< Isaia 40 >

1 Mângâiaţi-vă, mângâiaţi-vă poporul meu, spune Dumnezeul vostru.
Ẹ tù ú nínú, ẹ tu ènìyàn mi nínú, ni Ọlọ́run yín wí.
2 Vorbiţi cu mângâiere [inimii] Ierusalimului şi strigaţi-i, că războiul ei s-a împlinit, că nelegiuirea ei este iertată, fiindcă a primit dublu din mâna DOMNULUI pentru toate păcatele ei.
Sọ̀rọ̀ pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ fún Jerusalẹmu kí o sì kéde fún un pé iṣẹ́ àṣekára rẹ̀ ti parí, pé à ti san gbèsè ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, pé ó ti rí i gbà láti ọwọ́ Olúwa ìlọ́po méjì fún gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.
3 Vocea celui ce strigă în pustiu: Pregătiţi calea DOMNULUI, faceţi în pustie un drum mare şi drept pentru Dumnezeul nostru.
Ohùn ẹni tí ń kígbe ní ijù: “Ẹ tún ọ̀nà Olúwa ṣe, ṣe òpópó tí ó tọ́ ní aginjù fún Ọlọ́run wa.
4 Fiecare vale va fi înălţată şi fiecare munte şi deal va fi coborât, şi cea strâmbă va fi îndreptată şi locurile colţuroase, netede,
Gbogbo àfonífojì ni a ó gbé sókè, gbogbo òkè ńlá àti òkè kékeré ni yóò di pẹ̀tẹ́lẹ̀; wíwọ́ ni a ó sọ di títọ́ àti ọ̀nà pálapàla ni a óò sọ di títẹ́jú pẹrẹsẹ.
5 Şi gloria DOMNULUI va fi revelată şi toată făptura va vedea împreună, fiindcă gura DOMNULUI a spus-o.
Ògo Olúwa yóò sì di mí mọ̀, gbogbo ènìyàn lápapọ̀ ni yóò sì rí i. Nítorí ẹnu Olúwa ni ó ti sọ ọ́.”
6 Vocea a spus: Strigă. Iar el a spus: Ce să strig? Toată făptura este iarbă şi toată frumuseţea acesteia este ca floarea câmpului,
Ohùn kan wí pé, “Kígbe sókè.” Èmi sì sọ pé, “Igbe kí ni èmi ó ké?” “Gbogbo ènìyàn dàbí i koríko, àti gbogbo ògo wọn dàbí ìtànná igbó.
7 Iarba se ofileşte, floarea se vestejeşte, pentru că duhul DOMNULUI suflă peste ea, cu siguranţă poporul este iarbă.
Koríko ń rọ ìtànná sì ń rẹ̀, nítorí èémí Olúwa ń fẹ́ lù wọ́n. Nítòótọ́ koríko ni àwọn ènìyàn.
8 Iarba se ofileşte, floarea se vestejeşte, dar cuvântul Dumnezeului nostru va rămâne pentru totdeauna.
Koríko ń rọ ìtànná sì ń rẹ̀, ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ Ọlọ́run wa dúró títí láé.”
9 O, Sion, care aduci veşti bune, ridică-te la muntele înalt; Ierusalime, care aduci veşti bune, înalţă-ţi vocea cu tărie; înalţ-o, nu te teme; spune cetăţilor din Iuda: Iată-l pe Dumnezeul vostru!
Ìwọ tí o mú ìyìn ayọ̀ wá sí Sioni, lọ sí orí òkè gíga. Ìwọ tí ó mú ìyìn ayọ̀ wá sí Jerusalẹmu, gbé ohùn rẹ sókè pẹ̀lú ariwo, gbé e sókè, má ṣe bẹ̀rù; sọ fún àwọn ìlú u Juda, “Ọlọ́run rẹ nìyìí!”
10 Iată, Domnul DUMNEZEU va veni cu mână tare şi braţul său va stăpâni pentru el, iată, răsplata lui este cu el şi lucrarea lui înaintea lui.
Wò ó, Olúwa Olódùmarè náà ń bọ̀ wá pẹ̀lú agbára, apá rẹ̀ sì ń jẹ ọba fún un. Wò ó, èrè rẹ̀ sì wà pẹ̀lú rẹ̀, àti ìdápadà rẹ̀ tí ń bá a bọ̀ wá.
11 Îşi va paşte turma ca un păstor, el va aduna mieii cu braţul său şi îi va purta în sânul său [şi] va conduce uşurel pe cele ce alăptează.
