá kan yóò lóyún, yóò sì bí ọmọkùnrin kan, yóò sì pe orúkọ rẹ̀ ní Emmanueli.
15 El va mânca unt şi miere, pentru a şti să refuze răul şi să aleagă binele.
Òun yóò jẹ wàrà àti oyin nígbà tí ó bá ní ìmọ̀ tó láti kọ ẹ̀bi àti láti yan rere.
16 Căci înainte ca pruncul să ştie să refuze răul şi să aleagă binele, ţara pe care tu o deteşti va fi părăsită de amândoi împăraţii ei.
Ṣùgbọ́n kí ọ̀dọ́mọkùnrin náà tó mọ bí a ti ń kọ ẹ̀bi àti láti yan rere, ilẹ̀ àwọn ọba méjèèjì tí ń bà ọ́ lẹ́rù wọ̀nyí yóò ti di ahoro.
17 DOMNUL va aduce asupra ta şi asupra poporului tău şi asupra casei tatălui tău, zile ce nu au mai venit, din ziua în care Efraim a plecat din Iuda; [adică] pe împăratul Asiriei.
Olúwa yóò mú àsìkò mìíràn wá fún ọ àti àwọn ènìyàn rẹ àti lórí ilé baba rẹ irú èyí tí kò sí láti ìgbà tí Efraimu ti yà kúrò ní Juda, yóò sì mú ọba Asiria wá.”
18 Şi se va întâmpla, în acea zi, că DOMNUL va şuiera după musca care este în cea mai îndepărtată parte a râurilor Egiptului şi după albina ce este în ţara Asiriei.
Ní ọjọ́ náà ni Olúwa yóò súfèé pe àwọn eṣinṣin láti àwọn odò tó jìnnà ní Ejibiti wá, àti fún àwọn oyin láti ilẹ̀ Asiria.
19 Şi vor veni şi toate se vor odihni în văile pustiite şi în crăpăturile stâncilor şi pe toţi spinii şi pe toate tufişurile.
Gbogbo wọn yóò sì wá dó sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè àti pàlàpálá òkúta, lára koríko ẹ̀gún àti gbogbo ibi ihò omi.
20 În aceeaşi zi Domnul va rade cu o lamă angajată, adică cu cei de dincolo de râu, cu împăratul Asiriei, capul şi părul picioarelor şi de asemenea va mistui barba.
Ní ọjọ́ náà, Olúwa yóò lo abẹ fífẹ́lẹ́ tí a yá láti ìkọjá odò Eufurate, ọba Asiria, láti fá irun orí àti ti àwọn ẹsẹ̀ ẹ yín, àti láti mú irùngbọ̀n yín kúrò pẹ̀lú.
21 Şi se va întâmpla, în acea zi, că un om va hrăni o viţea şi două oi;
Ní ọjọ́ náà, ọkùnrin kan yóò máa sin ọ̀dọ́ abo màlúù kan àti ewúrẹ́ méjì.
22 Şi se va întâmpla din cauza abundenţei de lapte pe care îl vor da, că el va mânca unt, căci unt şi miere vor mânca toţi cei ce rămân în ţară.
Àti nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ wàrà tí wọn yóò máa fún un, yóò ní wàràǹkàṣì láti jẹ. Gbogbo àwọn tí ó bá kù ní ilẹ̀ náà yóò jẹ wàràǹkàṣì àti oyin.
23 Şi se va întâmpla, în acea zi, că fiecare loc unde erau o mie de vii pentru o mie de arginţi, va fi [acoperit de] mărăcini şi spini.
Ní ọjọ́ náà, ni gbogbo ibi tí àjàrà tí ó tó ẹgbẹ̀rún ṣékélì fàdákà, ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n nìkan ni yóò wà níbẹ̀.
24 Cu săgeţi şi cu arcuri vor veni acolo, pentru că toată ţara va deveni mărăcini şi spini.
Àwọn ènìyàn yóò máa lọ síbẹ̀ pẹ̀lú ọrun àti ọfà nítorí pé ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n ni yóò bo gbogbo ilẹ̀ náà.
25 Şi pe toate dealurile, care vor fi săpate cu cazmaua, acolo nu vor veni de frica mărăcinilor şi a spinilor, ci vor fi [un loc] unde vor trimite boi şi unde vor călca oile.
Àti ní orí àwọn òkè kéékèèké tí a ti ń fi ọkọ́ ro nígbà kan rí, ẹ kò ní lọ síbẹ̀ mọ́ nítorí ìbẹ̀rù ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n, wọn yóò di ibi tí a ń da màlúù lọ, àti ibi ìtẹ̀mọ́lẹ̀ fún àwọn àgùntàn kéékèèké.