< Isaia 45 >

1 Astfel spune DOMNUL unsului său, lui Cirus, a cărui dreaptă am ţinut-o, pentru a supune naţiuni înaintea lui; şi voi dezlega coapsele împăraţilor, pentru a deschide înaintea lui cele două porţi părăsite; şi porţile nu vor fi închise;
“Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún ẹni òróró rẹ̀, sí Kirusi, ọwọ́ ọ̀tún ẹni tí mo dì mú láti dojú àwọn orílẹ̀-èdè bolẹ̀ níwájú rẹ̀ àti láti gba ohun ìjà àwọn ọba lọ́wọ́ wọn, láti ṣí àwọn ìlẹ̀kùn níwájú rẹ̀ tí ó fi jẹ́ pé a kì yóò ti àwọn ẹnu-ọ̀nà.
2 Voi merge înaintea ta şi locurile strâmbe le voi îndrepta, voi sparge în bucăţi porţile de aramă şi voi tăia în două drugii de fier,
Èmi yóò lọ síwájú rẹ, Èmi ó sì tẹ́ àwọn òkè ńlá pẹrẹsẹ Èmi yóò fọ gbogbo ẹnu-ọ̀nà idẹ èmi ó sì gé ọ̀pá irin.
3 Şi îţi voi da tezaurele întunericului şi bogăţiile ascunse ale locurilor tainice, ca să ştii că eu, DOMNUL, care te chem pe nume, sunt Dumnezeul lui Israel.
Èmi yóò sì fún ọ ní àwọn ọrọ̀ ibi òkùnkùn, ọrọ̀ tí a kó pamọ́ sí àwọn ibi tí ó fi ara sin, tó bẹ́ẹ̀ tí ìwọ yóò fi mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ó pè ọ́ pẹ̀lú orúkọ rẹ.
4 De dragul lui Iacob, servitorul meu, şi Israel, alesul meu, te-am chemat chiar pe numele tău, ţi-am dat [încă] un nume, deşi nu m-ai cunoscut.
Nítorí Jakọbu ìránṣẹ́ mi àti Israẹli ẹni tí mo yàn, Mo pè ọ́ pẹ̀lú orúkọ rẹ, mo sì gbé oyè kan kà ọ́ lórí bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ kò gbà mí.
5 Eu sunt DOMNUL şi nu este altul, nu este Dumnezeu în afară de mine, te-am încins, deşi nu m-ai cunoscut,
Èmi ni Olúwa, àti pé kò sí ẹlòmíràn; yàtọ̀ sí èmi kò sí ọlọ́run kan, Èmi yóò fún ọ ní okun, bí o kò tilẹ̀ tí ì gbà mí,
6 Ca ei să ştie de la ridicarea soarelui şi de la vest, că nu este nimeni în afară de mine. Eu sunt DOMNUL şi nu este altul.
tí o fi jẹ́ pé láti ìlà-oòrùn títí dé ibi ìwọ̀ rẹ̀ kí ènìyàn le mọ̀, kò sí ẹnìkan lẹ́yìn mi. Èmi ni Olúwa, lẹ́yìn mi kò sí ẹlòmíràn mọ́.
7 Eu formez lumina şi creez întuneric, fac pace şi creez rău, eu DOMNUL fac toate acestea.
Mo dá ìmọ́lẹ̀, mo sì dá òkùnkùn, Mo mú àlàáfíà wá, Mo sì dá àjálù; Èmi Olúwa ni ó ṣe nǹkan wọ̀nyí.
8 Picuraţi voi ceruri de deasupra şi cerurile să toarne dreptate; să se deschidă pământul şi ele să aducă salvare şi dreptatea să răsară împreună; eu, DOMNUL, am creat aceasta.
“Ìwọ ọ̀run lókè rọ òjò òdodo sílẹ̀; jẹ́ kí àwọsánmọ̀ kí ó rọ̀ ọ́ sílẹ̀. Jẹ́ kí ilẹ̀ kí ó yanu gbagada, jẹ́ kí ìgbàlà kí ó dìde sókè, jẹ́ kí òdodo kí ó dàgbà pẹ̀lú rẹ̀; Èmi Olúwa ni ó ti dá a.
9 Vai celui ce se luptă cu Făcătorul său! Să se lupte ciobul cu cioburile pământului. Va spune lutul celui ce îl modelează: Ce faci? sau lucrarea ta: Nu are mâini?