Ó ń tọ́ àwọn agbo rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́-àgùntàn: Ó kó àwọn ọ̀dọ́-àgùntàn ní apá rẹ̀. Ó sì gbé wọn súnmọ́ oókan àyà rẹ̀; ó sì fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ darí àwọn tí ó ní.
12 Cine a măsurat apele în căuşul palmei sale şi a măsurat cerul cu palma şi a cuprins ţărâna pământului într-o măsură şi a cântărit munţii în cântare şi dealurile într-o balanţă?
Ta ni ó tiwọn omi nínú kòtò ọwọ́ rẹ̀, tàbí pẹ̀lú ìbú ọwọ́ rẹ̀ tí ó wọn àwọn ọ̀run? Ta ni ó ti kó erùpẹ̀ ilẹ̀ ayé jọ nínú apẹ̀rẹ̀, tàbí kí ó wọn àwọn òkè ńlá lórí ìwọ̀n àti òkè kéékèèké nínú òsùwọ̀n?
13 Cine a îndrumat duhul DOMNULUI, sau l-a învăţat ca sfătuitor al lui?
Ta ni ó ti mọ ọkàn Olúwa, tàbí tí ó ti tọ́ ọ ṣọ́nà gẹ́gẹ́ bí olùdámọ̀ràn rẹ̀?
14 De la cine a luat sfat şi cine l-a instruit şi l-a învăţat în cărarea judecăţii şi l-a învăţat cunoaştere şi i-a arătat calea înţelegerii?
Ta ni Olúwa ké sí kí ó là á lọ́yẹ àti ta ni ó kọ́ òun ní ọ̀nà tí ó tọ́? Ta ni ẹni náà tí ó kọ́ ọ ní ọgbọ́n tàbí tí ó fi ipa ọ̀nà òye hàn án?
15 Iată, naţiunile sunt ca o picătură dintr-o găleată şi sunt socotite ca praful mărunt al balanţei; iată, el ia insulele ca pe un lucru foarte mic.
Nítòótọ́ àwọn orílẹ̀-èdè dàbí i ẹ̀kún omi nínú garawa; a kà wọ́n sí gẹ́gẹ́ bí eruku lórí ìwọ̀n; ó wọn àwọn erékùṣù àfi bí eruku múnúmúnú ni wọ́n.
16 Şi Libanul nu este de ajuns pentru a arde, nici fiarele acestuia nu sunt de ajuns pentru o ofrandă arsă.
Lebanoni kò tó fún pẹpẹ iná, tàbí kí àwọn ẹranko rẹ̀ kí ó tó fún ẹbọ sísun.
17 Toate naţiunile înaintea lui sunt ca nimic; şi sunt socotite pentru el mai puţin decât nimic şi deşertăciune.
Níwájú rẹ̀ ni gbogbo orílẹ̀-èdè dàbí ohun tí kò sí; gbogbo wọn ló kà sí ohun tí kò wúlò tí kò tó ohun tí kò sí.
18 Cu cine atunci veţi asemăna pe Dumnezeu? Sau cu ce asemănare îl veţi compara?
Ta ni nígbà náà tí ìwọ yóò fi Ọlọ́run wé? Ère wo ni ìwọ yóò fi ṣe àkàwé rẹ̀?
19 Lucrătorul topeşte un chip cioplit şi aurarul îl acoperă cu aur şi toarnă lănţişoare de argint.
Ní ti ère, oníṣọ̀nà ni ó dà á, ti alágbẹ̀dẹ wúrà sì fi wúrà bò ó tí a sì ṣe ẹ̀wọ̀n ọ̀nà sílífà fún un.
20 Cel ce este atât de sărac încât nu are un dar, alege un lemn ce nu va putrezi; îşi caută un lucrător iscusit să pregătească un chip cioplit, ce nu va fi mutat.
Ọkùnrin kan tí ó tálákà jù kí ó lè mú irú ọrẹ bẹ́ẹ̀ wá, wá igi tí kò le è rà. Ó wá oníṣọ̀nà tí ó láti ṣe àgbékalẹ̀ ère tí kì yóò le è ṣubú.
21 Nu aţi cunoscut? Nu aţi auzit? Nu vi s-a spus de la început? Nu aţi înţeles de la întemeierea pământului?
Ǹjẹ́ o kò tí ì mọ̀ ìwọ kò tí ì gbọ́? A kò tí ì sọ fún ọ láti ìbẹ̀rẹ̀ wá? Ìwọ kò tí ì mọ láti ìgbà ìpìlẹ̀ ayé?
