< Isaia 41 >

1 Tăceţi înaintea mea, insule; şi să [îşi] înnoiască poporul tăria, să se apropie; să vorbească atunci, să ne apropiem împreună la judecată.
“Ẹ dákẹ́ jẹ́ẹ́ níwájú mi ẹ̀yin erékùṣù! Jẹ́ kí àwọn orílẹ̀-èdè tún agbára wọn ṣe! Jẹ́ kí wọn wá síwájú kí wọn sọ̀rọ̀, jẹ́ kí a pàdé pọ̀ ní ibi ìdájọ́.
2 Cine a ridicat pe cel drept din est, l-a chemat la piciorul său, i-a dat naţiunile înaintea lui şi l-a făcut să conducă peste împăraţi? I-a dat ca praf sabiei lui [şi] ca paie alungate arcului său.
“Ta ni ó ti ru ẹnìkan sókè láti ìlà-oòrùn wá, tí ó pè é ní olódodo sí iṣẹ́ tirẹ̀? Ó gbé àwọn orílẹ̀-èdè lé e lọ́wọ́ ó sì ṣẹ́gun àwọn ọba níwájú rẹ̀. Ó sọ wọ́n di erùpẹ̀ pẹ̀lú idà rẹ̀, láti kù ú ní ìyàngbò pẹ̀lú ọrun rẹ̀.
3 I-a urmărit [şi] a trecut în siguranţă, pe calea neumblată de picioarele lui.
Ó ń lépa wọn ó sì ń kọjá ní àlàáfíà, ní ojú ọ̀nà tí ẹsẹ̀ rẹ̀ kò rìn rí.
4 Cine a lucrat-o şi a făcut-o, chemând generaţiile de la început? Eu, DOMNUL, sunt cel dintâi şi cel din urmă; Eu sunt el.
Ta ni ó ti ṣe èyí tí ó sì ti jẹ́ kí ó wáyé, tí ó ti pe ìran-ìran láti àtètèkọ́ṣe? Èmi Olúwa pẹ̀lú ẹni kìn-ín-ní wọn àti ẹni tí ó gbẹ̀yìn, Èmi náà ni.”
5 Insulele au văzut şi s-au temut; marginile pământului s-au înspăimântat, s-au apropiat şi au venit.
Àwọn erékùṣù ti rí i wọ́n bẹ̀rù; ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé wárìrì. Wọ́n súnmọ́ tòsí wọ́n sì wá síwájú;
6 Ei au ajutat fiecare pe aproapele său; şi fiecare a spus fratelui său: Încurajează-te.
èkínní ran èkejì lọ́wọ́ ó sì sọ fún arákùnrin rẹ̀ pé, “Jẹ́ alágbára!”
7 Astfel tâmplarul a încurajat pe aurar [şi] cel care finisează cu ciocanul pe cel care a lovit nicovala, spunând: Este gata pentru sudură şi l-a fixat în cuie, să nu fie mişcat.
Oníṣọ̀nà gba alágbẹ̀dẹ wúrà níyànjú, àti ẹni tí ó fi òòlù dán mú òun lọ́kàn le, àní ẹni tí ó ń lu owú. Ó sọ nípa àjópọ̀ náà pé, “Ó dára.” Ó fi ìṣó kan ère náà mọ́lẹ̀ kí ó má ba à wó lulẹ̀.
8 Dar tu, Israel, eşti servitorul meu, Iacob, cel pe care l-am ales, sămânţa lui Avraam, prietenul meu.
“Ṣùgbọ́n ìwọ, ìwọ Israẹli, ìránṣẹ́ mi, Jakọbu, ẹni tí mo ti yàn, ẹ̀yin ìran Abrahamu, ọ̀rẹ́ mi,
9 Tu, cel pe care l-am luat de la marginile pământului şi te-am chemat dintre cei mai de seamă bărbaţi ai acestuia şi ţi-am spus: Tu eşti servitorul meu; te-am ales şi nu te-am lepădat.
mo mú ọ láti ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé, láti kọ̀rọ̀ rẹ̀ tí ó jìnnà jùlọ ni mo ti pè ọ́. Èmi wí pé, ‘Ìwọ ni ìránṣẹ́ mi’; Èmi ti yàn ọ́ bẹ́ẹ̀ ni èmi kò sì tí ì kọ̀ ọ́ sílẹ̀.
10 Nu te teme, căci eu sunt cu tine; nu te descuraja căci eu sunt Dumnezeul tău; te voi întări; da, te voi ajuta; da, te voi susţine cu dreapta dreptăţii mele.