“Ègbé ni fún ènìyàn tí ó ń bá Ẹlẹ́dàá rẹ̀ jà, ẹni tí òun jẹ́ àpáàdì kan láàrín àwọn àpáàdì tí ó wà lórí ilẹ̀. Ǹjẹ́ amọ̀ lè sọ fún amọ̀kòkò, pé: ‘Kí ni ohun tí ò ń ṣe?’ Ǹjẹ́ iṣẹ́ rẹ lè sọ pé, ‘Òun kò ní ọwọ́?’ (questioned)
10 Vai celui ce spune tatălui său: Ce naşti tu? sau femeii: Ce ai adus pe lume?
Ègbé ni fún ẹni tí ó sọ fún baba rẹ̀ pé, ‘Kí ni o bí?’ tàbí sí ìyá rẹ̀, ‘Kí ni ìwọ ti bí?’
11 Astfel spune DOMNUL, Cel Sfânt al lui Israel şi Făcătorul său: Întrebaţi-mă despre lucruri ce vor veni referitor la fiii mei şi referitor la lucrarea mâinilor mele să îmi porunciţi.
“Ohun tí Olúwa wí nìyìí, Ẹni Mímọ́ Israẹli, àti Ẹlẹ́dàá rẹ̀. Nípa ohun tí ó ń bọ̀, ǹjẹ́ o ń bi mí léèrè nípa àwọn ọmọ mi, tàbí kí o pàṣẹ fún mi nípa iṣẹ́ ọwọ́ mi bí?
12 Am făcut pământul şi am creat omul pe acesta; eu, mâinile mele, au întins cerurile şi întregii lor oştiri i-am poruncit.
Èmi ni ẹni tí ó dá ilẹ̀ ayé tí ó sì da ọmọ ènìyàn sórí i rẹ̀. Ọwọ́ mi ni ó ti ta àwọn ọ̀run; mo sì kó àwọn àgbájọ ìràwọ̀ rẹ̀ síta.
13 L-am ridicat în dreptate şi voi îndruma toate căile lui, el va construi cetatea mea şi va da drumul captivilor mei, nu pentru preţ nici pentru răsplată, spune DOMNUL oştirilor.
Èmi yóò gbé Kirusi sókè nínú òdodo mi. Èmi yóò mú kí gbogbo ọ̀nà rẹ̀ kí ó tọ́. Òun yóò tún ìlú mi kọ́ yóò sì tú àwọn àtìpó mi sílẹ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún owó tàbí ẹ̀bùn kan, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.”
14 Astfel spune DOMNUL: Munca Egiptului şi marfa Etiopiei şi a sabeenilor, bărbaţi de statură înaltă, vor veni peste tine şi vor fi ai tăi, vor veni după tine; în lanţuri vor veni şi ţi se vor pleca, îţi vor aduce cereri, spunând: Cu siguranţă Dumnezeu este în tine; şi nu este altul, nu este alt Dumnezeu.
Ohun tí Olúwa wí nìyìí: “Àwọn èròjà ilẹ̀ Ejibiti àti àwọn ọjà ilẹ̀ Kuṣi, àti àwọn Sabeani— wọn yóò wá sọ́dọ̀ rẹ wọn yóò sì jẹ́ tìrẹ; wọn yóò máa wọ́ tẹ̀lé ọ lẹ́yìn, wọn yóò máa wá lọ́wọ̀ọ̀wọ́. Wọn yóò máa foríbalẹ̀ níwájú rẹ̀, wọn yóò sì máa bẹ̀bẹ̀ níwájú rẹ pé, ‘Nítòótọ́ Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ kò sì ṣí ẹlòmíràn; kò sí ọlọ́run mìíràn.’”
15 Cu adevărat tu eşti un Dumnezeu care te ascunzi, O Dumnezeul lui Israel, Salvatorul.
Nítòótọ́ ìwọ jẹ́ Ọlọ́run tí ó fi ara rẹ̀ pamọ́, Ìwọ Ọlọ́run àti Olùgbàlà Israẹli,
16 Ei vor fi ruşinaţi şi de asemenea încurcaţi, cu toţii; vor merge spre încurcare toţi făcătorii de idoli.
Gbogbo àwọn tí ó ń gbẹ́ ère ni ojú yóò tì wọn yóò sì kan àbùkù; gbogbo wọn ni yóò bọ́ sínú àbùkù papọ̀.
17 Dar Israel va fi salvat în DOMNUL cu o salvare veşnică, voi nu veţi fi ruşinaţi, nici încurcaţi pentru totdeauna şi întotdeauna.
