< Isaia 6 >

1 În anul în care împăratul Ozia a murit am văzut de asemenea pe Domnul şezând pe un tron, înalt şi ridicat, şi trena lui a umplut templul.
Ní ọdún tí ọba Ussiah kú, mo rí Olúwa tí ó jókòó lórí ìtẹ́ tí ó ga tí a gbé sókè, ìṣẹ́tí aṣọ ìgúnwà rẹ̀ sì kún inú tẹmpili.
2 Deasupra stăteau serafimii, fiecare avea şase aripi; cu două îşi acoperea faţa şi cu două îşi acoperea picioarele şi cu două zbura.
Àwọn Serafu wà ní òkè rẹ̀, ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn ní ìyẹ́ mẹ́fà, wọ́n fi ìyẹ́ méjì bo ojú wọn, wọ́n fi méjì bo ẹsẹ̀ wọn, wọ́n sí ń fi méjì fò.
3 Şi unul striga către altul şi spunea: Sfânt, sfânt, sfânt este DOMNUL oştirilor, întregul pământ este plin de gloria sa.
Wọ́n sì ń kọ sí ara wọn wí pé, “Mímọ́, mímọ́, mímọ́ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun gbogbo ayé kún fún ògo rẹ̀.”
4 Şi stâlpii uşii se mişcau la vocea celui care striga şi s-a umplut casa cu fum.
Nípa ìró ohùn un wọn, òpó ìlẹ̀kùn àti gbogbo ògiri ilé náà sì mì tìtì, gbogbo inú tẹmpili sì kún fún èéfín.
5 Atunci am spus: Vai mie! Căci sunt stârpit, pentru că sunt un om cu buze necurate şi locuiesc în mijlocul unui popor cu buze necurate, fiindcă ochii mei au văzut pe Împăratul, pe DOMNUL oştirilor.
Mo kígbe pé, “Ègbé ni fún mi! Mo ti gbé!” Nítorí mo jẹ́ ènìyàn aláìmọ́ ètè, mo sì ń gbé láàrín àwọn ènìyàn aláìmọ́ ètè, ojú mi sì ti rí ọba, Olúwa àwọn ọmọ-ogun jùlọ.
6 Atunci unul dintre serafimi a zburat la mine, având în mâna lui un cărbune aprins, pe care îl luase cu cleştii de pe altar;
Nígbà náà ni ọ̀kan nínú àwọn Serafu wọ̀nyí fò wá sí ọ̀dọ̀ mi pẹ̀lú ẹ̀yín iná ní ọwọ́ rẹ̀, èyí tí ó ti fi ẹ̀mú mú ní orí pẹpẹ.
7 Şi l-a aşezat pe gura mea şi a spus: Iată, acesta ţi-a atins buzele; şi nelegiuirea ta este înlăturată şi păcatul tău îndepărtat.
Èyí ni ó fi kàn mí ní ẹnu tí ó sì wí pé, “Wò ó, èyí ti kan ètè rẹ; a ti mú ẹ̀bi rẹ kúrò, a sì ti wẹ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ nù.”
8 De asemenea am auzit vocea Domnului, spunând: Pe cine să trimit şi cine va merge pentru noi? Atunci am spus: Iată-mă, trimite-mă.
Nígbà náà ni mo sì gbọ́ ohùn Olúwa wí pé, “Ta ni èmi yóò rán? Ta ni yóò sì lọ fún wa?” Nígbà náà ni èmi sì wí pé, “Èmi nìyí, rán mi!”
9 Iar el a spus: Du-te şi spune acestui popor: Auziţi, într-adevăr, dar nu înţelegeţi; şi priviţi, într-adevăr, dar nu pricepeţi.
Òun sì wí pé, “Tọ àwọn ènìyàn yìí lọ kí o sì wí fún wọn pé, “‘Ní gbígbọ́ ẹ̀yin yóò gbọ́, kì yóò sì yé e yín; ní rí rí ẹ̀yin yóò ri, ẹ̀yin kì yóò mọ òye.’
10 Îngraşă inima acestui popor şi îngreunează-le urechile şi închide-le ochii, ca să nu vadă cu ochii lor şi să nu audă cu urechile lor şi să nu înţeleagă cu inima lor şi să se întoarcă şi să fie vindecaţi.
Mú kí àyà àwọn ènìyàn wọ̀nyí yigbì, mú kí etí wọn kí ó wúwo, kí o sì dìwọ́n ní ojú. Kí wọn kí ó má ba fi ojú wọn ríran, kí wọn kí ó má ba fi etí wọn gbọ́rọ̀, kí òye kí ó má ba yé ọkàn wọn, kí wọn kí ó má ba yípadà kí a má ba mú wọn ní ara dá.”
11 Atunci am spus: Doamne, până când? Iar el a răspuns: Până când cetăţile vor rămâne pustiite, fără locuitori, şi casele, fără oameni, şi pământul complet pustiit,
Nígbà náà ni mo wí pé, “Báwo ni yóò ti pẹ́ tó Olúwa?” Òun sì dáhùn pé: “Títí àwọn ìlú ńlá yóò fi dahoro, láìsí olùgbé nínú rẹ̀ mọ́, títí tí àwọn ilé yóò fi wà láìsí ènìyàn, títí tí ilẹ̀ yóò fi dahoro pátápátá.
12 Şi DOMNUL va fi îndepărtat pe oameni şi va fi o mare părăsire în mijlocul ţării.
Títí tí Olúwa yóò fi rán gbogbo wọn jìnnà réré tí ilẹ̀ náà sì di ìkọ̀sílẹ̀ pátápátá.
13 Dar totuşi în aceasta va rămâne o zecime şi ea se va întoarce şi va fi mâncată ca un ulm şi ca un stejar a căror viaţă este în ei, când îşi scutură frunzele; [tot astfel] sămânţa sfântă va fi viaţa acesteia.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìdámẹ́wàá ṣẹ́kù lórí ilẹ̀ náà, yóò sì tún pàpà padà di rírun. Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí igi tẹrẹbinti àti igi óákù, ti í fi kùkùté sílẹ̀ nígbà tí a bá gé wọn lulẹ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni irúgbìn mímọ́ náà yóò di kùkùté ní ilẹ̀ náà.”

< Isaia 6 >