Nítorí náà má bẹ̀rù, nítorí èmi wà pẹ̀lú rẹ; má ṣe jẹ́ kí àyà kí ó fò ọ́, nítorí èmi ni Ọlọ́run rẹ. Èmi yóò fún ọ lókun èmi ó sì ràn ọ́ lọ́wọ́. Èmi ó gbé ọ ró pẹ̀lú ọwọ́ ọ̀tún òdodo mi.
11 Iată, toţi cei care s-au aprins împotriva ta vor fi ruşinaţi şi încurcaţi, vor fi ca nimic; şi cei care se luptă cu tine vor pieri.
“Gbogbo àwọn tí ó bínú sí ọ ni ojú yóò tì, tí wọn yóò sì di ẹlẹ́yà; àwọn tó ń bá ọ jà yóò dàbí asán, wọn yóò ṣègbé.
12 Îi vei căuta şi nu îi vei găsi, pe cei care s-au certat cu tine, cei care se războiesc împotriva ta vor fi ca nimic şi ca un lucru de nimic.
Bó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ yóò wá àwọn ọ̀tá rẹ, ìwọ kì yóò rí wọn. Gbogbo àwọn tí ó gbóguntì ọ́ yóò dàbí ohun tí kò sí.
13 Fiindcă eu, DOMNUL Dumnezeul tău, îţi voi ţine mâna dreaptă, spunându-ţi: Nu te teme; te voi ajuta.
Nítorí Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ, tí ó di ọwọ́ ọ̀tún rẹ mú tí ó sì sọ fún ọ pé, má ṣe bẹ̀rù; Èmi yóò ràn ọ́ lọ́wọ́.
14 Nu te teme, tu, vierme Iacob [şi] voi bărbaţi ai lui Israel; te voi ajuta, spune DOMNUL şi răscumpărătorul tău, Cel Sfânt al lui Israel.
Má ṣe bẹ̀rù, ìwọ Jakọbu kòkòrò, ìwọ Israẹli kékeré, nítorí Èmi fúnra mi yóò ràn ọ́ lọ́wọ́,” ni Olúwa wí, olùdáǹdè rẹ, Ẹni Mímọ́ ti Israẹli.
15 Iată, te voi face o unealtă de vânturat nouă şi ascuţită cu dinţi, vei vântura munţii şi îi vei pisa mărunt şi vei face dealurile ca pleava.
“Kíyèsi, Èmi yóò sọ ọ́ di òòlù ìpakà tuntun, tí ó mú ti eyín rẹ̀ mú, ìwọ yóò lu àwọn òkè ńlá, ìwọ yóò fọ́ wọn túútúú, a ó sì sọ òkè kékeré di ìyàngbò.
16 Le vei vântura şi vântul le va duce şi vârtejul de vânt le va împrăştia, iar tu te vei bucura în DOMNUL [şi] te vei făli în Cel Sfânt al lui Israel.
Ìwọ yóò fẹ́ wọn, afẹ́fẹ́ yóò sì gbá wọn mú, àti ẹ̀fúùfù yóò sì fẹ́ wọn dànù. Ṣùgbọ́n ìwọ yóò yọ̀ nínú Olúwa ìwọ yóò sì ṣògo nínú Ẹni Mímọ́ ti Israẹli.
17 Când săracii şi nevoiaşii caută apă şi nu este şi limba lor se sfârşeşte de sete, eu, DOMNUL, îi voi asculta; eu, Dumnezeul lui Israel, nu îi voi părăsi.
“Àwọn tálákà àti aláìní wá omi, ṣùgbọ́n kò sí; ahọ́n wọn gbẹ fún òǹgbẹ. Ṣùgbọ́n Èmi Olúwa yóò dá wọn lóhùn; Èmi, Ọlọ́run Israẹli, kì yóò kọ̀ wọ́n sílẹ̀.
18 Voi deschide râuri în locuri înalte şi fântâni în mijlocul văilor, din pustiu voi face un iaz de apă; şi pământul uscat, izvoare de apă.
Èmi yóò mú kí odò kí ó sàn ní ibi gíga àti orísun omi ní àárín àfonífojì. Èmi yóò sọ aṣálẹ̀ di adágún omi, àti ilẹ̀ tí ó gbẹ gidigidi di orísun omi.
19 Voi sădi în pustiu cedrul, salcâmul şi mirtul şi măslinul; voi pune în pustiu împreună bradul şi pinul şi merişorul,
Èmi yóò fi sínú aṣálẹ̀ igi kedari àti kasia, maritili àti olifi. Èmi yóò gbin junifa sí inú aginjù, igi firi àti sípírẹ́ṣì papọ̀
20 Să vadă şi să ştie şi să ia aminte şi să înţeleagă împreună, că mâna DOMNULUI a făcut aceasta şi Cel Sfânt al lui Israel l-a creat.
tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ènìyàn yóò fi rí i tí wọn yóò sì fi mọ̀, kí wọn ṣàkíyèsí kí ó sì yé wọn, pé ọwọ́ Olúwa ni ó ti ṣe èyí, àti pé, Ẹni Mímọ́ Israẹli ni ó ti dá èyí.