22 El este cel ce şade pe rotocolul pământului şi locuitorii acestuia sunt ca greieri; el este cel ce întinde cerurile ca pe o perdea şi le întinde ca pe un cort de locuit,
Òun jókòó lórí ìtẹ́ ní òkè òbírí ilẹ̀ ayé, àwọn ènìyàn rẹ̀ sì dàbí i láńtata. Ó ta àwọn ọ̀run bí ìbòrí ìgúnwà, ó sì nà wọ́n jáde gẹ́gẹ́ bí àgọ́ láti gbé.
23 Care nimiceşte prinţii; pe judecătorii pământului el îi face deşertăciune.
Ó sọ àwọn ọmọ ọba di asán àti àwọn aláṣẹ ayé yìí ni ó ti sọ dòfo.
24 Da, ei nu vor fi sădiţi; da, nu vor fi semănaţi; da, tulpina lor nu va prinde rădăcină în pământ, iar el de asemenea va sufla peste ei şi se vor ofili şi vârtejul de vânt îi va duce ca pe paie.
Gẹ́rẹ́ tí a ti gbìn wọ́n, kété tí a gbìn wọ́n, kété tí wọ́n fi gbòǹgbò múlẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ó fẹ́ atẹ́gùn lù wọ́n gbogbo wọn sì gbẹ, bẹ́ ni ìjì líle sì gbá wọn lọ gẹ́gẹ́ bí ìyàngbò.
25 Cu cine mă veţi asemăna, sau cu cine voi fi egal? spune Cel Sfânt.
“Ta ni ẹ ó fi mi wé? Tàbí ta ni ó bá mi dọ́gba?” ni Ẹni Mímọ́ wí.
26 Ridicaţi-vă ochii în înalt şi priviţi cine a creat aceste lucruri, el, care aduce oştirea lor după număr, el le cheamă pe toate pe nume prin măreţia puterii sale, fiindcă este tare în putere; niciuna dintre ele nu se sfârşeşte.
Gbé ojú rẹ sókè kí o sì wo àwọn ọ̀run. Ta ni ó dá àwọn wọ̀nyí? Ẹni tí ó mú àkójọpọ̀ àwọn ìràwọ̀ jáde wá ní ọ̀kọ̀ọ̀kan tí ó sì pè wọ́n ní orúkọ lọ́kọ̀ọ̀kan. Nítorí agbára ńlá àti ipá rẹ̀, ọ̀kan ṣoṣo nínú wọn kò sọnù.
27 De ce spui tu, Iacobe, şi vorbeşti, Israele: Calea mea este ascunsă de DOMNUL şi judecata mea a trecut de la Dumnezeul meu?
Èéṣe tí o fi sọ, ìwọ Jakọbu? Àti tí o ṣàròyé, ìwọ Israẹli, “Ọ̀nà mi pamọ́ níwájú Olúwa; ìṣe mi ni a kò kọbi ara sí láti ọwọ́ Ọlọ́run mi”?
28 Nu ai cunoscut? Nu ai auzit, că Dumnezeul veşnic, DOMNUL, Creatorul marginilor pământului, nu leşină, nici nu oboseşte? Nu este cercetare a înţelegerii lui.
Ìwọ kò tí ì mọ̀? Ìwọ kò tí ì gbọ́? Olúwa òun ni Ọlọ́run ayérayé, Ẹlẹ́dàá gbogbo ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé. Agara kì yóò da bẹ́ẹ̀ ni kò ní ṣàárẹ̀, àti òye rẹ̀ ni ẹnikẹ́ni kò le ṣe òdínwọ̀n rẹ̀.
29 El dă putere celui leşinat; şi celor fără putere le creşte tăria.
Ó ń fi agbára fún àwọn aláàárẹ̀ ó sì fi kún agbára àwọn tí agara dá.
30 Chiar tinerii vor leşina şi vor obosi şi bărbaţi tineri vor cădea de tot,
Àní, ó ń rẹ̀ wọ́n àwọn ọ̀dọ́, wọ́n ń rẹ̀wẹ̀sì, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sì ń kọsẹ̀ wọ́n ṣubú;
31 Dar cei ce aşteaptă pe DOMNUL îşi vor înnoi tăria; se vor ridica cu aripi precum acvilele; vor alerga şi nu vor obosi; vor umbla şi nu vor leşina.
ṣùgbọ́n àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé Olúwa yóò sọ agbára wọn di ọ̀tun. Wọn yóò fìyẹ́ fò lókè bí idì; wọn yóò sáré àárẹ̀ kò ní mú wọn, wọn yóò rìn òòyì kò ní kọ́ wọn.

< Isaia 40 >