Ṣùgbọ́n Israẹli ni a ó gbàlà láti ọwọ́ Olúwa pẹ̀lú ìgbàlà ayérayé; a kì yóò kàn yín lábùkù tàbí kí a dójútì yín, títí ayé àìnípẹ̀kun.
18 Fiindcă astfel spune DOMNUL care a creat cerurile; Dumnezeu însuşi care a format pământul şi l-a făcut; el l-a întemeiat, nu l-a creat în zadar, l-a format pentru a fi locuit: Eu sunt DOMNUL; şi nu este altul.
Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa wí, ẹni tí ó dá àwọn ọ̀run, Òun ni Ọlọ́run; ẹni tí ó mọ tí ó sì dá ayé, Òun ló ṣe é; Òun kò dá a láti wà lófo, ṣùgbọ́n ó ṣe é kí a lè máa gbé ibẹ̀, Òun wí pé: “Èmi ni Olúwa, kò sì ṣí ẹlòmíràn.
19 Nu am vorbit în taină, într-un loc întunecos al pământului. Nu am spus seminţei lui Iacob: Voi mă căutaţi în zadar, eu, DOMNUL, vorbesc dreptate, vestesc lucruri drepte.
Èmi kò sọ̀rọ̀ níbi tí ó fi ara sin, láti ibìkan ní ilẹ̀ òkùnkùn, Èmi kò tí ì sọ fún àwọn ìran Jakọbu pé, ‘Ẹ wá mi lórí asán.’ Èmi Olúwa sọ òtítọ́, Mo sì sọ èyí tí ó tọ̀nà.
20 Adunaţi-vă şi veniţi; apropiaţi-vă împreună, voi, care aţi scăpat dintre naţiuni; nu au cunoaştere cei care înalţă lemnul chipului lor cioplit şi se roagă unui dumnezeu care nu poate salva.
“Ẹ kó ara yín jọ kí ẹ sì wá; ẹ kórajọ, ẹ̀yin ìsáǹsá láti àwọn orílẹ̀-èdè wá. Aláìmọ̀kan ni àwọn tí ó ń ru ère igi káàkiri, tí wọ́n gbàdúrà sí àwọn òrìṣà tí kò le gba ni.
21 Spuneţi şi aduceţi-i aproape; da, să facă sfat împreună, cine a vestit aceasta din vechime? Cine a spus aceasta de atunci? Oare nu eu, DOMNUL? Şi nu este alt Dumnezeu în afară de mine; un Dumnezeu drept şi un Salvator; nu este altul în afară de mine.
Jẹ́ kí a mọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀, fihàn wá, jẹ́ kí wọn jọ dámọ̀ràn papọ̀. Ta ló ti sọ èyí lọ́jọ́ tí o ti pẹ́, ta ló ti wí èyí láti àtètèkọ́ṣe? Kì í ha á ṣe Èmi, Olúwa? Àti pé kò sí Ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn mi, Ọlọ́run olódodo àti olùgbàlà; kò sí ẹlòmíràn àfi èmi.
22 Priviţi la mine şi fiţi salvaţi, toate marginile pământului, fiindcă eu sunt Dumnezeu şi nu este altul.
“Yípadà sí mi kí a sì gbà ọ́ là, ẹ̀yin ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé; nítorí Èmi ni Ọlọ́run kò sì ṣí ẹlòmíràn.
23 Am jurat pe mine însumi, cuvântul a ieşit din gura mea în dreptate şi nu se va întoarce: Căci fiecare genunchi mi se va pleca, fiecare limbă va jura.
Nípa èmi tìkára mi ni mo ti búra, ẹnu mi ni ó ti sọ ọ́ pẹ̀lú gbogbo ipá mi, ọ̀rọ̀ náà tí a kì yóò lè parẹ́. Níwájú mi ni gbogbo orúnkún yóò wólẹ̀; nípa mi ni gbogbo ahọ́n yóò búra.
24 Cu siguranţă, unul va spune: În DOMNUL am dreptate şi tărie, la el vor veni oameni; şi toţi cei aprinşi împotriva lui vor fi ruşinaţi.
Wọn yóò sọ ní ti èmi, ‘Nínú Olúwa nìkan ni òdodo àti agbára wà.’” Gbogbo àwọn tí ó ti bínú sí; yóò wá sọ́dọ̀ rẹ̀ a ó sì dójútì wọn.
25 În DOMNUL va fi declarată dreaptă şi se va glorifica toată sămânţa lui Israel.
Ṣùgbọ́n nínú Olúwa gbogbo àwọn ìran Israẹli ni a ó rí ní òdodo, a o sì gbé wọn ga.

< Isaia 45 >