21 Arătaţi cauza voastră, spune DOMNUL; aduceţi [argumentele] voastre puternice, spune Împăratul lui Iacob.
“Mú ẹjọ́ wá,” ni Olúwa wí. “Tẹ́ àwọn àwíjàre rẹ sílẹ̀,” ni ọba Jakọbu wí,
22 Să le aducă înainte şi să ne arate ce se va întâmpla, să arate lucrurile dinainte, ce sunt ele, să luăm aminte la ele şi să cunoaştem sfârşitul lor; sau vestiţi-ne lucrurile ce vor veni.
“Mú àwọn ère òrìṣà rẹ wọlé láti sọ fún wa ohun tí yóò ṣẹlẹ̀. Sọ fún wa ohun tí àwọn nǹkan àtijọ́ jẹ́, kí àwa lè ṣe àgbéyẹ̀wò wọn kí àwa sì mọ àbájáde wọn ní ìparí. Tàbí kí o sọ fún wa ohun tí ó ń bọ̀ wá,
23 Arătaţi lucrurile ce vor veni pe urmă, să cunoaştem că voi sunteţi dumnezei; da, faceţi bine, sau faceţi rău, ca să ne descurajăm şi să le privim împreună.
ẹ sọ fún wa ohun ti ọjọ́ iwájú mú dání kí àwa kí ó lè mọ̀ pé ọlọ́run ni yín. Ẹ ṣe nǹkan kan, ìbá à ṣe rere tàbí búburú, tó bẹ́ẹ̀ tí àyà yóò fi fò wá tí ẹ̀rù yóò sì fi kún inú wa.
24 Iată, voi sunteţi de nimic şi lucrarea voastră de nimic, o urâciune este cel care vă alege.
Ṣùgbọ́n ẹ̀yìn ko jásí nǹkan kan iṣẹ́ yín ni kò sì wúlò fún ohunkóhun; ẹni tí ó yàn yín jẹ́ ẹni ìríra.
25 Am ridicat pe unul din nord şi va veni, de la răsăritul soarelui va chema el numele meu; şi va veni peste prinţi ca peste mortar şi precum olarul calcă în picioare lutul.
“Èmi ti ru ẹnìkan sókè láti àríwá, òun sì ń bọ ẹnìkan láti ìlà-oòrùn tí ó pe orúkọ mi. Òun gun àwọn aláṣẹ mọ́lẹ̀ bí ẹni pé odò ni wọ́n, àfi bí ẹni pé amọ̀kòkò nì ti ń gún amọ̀.
26 Cine a vestit de la început, ca să ştim? Şi înainte de timp, ca să spunem: El este drept, da, nu este nimeni care arată, da, nu este nimeni care vesteşte, da, nu este nimeni care aude cuvintele voastre.
Ta ni ó sọ èyí láti ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀, tí àwa kò bá fi mọ̀, tàbí ṣáájú àkókò, tí àwa kò bá fi wí pé, ‘Òun sọ òtítọ́’? Ẹnikẹ́ni kò sọ nípa èyí, ẹnikẹ́ni kò sàsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀, ẹnikẹ́ni kò gbọ́ ọ̀rọ̀ kan láti ọ̀dọ̀ rẹ̀.
27 Cel dintâi va spune Sionului: Iată, iată-i; şi voi da Ierusalimului pe unul care aduce veşti bune.
Èmi ni ẹni àkọ́kọ́ tí ó sọ fún Sioni pé, ‘Wò ó, àwọn nìyìí!’ Mo fún Jerusalẹmu ní ìránṣẹ́ ìrò ìròyìn ayọ̀ kan.
28 Fiindcă am privit şi nu a fost vreun om, nici chiar printre ei; şi nu a fost vreun sfătuitor, care, când i-am întrebat, să poată răspunde vreun cuvânt.
Èmi wò, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan— kò sí ẹnìkan nínú wọn tí ó lè mú ìmọ̀ràn wá, kò sí ẹnìkan tí ó lè dáhùn nígbà tí mo bi wọ́n.
29 Iată, ei sunt toţi deşertăciune; faptele lor sunt nimic, chipurile lor turnate sunt vânt şi confuzie.
Kíyèsi i, irọ́ ni gbogbo wọn! Gbogbo ìṣe wọn jásí asán; àwọn ère wọn kò ṣé kò yà fún afẹ́fẹ́ àti dàrúdàpọ̀.

< Isaia 41 >