< Isaia 46 >
1 Bel se îndoaie, Nebo se apleacă, idolii lor au fost puşi pe animale şi pe vite; căruţele voastre au fost greu încărcate; ele sunt o povară pentru vita obosită.
Beli tẹrí i rẹ̀ ba, Nebo bẹ̀rẹ̀ mọ́lẹ̀; àwọn ère wọn ni àwọn ẹranko rù. Àwọn ère tí wọ́n ń rù káàkiri ti di àjàgà sí wọn lọ́rùn, ẹrù fún àwọn tí àárẹ̀ mú.
2 Ei se apleacă, se îndoaie împreună; nu pot salva povara, ci ei înşişi sunt duşi în captivitate.
Wọ́n bẹ̀rẹ̀ wọ́n sì foríbalẹ̀ papọ̀; wọn kò lè gba ẹrù náà, àwọn pẹ̀lú ni a kó lọ ní ìgbèkùn.
3 Dă-mi ascultare, casă a lui Iacob şi toată rămăşiţa casei lui Israel, voi cei duşi de mine de la naştere şi purtaţi din pântece,
“Tẹ́tí sí mi, ìwọ ilé Jakọbu, gbogbo ẹ̀yin tí ó ṣẹ́kù nínú ilé Israẹli, ìwọ tí mo ti gbéró láti ìgbà tí o ti wà nínú oyún, tí mo sì ti ń pọ̀n láti ìgbà tí a ti bí ọ.
4 Şi chiar până la bătrâneţea voastră eu sunt el; şi până la peri albi vă voi purta, eu v-am făcut şi vă voi susţine; chiar eu vă voi purta şi vă voi salva.
Pẹ̀lúpẹ̀lú sí àwọn arúgbó àti ewú orí yín, Èmi ni ẹni náà, Èmi ni ẹni tí yóò gbé ọ ró. Èmi ti mọ ọ́, èmi yóò sì gbé ọ; Èmi yóò dì ọ́ mú èmi ó sì gbà ọ́ sílẹ̀.
5 Cu cine mă veţi asemăna şi mă veţi face egal şi mă veţi compara, pentru a fi asemănători?
“Ta ni ìwọ yóò fi mí wé tàbí ta ni èmi yóò bá dọ́gba? Ta ni ìwọ yóò fi ṣe àkàwé mi tí àwa yóò jọ fi ara wé ara?
6 Varsă mult aur din pungă şi cântăresc argint în balanţă şi angajează un aurar; iar el îl face un dumnezeu, ei se pleacă, da, se închină.
Ọ̀pọ̀ da wúrà sílẹ̀ nínú àpò wọn wọ́n sì wọn fàdákà lórí òsùwọ̀n; wọ́n bẹ alágbẹ̀dẹ lọ́wẹ̀ láti fi wọ́n ṣe òrìṣà, wọn sì tẹríba láti sìn ín.
7 Îl poartă pe umăr, îl duc şi îl aşază la locul lui şi el stă acolo; din locul lui nu se va mişca, da, cineva va striga la el, totuşi nu îi poate răspunde, nici să îl salveze din tulburarea lui.
Wọ́n gbé e lé èjìká wọn, wọ́n rù wọ́n, wọ́n sì gbé e sí ààyè rẹ̀ níbẹ̀ ni ó sì dúró sí. Láti ibẹ̀ náà kò le è paradà. Bí ènìyàn tilẹ̀ pariwo lé e lórí, òun kò le è dáhùn; òun kò lè gbà á nínú ìyọnu rẹ̀.
8 Amintiţi-vă aceasta şi arătaţi-vă bărbaţi; aduceţi-vă din nou aminte voi călcătorilor [de lege].
“Rántí èyí, fi í sí ọkàn rẹ, fi sí ọkàn rẹ, ẹ̀yin ọlọ̀tẹ̀.
9 Amintiţi-vă lucrurile din vechime, fiindcă eu sunt Dumnezeu şi nu este altul; eu sunt Dumnezeu şi nu este nimeni ca mine,
Rántí àwọn nǹkan àtẹ̀yìnwá, àwọn ti àtijọ́-tijọ́; Èmi ni Ọlọ́run, kò sì sí ẹlòmíràn; Èmi ni Ọlọ́run, kò sí ẹlòmíràn bí ì mi.
10 Vestind sfârşitul de la început şi din vechime lucrurile care nu sunt încă făcute, spunând: Sfatul meu va sta în picioare şi voi împlini toată plăcerea mea;
Mo fi òpin hàn láti ìbẹ̀rẹ̀ wá, láti àtètèkọ́ṣe, ohun tí ó sì ń bọ̀ wá. Mo wí pé, Ète mi yóò dúró, àti pé èmi yóò ṣe ohun tí ó wù mí.
11 Chemând o pasăre răpitoare din est, pe bărbatul care împlineşte sfatul meu dintr-o ţară îndepărtată; da, am vorbit aceasta, şi o voi face să se întâmple; am hotărât şi voi împlini.
Láti ìlà-oòrùn wá ni mo ti pe ẹyẹ ajẹran wá; láti ọ̀nà jíjìn réré, ọkùnrin kan tí yóò mú ète mi ṣẹ. Ohun tí mo ti sọ, òun ni èmi yóò mú ṣẹ; èyí tí mo ti gbèrò, òun ni èmi yóò ṣe.
12 Daţi-mi ascultare, voi cei cu inimă tare, care sunteţi departe de dreptate;
Gbọ́ tèmi, ẹ̀yin alágídí ọkàn, ìwọ tí ó jìnnà sí òdodo.
13 Eu apropii dreptatea mea; nu va fi departe şi salvarea mea nu va întârzia; şi voi pune salvare în Sion pentru Israel, gloria mea.
Èmi ń mú òdodo mi bọ̀ nítòsí, kò tilẹ̀ jìnnà rárá; àti ìgbàlà mi ni a kì yóò dádúró. Èmi yóò fún Sioni ní ìgbàlà ògo mi fún Israẹli.